< Ezekiel 39 >

1 “Ọmọ ènìyàn, sọtẹ́lẹ̀ sí Gogu, kí ó sì wí pé: ‘Èyí yìí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: Èmi lòdì sí ọ, Ìwọ Gogu, olórí ọmọ-aládé ti Meṣeki àti Tubali.
«پس تو‌ای پسر انسان درباره جوج نبوت کرده، بگو خداوند یهوه چنین می‌فرماید که اینک‌ای جوج رئیس روش وماشک و توبال من به ضد تو هستم.۱
2 Èmi yóò dá ọ padà, èmi yóò sì darí rẹ. Èmi yóò mú ọ wá láti jìnnàjìnnà ìhà àríwá, Èmi yóò rán ọ lòdì sí orí àwọn òkè gíga Israẹli.
و تو رابرمی گردانم و رهبری می‌نمایم و تو را از اطراف شمال برآورده، بر کوههای اسرائیل خواهم آورد.۲
3 Nígbà náà èmi yóò lu ọrùn awọ rẹ ní ọwọ́ òsì rẹ, èmi yóò sì mú kí àwọn ọfà rẹ jábọ́ ni ọwọ́ ọ̀tún rẹ.
و کمان تو را از دست چپت انداخته، تیرهای تو را از دست راستت خواهم افکند.۳
4 Ìwọ yóò sì ṣubú ní orí àwọn òkè Israẹli, ìwọ àti gbogbo àwọn ọmọ-ogun rẹ àti gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè tí ó wà pẹ̀lú rẹ. Èmi yóò fi ọ ṣe oúnjẹ fún àwọn onírúurú ẹyẹ àti fún àwọn ẹranko igbó.
وتو و همه افواجت و قوم هایی که همراه تو هستندبر کوههای اسرائیل خواهید افتاد و تو را به هرجنس مرغان شکاری و به حیوانات صحرا به جهت خوراک خواهم داد.۴
5 Ìwọ yóò ṣubú ní gbangba pápá, nítorí tì mo ti sọ̀rọ̀, ni Olúwa Olódùmarè wí.
خداوند یهوه می‌گوید که به روی صحرا خواهی افتاد زیرا که من تکلم نموده‌ام.۵
6 Èmi yóò fi iná sí Magogu àti sí àwọn tí ń gbé ní agbègbè ilẹ̀ ibẹ̀ ní àìléwu, wọn yóò sì mọ̀ pé èmi ni Olúwa.
و آتشی بر ماجوج و بر کسانی که در جزایر به امنیت ساکنند خواهم فرستاد تابدانند که من یهوه هستم.۶
7 “‘Èmi yóò sọ orúkọ mímọ́ mí di mí mọ̀ láàrín àwọn ènìyàn mì Israẹli. Èmi ki yóò jẹ́ kí orúkọ mímọ́ mi di aláìmọ́ àwọn orílẹ̀-èdè yóò mọ̀ pé, Èmi Olúwa, Èmi ni ẹni mímọ́ ní Israẹli.
و نام قدوس خود را درمیان قوم خویش اسرائیل، معروف خواهم ساخت و دیگر نمی گذارم که اسم قدوس من بی‌حرمت شود تا امت‌ها بدانند که من یهوه قدوس اسرائیل می‌باشم.۷
8 Ó ń bọ̀! Ó dájú pé yóò ṣẹlẹ̀, ni Olúwa Olódùmarè. Èyí yìí ni ọjọ́ tí mo sọ̀rọ̀ nípa rẹ̀.
اینک خداوند یهوه می‌گوید: آن می‌آید و به وقوع خواهد پیوست. واین همان روز است که درباره‌اش تکلم نموده‌ام.۸
9 “‘Nígbà náà, àwọn ti ó ń gbé nì àárín àwọn ìlú tí ó wà ni Israẹli yóò jáde, wọn yóò sì lo àwọn ohun ìjà bi epo ìdáná yóò sì jó wọ́n kanlẹ̀—àpáta kéékèèké àti àpáta ńlá, àwọn ọfà, àwọn kùmọ̀ ogun àti ọ̀kọ̀ fún ọdún méje wọn yóò lò wọ́n bi epo ìdáná.
و ساکنان شهرهای اسرائیل بیرون خواهند آمدو اسلحه یعنی مجن و سپر و کمان و تیرها وچوب دستی و نیزه‌ها را آتش زده، خواهندسوزانید. و مدت هفت سال آتش را به آنها زنده نگاه خواهند داشت.۹
10 Wọn kò ní nílò láti kó igi jọ láti inú pápá, tàbí gé e láti inú igbó, nítorí pé wọ́n yóò lo òhun ìjà ogun bi epo ìdáná. Wọn yóò sì kógun àwọn tí ó ṣe ìgárá sí wọn, wọn yóò sì bo ilé àwọn tí ó bo ilé wọn, ni Olúwa Olódùmarè.
و هیزم از صحرا نخواهندآورد و چوب از جنگلها نخواهند برید زیرا که اسلحه‌ها را به آتش خواهند سوزانید. و خداوندیهوه می‌گوید که غارت کنندگان خود را غارت خواهند کرد و تاراج کنندگان خویش را تاراج خواهند نمود.۱۰
11 “‘Ní ọjọ́ náà èmi yóò sì fi ibi ìsìnkú fún Gogu ní Israẹli, ni àfonífojì àwọn ti ó rìn ìrìnàjò lọ sí agbègbè ilà oòrùn Òkun. Yóò di ojú ọ̀nà àwọn arìnrìn-àjò, nítorí Gogu àti gbogbo ìjọ rẹ̀ ni àwa yóò sin síbẹ̀. Nítorí náà, a yóò pè é ní àfonífojì tí Ammoni Gogu.
و در آن روز موضعی برای قبردر اسرائیل یعنی وادی عابریم را بطرف مشرق دریا به جوج خواهم داد. و راه عبور کنندگان رامسدود خواهد ساخت. و در آنجا جوج و تمامی جمعیت، او را دفن خواهند کرد و آن را وادی هامون جوج خواهند نامید.۱۱
12 “‘Fún oṣù méje ní ilé Israẹli yóò fi máa sìn wọ́n láti ṣe àfọ̀mọ́ ilẹ̀ náà.
و خاندان اسرائیل مدت هفت ماه ایشان را دفن خواهند کرد تا زمین را طاهر سازند.۱۲
13 Gbogbo ènìyàn ilẹ̀ náà yóò sìn wọ́n, ọjọ́ tí a yìn mi lógo yóò jẹ́ ọjọ́ ìrántí, ní Olúwa Olódùmarè wí.
و تمامی اهل زمین ایشان رادفن خواهند کرد. و خداوند یهوه می‌گوید: روزتمجید من نیکنامی ایشان خواهد بود.۱۳
14 “‘Wọn yóò gbà àwọn ènìyàn ṣiṣẹ́ lóòrèkóòrè láti ṣe àfọ̀mọ́ náà. Ọ̀pọ̀ yóò lọ káàkiri ilẹ̀ náà, ní àfikún pẹ̀lú wọn, àwọn tókù yóò sìn àwọn tí ó kú lórí ilẹ̀. Ní ìparí oṣù keje wọn yóò bẹ̀rẹ̀ wíwá kiri wọn.
وکسانی را معین خواهند کرد که پیوسته در زمین گردش نمایند. و همراه عبورکنندگان آنانی را که بر روی زمین باقی‌مانده باشند دفن کرده، آن راطاهر سازند. بعد از انقضای هفت ماه آنها راخواهند طلبید.۱۴
15 Bí wọ́n n lọ káàkiri ilẹ̀ náà ọ̀kan nínú wọn rí egungun ènìyàn, òun yóò gbé àmì ńlá kalẹ̀ ni ẹ̀gbẹ́ rẹ títí àwọn asìnkú yóò fi sìn ín ní àfonífojì Hamoni Gogu.
و عبورکنندگان در زمین گردش خواهند کرد. و اگر کسی استخوان آدمی بیند نشانی نزد آن برپا کند تا دفن کنندگان آن را دروادی هامون جوج مدفون سازند.۱۵
16 Bákan náà ìlú kan tí a ń pè ni Hamona yóò wà níbẹ̀. Nítorí náà wọn yóò wẹ ilẹ̀ náà.’
و اسم شهرنیز هامونه خواهد بود. پس زمین را طاهر خواهندساخت.۱۶
17 “Ọmọ ènìyàn èyí yìí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí pé, pe gbogbo oríṣìíríṣìí ẹyẹ àti gbogbo àwọn ẹranko igbó jáde, ‘Kí wọn péjọpọ̀ láti gbogbo agbègbè sí ìrúbọ tí mó ń múra rẹ̀ fún ọ, ìrúbọ ńlá náà ní orí òkè gíga tí Israẹli. Níbẹ̀ ẹ̀yin yóò jẹ ẹran, ẹ̀yin yóò sì mú ẹ̀jẹ̀.
«و اما تو‌ای پسر انسان! خداوند یهوه چنین می‌فرماید که بهر جنس مرغان و به همه حیوانات صحرا بگو: جمع شوید و بیایید و نزد قربانی من که آن را برای شما ذبح می‌نمایم، فراهم آیید. قربانی عظیمی بر کوههای اسرائیل تا گوشت بخورید و خون بنوشید.۱۷
18 Ẹ̀yin yóò jẹ ẹran-ara àwọn ènìyàn ńlá, ẹ o sì mú ẹ̀jẹ̀ àwọn ọmọ-aládé ayé bí ẹni pé wọn jẹ́ àgbò àti ọ̀dọ́-àgùntàn, ewúrẹ́ àti akọ màlúù gbogbo wọn jẹ́ ẹran ọlọ́ràá láti Baṣani.
گوشت جباران راخواهید خورد و خون روسای جهان را خواهیدنوشید. از قوچها و بره‌ها و بزها و گاوها که همه آنها از پرواریهای باشان می‌باشند.۱۸
19 Níbi ìrúbọ tí mo ń múra kalẹ̀ fún yín, ẹ̀yin yóò jẹ ọ̀rá títí ẹ̀yin yóò fi jẹ àjẹkì, ẹ̀yin yóò sì mú ẹ̀jẹ̀ títí ẹ̀yin yóò fi yó.
و از قربانی من که برای شما ذبح می‌نمایم، پیه خواهید خوردتا سیر شوید و خون خواهید نوشید تا مست شوید.۱۹
20 Ní orí tábìlì mi ni àwa yóò ti fi ẹṣin àti ẹlẹ́ṣin bọ yín yó, pẹ̀lú àwọn alágbára ńlá àti oríṣìíríṣìí jagunjagun,’ ni Olúwa Olódùmarè wí.
و خداوند یهوه می‌گوید که بر سفره من از اسبان و سواران و جباران و همه مردان جنگی سیر خواهید شد.۲۰
21 “Èmi yóò ṣe àfihàn ògo mi láàrín àwọn orílẹ̀-èdè, gbogbo orílẹ̀-èdè yóò sì rí ìyà tí mo fi jẹ wọ́n.
و من جلال خود را در میان امت‌ها قرار خواهم داد و جمیع امت‌ها داوری مرا که آن را اجرا خواهم داشت و دست مرا که برایشان فرود خواهم آورد، مشاهده خواهند نمود.۲۱
22 Láti ọjọ́ náà lọ, ilé Israẹli yóò mọ̀ pé èmi ni Olúwa Ọlọ́run wọn.
و خاندان اسرائیل از آن روز و بعد خواهنددانست که یهوه خدای ایشان من هستم.۲۲
23 Àwọn orílẹ̀-èdè yóò sì mọ̀ pé àwọn ènìyàn Israẹli lọ sí ìgbèkùn nítorí ẹ̀ṣẹ̀ wọn, nítorí pé wọ́n jẹ́ aláìṣòótọ́ sí mi. Nítorí náà mo mú ojú mi pamọ́ kúrò lọ́dọ̀ wọn, mo sì fi wọn lé àwọn ọ̀tá wọn lọ́wọ́, gbogbo wọn sì ṣubú nípasẹ̀ idà.
وامت‌ها خواهند دانست که خاندان اسرائیل به‌سبب گناه خودشان جلای وطن گردیدند. زیراچونکه به من خیانت ورزیدند، من روی خود را ازایشان پوشانیدم و ایشان را به‌دست ستم کاران ایشان تسلیم نمودم که جمیع ایشان به شمشیرافتادند.۲۳
24 Mo ṣe sí wọn gẹ́gẹ́ bí àìmọ́ àti àìṣedéédéé wọn, mo sì mú ojú mi pamọ́ kúrò lọ́dọ̀ wọn.
برحسب نجاسات و تقصیرات ایشان به ایشان عمل نموده، روی خود را از ایشان پوشانیدم.»۲۴
25 “Nítorí náà èyí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: Èmi yóò mú Jakọbu padà kúrò ní oko ẹrú, èmi yóò ní ìyọ́nú si gbogbo ènìyàn Israẹli, èmi yóò sì ní ìtara fún orúkọ mímọ́ mi.
بنابراین خداوند یهوه چنین می‌گوید: «الان اسیران یعقوب را باز آورده، بر تمامی خاندان اسرائیل رحمت خواهم فرمود و بر اسم قدوس خود غیرت خواهم نمود.۲۵
26 Wọn yóò gbàgbé ìtìjú wọn àti gbogbo àìṣòdodo tí wọ́n fihàn sí mi nígbà tí wọn ń gbé ni àìléwu ni ilẹ̀ wọn níbi tí kò ti sí ẹnikẹ́ni láti dẹ́rùbà wọ́n.
و حینی که ایشان درزمین خود به امنیت ساکن شوند و ترساننده‌ای نباشد، آنگاه خجالت خود را و خیانتی را که به من ورزیده‌اند متحمل خواهند شد.۲۶
27 Nígbà tí mo ti mú wọn padà kúrò ní àwọn orílẹ̀-èdè, tí mo sì kó wọn jọ pọ̀ kúrò ni ìlú àwọn ọ̀tá wọn, èmi yóò fi ara mi hàn ni mímọ́ nípasẹ̀ wọn ní ojú àwọn orílẹ̀-èdè púpọ̀.
و چون ایشان را از میان امت‌ها برگردانم و ایشان را از زمین دشمنانشان جمع نمایم، آنگاه در نظر امت های بسیار در ایشان تقدیس خواهم شد.۲۷
28 Nígbà náà, wọn yóò mọ̀ pé èmi ni Olúwa Ọlọ́run wọn nítorí bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé mo rán wọn lọ sí ìgbèkùn láàrín àwọn orílẹ̀-èdè, èmi yóò kó wọn jọ sí orí ilẹ̀ wọn, láìfi nǹkan kan sẹ́yìn.
و خواهنددانست که من یهوه خدای ایشان هستم، از آن روکه من ایشان را در میان امت‌ها جلای وطن ساختم و ایشان را به زمین خودشان جمع کردم و بار دیگرکسی را از ایشان در آنجا باقی نخواهم گذاشت.۲۸
29 Èmi kì yóò sì fi ojú mi pamọ́ kúrò lọ́dọ̀ wọn mọ nítorí èmi yóò tú èémí mi jáde sí ilé Israẹli, ní Olúwa Olódùmarè wí.”
و خداوند یهوه می‌گوید که من بار دیگرروی خود را از ایشان نخواهم پوشانید زیراکه روح خویش را بر خاندان اسرائیل خواهم ریخت.»۲۹

< Ezekiel 39 >