< Ezekiel 37 >

1 Ọwọ́ Olúwa wà lára mi, ó sì mú mi jáde pẹ̀lú ẹ̀mí Olúwa, ó mú kí ń wà ní àárín àfonífojì; ti o kún fún àwọn egungun.
The hond of the Lord was maad on me, and ledde me out in the spirit of the Lord; and he lefte me in the myddis of a feeld that was ful of boonys;
2 Ó mú mi lọ síwájú àti sẹ́yìn láàrín wọn, èmi sì rí ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn egungun ní orí ilẹ̀ àfonífojì, àwọn egungun tí ó gbẹ gan.
and he ledde me aboute bi tho in cumpas. Forsothe tho weren ful manye on the face of the feeld, and drie greetli.
3 Olúwa sì bi mí léèrè, “Ọmọ ènìyàn, ǹjẹ́ àwọn egungun wọ̀nyí lè yípadà di àwọn ènìyàn bí?” Èmi sì wí pé, “Ìwọ Olúwa Olódùmarè, ìwọ nìkan ni o lè dáhùn sí ìbéèrè yìí.”
And he seide to me, Gessist thou, sone of man, whether these boonys schulen lyue? And Y seide, Lord God, thou wost.
4 Nígbà náà ni ó wí fún mi pé, “Sọtẹ́lẹ̀ sí àwọn egungun kí ó sì sọ fún wọn pé, ‘Ẹ̀yin egungun gbígbẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa!
And he seide to me, Profesie thou of these boonys; and thou schalt seie to tho, Ye drie boonys, here the word of the Lord.
5 Èyí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí fún àwọn egungun wọ̀nyí. Èmi yóò mú kí èémí wọ inú yín ẹ̀yin yóò sì wá di ààyè.
The Lord God seith these thingis to these boonys, Lo! Y schal sende in to you a spirit, and ye schulen lyue.
6 Èmi yóò so iṣan ara mọ́ ọn yín, Èmi yóò sì mú kí ẹran-ara wá sí ara yín, Èmi yóò sì fi awọ ara bò yín, Èmi yóò sì fi èémí sínú yín, ẹ̀yin yóò sì wà ní ààyè. Nígbà náà ẹ̀yin yóò mọ̀ pé èmi ni Olúwa.’”
And Y schal yyue synewis on you, and Y schal make fleischis to wexe on you, and Y schal stretche forth aboue a skyn in you, and Y schal yyue a spirit to you, and ye schulen lyue; and ye schulen wite, that Y am the Lord.
7 Nítorí náà ni mo ṣe sọtẹ́lẹ̀ gẹ́gẹ́ bí a ti pa á láṣẹ fún mi. Bí mo sì ti ń sọtẹ́lẹ̀, ariwo wá, ìró tí ó kígbe sókè, àwọn egungun sì wà papọ̀, egungun sí egungun.
And Y profesiede, as he comaundide to me; forsothe a sown was maad, while Y profesiede, and lo! a stiryng togidere, and boonys camen to boonys, ech to his ioynture.
8 Mo wò ó, iṣan ara àti ẹran-ara farahàn lára wọn, awọ ara sì bò wọ́n, ṣùgbọ́n kò sí èémí nínú wọn.
And Y siy and lo! synewis and fleischis `wexeden vpon tho, and skyn was stretchid forth aboue in hem, and tho hadden no spirit.
9 Lẹ́yìn náà ni ó sọ fún mi pé, “Sọtẹ́lẹ̀ sí èémí; sọtẹ́lẹ̀, ọmọ ènìyàn, kí ó sì sọ fún un pé, ‘Èyí yìí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: wá láti atẹ́gùn mẹ́rẹ̀ẹ̀rin, ìwọ èémí, kí ó sì mí èémí sínú àwọn tí a pa wọ̀nyí, kí wọn kí ó lè wà ní ààyè.’”
And he seide to me, Profesie thou to the spirit, profesie thou, sone of man; and thou schalt seie to the spirit, The Lord God seith these thingis, Come, thou spirit, fro foure wyndis, and blowe thou on these slayn men, and lyue thei ayen.
10 Nítorí náà, mo sọtẹ́lẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ó ṣe pa á láṣẹ fún mi, èémí sì wọ inú wọn; wọ́n di alààyè, wọ́n sì dìde dúró lórí ẹsẹ̀ wọn—pẹ̀lú ìhámọ́ra tí ó pọ̀.
And Y profesiede, as he comaundide to me; and the spirit entride in to tho boonys, and thei lyueden, and stoden on her feet, a ful greet oost.
11 Lẹ́yìn náà ó sọ fún mi: “Ọmọ ènìyàn, àwọn egungun wọ̀nyí ni gbogbo ìdílé Israẹli. Wọ́n sọ wí pé, ‘Egungun wa ti gbẹ ìrètí wa sì ti lọ; a ti gé wa kúrò.’
And the Lord seide to me, Thou sone of man, alle these boonys is the hous of Israel; thei seien, Oure boonys drieden, and oure hope perischide, and we ben kit awei.
12 Nítorí náà sọtẹ́lẹ̀, kí o sì sọ fun wọn pé, ‘Èyí yìí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè sọ: Ẹ̀yin ènìyàn mi, Èmi yóò ṣí àwọn ibojì yín, èmi yóò sì mú yín wá si ilẹ̀ Israẹli.
Therfor profesie thou, and thou schalt seie to hem, The Lord God seith these thingis, Lo! Y schal opene youre graues, and Y schal lede you out of youre sepulcris, my puple, and Y schal lede you in to youre lond Israel.
13 Ẹ̀yin o sì mọ̀ èmi ni Olúwa, nígbà tí èmi bá ti ṣí ibojì yín, ẹ̀yin ènìyàn mi, ti èmi bá si mú un yín dìde kúrò nínú ibojì yín.
And ye schulen wite, that Y am the Lord, whanne Y schal opene youre sepulcris, and schal lede you out of youre biriels, my puple;
14 Èmi yóò fi èémí mi sínú yín, ẹ̀yin yóò sì yè, èmi yóò sì mú kí ẹ fi lélẹ̀ ní ilẹ̀ ẹ̀yin tìkára yín. Nígbà náà ẹ̀yin yóò mọ̀ pé Olúwa ti sọ̀rọ̀, èmi sì ti ṣe ni Olúwa wí.’”
and Y schal yyue my spirit in you, and ye schulen lyue. And Y schal make you for to reste on youre lond; and ye schulen wite, that Y the Lord spak, and dide, seith the Lord God.
15 Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mi wá:
And the word of the Lord was maad to me,
16 “Ọmọ ènìyàn, mú igi pátákó kan kí ó sì kọ̀wé sí ara rẹ̀, ‘Tí ó jẹ́ ti Juda àti ti Israẹli tí ó ní àṣepọ̀ pẹ̀lú rẹ̀.’ Lẹ́yìn náà, kí ó mú igi pátákò mìíràn kí ó sì kọ̀wé sí ara rẹ̀, ‘Tí ó jẹ́ ti tí Josẹfu (tí ó túmọ̀ sí ti Efraimu) àti gbogbo ilé Israẹli tí ó ni àṣepọ̀ pẹ̀lú rẹ̀.’
and he seide, And thou, sone of man, take to thee o tree, and write thou on it, To Juda, and to the sones of Israel, and to hise felowis. And take thou an other tree, and write on it, Joseph, the tree of Effraym, and of al the hous of Israel, and of hise felowis.
17 So wọ́n papọ̀ sí ara igi kan nítorí náà wọn yóò di ọ̀kan ní ọwọ́ rẹ.
And ioyne thou tho trees oon to the tother in to o tree to thee; and tho schulen be in to onement in thin hond.
18 “Nígbà tí àwọn ara ìlú rẹ bá béèrè lọ́wọ́ rẹ pé, ‘Ṣé ìwọ kò ní sọ ohun tí èyí túmọ̀ sí fún wa?’
Sotheli whanne the sones of thi puple that speken, schulen seie to thee, Whether thou schewist not to vs, what thou wolt to thee in these thingis?
19 Sọ fún wọn pé, ‘Èyí yìí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: Èmi yóò gba igi Josẹfu—èyí tí ó wà ní ọwọ́ Efraimu—àti ti ẹ̀yà Israẹli tí ó parapọ̀ mọ́ ọn, kí ó sì só papọ̀ mọ́ igi Juda, láti sọ wọ́n di igi kan ṣoṣo, wọn yóò sì di ọ̀kan ní ọwọ́ mi.’
thou schalt speke to hem, The Lord God seith these thingis, Lo! Y schal take the tree of Joseph, which is in the hond of Effraym, and the lynagis of Israel, that ben ioyned to hym, and Y schal yyue hem togidere with the tree of Juda; and Y schal make hem in to o tree, and thei schulen be oon in the hond of hym.
20 Gbé igi pátákó tí ó kọ nǹkan sí i sókè ní iwájú wọn,
Sotheli the trees, on whiche thou hast write, schulen be in thin hond bifore the iyen of hem.
21 kí ó sì sọ fún wọn pé, ‘Èyí yìí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: Èmi yóò mú Israẹli jáde kúrò ní àwọn orílẹ̀-èdè tí wọ́n ti lọ. Èmi yóò ṣà wọ́n jọ pọ̀ láti gbogbo agbègbè, èmi yóò sì mú wọn padà sí ilẹ̀ ara wọn.
And thou schalt seie to hem, The Lord God seith these thingis, Lo! Y schal take the sones of Israel fro the myddis of naciouns, to whiche thei yeden forth; and Y schal gadere hem togidere on ech side. And Y schal brynge hem to her lond,
22 Èmi yóò ṣe wọ́n ní orílẹ̀-èdè kan ní ilẹ̀ náà, ní orí òkè Israẹli, ọba kan ni yóò wà lórí gbogbo wọn, wọn kì yóò sì jẹ́ orílẹ̀-èdè méjì mọ́, tàbí kí a pín wọn sí ìjọba méjì.
and Y schal make hem o folc in the lond, in the hillis of Israel, and o kyng schal be comaundynge to alle: and thei schulen no more be twei folkis, and thei schulen no more be departid in to twey rewmes.
23 Wọn kì yóò sì tún fi àwọn òrìṣà wọn ba ara wọn jẹ́ mọ́, tàbí ohun ìríra wọn, tàbí ohun ìrékọjá wọn: ṣùgbọ́n èmi yóò gbà wọn là kúrò nínú gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ àgàbàgebè wọn, èmi yóò sì wẹ̀ wọn mọ́. Wọn yóò jẹ́ ènìyàn mi, Èmi yóò sì jẹ́ Ọlọ́run wọn.
And thei schulen no more be defoulid in her idols, and her abhomynaciouns, and in alle her wickidnessis. And Y schal make hem saaf fro alle her seetis, in which thei synneden, and Y schal clense hem; and thei schulen be a puple to me, and Y schal be God to hem.
24 “‘Dafidi ìránṣẹ́ mi ni yóò jẹ ọba lórí wọn, gbogbo wọn yóò sì ní olùṣọ àgùntàn kan. Wọn yóò sì tẹ̀lé òfin mi, wọn yóò sì ṣe àníyàn láti pa àṣẹ mi mọ́.
And my seruaunt Dauid schal be kyng on hem, and o scheepherde schal be of alle hem; thei schulen go in my domes, and thei schulen kepe my comaundementis, and schulen do tho.
25 Wọn yóò gbé ní ilẹ̀ tí mo fún Jakọbu ìránṣẹ́ mi, ilẹ̀ tí àwọn baba yín ń gbé. Àwọn àti àwọn ọmọ wọn àti àwọn ọmọ ọmọ wọn ni yóò máa gbé ibẹ̀ láéláé, ìránṣẹ́ mi Dafidi ni yóò jẹ́ Ọmọ-aládé wọn láéláé.
And thei schulen dwelle on the lond, which Y yaf to my seruaunt Jacob, in which youre fadris dwelliden; and thei schulen dwelle on that lond, thei, and the sones of hem, and the sones of her sones, til in to with outen ende; and Dauid, my seruaunt, schal be the prince of hem with outen ende.
26 Èmi yóò dá májẹ̀mú àlàáfíà pẹ̀lú wọn, yóò sì jẹ́ májẹ̀mú títí ayérayé. Èmi yóò gbé wọn kalẹ̀, èmi yóò sì sọ wọ́n di púpọ̀ ní iye, èmi yóò sì gbé ilé mímọ́ mi kalẹ̀ ní àárín wọn títí láé.
And Y schal smyte to hem a boond of pees; it schal be a couenaunt euerlastynge to hem, and Y schal founde hem, and Y schal multiplie, and Y schal yyue myn halewing in the myddis of hem with outen ende.
27 Ibùgbé mí yóò wà pẹ̀lú wọn, Èmi yóò jẹ́ Ọlọ́run wọn, wọn yóò sì jẹ́ ènìyàn mi.
And my tabernacle schal be among hem, and Y schal be God to hem, and thei schulen be a puple to me.
28 Nígbà náà ni àwọn orílẹ̀-èdè yóò mọ̀ pé, Èmi Olúwa sọ Israẹli di mímọ́, nígbà tí ibi mímọ́ mi bá wà ní àárín wọn títí ayérayé.’”
And hethene men schulen wite, that Y am the Lord, halewere of Israel, whanne myn halewyng schal be in the myddis of hem with outen ende.

< Ezekiel 37 >