< Ezekiel 39 >

1 “Ọmọ ènìyàn, sọtẹ́lẹ̀ sí Gogu, kí ó sì wí pé: ‘Èyí yìí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: Èmi lòdì sí ọ, Ìwọ Gogu, olórí ọmọ-aládé ti Meṣeki àti Tubali.
Aa le mitokia amy Goge ry ana’ ondatio, le ano ty hoe: Inay ty nafè’ Iehovà Talè: Inao t’ie atreatreko ry Goge, roandrian-drovabei’ i Meseke naho i Tobale;
2 Èmi yóò dá ọ padà, èmi yóò sì darí rẹ. Èmi yóò mú ọ wá láti jìnnàjìnnà ìhà àríwá, Èmi yóò rán ọ lòdì sí orí àwọn òkè gíga Israẹli.
hampitoliheko naho haronjeko mb’eo naho ho rambeseko boak’ an-kotsokotsoke fara’ i avara­tsey vaho haseseko hiatreatre o vohi’ Israeleo;
3 Nígbà náà èmi yóò lu ọrùn awọ rẹ ní ọwọ́ òsì rẹ, èmi yóò sì mú kí àwọn ọfà rẹ jábọ́ ni ọwọ́ ọ̀tún rẹ.
ho takapiheko boak’ am-pità’o havia ty fale’o, vaho hampipopoheko boak’ am-pità’o havana o ana-pale’ oo.
4 Ìwọ yóò sì ṣubú ní orí àwọn òkè Israẹli, ìwọ àti gbogbo àwọn ọmọ-ogun rẹ àti gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè tí ó wà pẹ̀lú rẹ. Èmi yóò fi ọ ṣe oúnjẹ fún àwọn onírúurú ẹyẹ àti fún àwọn ẹranko igbó.
Ie hitsingoro amo vohi’ Israeleo, ihe naho o lia-rai’o iabio naho i valobohòke mihipok’ ama’oy; hatoloko amy ze hene karaza-voroñe naho amy ze fonga mpitiliñe vaho amo bibin-kivokeo habotse’e.
5 Ìwọ yóò ṣubú ní gbangba pápá, nítorí tì mo ti sọ̀rọ̀, ni Olúwa Olódùmarè wí.
Hitsin­goritritse amy ze montoñe iaby irehe; amy te Izaho ty nivolañe, hoe t’Iehovà Talè.
6 Èmi yóò fi iná sí Magogu àti sí àwọn tí ń gbé ní agbègbè ilẹ̀ ibẹ̀ ní àìléwu, wọn yóò sì mọ̀ pé èmi ni Olúwa.
Hahitriko amy Magoge ty afo, naho amo mimoneñe amo tokonoseoo. vaho ho fohi’ iareo te Izaho Iehovà.
7 “‘Èmi yóò sọ orúkọ mímọ́ mí di mí mọ̀ láàrín àwọn ènìyàn mì Israẹli. Èmi ki yóò jẹ́ kí orúkọ mímọ́ mi di aláìmọ́ àwọn orílẹ̀-èdè yóò mọ̀ pé, Èmi Olúwa, Èmi ni ẹni mímọ́ ní Israẹli.
Izay ty hampahafohineko añivo’ ondatiko Israeleo ty tahinako masiñe naho tsy ho tivàñe ka ty añarako masiñe vaho ho fohi’ o fifeheañeo te Izaho Iehovà ro Masiñe am’Israele ao.
8 Ó ń bọ̀! Ó dájú pé yóò ṣẹlẹ̀, ni Olúwa Olódùmarè. Èyí yìí ni ọjọ́ tí mo sọ̀rọ̀ nípa rẹ̀.
Hehe te tondroke, naho toe ho heneke, hoe t’Iehovà Talè, i andro nivolañakoy.
9 “‘Nígbà náà, àwọn ti ó ń gbé nì àárín àwọn ìlú tí ó wà ni Israẹli yóò jáde, wọn yóò sì lo àwọn ohun ìjà bi epo ìdáná yóò sì jó wọ́n kanlẹ̀—àpáta kéékèèké àti àpáta ńlá, àwọn ọfà, àwọn kùmọ̀ ogun àti ọ̀kọ̀ fún ọdún méje wọn yóò lò wọ́n bi epo ìdáná.
Hiakatse mb’eo o mpimoneñe amo rova’ Israeleo le ho viañe’ iereo afo hamorototo o fialiañeo, o fikalañan’ arañañeo, o fañaron-tsirao, o fale naho ana-paleo, o kobaiñe naho lefoñeo vaho harehe’ iareo añ’ afo hahamodo fito taoñe;
10 Wọn kò ní nílò láti kó igi jọ láti inú pápá, tàbí gé e láti inú igbó, nítorí pé wọ́n yóò lo òhun ìjà ogun bi epo ìdáná. Wọn yóò sì kógun àwọn tí ó ṣe ìgárá sí wọn, wọn yóò sì bo ilé àwọn tí ó bo ilé wọn, ni Olúwa Olódùmarè.
le tsy eo ty hitoha hatae an-kivok’ añe, ndra hamira hatae añ’ala ao; fa harehe’e añ’ afo ao o fialiañeo; naho ho kopaheñe o nikopak’ iareoo, vaho ho kamereñe o nikametse am’ iareoo, hoe t’Iehovà Talè.
11 “‘Ní ọjọ́ náà èmi yóò sì fi ibi ìsìnkú fún Gogu ní Israẹli, ni àfonífojì àwọn ti ó rìn ìrìnàjò lọ sí agbègbè ilà oòrùn Òkun. Yóò di ojú ọ̀nà àwọn arìnrìn-àjò, nítorí Gogu àti gbogbo ìjọ rẹ̀ ni àwa yóò sin síbẹ̀. Nítorí náà, a yóò pè é ní àfonífojì tí Ammoni Gogu.
Hifetsak’ amy andro zay te ho tolo­rako toetse e Israele ao ho kibori’ i Goge, i vavatanem-pitsàhañe atiñana’ i riakeiy; ze hanebam-pi­tsake; ao ty handeveña’ iareo i Goge naho i valobohò’ey; vaho ho tokaveñe ty hoe: Vavatanem-balobohò’ i Goge.
12 “‘Fún oṣù méje ní ilé Israẹli yóò fi máa sìn wọ́n láti ṣe àfọ̀mọ́ ilẹ̀ náà.
Fito volañe ty handeveña’ i anjomba’ Israeley iareo hañalio i taney.
13 Gbogbo ènìyàn ilẹ̀ náà yóò sìn wọ́n, ọjọ́ tí a yìn mi lógo yóò jẹ́ ọjọ́ ìrántí, ní Olúwa Olódùmarè wí.
Eka hene handenteke iareo ze ondati’ i taney, le hahazoako engeñe vaho ho andro añonjonañe ahy hoe t’Iehovà Talè.
14 “‘Wọn yóò gbà àwọn ènìyàn ṣiṣẹ́ lóòrèkóòrè láti ṣe àfọ̀mọ́ náà. Ọ̀pọ̀ yóò lọ káàkiri ilẹ̀ náà, ní àfikún pẹ̀lú wọn, àwọn tókù yóò sìn àwọn tí ó kú lórí ilẹ̀. Ní ìparí oṣù keje wọn yóò bẹ̀rẹ̀ wíwá kiri wọn.
Ho joboñe’ iereo ondaty mahafitoloñe, hiranga i taney mindre amo mpitsàkeo handenteke ze mbe midoñe ambone tane eo, hañalio aze; toe hitsoeke mifototse ami’ty volam-paha-fito iereo.
15 Bí wọ́n n lọ káàkiri ilẹ̀ náà ọ̀kan nínú wọn rí egungun ènìyàn, òun yóò gbé àmì ńlá kalẹ̀ ni ẹ̀gbẹ́ rẹ títí àwọn asìnkú yóò fi sìn ín ní àfonífojì Hamoni Gogu.
Aa naho iranga’ t’in­daty vaho ie mahaisake taola’ ondaty, le hañoreña’e vorovoro marine aze eo ampara’ te naleve’ o mpandentekeo am-bavatane’ i Valobohò’ i Gogey ao.
16 Bákan náà ìlú kan tí a ń pè ni Hamona yóò wà níbẹ̀. Nítorí náà wọn yóò wẹ ilẹ̀ náà.’
Le hatao Hamonà ka ty añara’ i rovay; izay ty hañaliova’ iareo i taney.
17 “Ọmọ ènìyàn èyí yìí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí pé, pe gbogbo oríṣìíríṣìí ẹyẹ àti gbogbo àwọn ẹranko igbó jáde, ‘Kí wọn péjọpọ̀ láti gbogbo agbègbè sí ìrúbọ tí mó ń múra rẹ̀ fún ọ, ìrúbọ ńlá náà ní orí òkè gíga tí Israẹli. Níbẹ̀ ẹ̀yin yóò jẹ ẹran, ẹ̀yin yóò sì mú ẹ̀jẹ̀.
Aa ihe, ana’ondatio, hoe ty nafè’ Iehovà Talè: Misaontsia amy ze fonga karazam-boroñe naho amy ze hene bibin-kivoke: Mitontona, mb’etoa; songa hivory añ’ ila’ i fisoroñakoy, i hisoroñako ho anahareoy, fisoroñam-bey an-kaboa’ Israele ey, hihinana’ areo nofotse naho hinoma’ areo lio.
18 Ẹ̀yin yóò jẹ ẹran-ara àwọn ènìyàn ńlá, ẹ o sì mú ẹ̀jẹ̀ àwọn ọmọ-aládé ayé bí ẹni pé wọn jẹ́ àgbò àti ọ̀dọ́-àgùntàn, ewúrẹ́ àti akọ màlúù gbogbo wọn jẹ́ ẹran ọlọ́ràá láti Baṣani.
Habotse’ areo ty nofo’ o fanalolahio naho hinoñe ty lio’ o roandria’ ty tane toio; hoe t’ie añondrilahy naho ose-lahy vaho añombelahy songa vinondrake e Basane ao.
19 Níbi ìrúbọ tí mo ń múra kalẹ̀ fún yín, ẹ̀yin yóò jẹ ọ̀rá títí ẹ̀yin yóò fi jẹ àjẹkì, ẹ̀yin yóò sì mú ẹ̀jẹ̀ títí ẹ̀yin yóò fi yó.
Fonga hamotseke solike ampara’ te etsake, naho hinon-dio ampara’ te mamo amy soroñe nisoroñako ho anahareoy
20 Ní orí tábìlì mi ni àwa yóò ti fi ẹṣin àti ẹlẹ́ṣin bọ yín yó, pẹ̀lú àwọn alágbára ńlá àti oríṣìíríṣìí jagunjagun,’ ni Olúwa Olódùmarè wí.
ie hampivon­tsiñeñe am-pandam­bañako eo amo soavalao naho amo sarete maozatseo vaho amo lahin-defoñe iabio, hoe t’Iehovà Talè.
21 “Èmi yóò ṣe àfihàn ògo mi láàrín àwọn orílẹ̀-èdè, gbogbo orílẹ̀-èdè yóò sì rí ìyà tí mo fi jẹ wọ́n.
Aa le hajadoko amo kilakila’ ndatio ty engeko, naho ho oni’ o kilakila’ ndatio i zaka nafetsakoy vaho ty tañako napetako am’ iareo.
22 Láti ọjọ́ náà lọ, ilé Israẹli yóò mọ̀ pé èmi ni Olúwa Ọlọ́run wọn.
Le ho fohi’ i anjomba’ Israeley te Izaho Iehovà, Andrianañahare’ iareo henane zay vaho nainai’e.
23 Àwọn orílẹ̀-èdè yóò sì mọ̀ pé àwọn ènìyàn Israẹli lọ sí ìgbèkùn nítorí ẹ̀ṣẹ̀ wọn, nítorí pé wọ́n jẹ́ aláìṣòótọ́ sí mi. Nítorí náà mo mú ojú mi pamọ́ kúrò lọ́dọ̀ wọn, mo sì fi wọn lé àwọn ọ̀tá wọn lọ́wọ́, gbogbo wọn sì ṣubú nípasẹ̀ idà.
Ho fohi’ o kilakila’ ndatio te nisese mb’ am-pandrohizañe añe ty anjomba’ Israele ty amo hakeo’eo amy t’ie niola amako, le naetako am’ iereo ty tareheko naho natoloko am-pità’ o rafelahi’ iareoo, vaho fonga nitsingorom-pibara.
24 Mo ṣe sí wọn gẹ́gẹ́ bí àìmọ́ àti àìṣedéédéé wọn, mo sì mú ojú mi pamọ́ kúrò lọ́dọ̀ wọn.
Mira ami’ty haleora’ iareo naho ami’ty fiolà’ iareo ty nanoeko am’ iareo, vaho nañetahako tarehe.
25 “Nítorí náà èyí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: Èmi yóò mú Jakọbu padà kúrò ní oko ẹrú, èmi yóò ní ìyọ́nú si gbogbo ènìyàn Israẹli, èmi yóò sì ní ìtara fún orúkọ mímọ́ mi.
Aa le hoe ty nafè’Iehovà Talè: Hampoliko henane zao ty fandrohiza’ Iakobe naho ho tretrezeko iaby ty anjomba’ Israele vaho ho farahieko ty añarako masiñe.
26 Wọn yóò gbàgbé ìtìjú wọn àti gbogbo àìṣòdodo tí wọ́n fihàn sí mi nígbà tí wọn ń gbé ni àìléwu ni ilẹ̀ wọn níbi tí kò ti sí ẹnikẹ́ni láti dẹ́rùbà wọ́n.
Ie amy zay, ho haliño’ iereo ty fisalara’ iareo ty amo fiolàñe niolà’ iareo amakoo ie fa mierañerañe an-tane’ iareo ao, ie tsy eo ty mpañembañe,
27 Nígbà tí mo ti mú wọn padà kúrò ní àwọn orílẹ̀-èdè, tí mo sì kó wọn jọ pọ̀ kúrò ni ìlú àwọn ọ̀tá wọn, èmi yóò fi ara mi hàn ni mímọ́ nípasẹ̀ wọn ní ojú àwọn orílẹ̀-èdè púpọ̀.
naho hampoliko hirik’ amo kilakila’ ndatio iereo, naho hambineko boak’ an-tane’ o rafelahi’eo vaho ho toloreñ’ asin-draho am-pahaisaham-pifeheañe maro;
28 Nígbà náà, wọn yóò mọ̀ pé èmi ni Olúwa Ọlọ́run wọn nítorí bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé mo rán wọn lọ sí ìgbèkùn láàrín àwọn orílẹ̀-èdè, èmi yóò kó wọn jọ sí orí ilẹ̀ wọn, láìfi nǹkan kan sẹ́yìn.
le ho fohi’ iereo te Izaho Iehovà Andrianañahare’ iareo, ty nanese iareo mb’am-pandrohizañe añe añivo’ o kilakila’ ndatio naho natontoko boak’ an-tane’ iareo añe naho leo raike tsy hapoko
29 Èmi kì yóò sì fi ojú mi pamọ́ kúrò lọ́dọ̀ wọn mọ nítorí èmi yóò tú èémí mi jáde sí ilé Israẹli, ní Olúwa Olódùmarè wí.”
vaho tsy hañetahako tarehe ka fa hakofòko amy anjomba’ Israeley ty Tioko, hoe t’Iehovà Talè.

< Ezekiel 39 >