< Ezekiel 38 >

1 Ọrọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá:
Ilizwi leNkosi laselifika kimi lisithi:
2 “Ọmọ ènìyàn, kọ ojú rẹ sí Gogu, ti ilẹ̀ Magogu; olórí ọmọ-aládé, Meṣeki, àti Tubali sọtẹ́lẹ̀ ní ìlòdì sí i
Ndodana yomuntu, misa ubuso bakho bumelene loGogi, ilizwe likaMagogi, isiphathamandla esiyinhloko yeMesheki leThubhali, uprofethe umelene laye,
3 kí ó sì wí pé, ‘Èyí yìí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: Èmi lòdì sí ọ, ìwọ Gogu, olórí ọmọ-aládé, Meṣeki àti Tubali.
uthi: Itsho njalo iNkosi uJehova: Khangela, ngimelene lawe, wena Gogi isiphathamandla esiyinhloko yeMesheki leThubhali.
4 Èmi yóò yí ọ kiri, èmi yóò sì fi ìwọ̀ kọ́ ọ ní ẹnu, èmi yóò sì fà ọ́ jáde pẹ̀lú gbogbo ọmọ-ogun rẹ, àwọn ẹṣin àti àwọn agẹṣinjagun nínú ìhámọ́ra, àti ìpéjọ ńlá pẹ̀lú asà ogun ńlá àti kéékèèké, gbogbo wọn ń fi idà wọn.
Njalo ngizakuphendula, ngifake izingwegwe emihlathini yakho, ngikukhuphe wena lebutho lakho lonke, amabhiza labagadi bamabhiza, bonke begqoke bephelele, ixuku elikhulu elilomhawu lesihlangu, bonke bephethe izinkemba.
5 Persia, Kuṣi àti Puti yóò wà pẹ̀lú wọn, gbogbo wọn yóò wà pẹ̀lú asà àti ìṣíborí wọn
IPerisiya, iEthiyophiya, lePuti ilabo; bonke belesihlangu lengowane.
6 Gomeri náà pẹ̀lú gbogbo àwọn ọmọ-ogun rẹ̀, àti Beti-Togarma láti jìnnàjìnnà àríwá pẹ̀lú gbogbo àwọn ọ̀wọ́ ogun rẹ̀—ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn orílẹ̀-èdè pẹ̀lú rẹ̀.
IGomeri lamaviyo ayo wonke, indlu kaTogarima ezinhlangothini zenyakatho, lamaviyo ayo wonke; abantu abanengi kanye lawe.
7 “‘Múra sílẹ̀, múra tán, kí ìwọ àti gbogbo ìjọ náà péjọpọ̀ pẹ̀lú rẹ, kí o sì pàṣẹ fún wọn.
Lunga, uzilungisele, wena lexuku lakho lonke elibuthene kuwe, ube ngumgcini wabo.
8 Lẹ́yìn ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọjọ́, àwa yóò bẹ̀ ọ wò; ní ọdún ìkẹyìn ìwọ yóò dó ti ilẹ̀ tí a ti gbà padà lọ́wọ́ idà, tí àwọn ènìyàn wọn kórajọ pọ̀ láti ọ̀pọ̀ orílẹ̀-èdè sí àwọn òkè gíga ti Israẹli, tí ó ti di ahoro fún ìgbà pípẹ́. A ti mú wọn jáde láti ọ̀dọ̀ àwọn orílẹ̀-èdè, nísinsin yìí gbogbo wọn ń gbé ní àìléwu.
Emva kwensuku ezinengi uzahanjelwa; ekucineni kweminyaka uzakuza elizweni elabuyiswa enkembeni, elabuthwa ezizweni ezinengi, ngasezintabeni zakoIsrayeli, ezaziyincithakalo njalonjalo. Kodwa selikhutshwe emazweni, njalo bazahlala bevikelekile bonke.
9 Ìwọ àti ọ̀wọ́ ogun rẹ àti ọ̀pọ̀ orílẹ̀-èdè pẹ̀lú rẹ yóò gòkè, ẹ̀yin yóò tẹ̀síwájú bí ìjì; ìwọ yóò dàbí ìkùùkuu tí ó bo ilẹ̀ mọ́lẹ̀.
Khona uzakwenyuka, uze njengesiphepho, ube njengeyezi lokusibekela umhlaba, wena, lawo wonke amaviyo akho, labantu abanengi kanye lawe.
10 “‘Èyí ni Olúwa Olódùmarè wí: Ní ọjọ́ náà èrò kan yóò wá sọ́kàn rẹ, ìwọ yóò sì pète ìlànà búburú.
Itsho njalo iNkosi uJehova: Kuzakuthi-ke ngalolosuku kuvele izinto enhliziyweni yakho, unakane icebo elibi,
11 Ìwọ yóò wí pé, “Èmi yóò gbé ogun ti ilẹ̀ àwọn tí a kò fi odi yíká, Èmi yóò gbé ogun ti àwọn ènìyàn àlàáfíà tí a kò funra sí gbogbo wọn ń gbé ní àìsí odi, ní àìsí ẹnu-ọ̀nà òde àti àsígbè-irin.
uthi: Ngizakwenyukela elizweni lemizi engabiyelwanga; ngizakuya kwabalokuthula, abahlezi bevikelekile, bonke behlezi bengelamduli, bengelamgoqo lezivalo,
12 Èmi yóò mú ohun ọdẹ, èmi yóò sì kó ìkógun, èmi yóò sì yí ọwọ́ mi padà sí ibi ìwólulẹ̀ ti a ti tún kọ́, àwọn ènìyàn tí a kójọpọ̀ láti ọ̀dọ̀ àwọn orílẹ̀-èdè, tí ó ní ọrọ̀ nínú ẹran ọ̀sìn àti ẹrú, tí ó ń gbé ní àárín gbùngbùn ilẹ̀ náà.”
ukuphanga impango, lokubamba okubanjiweyo; ukuphendulela isandla sakho phezu kwezindawo ezingamanxiwa esezihlalwa, laphezu kwabantu ababuthwe ezizweni, abazuze izifuyo lempahla, abahlala enkabeni yelizwe.
13 Ṣeba, Dedani àti àwọn oníṣòwò Tarṣiṣi àti gbogbo àwọn ọmọ kìnnìún wọn, yóò sọ fún un yín pé, “Ṣé ẹ̀yin wá fún ìkógun? Ṣé ẹ̀yin ti kó àwọn ogun yín jọ pọ̀ fún ìkógun, láti kó fàdákà àti wúrà lọ, láti kó ẹran ọ̀sìn àti ẹrú àti láti gba ọ̀pọ̀ ìkógun?”’”
IShebha, leDedani, labathengiselani beTarshishi, lazo zonke izilwane zayo ezintsha, kuzakuthi kuwe: Ufike yini ukuzaphanga impango? Ixuku lakho ulibuthanisele ukubamba okubanjiweyo yini, ukususa isiliva legolide, ukuthatha izifuyo lempahla, ukuphanga impango enkulu yini?
14 “Nítorí náà, ọmọ ènìyàn, sọtẹ́lẹ̀ kí ó sì sọ fún Gogu: ‘Èyí yìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Ní ọjọ́ náà, nígbà tí àwọn ènìyàn mi Israẹli ń gbé ní àìléwu, ìwọ kì yóò ha ṣe àkíyèsí rẹ̀?
Ngakho, profetha, ndodana yomuntu, uthi kuGogi: Itsho njalo iNkosi uJehova: Ngalolosuku, mhla abantu bami uIsrayeli behlezi ngokuvikeleka, kawuyikukwazi yini?
15 Ìwọ yóò wá láti ààyè rẹ ní jìnnàjìnnà àríwá, ìwọ àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀-èdè pẹ̀lú rẹ, gbogbo wọn yóò sì gun ẹṣin ẹgbẹ́ ńlá, jagunjagun alágbára.
Khona uzakuza uvele endaweni yakho, ezinhlangothini zenyakatho, wena, labantu abanengi kanye lawe, bonke begade amabhiza, ixuku elikhulu, lebutho elilamandla.
16 Ìwọ yóò tẹ̀síwájú ní ìlòdì sí àwọn Israẹli ènìyàn mi gẹ́gẹ́ bí ìkùùkuu tí ó bo ilẹ̀. Ni àwọn ọjọ́ tí ń bọ̀, ìwọ Gogu, èmi yóò mú ọ wá ní ìlòdì sí ilẹ̀ mi, kí àwọn orílẹ̀-èdè lè mọ̀ mi nígbà tí mo bá fi ara hàn ni mímọ́ láti ọ̀dọ̀ rẹ ní ojú wọn.
Njalo uzakwenyuka umelane labantu bami uIsrayeli, njengeyezi elisibekela umhlaba. Kuzakwenzeka ekucineni kwezinsuku, ngikuse umelane lelizwe lami, ukuze izizwe zingazi, lapho ngizangcweliswa kuwe, wena Gogi, phambi kwamehlo azo.
17 “‘Èyí yìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Ìwọ ha kọ́ ni mo sọ̀rọ̀ nípa rẹ̀ ní ìgbà ìṣáájú láti ẹnu àwọn wòlíì ìránṣẹ́ mi ti Israẹli? Ní ìgbà náà wọ́n sọtẹ́lẹ̀ fún ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọdún pé èmi yóò mú ọ lòdì sí wọn.
Itsho njalo iNkosi uJehova: Unguwe yini engakhuluma ngaye ensukwini zasendulo ngesandla sezinceku zami abaprofethi bakoIsrayeli, abaprofetha ngalezonsuku okweminyaka eminengi ukuthi ngizakuletha umelane labo?
18 Èyí ni ohun tí yóò ṣẹlẹ̀ ní ọjọ́ náà, nígbà tí Gogu bá kọlu ilẹ̀ Israẹli, gbígbóná ìbínú mi yóò ru sókè, ni Olúwa Olódùmarè wí.
Kuzakuthi-ke ngalolosuku mhla uGogi ezakuza ukumelana lelizwe lakoIsrayeli, itsho iNkosi uJehova, ulaka lwami luvuke ebusweni bami.
19 Ní ìtara mi àti ní gbígbóná ìbínú mi, mo tẹnumọ́ ọn pé; ní àsìkò náà ilẹ̀ mímì tí ó lágbára ní ilẹ̀ Israẹli yóò ṣẹlẹ̀.
Ngoba ebukhweleni bami lemlilweni wolaka lwami ngathi: Isibili ngalolosuku kuzakuba khona ukuzamazama okukhulu elizweni lakoIsrayeli.
20 Ẹja inú Òkun, àwọn ẹyẹ òfúrufú, àwọn ẹranko igbó, àti gbogbo ẹ̀dá tí ó ń rìn lórí ilẹ̀ yóò wárìrì fún ìfarahàn mi. A yóò yí òkè gíga po, àwọn bèbè òkúta ni àwa yóò fọ́ sí wẹ́wẹ́, gbogbo ògiri ni yóò wó palẹ̀.
Ukuze kuthuthumele ebukhoneni bami izinhlanzi zolwandle, lenyoni zamazulu, lenyamazana zeganga, lazo zonke izinto ezihuquzelayo, ezihuquzela emhlabathini, labo bonke abantu abasebusweni bomhlaba, lezintaba zizawiselwa phansi, lamawa azawela phansi, lawo wonke umduli uwele emhlabathini.
21 Èmi yóò fa idà yọ ni ìlòdì sí Gogu ní orí gbogbo àwọn òkè gíga mi ni Olúwa Olódùmarè wí. Idà gbogbo ènìyàn yóò lòdì sí arákùnrin rẹ̀.
Njalo ngizabiza inkemba imelane laye kuzo zonke izintaba zami, itsho iNkosi uJehova; inkemba yalowo lalowomuntu izamelana lomfowabo.
22 Èmi yóò gbé ìdájọ́ mi jáde lórí rẹ̀ pẹ̀lú ìyọnu àti ìtàjẹ̀ sílẹ̀, Èmi yóò dá àgbàrá òjò, òkúta yìnyín àti imí-ọjọ́ tí ń jó lé e lórí àti lórí ọ̀wọ́ ogun àti lórí ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀-èdè pẹ̀lú rẹ̀.
Futhi ngizamehlulela ngomatshayabhuqe wesifo langegazi; nginise phezu kwakhe, laphezu kwamaxuku akhe, laphezu kwezizwe ezinengi ezilaye, izulu elikhukhulayo, lamatshe esiqhotho, umlilo, lesolufa.
23 Nítorí náà, Èmi yóò fi títóbi mi àti ìjẹ́-mímọ́ mi hàn, Èmi yóò sì fi ara mi hàn ní ojú ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀-èdè. Nígbà náà ni wọn yóò mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.’
Ngalokho ngizazikhulisa ngizingcwelise, ngaziwe phambi kwamehlo ezizwe ezinengi; khona bazakwazi ukuthi ngiyiNkosi.

< Ezekiel 38 >