< Ezekiel 37 >

1 Ọwọ́ Olúwa wà lára mi, ó sì mú mi jáde pẹ̀lú ẹ̀mí Olúwa, ó mú kí ń wà ní àárín àfonífojì; ti o kún fún àwọn egungun.
Na rĩrĩ, guoko kwa Jehova nĩ kwagĩire igũrũ rĩakwa, ngĩoywo nĩ Roho wa Jehova akĩndwara handũ gĩtuamba-inĩ gatagatĩ; nakĩo kĩaiyũrĩte mahĩndĩ.
2 Ó mú mi lọ síwájú àti sẹ́yìn láàrín wọn, èmi sì rí ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn egungun ní orí ilẹ̀ àfonífojì, àwọn egungun tí ó gbẹ gan.
Nake akĩndongoria akĩnjeeria kũu maarĩ, na ngĩona mahĩndĩ maingĩ mũno maaraganĩte kũu gĩtuamba-inĩ kĩu, na mahĩndĩ macio maarĩ momũ mũno.
3 Olúwa sì bi mí léèrè, “Ọmọ ènìyàn, ǹjẹ́ àwọn egungun wọ̀nyí lè yípadà di àwọn ènìyàn bí?” Èmi sì wí pé, “Ìwọ Olúwa Olódùmarè, ìwọ nìkan ni o lè dáhùn sí ìbéèrè yìí.”
Nake akĩnjũũria atĩrĩ, “Mũrũ wa mũndũ, mahĩndĩ maya-rĩ, no macooke muoyo?” Na niĩ ngĩmũcookeria atĩrĩ, “Mwathani Jehova, wee nowe wiki ũũĩ.”
4 Nígbà náà ni ó wí fún mi pé, “Sọtẹ́lẹ̀ sí àwọn egungun kí ó sì sọ fún wọn pé, ‘Ẹ̀yin egungun gbígbẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa!
Ningĩ agĩcooka akĩnjĩĩra atĩrĩ, “Rathĩra mahĩndĩ maya ũhoro, ũmeere atĩrĩ, ‘Mahĩndĩ maya momũ, iguai kiugo kĩa Jehova!
5 Èyí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí fún àwọn egungun wọ̀nyí. Èmi yóò mú kí èémí wọ inú yín ẹ̀yin yóò sì wá di ààyè.
Mwathani Jehova ekwĩra mahĩndĩ maya ũũ: Nĩngũtũma mũgĩe na mĩhũmũ, na inyuĩ nĩmũgũcooka muoyo.
6 Èmi yóò so iṣan ara mọ́ ọn yín, Èmi yóò sì mú kí ẹran-ara wá sí ara yín, Èmi yóò sì fi awọ ara bò yín, Èmi yóò sì fi èémí sínú yín, ẹ̀yin yóò sì wà ní ààyè. Nígbà náà ẹ̀yin yóò mọ̀ pé èmi ni Olúwa.’”
Nĩngũmwĩkĩra mĩkiha, na ndũme mũgĩe na nyama na ndĩmũhumbĩre na gĩkonde; nĩngũmwĩkĩra mĩhũmũ, na nĩmũgũcooka muoyo. Hĩndĩ ĩyo nĩmũkamenya atĩ niĩ nĩ niĩ Jehova.’”
7 Nítorí náà ni mo ṣe sọtẹ́lẹ̀ gẹ́gẹ́ bí a ti pa á láṣẹ fún mi. Bí mo sì ti ń sọtẹ́lẹ̀, ariwo wá, ìró tí ó kígbe sókè, àwọn egungun sì wà papọ̀, egungun sí egungun.
Nĩ ũndũ ũcio ngĩratha ũhoro o ta ũrĩa ndaathĩtwo. Na rĩrĩa ndaarathaga, hakĩgĩa na inegene, mũgambo wa gũkaragacana, namo mahĩndĩ macio magĩcookanĩrĩra, o ihĩndĩ rĩgĩcookerera ihĩndĩ rĩrĩa rĩagĩrĩire.
8 Mo wò ó, iṣan ara àti ẹran-ara farahàn lára wọn, awọ ara sì bò wọ́n, ṣùgbọ́n kò sí èémí nínú wọn.
Na niĩ ngĩcũthĩrĩria, ngĩona maagĩa mĩkiha na nyama, nakĩo gĩkonde gĩkĩmahumbĩra, no matiarĩ na mĩhũmũ.
9 Lẹ́yìn náà ni ó sọ fún mi pé, “Sọtẹ́lẹ̀ sí èémí; sọtẹ́lẹ̀, ọmọ ènìyàn, kí ó sì sọ fún un pé, ‘Èyí yìí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: wá láti atẹ́gùn mẹ́rẹ̀ẹ̀rin, ìwọ èémí, kí ó sì mí èémí sínú àwọn tí a pa wọ̀nyí, kí wọn kí ó lè wà ní ààyè.’”
Ningĩ akĩnjĩĩra atĩrĩ, “Rathĩra mĩhũmũ ũhoro; mũrũ wa mũndũ, mĩrathĩre ũhoro ũmĩĩre atĩrĩ, ‘Mwathani Jehova ekuuga ũũ: Ũkai inyuĩ mĩhũmũ ya muoyo muumĩte mĩena ĩna ĩrĩa yumaga rũhuho, na mwĩkĩre mĩhũmũ thĩinĩ wa aya moragĩtwo, nĩguo macooke muoyo.’”
10 Nítorí náà, mo sọtẹ́lẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ó ṣe pa á láṣẹ fún mi, èémí sì wọ inú wọn; wọ́n di alààyè, wọ́n sì dìde dúró lórí ẹsẹ̀ wọn—pẹ̀lú ìhámọ́ra tí ó pọ̀.
Nĩ ũndũ ũcio ngĩratha ũhoro o ta ũrĩa aanjathĩte, nayo mĩhũmũ ĩkĩmatoonya; nao makĩgĩa muoyo, makĩĩrũgamia na magũrũ mao, nao magĩkorwo marĩ mbũtũ nene ya ita.
11 Lẹ́yìn náà ó sọ fún mi: “Ọmọ ènìyàn, àwọn egungun wọ̀nyí ni gbogbo ìdílé Israẹli. Wọ́n sọ wí pé, ‘Egungun wa ti gbẹ ìrètí wa sì ti lọ; a ti gé wa kúrò.’
Nake akĩnjĩĩra atĩrĩ, “Mũrũ wa mũndũ, mahĩndĩ maya nĩmo andũ a nyũmba yothe ya Isiraeli. Moigaga atĩrĩ, ‘Mahĩndĩ maitũ nĩmomũ, naguo mwĩhoko witũ nĩmũthiru; na ithuĩ nĩtũeheretio.’
12 Nítorí náà sọtẹ́lẹ̀, kí o sì sọ fun wọn pé, ‘Èyí yìí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè sọ: Ẹ̀yin ènìyàn mi, Èmi yóò ṣí àwọn ibojì yín, èmi yóò sì mú yín wá si ilẹ̀ Israẹli.
Nĩ ũndũ ũcio, marathĩre ũhoro, ũmeere atĩrĩ, ‘Mwathani Jehova ekuuga ũũ: Inyuĩ andũ akwa, nĩngũhingũra mbĩrĩra cianyu ndĩmwambatie muume kũu; nĩngũmũcookia bũrũri ũcio wa Isiraeli.
13 Ẹ̀yin o sì mọ̀ èmi ni Olúwa, nígbà tí èmi bá ti ṣí ibojì yín, ẹ̀yin ènìyàn mi, ti èmi bá si mú un yín dìde kúrò nínú ibojì yín.
Hĩndĩ ĩyo nĩmũkamenya atĩ niĩ nĩ niĩ Jehova, rĩrĩa ngaahingũra mbĩrĩra cianyu ndĩmwambatie muume kuo, inyuĩ andũ aya akwa.
14 Èmi yóò fi èémí mi sínú yín, ẹ̀yin yóò sì yè, èmi yóò sì mú kí ẹ fi lélẹ̀ ní ilẹ̀ ẹ̀yin tìkára yín. Nígbà náà ẹ̀yin yóò mọ̀ pé Olúwa ti sọ̀rọ̀, èmi sì ti ṣe ni Olúwa wí.’”
Nĩngamwĩkĩra Roho wakwa, na inyuĩ nĩmũgatũũra muoyo, na nĩngamũtwara bũrũri ũrĩa ũrĩ wanyu kĩũmbe mũgatũũre kuo. Hĩndĩ ĩyo nĩmũkamenya atĩ niĩ Jehova nĩ niĩ njarĩtie, na nĩ niĩ njĩkĩte ũguo, ũguo nĩguo Jehova ekuuga.’”
15 Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mi wá:
Kiugo kĩa Jehova nĩkĩanginyĩrĩire, ngĩĩrwo atĩrĩ:
16 “Ọmọ ènìyàn, mú igi pátákó kan kí ó sì kọ̀wé sí ara rẹ̀, ‘Tí ó jẹ́ ti Juda àti ti Israẹli tí ó ní àṣepọ̀ pẹ̀lú rẹ̀.’ Lẹ́yìn náà, kí ó mú igi pátákò mìíràn kí ó sì kọ̀wé sí ara rẹ̀, ‘Tí ó jẹ́ ti tí Josẹfu (tí ó túmọ̀ sí ti Efraimu) àti gbogbo ilé Israẹli tí ó ni àṣepọ̀ pẹ̀lú rẹ̀.’
“Mũrũ wa mũndũ, oya gathanju ka mũtĩ wandĩke igũrũ rĩako atĩrĩ, ‘Gaka nĩ ka Juda na andũ a Isiraeli arĩa makuruhanĩte nake.’ Ningĩ woe gathanju kangĩ ka mũtĩ wandĩke igũrũ rĩako atĩrĩ, ‘Gathanju ka Efiraimu, karĩa ka Jusufu na andũ othe a nyũmba ya Isiraeli arĩa makuruhanĩte nake.’
17 So wọ́n papọ̀ sí ara igi kan nítorí náà wọn yóò di ọ̀kan ní ọwọ́ rẹ.
Tũnyiitithanie tũtuĩke rũthanju rũmwe nĩguo tũtuĩke rũthanju rũmwe guoko-inĩ gwaku.
18 “Nígbà tí àwọn ara ìlú rẹ bá béèrè lọ́wọ́ rẹ pé, ‘Ṣé ìwọ kò ní sọ ohun tí èyí túmọ̀ sí fún wa?’
“Rĩrĩa andũ anyu magaakũũria atĩrĩ, ‘Kaĩ ũtangĩtwĩra gĩtũmi kĩa maũndũ maya ũreka?’
19 Sọ fún wọn pé, ‘Èyí yìí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: Èmi yóò gba igi Josẹfu—èyí tí ó wà ní ọwọ́ Efraimu—àti ti ẹ̀yà Israẹli tí ó parapọ̀ mọ́ ọn, kí ó sì só papọ̀ mọ́ igi Juda, láti sọ wọ́n di igi kan ṣoṣo, wọn yóò sì di ọ̀kan ní ọwọ́ mi.’
ũkaamacookeria, ũmeere atĩrĩ, ‘Mwathani Jehova ekuuga ũũ: Nĩnguoya gathanju kau ka Jusufu na mĩhĩrĩga ya Isiraeli ĩyo ĩkuruhanĩte nake, o kau karĩ guoko-inĩ kwa Efiraimu, ndĩkoohanie hamwe na gathanju ka Juda, tũtuĩke rũthanju rũmwe, natuo tũtuĩke rũthanju rũmwe guoko-inĩ gwakwa.’
20 Gbé igi pátákó tí ó kọ nǹkan sí i sókè ní iwájú wọn,
Nyiita tũthanju tũu wandĩkĩte maitho-inĩ mao,
21 kí ó sì sọ fún wọn pé, ‘Èyí yìí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: Èmi yóò mú Israẹli jáde kúrò ní àwọn orílẹ̀-èdè tí wọ́n ti lọ. Èmi yóò ṣà wọ́n jọ pọ̀ láti gbogbo agbègbè, èmi yóò sì mú wọn padà sí ilẹ̀ ara wọn.
ũmeere atĩrĩ, ‘Mwathani Jehova ekuuga ũũ: Nĩngaruta andũ a Isiraeli kuuma ndũrĩrĩ-inĩ kũrĩa maathiĩte. Nĩngamacookanĩrĩria ndĩmarute kũrĩa guothe marĩ, na ndĩmacookie bũrũri wao kĩũmbe.
22 Èmi yóò ṣe wọ́n ní orílẹ̀-èdè kan ní ilẹ̀ náà, ní orí òkè Israẹli, ọba kan ni yóò wà lórí gbogbo wọn, wọn kì yóò sì jẹ́ orílẹ̀-èdè méjì mọ́, tàbí kí a pín wọn sí ìjọba méjì.
Nĩngamatua rũrĩrĩ rũmwe marĩ kũu bũrũri ũcio, o kũu irĩma-igũrũ cia Isiraeli. Gũkaagĩa mũthamaki ũmwe igũrũ rĩao othe, na matigacooka rĩngĩ gũtuĩka ndũrĩrĩ igĩrĩ, kana magayũkanio matuĩke mothamaki meerĩ.
23 Wọn kì yóò sì tún fi àwọn òrìṣà wọn ba ara wọn jẹ́ mọ́, tàbí ohun ìríra wọn, tàbí ohun ìrékọjá wọn: ṣùgbọ́n èmi yóò gbà wọn là kúrò nínú gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ àgàbàgebè wọn, èmi yóò sì wẹ̀ wọn mọ́. Wọn yóò jẹ́ ènìyàn mi, Èmi yóò sì jẹ́ Ọlọ́run wọn.
Matigethaahia rĩngĩ na mĩhianano yao, kana mĩhiano mĩũru, kana waganu wao o wothe, nĩgũkorwo nĩngamahonokia matige gũcooka na thuutha nĩ ũndũ wa mehia mao, na nĩngamatheria. Magaatuĩka andũ akwa, na niĩ nduĩke Ngai wao.
24 “‘Dafidi ìránṣẹ́ mi ni yóò jẹ ọba lórí wọn, gbogbo wọn yóò sì ní olùṣọ àgùntàn kan. Wọn yóò sì tẹ̀lé òfin mi, wọn yóò sì ṣe àníyàn láti pa àṣẹ mi mọ́.
“‘Daudi ndungata yakwa nĩwe ũgaatuĩka mũthamaki wao, nao othe magĩe na mũrĩithi ũmwe. Nĩmakarũmĩrĩra mawatho makwa na mamenyerere watho wakwa wa kũrũmĩrĩrwo.
25 Wọn yóò gbé ní ilẹ̀ tí mo fún Jakọbu ìránṣẹ́ mi, ilẹ̀ tí àwọn baba yín ń gbé. Àwọn àti àwọn ọmọ wọn àti àwọn ọmọ ọmọ wọn ni yóò máa gbé ibẹ̀ láéláé, ìránṣẹ́ mi Dafidi ni yóò jẹ́ Ọmọ-aládé wọn láéláé.
Magaatũũra bũrũri ũcio ndaaheire ndungata yakwa Jakubu, bũrũri ũrĩa maithe manyu maatũũraga. O ene, hamwe na ciana ciao, o na ciana cia ciana ciao, magaatũũra kuo nginya tene, nake Daudi ndungata yakwa atuĩke mũnene wao nginya tene.
26 Èmi yóò dá májẹ̀mú àlàáfíà pẹ̀lú wọn, yóò sì jẹ́ májẹ̀mú títí ayérayé. Èmi yóò gbé wọn kalẹ̀, èmi yóò sì sọ wọ́n di púpọ̀ ní iye, èmi yóò sì gbé ilé mímọ́ mi kalẹ̀ ní àárín wọn títí láé.
Nĩngarĩĩkanĩra kĩrĩkanĩro gĩa thayũ nao; nakĩo gĩgaatuĩka kĩrĩkanĩro gĩa gũtũũra nginya tene. Nĩngamahaanda na ndũme maingĩhe, na nĩngahaanda handũ-hakwa-harĩa-haamũre gatagatĩ-inĩ kao nginya tene.
27 Ibùgbé mí yóò wà pẹ̀lú wọn, Èmi yóò jẹ́ Ọlọ́run wọn, wọn yóò sì jẹ́ ènìyàn mi.
Ningĩ gĩikaro gĩakwa gĩgaatũũra hamwe nao; nĩngatuĩka Ngai wao, nao matuĩke andũ akwa.
28 Nígbà náà ni àwọn orílẹ̀-èdè yóò mọ̀ pé, Èmi Olúwa sọ Israẹli di mímọ́, nígbà tí ibi mímọ́ mi bá wà ní àárín wọn títí ayérayé.’”
Hĩndĩ ĩyo ndũrĩrĩ nĩikamenya atĩ niĩ Jehova nĩ niĩ nduuaga andũ a Isiraeli atheru, hĩndĩ ĩrĩa handũ-hakwa-harĩa-haamũre hagaatũũra hamwe nao nginya tene.’”

< Ezekiel 37 >