< Ezekiel 39 >
1 “Ọmọ ènìyàn, sọtẹ́lẹ̀ sí Gogu, kí ó sì wí pé: ‘Èyí yìí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: Èmi lòdì sí ọ, Ìwọ Gogu, olórí ọmọ-aládé ti Meṣeki àti Tubali.
NOLAILA, e ke keiki a ke kanaka, e wanana ku e oe ia Goga, a e olelo aku, Ke i mai nei Iehova ka Haku, penei; Eia hoi. ke ku e nei au ia oe, e Goga, ka moi nui o Meseka a me Tubala:
2 Èmi yóò dá ọ padà, èmi yóò sì darí rẹ. Èmi yóò mú ọ wá láti jìnnàjìnnà ìhà àríwá, Èmi yóò rán ọ lòdì sí orí àwọn òkè gíga Israẹli.
E hoihoi au ia oe ihope, a e alakai aku au ia oe, a e hoohele mai au ia oe mai na wahi kukulu akau mai, a e lawe mai au ia oe maluna o na mauna o ka Iseraela.
3 Nígbà náà èmi yóò lu ọrùn awọ rẹ ní ọwọ́ òsì rẹ, èmi yóò sì mú kí àwọn ọfà rẹ jábọ́ ni ọwọ́ ọ̀tún rẹ.
A e pai ae au i kou kakaka mai loko ae o kou lima hema, a e hoohaule iho au i kou mau pua mai loko iho o kou lima akau.
4 Ìwọ yóò sì ṣubú ní orí àwọn òkè Israẹli, ìwọ àti gbogbo àwọn ọmọ-ogun rẹ àti gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè tí ó wà pẹ̀lú rẹ. Èmi yóò fi ọ ṣe oúnjẹ fún àwọn onírúurú ẹyẹ àti fún àwọn ẹranko igbó.
A e haule oe maluna iho o na mauna o ka Iseraela, o oe a me kou mau puali kaua a pau, a me ka poe me oe; a e haawi aku au ia oe i na manu kaili wale o kela eheu keia eheu, a me na holoholona o ke kula a pau i ka aiia.
5 Ìwọ yóò ṣubú ní gbangba pápá, nítorí tì mo ti sọ̀rọ̀, ni Olúwa Olódùmarè wí.
E haule oe ma ke kula mawaho; no ka mea, owau o Iehova ka Haku ka i olelo aku.
6 Èmi yóò fi iná sí Magogu àti sí àwọn tí ń gbé ní agbègbè ilẹ̀ ibẹ̀ ní àìléwu, wọn yóò sì mọ̀ pé èmi ni Olúwa.
E hoouna aku hoi au i ke ahi maloko o Magoga, a iwaena hoi o ka poe e noho palaka ana ma na mokupuni; a e ike lakou owau no Iehova.
7 “‘Èmi yóò sọ orúkọ mímọ́ mí di mí mọ̀ láàrín àwọn ènìyàn mì Israẹli. Èmi ki yóò jẹ́ kí orúkọ mímọ́ mi di aláìmọ́ àwọn orílẹ̀-èdè yóò mọ̀ pé, Èmi Olúwa, Èmi ni ẹni mímọ́ ní Israẹli.
A e hoikeia au i ko'u inoa hoano iwaena o ko'u poe kanaka Iseraela, aole e hoohaumia hou i ko'u inoa; a e ike no hoi na lahuikanaka owau no Iehova, ka Mea hoano iloko o ka Iseraela.
8 Ó ń bọ̀! Ó dájú pé yóò ṣẹlẹ̀, ni Olúwa Olódùmarè. Èyí yìí ni ọjọ́ tí mo sọ̀rọ̀ nípa rẹ̀.
Aia hoi ua hiki mai ia, ua hanaia no hoi, wahi a Iehova ka Haku; o ka la keia a'u i olelo ai.
9 “‘Nígbà náà, àwọn ti ó ń gbé nì àárín àwọn ìlú tí ó wà ni Israẹli yóò jáde, wọn yóò sì lo àwọn ohun ìjà bi epo ìdáná yóò sì jó wọ́n kanlẹ̀—àpáta kéékèèké àti àpáta ńlá, àwọn ọfà, àwọn kùmọ̀ ogun àti ọ̀kọ̀ fún ọdún méje wọn yóò lò wọ́n bi epo ìdáná.
A o ka poe e noho ana ma na kulanakauhale o ka Iseraela e puka aku lakou, a e kukuni a e hoopau i ke ahi i na mea oi, na palekaua a me na paleumauma, a me na kakaka, a me na pua, na ihe pahu a me na ihe o, a e kahu ahi lakou me ia mau mea i na makahiki ehiku.
10 Wọn kò ní nílò láti kó igi jọ láti inú pápá, tàbí gé e láti inú igbó, nítorí pé wọ́n yóò lo òhun ìjà ogun bi epo ìdáná. Wọn yóò sì kógun àwọn tí ó ṣe ìgárá sí wọn, wọn yóò sì bo ilé àwọn tí ó bo ilé wọn, ni Olúwa Olódùmarè.
Aole lakou e lawe mai i wahie mai ke kula mai, aole hoi e kua ma ka ululaau, no ka mea, e puhi lakou i na mea oi me ke ahi; a e kaili lakou i ka ka poe i kaili i ka lakou, a e lawe wale lakou i ka ka poe i lawe wale i ka lakou, wahi a Iehova ka Haku.
11 “‘Ní ọjọ́ náà èmi yóò sì fi ibi ìsìnkú fún Gogu ní Israẹli, ni àfonífojì àwọn ti ó rìn ìrìnàjò lọ sí agbègbè ilà oòrùn Òkun. Yóò di ojú ọ̀nà àwọn arìnrìn-àjò, nítorí Gogu àti gbogbo ìjọ rẹ̀ ni àwa yóò sin síbẹ̀. Nítorí náà, a yóò pè é ní àfonífojì tí Ammoni Gogu.
A e hiki no keia ia la, e haawi aku au ia Goga i wahi luakupapau malaila, maloko o ka Iseraela, i ka papu o na mea hele ma ka hikina o ke kai; e paa ai ilaila o ka poe hele: malaila e kanu ai lakou ia Goga a me kona lehulehu a pau; a kapa lakou ia wahi Ka papu o Hamonagoga.
12 “‘Fún oṣù méje ní ilé Israẹli yóò fi máa sìn wọ́n láti ṣe àfọ̀mọ́ ilẹ̀ náà.
Ma na malama ehiku, e kanu ai ka ohaua a Iseraela ia lakou, e hoomaemae lakou i ka aina.
13 Gbogbo ènìyàn ilẹ̀ náà yóò sìn wọ́n, ọjọ́ tí a yìn mi lógo yóò jẹ́ ọjọ́ ìrántí, ní Olúwa Olódùmarè wí.
E pau na kanaka o ka aina i ke kanu aku ia lakou; e lilo hoi ia i mea e kaulana ai lakou, i ka la e hoonaniia mai ai au, wahi a Iehova ka Haku.
14 “‘Wọn yóò gbà àwọn ènìyàn ṣiṣẹ́ lóòrèkóòrè láti ṣe àfọ̀mọ́ náà. Ọ̀pọ̀ yóò lọ káàkiri ilẹ̀ náà, ní àfikún pẹ̀lú wọn, àwọn tókù yóò sìn àwọn tí ó kú lórí ilẹ̀. Ní ìparí oṣù keje wọn yóò bẹ̀rẹ̀ wíwá kiri wọn.
A e hookaawale ae lakou i mau kanaka e mau i ka hele ana mawaena o ka aina, e kanu me na mea hele i ka poe e koe ana ma luna o ka honua, e hoomaemae ae ia ia; a mahope o na malama ehiku e huli lakou.
15 Bí wọ́n n lọ káàkiri ilẹ̀ náà ọ̀kan nínú wọn rí egungun ènìyàn, òun yóò gbé àmì ńlá kalẹ̀ ni ẹ̀gbẹ́ rẹ títí àwọn asìnkú yóò fi sìn ín ní àfonífojì Hamoni Gogu.
A o na mea hele, e hele ana mawaena o ka aina, a i ike kekahi i ka iwi kanaka, alaila e kukulu oia i ka hoailona ma ia mea, a pau ia i ke kanuia e ka poe kanu ma ka papu o Hamonagoga.
16 Bákan náà ìlú kan tí a ń pè ni Hamona yóò wà níbẹ̀. Nítorí náà wọn yóò wẹ ilẹ̀ náà.’
A o ka inoa auanei o ke kulanakauhale o Hamona. Pela e hoomaemae ai lakou i ka aina.
17 “Ọmọ ènìyàn èyí yìí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí pé, pe gbogbo oríṣìíríṣìí ẹyẹ àti gbogbo àwọn ẹranko igbó jáde, ‘Kí wọn péjọpọ̀ láti gbogbo agbègbè sí ìrúbọ tí mó ń múra rẹ̀ fún ọ, ìrúbọ ńlá náà ní orí òkè gíga tí Israẹli. Níbẹ̀ ẹ̀yin yóò jẹ ẹran, ẹ̀yin yóò sì mú ẹ̀jẹ̀.
A o oe, e ke keiki a ke kanaka, ke i mai nei Iehova ka Haku, penei; E olelo aku i na manu o kela eheu keia eheu, a me na holoholona a pau o ke kula, E akoakoa oukou a e haele mai, e houluulu oukou ia oukou iho a puni i ka'u mohai, a'u e kaumaha ai no oukou, he mohai nui maluna o na mauna o ka Iseraela, e ai oukou i ka io a e inu hoi i ke koko.
18 Ẹ̀yin yóò jẹ ẹran-ara àwọn ènìyàn ńlá, ẹ o sì mú ẹ̀jẹ̀ àwọn ọmọ-aládé ayé bí ẹni pé wọn jẹ́ àgbò àti ọ̀dọ́-àgùntàn, ewúrẹ́ àti akọ màlúù gbogbo wọn jẹ́ ẹran ọlọ́ràá láti Baṣani.
E ai no oukou i ka io o na mea ikaika, a e inu no hoi i ke koko o na moi o ka honua, o na hipakane a me na keikihipa a me na kao nui a me na bipi, ko Basana mau mea i kupaluia lakou a pau.
19 Níbi ìrúbọ tí mo ń múra kalẹ̀ fún yín, ẹ̀yin yóò jẹ ọ̀rá títí ẹ̀yin yóò fi jẹ àjẹkì, ẹ̀yin yóò sì mú ẹ̀jẹ̀ títí ẹ̀yin yóò fi yó.
E ai oukou i ka momona, a maona oukou, a e inu oukou i ke koko a ona oukou, o kuu mohai a'u i kaumaha aku ai no oukou.
20 Ní orí tábìlì mi ni àwa yóò ti fi ẹṣin àti ẹlẹ́ṣin bọ yín yó, pẹ̀lú àwọn alágbára ńlá àti oríṣìíríṣìí jagunjagun,’ ni Olúwa Olódùmarè wí.
Pela oukou e hoopihaia'i ma ka'u papaaina, me na lio, a me na hoohololio, a me na kanaka kaua a pau, wahi a Iehova ka Haku.
21 “Èmi yóò ṣe àfihàn ògo mi láàrín àwọn orílẹ̀-èdè, gbogbo orílẹ̀-èdè yóò sì rí ìyà tí mo fi jẹ wọ́n.
A e kau aku au i ko'u nani iwaena o na lahuikanaka, a e ike no ko na aina a pau i ko'u hoopai ana a'u i hana'i, a me kuu lima a'u i kau aku ai maluna o lakou.
22 Láti ọjọ́ náà lọ, ilé Israẹli yóò mọ̀ pé èmi ni Olúwa Ọlọ́run wọn.
Pela e ike ai no hoi ka ohana a Iseraela, owau no ko lakou Akua mai ia la aku no.
23 Àwọn orílẹ̀-èdè yóò sì mọ̀ pé àwọn ènìyàn Israẹli lọ sí ìgbèkùn nítorí ẹ̀ṣẹ̀ wọn, nítorí pé wọ́n jẹ́ aláìṣòótọ́ sí mi. Nítorí náà mo mú ojú mi pamọ́ kúrò lọ́dọ̀ wọn, mo sì fi wọn lé àwọn ọ̀tá wọn lọ́wọ́, gbogbo wọn sì ṣubú nípasẹ̀ idà.
A e ike na lahuikanaka ua hele ka ohana a Iseraela i ke pio ana, no ko lakou hewa; no ka lakou hana hewa ana mai ia'u, ua huna au i kuu maka ia lakou, a haawi hoi ia lakou iloko o ka lima o ko lakou poe enemi, a pau lakou i ka haule i ka pahikaua.
24 Mo ṣe sí wọn gẹ́gẹ́ bí àìmọ́ àti àìṣedéédéé wọn, mo sì mú ojú mi pamọ́ kúrò lọ́dọ̀ wọn.
E like me ko lakou haumia ana, a me ko lakou lawehala ana, pela i hana aku ai au ia lakou, a huna aku au i ko'u maka ia lakou.
25 “Nítorí náà èyí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: Èmi yóò mú Jakọbu padà kúrò ní oko ẹrú, èmi yóò ní ìyọ́nú si gbogbo ènìyàn Israẹli, èmi yóò sì ní ìtara fún orúkọ mímọ́ mi.
Nolaila, ke i mai nei Iehova ka Haku, penei; Ano, e lawe mai hoi au i ke pio ana o Iakoba, a e aloha hoi au i ka ohana a pau a Iseraela, a e lili hoi au no ko'u inoa hoano;
26 Wọn yóò gbàgbé ìtìjú wọn àti gbogbo àìṣòdodo tí wọ́n fihàn sí mi nígbà tí wọn ń gbé ni àìléwu ni ilẹ̀ wọn níbi tí kò ti sí ẹnikẹ́ni láti dẹ́rùbà wọ́n.
Mahope o ko lakou halihali ana i ko lakou hoinoia, a me ko lakou mau lawehala ana a pau i hana hewa mai ai lakou ia'u i ko lakou wa i noho maluhia ai i ko lakou aina, aohe mea o lakou i hooweliweli ia.
27 Nígbà tí mo ti mú wọn padà kúrò ní àwọn orílẹ̀-èdè, tí mo sì kó wọn jọ pọ̀ kúrò ni ìlú àwọn ọ̀tá wọn, èmi yóò fi ara mi hàn ni mímọ́ nípasẹ̀ wọn ní ojú àwọn orílẹ̀-èdè púpọ̀.
Aia lawe hou mai au ia lakou mai na kanaka mai, a houluulu mai hoi ia lakou mai na aina mai o ko lakou poe enemi, a e hoanoia mai au iloko o lakou imua o na maka o na lahuikanaka he nui no;
28 Nígbà náà, wọn yóò mọ̀ pé èmi ni Olúwa Ọlọ́run wọn nítorí bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé mo rán wọn lọ sí ìgbèkùn láàrín àwọn orílẹ̀-èdè, èmi yóò kó wọn jọ sí orí ilẹ̀ wọn, láìfi nǹkan kan sẹ́yìn.
Alaila e ike lakou, owau no Iehova ko lakou Akua, ka mea i hooalakaiia'i lakou i ke pio ana iwaena o na lahuikanaka; aka, ua houluulu hou mai au ia lakou i ko lakou aina ponoi, aole hoi i hookoe aku i kekahi o lakou ilaila.
29 Èmi kì yóò sì fi ojú mi pamọ́ kúrò lọ́dọ̀ wọn mọ nítorí èmi yóò tú èémí mi jáde sí ilé Israẹli, ní Olúwa Olódùmarè wí.”
Aole hoi au e huna hou aku i ko'u maka ia lakou, no ka mea, ua ninini aku au i ko'u Uhane maluna o ka ohana a Iseraela, wahi a Iehova ka Haku.