< Ezekiel 39 >

1 “Ọmọ ènìyàn, sọtẹ́lẹ̀ sí Gogu, kí ó sì wí pé: ‘Èyí yìí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: Èmi lòdì sí ọ, Ìwọ Gogu, olórí ọmọ-aládé ti Meṣeki àti Tubali.
De aceea, tu fiu al omului, profețește împotriva lui Gog și spune: Astfel spune Domnul DUMNEZEU: Iată, eu [sunt] împotriva ta, Gog, cel dintâi prinț al Meșecului și al Tubalului;
2 Èmi yóò dá ọ padà, èmi yóò sì darí rẹ. Èmi yóò mú ọ wá láti jìnnàjìnnà ìhà àríwá, Èmi yóò rán ọ lòdì sí orí àwọn òkè gíga Israẹli.
Și te voi întoarce și voi lăsa doar a șasea parte din tine și te voi face să te urci din părțile de nord și te voi aduce pe munții lui Israel;
3 Nígbà náà èmi yóò lu ọrùn awọ rẹ ní ọwọ́ òsì rẹ, èmi yóò sì mú kí àwọn ọfà rẹ jábọ́ ni ọwọ́ ọ̀tún rẹ.
Și îți voi lovi arcul din stânga ta și voi face să îți cadă săgețile din dreapta ta.
4 Ìwọ yóò sì ṣubú ní orí àwọn òkè Israẹli, ìwọ àti gbogbo àwọn ọmọ-ogun rẹ àti gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè tí ó wà pẹ̀lú rẹ. Èmi yóò fi ọ ṣe oúnjẹ fún àwọn onírúurú ẹyẹ àti fún àwọn ẹranko igbó.
Vei cădea pe munții lui Israel, tu și toate cetele tale și popoarele care [sunt] cu tine; te voi da păsărilor răpitoare de fiecare fel și fiarelor câmpului să fii mâncat.
5 Ìwọ yóò ṣubú ní gbangba pápá, nítorí tì mo ti sọ̀rọ̀, ni Olúwa Olódùmarè wí.
Vei cădea în câmp deschis, pentru că eu am vorbit [aceasta], spune Domnul DUMNEZEU.
6 Èmi yóò fi iná sí Magogu àti sí àwọn tí ń gbé ní agbègbè ilẹ̀ ibẹ̀ ní àìléwu, wọn yóò sì mọ̀ pé èmi ni Olúwa.
Și voi trimite un foc asupra Magogului și printre cei care locuiesc fără grijă în insule; și vor cunoaște că eu [sunt] DOMNUL.
7 “‘Èmi yóò sọ orúkọ mímọ́ mí di mí mọ̀ láàrín àwọn ènìyàn mì Israẹli. Èmi ki yóò jẹ́ kí orúkọ mímọ́ mi di aláìmọ́ àwọn orílẹ̀-èdè yóò mọ̀ pé, Èmi Olúwa, Èmi ni ẹni mímọ́ ní Israẹli.
Astfel voi face cunoscut numele meu sfânt în mijlocul poporului meu Israel; și nu [îi] voi mai lăsa să pângărească numele meu sfânt; și păgânii vor cunoaște că eu [sunt] DOMNUL, Cel Sfânt în Israel.
8 Ó ń bọ̀! Ó dájú pé yóò ṣẹlẹ̀, ni Olúwa Olódùmarè. Èyí yìí ni ọjọ́ tí mo sọ̀rọ̀ nípa rẹ̀.
Iată, aceasta a venit și s-a făcut, spune Domnul DUMNEZEU; aceasta [este] ziua despre care am vorbit.
9 “‘Nígbà náà, àwọn ti ó ń gbé nì àárín àwọn ìlú tí ó wà ni Israẹli yóò jáde, wọn yóò sì lo àwọn ohun ìjà bi epo ìdáná yóò sì jó wọ́n kanlẹ̀—àpáta kéékèèké àti àpáta ńlá, àwọn ọfà, àwọn kùmọ̀ ogun àti ọ̀kọ̀ fún ọdún méje wọn yóò lò wọ́n bi epo ìdáná.
Și cei ce locuiesc în cetățile lui Israel vor ieși și le vor pune pe foc, vor arde armele, deopotrivă scuturile și platoșele, arcurile și săgețile și ciomegele și sulițele și le vor arde cu foc șapte ani;
10 Wọn kò ní nílò láti kó igi jọ láti inú pápá, tàbí gé e láti inú igbó, nítorí pé wọ́n yóò lo òhun ìjà ogun bi epo ìdáná. Wọn yóò sì kógun àwọn tí ó ṣe ìgárá sí wọn, wọn yóò sì bo ilé àwọn tí ó bo ilé wọn, ni Olúwa Olódùmarè.
Astfel încât nu vor lua lemn de pe câmp, nici nu vor tăia din păduri, pentru că vor arde armele cu foc; și vor prăda pe cei care i-au prădat și vor jefui pe cei care i-au jefuit, spune Domnul DUMNEZEU.
11 “‘Ní ọjọ́ náà èmi yóò sì fi ibi ìsìnkú fún Gogu ní Israẹli, ni àfonífojì àwọn ti ó rìn ìrìnàjò lọ sí agbègbè ilà oòrùn Òkun. Yóò di ojú ọ̀nà àwọn arìnrìn-àjò, nítorí Gogu àti gbogbo ìjọ rẹ̀ ni àwa yóò sin síbẹ̀. Nítorí náà, a yóò pè é ní àfonífojì tí Ammoni Gogu.
Și se va întâmpla în acea zi, [că] voi da lui Gog un loc pentru morminte în Israel, valea trecătorilor spre estul mării; și aceasta va astupa [nasurile] trecătorilor; și acolo vor îngropa pe Gog și toată mulțimea lui; și [o] vor numi Valea lui Hamon-Gog.
12 “‘Fún oṣù méje ní ilé Israẹli yóò fi máa sìn wọ́n láti ṣe àfọ̀mọ́ ilẹ̀ náà.
Și șapte luni îi va îngropa casa lui Israel, ca să curețe pământul.
13 Gbogbo ènìyàn ilẹ̀ náà yóò sìn wọ́n, ọjọ́ tí a yìn mi lógo yóò jẹ́ ọjọ́ ìrántí, ní Olúwa Olódùmarè wí.
Da, tot poporul țării [îi] va îngropa; și va fi pentru ei un renume, ziua în care voi fi glorificat, spune Domnul DUMNEZEU.
14 “‘Wọn yóò gbà àwọn ènìyàn ṣiṣẹ́ lóòrèkóòrè láti ṣe àfọ̀mọ́ náà. Ọ̀pọ̀ yóò lọ káàkiri ilẹ̀ náà, ní àfikún pẹ̀lú wọn, àwọn tókù yóò sìn àwọn tí ó kú lórí ilẹ̀. Ní ìparí oṣù keje wọn yóò bẹ̀rẹ̀ wíwá kiri wọn.
Și vor pune deoparte oameni [care] să lucreze continuu, să treacă prin țară pentru a îngropa împreună cu trecătorii pe cei care rămân pe fața pământului, ca să o curețe; la sfârșitul a șapte luni vor cerceta.
15 Bí wọ́n n lọ káàkiri ilẹ̀ náà ọ̀kan nínú wọn rí egungun ènìyàn, òun yóò gbé àmì ńlá kalẹ̀ ni ẹ̀gbẹ́ rẹ títí àwọn asìnkú yóò fi sìn ín ní àfonífojì Hamoni Gogu.
Și trecătorii [care] trec prin țară, când [vreunul] vede un os de om, atunci să ridice un semn lângă el, până groparii îl vor fi îngropat în valea lui Hamon-Gog.
16 Bákan náà ìlú kan tí a ń pè ni Hamona yóò wà níbẹ̀. Nítorí náà wọn yóò wẹ ilẹ̀ náà.’
Și de asemenea numele cetății [va fi] Hamona. Astfel vor curăți pământul.
17 “Ọmọ ènìyàn èyí yìí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí pé, pe gbogbo oríṣìíríṣìí ẹyẹ àti gbogbo àwọn ẹranko igbó jáde, ‘Kí wọn péjọpọ̀ láti gbogbo agbègbè sí ìrúbọ tí mó ń múra rẹ̀ fún ọ, ìrúbọ ńlá náà ní orí òkè gíga tí Israẹli. Níbẹ̀ ẹ̀yin yóò jẹ ẹran, ẹ̀yin yóò sì mú ẹ̀jẹ̀.
Și tu fiu al omului, astfel spune Domnul DUMNEZEU: Vorbește fiecărei păsări înaripate și tuturor fiarelor câmpului: Adunați-vă și veniți; strângeți-vă din fiecare parte la sacrificiul meu pe care îl sacrific pentru voi, un mare sacrificiu pe munții lui Israel, ca să mâncați carne și să beți sânge.
18 Ẹ̀yin yóò jẹ ẹran-ara àwọn ènìyàn ńlá, ẹ o sì mú ẹ̀jẹ̀ àwọn ọmọ-aládé ayé bí ẹni pé wọn jẹ́ àgbò àti ọ̀dọ́-àgùntàn, ewúrẹ́ àti akọ màlúù gbogbo wọn jẹ́ ẹran ọlọ́ràá láti Baṣani.
Să mâncați carnea celor puternici și să beți sângele prinților pământului, a berbecilor, a mieilor și a caprelor, a taurilor, cu toate vitele îngrășate ale Basanului.
19 Níbi ìrúbọ tí mo ń múra kalẹ̀ fún yín, ẹ̀yin yóò jẹ ọ̀rá títí ẹ̀yin yóò fi jẹ àjẹkì, ẹ̀yin yóò sì mú ẹ̀jẹ̀ títí ẹ̀yin yóò fi yó.
Și veți mânca grăsime până veți fi săturați și veți bea sânge până veți fi beți, din sacrificiul meu pe care l-am sacrificat pentru voi.
20 Ní orí tábìlì mi ni àwa yóò ti fi ẹṣin àti ẹlẹ́ṣin bọ yín yó, pẹ̀lú àwọn alágbára ńlá àti oríṣìíríṣìí jagunjagun,’ ni Olúwa Olódùmarè wí.
Astfel veți fi săturați la masa mea cu cai și care, cu războinici și cu toți bărbații de război, spune Domnul DUMNEZEU.
21 “Èmi yóò ṣe àfihàn ògo mi láàrín àwọn orílẹ̀-èdè, gbogbo orílẹ̀-èdè yóò sì rí ìyà tí mo fi jẹ wọ́n.
Și eu voi pune gloria mea printre păgâni și toți păgânii vor vedea judecata mea pe care am făcut-o și mâna mea pe care am pus-o asupra lor.
22 Láti ọjọ́ náà lọ, ilé Israẹli yóò mọ̀ pé èmi ni Olúwa Ọlọ́run wọn.
Astfel casa lui Israel va cunoaște că eu [sunt] DOMNUL Dumnezeul lor din acea zi înainte.
23 Àwọn orílẹ̀-èdè yóò sì mọ̀ pé àwọn ènìyàn Israẹli lọ sí ìgbèkùn nítorí ẹ̀ṣẹ̀ wọn, nítorí pé wọ́n jẹ́ aláìṣòótọ́ sí mi. Nítorí náà mo mú ojú mi pamọ́ kúrò lọ́dọ̀ wọn, mo sì fi wọn lé àwọn ọ̀tá wọn lọ́wọ́, gbogbo wọn sì ṣubú nípasẹ̀ idà.
Și păgânii vor cunoaște că [ea], casa lui Israel, a mers în captivitate pentru nelegiuirea lor, pentru că au încălcat [legea] împotriva mea, de aceea mi-am ascuns fața de la ei și i-am dat în mâna dușmanilor lor, astfel că au căzut toți prin sabie.
24 Mo ṣe sí wọn gẹ́gẹ́ bí àìmọ́ àti àìṣedéédéé wọn, mo sì mú ojú mi pamọ́ kúrò lọ́dọ̀ wọn.
Conform cu necurăția lor și conform cu fărădelegile lor le-am făcut și mi-am ascuns fața de la ei.
25 “Nítorí náà èyí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: Èmi yóò mú Jakọbu padà kúrò ní oko ẹrú, èmi yóò ní ìyọ́nú si gbogbo ènìyàn Israẹli, èmi yóò sì ní ìtara fún orúkọ mímọ́ mi.
De aceea astfel spune Domnul DUMNEZEU: Acum voi întoarce din nou pe captivii lui Iacob și voi avea milă de toată casa lui Israel și voi fi gelos pentru numele meu cel sfânt;
26 Wọn yóò gbàgbé ìtìjú wọn àti gbogbo àìṣòdodo tí wọ́n fihàn sí mi nígbà tí wọn ń gbé ni àìléwu ni ilẹ̀ wọn níbi tí kò ti sí ẹnikẹ́ni láti dẹ́rùbà wọ́n.
După ce își vor fi purtat rușinea și toate fărădelegile lor prin care au încălcat legea împotriva mea, când locuiau în siguranță în țara lor și nimeni nu îi înfricoșa.
27 Nígbà tí mo ti mú wọn padà kúrò ní àwọn orílẹ̀-èdè, tí mo sì kó wọn jọ pọ̀ kúrò ni ìlú àwọn ọ̀tá wọn, èmi yóò fi ara mi hàn ni mímọ́ nípasẹ̀ wọn ní ojú àwọn orílẹ̀-èdè púpọ̀.
După ce îi voi fi întors din nou dintre popoare și îi voi fi adunat din țările dușmanilor lor și voi fi sfințit în ei înaintea ochilor multor națiuni;
28 Nígbà náà, wọn yóò mọ̀ pé èmi ni Olúwa Ọlọ́run wọn nítorí bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé mo rán wọn lọ sí ìgbèkùn láàrín àwọn orílẹ̀-èdè, èmi yóò kó wọn jọ sí orí ilẹ̀ wọn, láìfi nǹkan kan sẹ́yìn.
Atunci vor cunoaște că eu [sunt] DOMNUL Dumnezeul lor, care i-a făcut să fie duși în captivitate printre păgâni; dar i-am adunat [apoi] în propria lor țară și nu am mai lăsat pe niciunul dintre ei acolo,
29 Èmi kì yóò sì fi ojú mi pamọ́ kúrò lọ́dọ̀ wọn mọ nítorí èmi yóò tú èémí mi jáde sí ilé Israẹli, ní Olúwa Olódùmarè wí.”
Nici nu îmi voi mai ascunde fața de la ei, pentru că am turnat duhul meu peste casa lui Israel, spune DOMNUL Dumnezeu.

< Ezekiel 39 >