< Ezekiel 38 >
És lőn az Úr beszéde hozzám, mondván:
2 “Ọmọ ènìyàn, kọ ojú rẹ sí Gogu, ti ilẹ̀ Magogu; olórí ọmọ-aládé, Meṣeki, àti Tubali sọtẹ́lẹ̀ ní ìlòdì sí i
Embernek fia! vesd tekintetedet Góg ellen, és Mágóg földjén, Rós, Mések és Tubál fejedelme ellen, és prófétálj felőle.
3 kí ó sì wí pé, ‘Èyí yìí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: Èmi lòdì sí ọ, ìwọ Gogu, olórí ọmọ-aládé, Meṣeki àti Tubali.
És mondjad: Ezt mondja az Úr Isten: Ímé, én ellened megyek Góg, Rós, Mések és Tubál fejedelme.
4 Èmi yóò yí ọ kiri, èmi yóò sì fi ìwọ̀ kọ́ ọ ní ẹnu, èmi yóò sì fà ọ́ jáde pẹ̀lú gbogbo ọmọ-ogun rẹ, àwọn ẹṣin àti àwọn agẹṣinjagun nínú ìhámọ́ra, àti ìpéjọ ńlá pẹ̀lú asà ogun ńlá àti kéékèèké, gbogbo wọn ń fi idà wọn.
És elcsalogatlak, és horgokat vetek szádba, és kivezetlek téged és egész seregedet, lovakat és lovagokat, kik mindnyájan teljes fegyverzetbe öltözvék, nagy sokaságot, nagy és kis paizszsal, fegyvert viselők mindnyájan;
5 Persia, Kuṣi àti Puti yóò wà pẹ̀lú wọn, gbogbo wọn yóò wà pẹ̀lú asà àti ìṣíborí wọn
Perzsák, szerecsenek, libiaiak vannak velök, mindnyájan paizszsal és sisakkal;
6 Gomeri náà pẹ̀lú gbogbo àwọn ọmọ-ogun rẹ̀, àti Beti-Togarma láti jìnnàjìnnà àríwá pẹ̀lú gbogbo àwọn ọ̀wọ́ ogun rẹ̀—ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn orílẹ̀-èdè pẹ̀lú rẹ̀.
Továbbá Gómer és minden serege, Tógarma háza messze északról minden seregével, sok nép van veled.
7 “‘Múra sílẹ̀, múra tán, kí ìwọ àti gbogbo ìjọ náà péjọpọ̀ pẹ̀lú rẹ, kí o sì pàṣẹ fún wọn.
Készülj hozzá és készítsd elő magadat te és minden sokaságod, kik te hozzád gyűltek, és légy nekik vezérök.
8 Lẹ́yìn ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọjọ́, àwa yóò bẹ̀ ọ wò; ní ọdún ìkẹyìn ìwọ yóò dó ti ilẹ̀ tí a ti gbà padà lọ́wọ́ idà, tí àwọn ènìyàn wọn kórajọ pọ̀ láti ọ̀pọ̀ orílẹ̀-èdè sí àwọn òkè gíga ti Israẹli, tí ó ti di ahoro fún ìgbà pípẹ́. A ti mú wọn jáde láti ọ̀dọ̀ àwọn orílẹ̀-èdè, nísinsin yìí gbogbo wọn ń gbé ní àìléwu.
Sok idő mulva kirendeltetel: esztendők végével bejösz a földre, mely a fegyvertől már megnyugodott, melynek lakói sok nép közül gyűjtettek egybe Izráel hegyeire, melyek szüntelen való pusztulásban voltak; és e nemzetség a népek közül hozatott ki, s aztán lakozék bátorságosan mindnyája;
9 Ìwọ àti ọ̀wọ́ ogun rẹ àti ọ̀pọ̀ orílẹ̀-èdè pẹ̀lú rẹ yóò gòkè, ẹ̀yin yóò tẹ̀síwájú bí ìjì; ìwọ yóò dàbí ìkùùkuu tí ó bo ilẹ̀ mọ́lẹ̀.
És feljösz, bemégy mint a szélvész, és leszel mint a felleg, hogy beborítsd a földet, te és minden sereged s a sok nép veled.
10 “‘Èyí ni Olúwa Olódùmarè wí: Ní ọjọ́ náà èrò kan yóò wá sọ́kàn rẹ, ìwọ yóò sì pète ìlànà búburú.
Így szól az Úr Isten: És lészen abban az időben, hogy tanácsok támadnak szívedben, és gondolsz gondolatot.
11 Ìwọ yóò wí pé, “Èmi yóò gbé ogun ti ilẹ̀ àwọn tí a kò fi odi yíká, Èmi yóò gbé ogun ti àwọn ènìyàn àlàáfíà tí a kò funra sí gbogbo wọn ń gbé ní àìsí odi, ní àìsí ẹnu-ọ̀nà òde àti àsígbè-irin.
És mondasz: Felmegyek a nyilt földre, jövök azokra, kik nyugalomban vannak s bátorságosan laknak; kik laknak mindnyájan kőfal-kerítés nélkül, sem zárjok, sem kapujok nincs nékik;
12 Èmi yóò mú ohun ọdẹ, èmi yóò sì kó ìkógun, èmi yóò sì yí ọwọ́ mi padà sí ibi ìwólulẹ̀ ti a ti tún kọ́, àwọn ènìyàn tí a kójọpọ̀ láti ọ̀dọ̀ àwọn orílẹ̀-èdè, tí ó ní ọrọ̀ nínú ẹran ọ̀sìn àti ẹrú, tí ó ń gbé ní àárín gbùngbùn ilẹ̀ náà.”
Hogy zsákmányt vess és prédát prédálj, hogy fordítsd kezedet a már népes pusztaságok ellen s a nép ellen, a mely a pogányok közül gyűjtetett egybe, mely jószágot és gazdagságot szerez s lakozik a földnek köldökén.
13 Ṣeba, Dedani àti àwọn oníṣòwò Tarṣiṣi àti gbogbo àwọn ọmọ kìnnìún wọn, yóò sọ fún un yín pé, “Ṣé ẹ̀yin wá fún ìkógun? Ṣé ẹ̀yin ti kó àwọn ogun yín jọ pọ̀ fún ìkógun, láti kó fàdákà àti wúrà lọ, láti kó ẹran ọ̀sìn àti ẹrú àti láti gba ọ̀pọ̀ ìkógun?”’”
Séba és Dedán és Társis kalmárai és minden fiatal oroszlánja ezt mondják néked: Nemde te zsákmányt vetni jöttél? Nemde prédát prédálni gyűjtötted egybe sokaságodat? hogy elvigy ezüstöt és aranyat, magadhoz végy jószágot s gazdagságot, hogy nagy zsákmányt vess.
14 “Nítorí náà, ọmọ ènìyàn, sọtẹ́lẹ̀ kí ó sì sọ fún Gogu: ‘Èyí yìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Ní ọjọ́ náà, nígbà tí àwọn ènìyàn mi Israẹli ń gbé ní àìléwu, ìwọ kì yóò ha ṣe àkíyèsí rẹ̀?
Annakokáért prófétálj, embernek fia, és mondd ezt Gógnak: Így szól az Úr Isten: Avagy abban az időben, mikor az én népem, Izráel bátorságosan lakik, nem tudod-é meg?
15 Ìwọ yóò wá láti ààyè rẹ ní jìnnàjìnnà àríwá, ìwọ àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀-èdè pẹ̀lú rẹ, gbogbo wọn yóò sì gun ẹṣin ẹgbẹ́ ńlá, jagunjagun alágbára.
És eljössz helyedről, a messze északról te és sok nép veled, lovon ülők mindnyájan, nagy sokaság és hatalmas sereg.
16 Ìwọ yóò tẹ̀síwájú ní ìlòdì sí àwọn Israẹli ènìyàn mi gẹ́gẹ́ bí ìkùùkuu tí ó bo ilẹ̀. Ni àwọn ọjọ́ tí ń bọ̀, ìwọ Gogu, èmi yóò mú ọ wá ní ìlòdì sí ilẹ̀ mi, kí àwọn orílẹ̀-èdè lè mọ̀ mi nígbà tí mo bá fi ara hàn ni mímọ́ láti ọ̀dọ̀ rẹ ní ojú wọn.
És feljössz az én népem, Izráel ellen, mint a felleg, hogy beborítsd a földet, az utolsó időkben lészen ez, és hozlak téged az én földemre, hogy a pogányok megismerjenek engem, mikor megszentelem magamat rajtad az ő szemök láttára, Góg!
17 “‘Èyí yìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Ìwọ ha kọ́ ni mo sọ̀rọ̀ nípa rẹ̀ ní ìgbà ìṣáájú láti ẹnu àwọn wòlíì ìránṣẹ́ mi ti Israẹli? Ní ìgbà náà wọ́n sọtẹ́lẹ̀ fún ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọdún pé èmi yóò mú ọ lòdì sí wọn.
Így szól az Úr Isten: Te vagy-é hát, a kiről szólottam a régi napokban az én szolgáim, Izráel prófétái által, kik prófétáltak azokban a napokban esztendőkön át, hogy téged ő reájok hozlak?
18 Èyí ni ohun tí yóò ṣẹlẹ̀ ní ọjọ́ náà, nígbà tí Gogu bá kọlu ilẹ̀ Israẹli, gbígbóná ìbínú mi yóò ru sókè, ni Olúwa Olódùmarè wí.
És lészen azon a napon, a mely napon Góg eljő Izráel földje ellen, ezt mondja az Úr Isten, felszáll haragom orromban.
19 Ní ìtara mi àti ní gbígbóná ìbínú mi, mo tẹnumọ́ ọn pé; ní àsìkò náà ilẹ̀ mímì tí ó lágbára ní ilẹ̀ Israẹli yóò ṣẹlẹ̀.
És féltő szerelmemben, búsulásom tüzében szólok: Bizony azon a napon nagy földindulás lesz Izráel földjén.
20 Ẹja inú Òkun, àwọn ẹyẹ òfúrufú, àwọn ẹranko igbó, àti gbogbo ẹ̀dá tí ó ń rìn lórí ilẹ̀ yóò wárìrì fún ìfarahàn mi. A yóò yí òkè gíga po, àwọn bèbè òkúta ni àwa yóò fọ́ sí wẹ́wẹ́, gbogbo ògiri ni yóò wó palẹ̀.
És megremegnek előttem a tenger halai és az ég madarai és a mező vadai és a földön csúszó-mászó mindenféle állatok és minden ember a föld színén; és leszakadnak a hegyek, és leesnek a meredek kősziklák, és minden fal a földre hull.
21 Èmi yóò fa idà yọ ni ìlòdì sí Gogu ní orí gbogbo àwọn òkè gíga mi ni Olúwa Olódùmarè wí. Idà gbogbo ènìyàn yóò lòdì sí arákùnrin rẹ̀.
És előhívom ellene minden hegyem felől a fegyvert, ezt mondja az Úr Isten; egyiknek fegyvere a másik ellen lészen.
22 Èmi yóò gbé ìdájọ́ mi jáde lórí rẹ̀ pẹ̀lú ìyọnu àti ìtàjẹ̀ sílẹ̀, Èmi yóò dá àgbàrá òjò, òkúta yìnyín àti imí-ọjọ́ tí ń jó lé e lórí àti lórí ọ̀wọ́ ogun àti lórí ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀-èdè pẹ̀lú rẹ̀.
És törvénykezem vele döghalállal és vérrel; és ömlő záporesőt, jégeső köveit, tüzet és kénkövet, mint esőt bocsátok reá és seregére s a sok népre, a mely vele lesz.
23 Nítorí náà, Èmi yóò fi títóbi mi àti ìjẹ́-mímọ́ mi hàn, Èmi yóò sì fi ara mi hàn ní ojú ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀-èdè. Nígbà náà ni wọn yóò mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.’
És nagynak s szentnek mutatom, és megjelentem magamat a pogányok sokasága előtt, hogy megtudják, hogy én vagyok az Úr!