< Ezekiel 38 >

1 Ọrọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá:
Et la parole du Seigneur me vint, disant:
2 “Ọmọ ènìyàn, kọ ojú rẹ sí Gogu, ti ilẹ̀ Magogu; olórí ọmọ-aládé, Meṣeki, àti Tubali sọtẹ́lẹ̀ ní ìlòdì sí i
Fils de l'homme, tourne ton visage contre la terre de Magog et contre Gog, prince de Rhos, de Mésoch et de Thubal, et prophétise contre lui.
3 kí ó sì wí pé, ‘Èyí yìí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: Èmi lòdì sí ọ, ìwọ Gogu, olórí ọmọ-aládé, Meṣeki àti Tubali.
Et dis-lui: Ainsi parle le Seigneur Maître: Voilà que je suis contre toi, prince de Rhos, de Mésoch et de Thubal.
4 Èmi yóò yí ọ kiri, èmi yóò sì fi ìwọ̀ kọ́ ọ ní ẹnu, èmi yóò sì fà ọ́ jáde pẹ̀lú gbogbo ọmọ-ogun rẹ, àwọn ẹṣin àti àwọn agẹṣinjagun nínú ìhámọ́ra, àti ìpéjọ ńlá pẹ̀lú asà ogun ńlá àti kéékèèké, gbogbo wọn ń fi idà wọn.
Je rassemblerai ton peuple et toute ton armée, chevaux et cavaliers, tous portant cuirasse; troupe nombreuse armée d'écus, de casques et de glaives.
5 Persia, Kuṣi àti Puti yóò wà pẹ̀lú wọn, gbogbo wọn yóò wà pẹ̀lú asà àti ìṣíborí wọn
Perses, Éthiopiens et Libyens, tous portant casque et bouclier,
6 Gomeri náà pẹ̀lú gbogbo àwọn ọmọ-ogun rẹ̀, àti Beti-Togarma láti jìnnàjìnnà àríwá pẹ̀lú gbogbo àwọn ọ̀wọ́ ogun rẹ̀—ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn orílẹ̀-èdè pẹ̀lú rẹ̀.
Gomer et tous ceux qui lui appartiennent, la maison de Thorgama aux dernières limites du nord, et tous ceux qui lui appartiennent, et beaucoup de nations seront avec toi.
7 “‘Múra sílẹ̀, múra tán, kí ìwọ àti gbogbo ìjọ náà péjọpọ̀ pẹ̀lú rẹ, kí o sì pàṣẹ fún wọn.
Prépare-toi, sois tout prêt, toi et toute ta troupe réunie autour de toi, et sois pour moi un rempart;
8 Lẹ́yìn ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọjọ́, àwa yóò bẹ̀ ọ wò; ní ọdún ìkẹyìn ìwọ yóò dó ti ilẹ̀ tí a ti gbà padà lọ́wọ́ idà, tí àwọn ènìyàn wọn kórajọ pọ̀ láti ọ̀pọ̀ orílẹ̀-èdè sí àwọn òkè gíga ti Israẹli, tí ó ti di ahoro fún ìgbà pípẹ́. A ti mú wọn jáde láti ọ̀dọ̀ àwọn orílẹ̀-èdè, nísinsin yìí gbogbo wọn ń gbé ní àìléwu.
Et il se préparera à la fin de bien des jours, et à la fin des temps il viendra, et il entrera dans une terre sauvée du glaive, quand les peuples de maintes nations étaient rassemblés contre la terre d'Israël, qui avait été entièrement dévastée; et il est venu d'entre les gentils, et ils habiteront tous en paix.
9 Ìwọ àti ọ̀wọ́ ogun rẹ àti ọ̀pọ̀ orílẹ̀-èdè pẹ̀lú rẹ yóò gòkè, ẹ̀yin yóò tẹ̀síwájú bí ìjì; ìwọ yóò dàbí ìkùùkuu tí ó bo ilẹ̀ mọ́lẹ̀.
Et tu te répandras comme la pluie; et comme une nuée tu viendras couvrir la terre, et tu seras là, toi et tous ceux qui t'appartiennent, et beaucoup de nations avec toi.
10 “‘Èyí ni Olúwa Olódùmarè wí: Ní ọjọ́ náà èrò kan yóò wá sọ́kàn rẹ, ìwọ yóò sì pète ìlànà búburú.
Or voici ce que dit le Seigneur Maître: En ce jour-là ceci adviendra: des pensées s'élèveront en ton cœur, et tu concevras de mauvais desseins.
11 Ìwọ yóò wí pé, “Èmi yóò gbé ogun ti ilẹ̀ àwọn tí a kò fi odi yíká, Èmi yóò gbé ogun ti àwọn ènìyàn àlàáfíà tí a kò funra sí gbogbo wọn ń gbé ní àìsí odi, ní àìsí ẹnu-ọ̀nà òde àti àsígbè-irin.
Et tu diras: J'entrerai en une terre répudiée; je marcherai contre des hommes qui vivent dans le repos, qui demeurent chez eux en paix, qui habitent une terre où il n'y a ni remparts, ni portes, ni verrous.
12 Èmi yóò mú ohun ọdẹ, èmi yóò sì kó ìkógun, èmi yóò sì yí ọwọ́ mi padà sí ibi ìwólulẹ̀ ti a ti tún kọ́, àwọn ènìyàn tí a kójọpọ̀ láti ọ̀dọ̀ àwọn orílẹ̀-èdè, tí ó ní ọrọ̀ nínú ẹran ọ̀sìn àti ẹrú, tí ó ń gbé ní àárín gbùngbùn ilẹ̀ náà.”
Saisis donc cette proie; pille ces dépouilles; porte les mains sur cette terre déserte et repeuplée, sur ce peuple rassemblé d'entre maintes nations, ayant acquis des richesses, et habitant l'intérieur des terres.
13 Ṣeba, Dedani àti àwọn oníṣòwò Tarṣiṣi àti gbogbo àwọn ọmọ kìnnìún wọn, yóò sọ fún un yín pé, “Ṣé ẹ̀yin wá fún ìkógun? Ṣé ẹ̀yin ti kó àwọn ogun yín jọ pọ̀ fún ìkógun, láti kó fàdákà àti wúrà lọ, láti kó ẹran ọ̀sìn àti ẹrú àti láti gba ọ̀pọ̀ ìkógun?”’”
Saba et Dédan, les marchands de Carthage et toutes leurs villes te diront: Tu es venu pour saisir une proie et piller des dépouilles; tu as rassemblé tes troupes pour prendre de l'argent et de l'or, pour emporter des richesses et recueillir du butin.
14 “Nítorí náà, ọmọ ènìyàn, sọtẹ́lẹ̀ kí ó sì sọ fún Gogu: ‘Èyí yìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Ní ọjọ́ náà, nígbà tí àwọn ènìyàn mi Israẹli ń gbé ní àìléwu, ìwọ kì yóò ha ṣe àkíyèsí rẹ̀?
À cause de cela, prophétise, fils de l'homme, et dis à Gog: Ainsi parle le Seigneur: N'est-ce pas dans le temps même où mon peuple Israël sera en paix dans sa demeure, que tu t'élèveras?
15 Ìwọ yóò wá láti ààyè rẹ ní jìnnàjìnnà àríwá, ìwọ àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀-èdè pẹ̀lú rẹ, gbogbo wọn yóò sì gun ẹṣin ẹgbẹ́ ńlá, jagunjagun alágbára.
Alors tu viendras des régions les plus lointaines du nord, et il y aura avec toi divers peuples, tous rassemblés en grand nombre, immense armée de cavaliers.
16 Ìwọ yóò tẹ̀síwájú ní ìlòdì sí àwọn Israẹli ènìyàn mi gẹ́gẹ́ bí ìkùùkuu tí ó bo ilẹ̀. Ni àwọn ọjọ́ tí ń bọ̀, ìwọ Gogu, èmi yóò mú ọ wá ní ìlòdì sí ilẹ̀ mi, kí àwọn orílẹ̀-èdè lè mọ̀ mi nígbà tí mo bá fi ara hàn ni mímọ́ láti ọ̀dọ̀ rẹ ní ojú wọn.
Et tu marcheras contre mon peuple d'Israël, comme une nuée qui vient couvrir la terre. Or ceci arrivera vers les jours de la fin: je te conduirai sur ma terre, afin que toutes les nations me connaissent quand devant elles je me sanctifierai en toi.
17 “‘Èyí yìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Ìwọ ha kọ́ ni mo sọ̀rọ̀ nípa rẹ̀ ní ìgbà ìṣáájú láti ẹnu àwọn wòlíì ìránṣẹ́ mi ti Israẹli? Ní ìgbà náà wọ́n sọtẹ́lẹ̀ fún ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọdún pé èmi yóò mú ọ lòdì sí wọn.
Voici ce que le Seigneur dit à Gog: Tu es celui de qui j'ai parlé dès les jours d'autrefois, par la voix de mes serviteurs les prophètes d'Israël, annonçant qu'en ces années et ces jours-là je te conduirais contre eux.
18 Èyí ni ohun tí yóò ṣẹlẹ̀ ní ọjọ́ náà, nígbà tí Gogu bá kọlu ilẹ̀ Israẹli, gbígbóná ìbínú mi yóò ru sókè, ni Olúwa Olódùmarè wí.
Et ceci adviendra: le jour où Gog viendra sur la terre d'Israël, dit le Seigneur Maître, ma colère éclatera
19 Ní ìtara mi àti ní gbígbóná ìbínú mi, mo tẹnumọ́ ọn pé; ní àsìkò náà ilẹ̀ mímì tí ó lágbára ní ilẹ̀ Israẹli yóò ṣẹlẹ̀.
Avec ma jalousie; j'ai parlé dans le feu de ma colère; et, en vérité, ce jour-là il y aura un grand ébranlement dans la terre d'Israël.
20 Ẹja inú Òkun, àwọn ẹyẹ òfúrufú, àwọn ẹranko igbó, àti gbogbo ẹ̀dá tí ó ń rìn lórí ilẹ̀ yóò wárìrì fún ìfarahàn mi. A yóò yí òkè gíga po, àwọn bèbè òkúta ni àwa yóò fọ́ sí wẹ́wẹ́, gbogbo ògiri ni yóò wó palẹ̀.
Et les poissons de la mer trembleront en présence du Seigneur, ainsi que les oiseaux du ciel, et les bêtes des champs, et les reptiles qui se traînent à terre, et tous les hommes qui seront encore sur la face de la terre. Et les montagnes se fendront, et les vallons seront bouleversés, et toute muraille s'écroulera.
21 Èmi yóò fa idà yọ ni ìlòdì sí Gogu ní orí gbogbo àwọn òkè gíga mi ni Olúwa Olódùmarè wí. Idà gbogbo ènìyàn yóò lòdì sí arákùnrin rẹ̀.
Mais alors contre lui-même j'appellerai tous les épouvantements, dit le Seigneur; et l'épée de l'homme se tournera contre son frère.
22 Èmi yóò gbé ìdájọ́ mi jáde lórí rẹ̀ pẹ̀lú ìyọnu àti ìtàjẹ̀ sílẹ̀, Èmi yóò dá àgbàrá òjò, òkúta yìnyín àti imí-ọjọ́ tí ń jó lé e lórí àti lórí ọ̀wọ́ ogun àti lórí ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀-èdè pẹ̀lú rẹ̀.
Et à mon tour j'exercerai sur lui mes jugements par la peste, par le sang, par les inondations, par une grêle de pierres; et je ferai tomber sur lui, sur ses compagnons et sur toutes les nations qui seront avec lui, une pluie de soufre et de feu.
23 Nítorí náà, Èmi yóò fi títóbi mi àti ìjẹ́-mímọ́ mi hàn, Èmi yóò sì fi ara mi hàn ní ojú ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀-èdè. Nígbà náà ni wọn yóò mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.’
Et je serai célébré, et je serai sanctifié, et je serai glorifié; et je me ferai connaître devant maintes nations, et elles sauront que je suis le Seigneur.

< Ezekiel 38 >