< Ezekiel 38 >

1 Ọrọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá:
И Господното слово дойде към мене и рече:
2 “Ọmọ ènìyàn, kọ ojú rẹ sí Gogu, ti ilẹ̀ Magogu; olórí ọmọ-aládé, Meṣeki, àti Tubali sọtẹ́lẹ̀ ní ìlòdì sí i
Сине човешки, насочи лицето си към Гога, в земята на Магога, княза на Рос, Мосох и Тувал, и пророкувай против него, като речеш:
3 kí ó sì wí pé, ‘Èyí yìí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: Èmi lòdì sí ọ, ìwọ Gogu, olórí ọmọ-aládé, Meṣeki àti Tubali.
Така казва Господ Иеова: Ето, Аз съм против тебе, Гоге, княже на Рос, Мосох и Тувал.
4 Èmi yóò yí ọ kiri, èmi yóò sì fi ìwọ̀ kọ́ ọ ní ẹnu, èmi yóò sì fà ọ́ jáde pẹ̀lú gbogbo ọmọ-ogun rẹ, àwọn ẹṣin àti àwọn agẹṣinjagun nínú ìhámọ́ra, àti ìpéjọ ńlá pẹ̀lú asà ogun ńlá àti kéékèèké, gbogbo wọn ń fi idà wọn.
Ще те обърна, ще туря кука на челюстите ти, и ще те извадя, с цялата ти войска, коне и конници, всички напълно въоръжени, едно голямо пълчище с щитове и щитчета, всички употребяващи ножове,
5 Persia, Kuṣi àti Puti yóò wà pẹ̀lú wọn, gbogbo wọn yóò wà pẹ̀lú asà àti ìṣíborí wọn
персийци, етиопяни, и ливийци с тях, всички с щитове и шлемове,
6 Gomeri náà pẹ̀lú gbogbo àwọn ọmọ-ogun rẹ̀, àti Beti-Togarma láti jìnnàjìnnà àríwá pẹ̀lú gbogbo àwọn ọ̀wọ́ ogun rẹ̀—ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn orílẹ̀-èdè pẹ̀lú rẹ̀.
Гомера и всичките му пълчища, дома на Тогарма, от най-далечните страни на север, и всичките му пълчища, и много народи с тебе.
7 “‘Múra sílẹ̀, múra tán, kí ìwọ àti gbogbo ìjọ náà péjọpọ̀ pẹ̀lú rẹ, kí o sì pàṣẹ fún wọn.
Приготви се, да! приготви себе си, ти и цялото пълчище, което се е събрало при тебе, и стани им военачалник.
8 Lẹ́yìn ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọjọ́, àwa yóò bẹ̀ ọ wò; ní ọdún ìkẹyìn ìwọ yóò dó ti ilẹ̀ tí a ti gbà padà lọ́wọ́ idà, tí àwọn ènìyàn wọn kórajọ pọ̀ láti ọ̀pọ̀ orílẹ̀-èdè sí àwọn òkè gíga ti Israẹli, tí ó ti di ahoro fún ìgbà pípẹ́. A ti mú wọn jáde láti ọ̀dọ̀ àwọn orílẹ̀-èdè, nísinsin yìí gbogbo wọn ń gbé ní àìléwu.
След много дни ще бъдеш наказан; в послешните години ще дойдеш в земята, която е била отървана от ножа, и е била събрана от много племена, върху Израилевите планини, които са били непрекъснато пусти; но Израил биде пренесен изсред племената, и те всички ще живеят в нея в безопасност.
9 Ìwọ àti ọ̀wọ́ ogun rẹ àti ọ̀pọ̀ orílẹ̀-èdè pẹ̀lú rẹ yóò gòkè, ẹ̀yin yóò tẹ̀síwájú bí ìjì; ìwọ yóò dàbí ìkùùkuu tí ó bo ilẹ̀ mọ́lẹ̀.
И ти като възлезеш, ще дойдеш като вихрушка; ще бъдеш като облак, за да покриеш земята, ти и всичките твои пълчища, и много племена с тебе.
10 “‘Èyí ni Olúwa Olódùmarè wí: Ní ọjọ́ náà èrò kan yóò wá sọ́kàn rẹ, ìwọ yóò sì pète ìlànà búburú.
Така казва Господ Иеова: В оня ден ще дойдат мисли в ума ти, и ще скроиш лоши намерения, като речеш:
11 Ìwọ yóò wí pé, “Èmi yóò gbé ogun ti ilẹ̀ àwọn tí a kò fi odi yíká, Èmi yóò gbé ogun ti àwọn ènìyàn àlàáfíà tí a kò funra sí gbogbo wọn ń gbé ní àìsí odi, ní àìsí ẹnu-ọ̀nà òde àti àsígbè-irin.
Ще вляза в земята на неукрепени села! ще отида при ония, които са в спокойствие и живеят безгрижно, всички които живеят в неукрепени места, без лостове и порти,
12 Èmi yóò mú ohun ọdẹ, èmi yóò sì kó ìkógun, èmi yóò sì yí ọwọ́ mi padà sí ibi ìwólulẹ̀ ti a ti tún kọ́, àwọn ènìyàn tí a kójọpọ̀ láti ọ̀dọ̀ àwọn orílẹ̀-èdè, tí ó ní ọrọ̀ nínú ẹran ọ̀sìn àti ẹrú, tí ó ń gbé ní àárín gbùngbùn ilẹ̀ náà.”
за да ги обереш и да вземеш корист, за да обърнеш ръката си против запустелите места сега населени, и против събраните изсред народите люде, които са придобили добитък и имот, и живеят в най-отбраната страна на света.
13 Ṣeba, Dedani àti àwọn oníṣòwò Tarṣiṣi àti gbogbo àwọn ọmọ kìnnìún wọn, yóò sọ fún un yín pé, “Ṣé ẹ̀yin wá fún ìkógun? Ṣé ẹ̀yin ti kó àwọn ogun yín jọ pọ̀ fún ìkógun, láti kó fàdákà àti wúrà lọ, láti kó ẹran ọ̀sìn àti ẹrú àti láti gba ọ̀pọ̀ ìkógun?”’”
Шева, Дедан, и търговците на Тарсис с всичките му млади лъвове ще ти рекат: Да обереш ли си дошъл? Да вземеш корист ли си събрал множеството си? Да грабнеш сребро и злато ли, да вземеш добитък и имот ли, да направиш голям обир ли?
14 “Nítorí náà, ọmọ ènìyàn, sọtẹ́lẹ̀ kí ó sì sọ fún Gogu: ‘Èyí yìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Ní ọjọ́ náà, nígbà tí àwọn ènìyàn mi Israẹli ń gbé ní àìléwu, ìwọ kì yóò ha ṣe àkíyèsí rẹ̀?
Затова, сине човешки, пророкувай като речеш на Гога: Така казва Господ Иеова: В оня ден, когато людете Ми Израил ще живеят в безопасност, ти няма ли да го знаеш?
15 Ìwọ yóò wá láti ààyè rẹ ní jìnnàjìnnà àríwá, ìwọ àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀-èdè pẹ̀lú rẹ, gbogbo wọn yóò sì gun ẹṣin ẹgbẹ́ ńlá, jagunjagun alágbára.
Ще дойдеш от мястото си, от най-далечните страни на север, ти и много племена с тебе, всички яздещи на коне, голямо множество и силна войска;
16 Ìwọ yóò tẹ̀síwájú ní ìlòdì sí àwọn Israẹli ènìyàn mi gẹ́gẹ́ bí ìkùùkuu tí ó bo ilẹ̀. Ni àwọn ọjọ́ tí ń bọ̀, ìwọ Gogu, èmi yóò mú ọ wá ní ìlòdì sí ilẹ̀ mi, kí àwọn orílẹ̀-èdè lè mọ̀ mi nígbà tí mo bá fi ara hàn ni mímọ́ láti ọ̀dọ̀ rẹ ní ojú wọn.
и ще възлезеш против людете Ми Израиля като облак, покриващ земята. Това ще бъде в послешните дни; и Аз ще те доведа против земята, за да Ме познаят народите, когато се осветя у тебе, Гоге, пред очите им.
17 “‘Èyí yìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Ìwọ ha kọ́ ni mo sọ̀rọ̀ nípa rẹ̀ ní ìgbà ìṣáájú láti ẹnu àwọn wòlíì ìránṣẹ́ mi ti Israẹli? Ní ìgbà náà wọ́n sọtẹ́lẹ̀ fún ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọdún pé èmi yóò mú ọ lòdì sí wọn.
Така казва Господ Иеова: Ти ли си оня, за когото говорих в древно време чрез слугите Си Израилевите пророци, които в ония дни пророкуваха през много години, че щях да те доведа против тях?
18 Èyí ni ohun tí yóò ṣẹlẹ̀ ní ọjọ́ náà, nígbà tí Gogu bá kọlu ilẹ̀ Israẹli, gbígbóná ìbínú mi yóò ru sókè, ni Olúwa Olódùmarè wí.
Но в оня ден, в деня когато Бог дойде против Израилевата земя, яростта Ми ще възлезе в ноздрите Ми, казва Господ Иеова.
19 Ní ìtara mi àti ní gbígbóná ìbínú mi, mo tẹnumọ́ ọn pé; ní àsìkò náà ilẹ̀ mímì tí ó lágbára ní ilẹ̀ Israẹli yóò ṣẹlẹ̀.
Защото в ревнивостта Си и в пламенния Си гняв казах: Непременно в оня ден ще има голям трепет в Израилевата земя,
20 Ẹja inú Òkun, àwọn ẹyẹ òfúrufú, àwọn ẹranko igbó, àti gbogbo ẹ̀dá tí ó ń rìn lórí ilẹ̀ yóò wárìrì fún ìfarahàn mi. A yóò yí òkè gíga po, àwọn bèbè òkúta ni àwa yóò fọ́ sí wẹ́wẹ́, gbogbo ògiri ni yóò wó palẹ̀.
така щото морските риби и небесните птици, полските зверове и всички гадини, които пълзят по света, и всичките човеци, които са по лицето на света, ще се разтреперят от присъствието Ми; и планините ще се сринат, стръмните височини ще паднат, и всяка стена ще се събори до земята.
21 Èmi yóò fa idà yọ ni ìlòdì sí Gogu ní orí gbogbo àwọn òkè gíga mi ni Olúwa Olódùmarè wí. Idà gbogbo ènìyàn yóò lòdì sí arákùnrin rẹ̀.
И ще призова нож против него по всичките Си планини, казва Господ Иеова; ножът на всеки човек ще бъде против брата му.
22 Èmi yóò gbé ìdájọ́ mi jáde lórí rẹ̀ pẹ̀lú ìyọnu àti ìtàjẹ̀ sílẹ̀, Èmi yóò dá àgbàrá òjò, òkúta yìnyín àti imí-ọjọ́ tí ń jó lé e lórí àti lórí ọ̀wọ́ ogun àti lórí ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀-èdè pẹ̀lú rẹ̀.
Аз ще се съдя с него чрез мор, и чрез кръв; и ще наваля върху него, върху пълчищата му, и върху многото племена, които са с него, пороен дъжд и градушка от големи камъни, огън и сяра,
23 Nítorí náà, Èmi yóò fi títóbi mi àti ìjẹ́-mímọ́ mi hàn, Èmi yóò sì fi ara mi hàn ní ojú ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀-èdè. Nígbà náà ni wọn yóò mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.’
Аз ще възвелича и осветя, и ще стана познат пред очите на много народи; и те ще познаят, че Аз съм Господ.

< Ezekiel 38 >