< Ezekiel 39 >

1 “Ọmọ ènìyàn, sọtẹ́lẹ̀ sí Gogu, kí ó sì wí pé: ‘Èyí yìí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: Èmi lòdì sí ọ, Ìwọ Gogu, olórí ọmọ-aládé ti Meṣeki àti Tubali.
But profesie thou, sone of man, ayens Gog; and thou schalt seie, The Lord God seith these thingis, Lo! Y on thee, thou Gog, prince of the heed of Mosoch and of Tubal.
2 Èmi yóò dá ọ padà, èmi yóò sì darí rẹ. Èmi yóò mú ọ wá láti jìnnàjìnnà ìhà àríwá, Èmi yóò rán ọ lòdì sí orí àwọn òkè gíga Israẹli.
And Y schal lede thee aboute, and Y schal disseyue thee, and Y schal make thee to stie fro the sidis of the north, and Y schal brynge thee on the hillis of Israel.
3 Nígbà náà èmi yóò lu ọrùn awọ rẹ ní ọwọ́ òsì rẹ, èmi yóò sì mú kí àwọn ọfà rẹ jábọ́ ni ọwọ́ ọ̀tún rẹ.
And Y schal smyte thi bouwe in thi left hond, and Y schal caste doun thin arowis fro thi riyt hond.
4 Ìwọ yóò sì ṣubú ní orí àwọn òkè Israẹli, ìwọ àti gbogbo àwọn ọmọ-ogun rẹ àti gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè tí ó wà pẹ̀lú rẹ. Èmi yóò fi ọ ṣe oúnjẹ fún àwọn onírúurú ẹyẹ àti fún àwọn ẹranko igbó.
Thou schalt falle doun on the hillis of Israel, thou, and alle thi cumpenyes, and puplis that ben with thee; Y yaf thee for to be deuourid to wielde beestis, to briddis, and to ech volatil, and to the beestis of erthe.
5 Ìwọ yóò ṣubú ní gbangba pápá, nítorí tì mo ti sọ̀rọ̀, ni Olúwa Olódùmarè wí.
Thou schalt falle doun on the face of the feeld; for Y the Lord haue spoke, seith the Lord God.
6 Èmi yóò fi iná sí Magogu àti sí àwọn tí ń gbé ní agbègbè ilẹ̀ ibẹ̀ ní àìléwu, wọn yóò sì mọ̀ pé èmi ni Olúwa.
And Y schal sende fier in Magog, and in hem that dwellen tristili in ilis; and thei schulen wite, that Y am the Lord God of Israel.
7 “‘Èmi yóò sọ orúkọ mímọ́ mí di mí mọ̀ láàrín àwọn ènìyàn mì Israẹli. Èmi ki yóò jẹ́ kí orúkọ mímọ́ mi di aláìmọ́ àwọn orílẹ̀-èdè yóò mọ̀ pé, Èmi Olúwa, Èmi ni ẹni mímọ́ ní Israẹli.
And Y schal make myn hooli name knowun in the myddis of my puple Israel, and Y schal no more defoule myn hooli name; and hethene men schulen wite, that Y am the Lord God, the hooli of Israel.
8 Ó ń bọ̀! Ó dájú pé yóò ṣẹlẹ̀, ni Olúwa Olódùmarè. Èyí yìí ni ọjọ́ tí mo sọ̀rọ̀ nípa rẹ̀.
Lo! it cometh, and it is don, seith the Lord God.
9 “‘Nígbà náà, àwọn ti ó ń gbé nì àárín àwọn ìlú tí ó wà ni Israẹli yóò jáde, wọn yóò sì lo àwọn ohun ìjà bi epo ìdáná yóò sì jó wọ́n kanlẹ̀—àpáta kéékèèké àti àpáta ńlá, àwọn ọfà, àwọn kùmọ̀ ogun àti ọ̀kọ̀ fún ọdún méje wọn yóò lò wọ́n bi epo ìdáná.
This is the day of which Y spak. And dwelleris schulen go out of the citees of Israel, and thei schulen set a fier, and schulen brenne armuris, scheeld and spere, bouwe and arowis, and stauys of hond, and schaftis with out irun; and thei schulen brenne tho in fier bi seuene yeer.
10 Wọn kò ní nílò láti kó igi jọ láti inú pápá, tàbí gé e láti inú igbó, nítorí pé wọ́n yóò lo òhun ìjà ogun bi epo ìdáná. Wọn yóò sì kógun àwọn tí ó ṣe ìgárá sí wọn, wọn yóò sì bo ilé àwọn tí ó bo ilé wọn, ni Olúwa Olódùmarè.
And thei schulen not bere trees of cuntries, nether schulen kitte doun of forestis, for thei schulen brenne armuris bi fier; and thei schulen take preies of hem, to whiche thei weren preies, and thei schulen rauysche her wasteris, seith the Lord God.
11 “‘Ní ọjọ́ náà èmi yóò sì fi ibi ìsìnkú fún Gogu ní Israẹli, ni àfonífojì àwọn ti ó rìn ìrìnàjò lọ sí agbègbè ilà oòrùn Òkun. Yóò di ojú ọ̀nà àwọn arìnrìn-àjò, nítorí Gogu àti gbogbo ìjọ rẹ̀ ni àwa yóò sin síbẹ̀. Nítorí náà, a yóò pè é ní àfonífojì tí Ammoni Gogu.
And it schal be in that dai, Y schal yyue to Gog a named place, a sepulcre in Israel, the valei of weigoeris at the eest of the see, that schal make hem that passen forth for to wondre; and thei schulen birie there Gog, and al the multitude of hym, and it schal be clepid the valei of the multitude of Gog.
12 “‘Fún oṣù méje ní ilé Israẹli yóò fi máa sìn wọ́n láti ṣe àfọ̀mọ́ ilẹ̀ náà.
And the hous of Israel schulen birie hem, that thei clense the lond in seuene monethis.
13 Gbogbo ènìyàn ilẹ̀ náà yóò sìn wọ́n, ọjọ́ tí a yìn mi lógo yóò jẹ́ ọjọ́ ìrántí, ní Olúwa Olódùmarè wí.
Forsothe al the puple of the lond schal byrie hym, and it schal be a named dai to hem, in which Y am glorified, seith the Lord God.
14 “‘Wọn yóò gbà àwọn ènìyàn ṣiṣẹ́ lóòrèkóòrè láti ṣe àfọ̀mọ́ náà. Ọ̀pọ̀ yóò lọ káàkiri ilẹ̀ náà, ní àfikún pẹ̀lú wọn, àwọn tókù yóò sìn àwọn tí ó kú lórí ilẹ̀. Ní ìparí oṣù keje wọn yóò bẹ̀rẹ̀ wíwá kiri wọn.
And thei schulen ordeyne bisili men cumpassynge the lond, that schulen birie and seke hem that weren left on the face of the lond, that thei clense it. Forsothe aftir seuene monethis thei schulen bigynne to seke,
15 Bí wọ́n n lọ káàkiri ilẹ̀ náà ọ̀kan nínú wọn rí egungun ènìyàn, òun yóò gbé àmì ńlá kalẹ̀ ni ẹ̀gbẹ́ rẹ títí àwọn asìnkú yóò fi sìn ín ní àfonífojì Hamoni Gogu.
and thei schulen cumpas goynge aboute the lond; and whanne thei schulen se the boon of a man, thei schulen sette a `notable signe bisidis it, til the birieris of careyns birie it in the valei of the multitude of Gog.
16 Bákan náà ìlú kan tí a ń pè ni Hamona yóò wà níbẹ̀. Nítorí náà wọn yóò wẹ ilẹ̀ náà.’
Sotheli the name of the cite is Amona; and thei schulen clense the lond.
17 “Ọmọ ènìyàn èyí yìí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí pé, pe gbogbo oríṣìíríṣìí ẹyẹ àti gbogbo àwọn ẹranko igbó jáde, ‘Kí wọn péjọpọ̀ láti gbogbo agbègbè sí ìrúbọ tí mó ń múra rẹ̀ fún ọ, ìrúbọ ńlá náà ní orí òkè gíga tí Israẹli. Níbẹ̀ ẹ̀yin yóò jẹ ẹran, ẹ̀yin yóò sì mú ẹ̀jẹ̀.
Forsothe, thou, sone of man, the Lord God seith these thingis, Seie thou to ech brid, and to alle foulis, and to alle beestis of the feeld, Come ye to gidere, and haste ye, renne ye togidere on ech side to my sacrifice, which Y sle to you, a greet sacrifice on the hillis of Israel, that ye ete fleischis and drynke blood.
18 Ẹ̀yin yóò jẹ ẹran-ara àwọn ènìyàn ńlá, ẹ o sì mú ẹ̀jẹ̀ àwọn ọmọ-aládé ayé bí ẹni pé wọn jẹ́ àgbò àti ọ̀dọ́-àgùntàn, ewúrẹ́ àti akọ màlúù gbogbo wọn jẹ́ ẹran ọlọ́ràá láti Baṣani.
Ye schulen ete the fleischis of stronge men, and ye schulen drynke the blood of prynces of erthe, of wetheris, of lambren, and of buckis of geet, and of bolis, and of beestis maad fat, and of alle fat thingis.
19 Níbi ìrúbọ tí mo ń múra kalẹ̀ fún yín, ẹ̀yin yóò jẹ ọ̀rá títí ẹ̀yin yóò fi jẹ àjẹkì, ẹ̀yin yóò sì mú ẹ̀jẹ̀ títí ẹ̀yin yóò fi yó.
And ye schulen ete the ynnere fatnesse in to fulnesse, and ye schulen drynke the blood in to drunkenesse, of the sacrifice which Y schal sle to you.
20 Ní orí tábìlì mi ni àwa yóò ti fi ẹṣin àti ẹlẹ́ṣin bọ yín yó, pẹ̀lú àwọn alágbára ńlá àti oríṣìíríṣìí jagunjagun,’ ni Olúwa Olódùmarè wí.
And ye schulen be fillid on my boord, of hors, and of strong horse man, and of alle men werriours, seith the Lord God.
21 “Èmi yóò ṣe àfihàn ògo mi láàrín àwọn orílẹ̀-èdè, gbogbo orílẹ̀-èdè yóò sì rí ìyà tí mo fi jẹ wọ́n.
And Y schal sette my glorie among hethene men, and alle hethene men schulen se my doom, which Y haue do, and myn hond, which Y haue set on hem.
22 Láti ọjọ́ náà lọ, ilé Israẹli yóò mọ̀ pé èmi ni Olúwa Ọlọ́run wọn.
And the hous of Israel schulen wite, that Y am her Lord God, fro that dai and afterward.
23 Àwọn orílẹ̀-èdè yóò sì mọ̀ pé àwọn ènìyàn Israẹli lọ sí ìgbèkùn nítorí ẹ̀ṣẹ̀ wọn, nítorí pé wọ́n jẹ́ aláìṣòótọ́ sí mi. Nítorí náà mo mú ojú mi pamọ́ kúrò lọ́dọ̀ wọn, mo sì fi wọn lé àwọn ọ̀tá wọn lọ́wọ́, gbogbo wọn sì ṣubú nípasẹ̀ idà.
And hethen men schulen wite, that the hous of Israel is takun in her wickidnesse, for that that thei forsoken me; and Y hidde my face fro hem, and Y bitook hem into the hondis of enemyes, and alle thei fellen doun bi swerd.
24 Mo ṣe sí wọn gẹ́gẹ́ bí àìmọ́ àti àìṣedéédéé wọn, mo sì mú ojú mi pamọ́ kúrò lọ́dọ̀ wọn.
Bi the unclennes and greet trespasse of hem Y dide to hem, and Y hidde my face fro hem.
25 “Nítorí náà èyí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: Èmi yóò mú Jakọbu padà kúrò ní oko ẹrú, èmi yóò ní ìyọ́nú si gbogbo ènìyàn Israẹli, èmi yóò sì ní ìtara fún orúkọ mímọ́ mi.
Therfor the Lord God seith these thingis, Now Y schal leede ayen the caitiftee of Jacob, and Y schal haue merci on al the hous of Israel; and Y schal take feruoure for myn hooli name.
26 Wọn yóò gbàgbé ìtìjú wọn àti gbogbo àìṣòdodo tí wọ́n fihàn sí mi nígbà tí wọn ń gbé ni àìléwu ni ilẹ̀ wọn níbi tí kò ti sí ẹnikẹ́ni láti dẹ́rùbà wọ́n.
And thei schulen bere here schenschipe, and al the trespassing bi which thei trespassiden ayens me, whanne thei dwelliden in her lond tristili, and dredden no man;
27 Nígbà tí mo ti mú wọn padà kúrò ní àwọn orílẹ̀-èdè, tí mo sì kó wọn jọ pọ̀ kúrò ni ìlú àwọn ọ̀tá wọn, èmi yóò fi ara mi hàn ni mímọ́ nípasẹ̀ wọn ní ojú àwọn orílẹ̀-èdè púpọ̀.
and whanne Y schal bringe hem ayen fro puplis, and schal gadere fro the londis of her enemyes, and schal be halewid in hem, bifor the iyen of ful many folkis.
28 Nígbà náà, wọn yóò mọ̀ pé èmi ni Olúwa Ọlọ́run wọn nítorí bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé mo rán wọn lọ sí ìgbèkùn láàrín àwọn orílẹ̀-èdè, èmi yóò kó wọn jọ sí orí ilẹ̀ wọn, láìfi nǹkan kan sẹ́yìn.
And thei schulen wite, that Y am the Lord God of hem, for that Y translatide hem in to naciouns, and haue gaderid hem on her lond, and Y lefte not ony of hem there.
29 Èmi kì yóò sì fi ojú mi pamọ́ kúrò lọ́dọ̀ wọn mọ nítorí èmi yóò tú èémí mi jáde sí ilé Israẹli, ní Olúwa Olódùmarè wí.”
And Y schal no more hide my face fro hem, for Y haue schede out my spirit on al the hous of Israel, seith the Lord God.

< Ezekiel 39 >