< Ezekiel 37 >

1 Ọwọ́ Olúwa wà lára mi, ó sì mú mi jáde pẹ̀lú ẹ̀mí Olúwa, ó mú kí ń wà ní àárín àfonífojì; ti o kún fún àwọn egungun.
BOEIPA kut te kai soah om. Te vaengah BOEIPA Mueihla loh kai n'khuen tih kolbawn khui la kai n'khueh hatah a rhuhrhong bae muep.
2 Ó mú mi lọ síwájú àti sẹ́yìn láàrín wọn, èmi sì rí ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn egungun ní orí ilẹ̀ àfonífojì, àwọn egungun tí ó gbẹ gan.
Kai te te lakli lamloh a kaep a kaep ah n'thak. Te vaengah kolbawn hman kah te bahoeng yet tih koh aih coeng he.
3 Olúwa sì bi mí léèrè, “Ọmọ ènìyàn, ǹjẹ́ àwọn egungun wọ̀nyí lè yípadà di àwọn ènìyàn bí?” Èmi sì wí pé, “Ìwọ Olúwa Olódùmarè, ìwọ nìkan ni o lè dáhùn sí ìbéèrè yìí.”
Te vaengah kai te, ‘Hlang capa he kah a rhuh he hing aya?’ a ti. Tedae, “Ka Boeipa Yahovah, namah loh na ming,” ka ti nah.
4 Nígbà náà ni ó wí fún mi pé, “Sọtẹ́lẹ̀ sí àwọn egungun kí ó sì sọ fún wọn pé, ‘Ẹ̀yin egungun gbígbẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa!
Te phoeiah kai te he rhuhrhong taengah tonghma lamtah a rhuh koh rhoek te, ‘BOEIPA ol hnatun lah,’ ti nah.
5 Èyí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí fún àwọn egungun wọ̀nyí. Èmi yóò mú kí èémí wọ inú yín ẹ̀yin yóò sì wá di ààyè.
He kah rhuhrhong taengah ka Boeipa Yahovah loh he ni a thui. Kai loh nangmih khuila mueihla kan khuen dongah na hing ni.
6 Èmi yóò so iṣan ara mọ́ ọn yín, Èmi yóò sì mú kí ẹran-ara wá sí ara yín, Èmi yóò sì fi awọ ara bò yín, Èmi yóò sì fi èémí sínú yín, ẹ̀yin yóò sì wà ní ààyè. Nígbà náà ẹ̀yin yóò mọ̀ pé èmi ni Olúwa.’”
Nangmih soah tharhui kang khueh vetih nangmih soah pumsa ka soe sak ni. Nangmih soah na vin ka saibawn sak vetih na khuiah mueihla kam paek ni. Te daengah ni na hing uh vetih kai he BOEIPA la nan ming uh eh,” a ti.
7 Nítorí náà ni mo ṣe sọtẹ́lẹ̀ gẹ́gẹ́ bí a ti pa á láṣẹ fún mi. Bí mo sì ti ń sọtẹ́lẹ̀, ariwo wá, ìró tí ó kígbe sókè, àwọn egungun sì wà papọ̀, egungun sí egungun.
Te dongah n'uen bangla ka tonghma tih ka tonghma vanbangla ol om. Te vaengah hinghuennah tarha om. Te vaengah rhuh rhoek khaw, a rhuh te a rhuh taengla cet uh.
8 Mo wò ó, iṣan ara àti ẹran-ara farahàn lára wọn, awọ ara sì bò wọ́n, ṣùgbọ́n kò sí èémí nínú wọn.
Te vaengah ka sawt hatah a soah tharhui neh a saa tarha soe. Te so ah te a vin loh a saibawn thil dae a khuiah mueihla om pawh.
9 Lẹ́yìn náà ni ó sọ fún mi pé, “Sọtẹ́lẹ̀ sí èémí; sọtẹ́lẹ̀, ọmọ ènìyàn, kí ó sì sọ fún un pé, ‘Èyí yìí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: wá láti atẹ́gùn mẹ́rẹ̀ẹ̀rin, ìwọ èémí, kí ó sì mí èémí sínú àwọn tí a pa wọ̀nyí, kí wọn kí ó lè wà ní ààyè.’”
Te vaengah kai taengah, “Mueihla te tonghma thil, hlang capa aw tonghma lamtah, yilh te thui pah. Ka Boeipa Yahovah loh he ni a thui. Hmuen pali lamkah yilh aw ha pawk laeh. Mueihla te he a khuila a ueng daengah ni a ngawn rhoek he a hing eh,” a ti.
10 Nítorí náà, mo sọtẹ́lẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ó ṣe pa á láṣẹ fún mi, èémí sì wọ inú wọn; wọ́n di alààyè, wọ́n sì dìde dúró lórí ẹsẹ̀ wọn—pẹ̀lú ìhámọ́ra tí ó pọ̀.
Kai n'uen bangla ka tonghma tangloeng vaengah amih khuila mueihla kun. Te vaengah hing uh tih amamih kho dongah bahoeng, bahoeng tatthai tanglue la pai uh.
11 Lẹ́yìn náà ó sọ fún mi: “Ọmọ ènìyàn, àwọn egungun wọ̀nyí ni gbogbo ìdílé Israẹli. Wọ́n sọ wí pé, ‘Egungun wa ti gbẹ ìrètí wa sì ti lọ; a ti gé wa kúrò.’
Te phoeiah kai taengah, “Hlang capa aw, hekah rhuh he Israel imkhui pum coeng ni. Amih loh, ‘Kaimih rhuh he rhae tih kaimih kah ngaiuepnah paltham coeng, mamih he n'tuiphih coeng,’ a ti uh lah ko te.
12 Nítorí náà sọtẹ́lẹ̀, kí o sì sọ fun wọn pé, ‘Èyí yìí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè sọ: Ẹ̀yin ènìyàn mi, Èmi yóò ṣí àwọn ibojì yín, èmi yóò sì mú yín wá si ilẹ̀ Israẹli.
Te dongah tonghma lamtah amih te thui pah. Ka Boeipa Yahovah loh he ni a thui. Kai loh na phuel te ka ong tih ka pilnam namah kah phuel lamloh nangmih kan doek ni. Te vaengah nangmih te Israel khohmuen la kam pawk puei ni.
13 Ẹ̀yin o sì mọ̀ èmi ni Olúwa, nígbà tí èmi bá ti ṣí ibojì yín, ẹ̀yin ènìyàn mi, ti èmi bá si mú un yín dìde kúrò nínú ibojì yín.
Te vaengah kai he BOEIPA la nan ming uh bitni. Na phuel te ka ong tih ka pilnam nangmih te na phuel lamloh nangmih kan doek ni.
14 Èmi yóò fi èémí mi sínú yín, ẹ̀yin yóò sì yè, èmi yóò sì mú kí ẹ fi lélẹ̀ ní ilẹ̀ ẹ̀yin tìkára yín. Nígbà náà ẹ̀yin yóò mọ̀ pé Olúwa ti sọ̀rọ̀, èmi sì ti ṣe ni Olúwa wí.’”
Nangmih ah ka Mueihla kam paek vetih na hing uh ni. Nangmih te na khohmuen ah kang khueh vaengah BOEIPA kamah loh ka thui tih BOEIPA kah olphong ka vai te na ming uh bitni,” a ti.
15 Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mi wá:
BOEIPA ol te kai taengah ha pawk bal tih,
16 “Ọmọ ènìyàn, mú igi pátákó kan kí ó sì kọ̀wé sí ara rẹ̀, ‘Tí ó jẹ́ ti Juda àti ti Israẹli tí ó ní àṣepọ̀ pẹ̀lú rẹ̀.’ Lẹ́yìn náà, kí ó mú igi pátákò mìíràn kí ó sì kọ̀wé sí ara rẹ̀, ‘Tí ó jẹ́ ti tí Josẹfu (tí ó túmọ̀ sí ti Efraimu) àti gbogbo ilé Israẹli tí ó ni àṣepọ̀ pẹ̀lú rẹ̀.’
“Nang hlang capa aw namah ham thing pakhat lo lamtah a soah Judah ham neh Israel ca rhoek kah a hui, a hui ham daek pah. Thing pakhat te lo bal lamtah a soah Ephraim thing Joseph ham neh Israel imkhui boeih kah a hui a hui ham daek pah.
17 So wọ́n papọ̀ sí ara igi kan nítorí náà wọn yóò di ọ̀kan ní ọwọ́ rẹ.
Te rhoi te khat neh khat namah ham thing pakhat la cong lah. Na kut dongah pakhat la om bitni.
18 “Nígbà tí àwọn ara ìlú rẹ bá béèrè lọ́wọ́ rẹ pé, ‘Ṣé ìwọ kò ní sọ ohun tí èyí túmọ̀ sí fún wa?’
Te van bangla nang taengah na pilnam paca loh m'voek tih, ‘Kaimih taengah na thui mahpawt nim? Na taengkah rhoek te balae? a ti uh ni.
19 Sọ fún wọn pé, ‘Èyí yìí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: Èmi yóò gba igi Josẹfu—èyí tí ó wà ní ọwọ́ Efraimu—àti ti ẹ̀yà Israẹli tí ó parapọ̀ mọ́ ọn, kí ó sì só papọ̀ mọ́ igi Juda, láti sọ wọ́n di igi kan ṣoṣo, wọn yóò sì di ọ̀kan ní ọwọ́ mi.’
Amih te thui pah. Ka Boeipa Yahovah loh he ni a thui. Kai loh Ephraim kut kah Joseph thing neh Israel koca a hui a hui te ka loh coeng ne. Te rhoi te Judah thing neh ka khueh vetih thing pakhat la ka saii ni. Ka kut dongah pakhat la om ni.
20 Gbé igi pátákó tí ó kọ nǹkan sí i sókè ní iwájú wọn,
A soah na kut neh na daek thing rhoek te amih mikhmuh ah om saeh.
21 kí ó sì sọ fún wọn pé, ‘Èyí yìí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: Èmi yóò mú Israẹli jáde kúrò ní àwọn orílẹ̀-èdè tí wọ́n ti lọ. Èmi yóò ṣà wọ́n jọ pọ̀ láti gbogbo agbègbè, èmi yóò sì mú wọn padà sí ilẹ̀ ara wọn.
Te dongah amih te thui pah. Ka Boeipa Yahovah loh he ni a thui. Israel ca rhoek te a pongpa nah namtom lakli lamloh ka loh coeng ne. Amih te a kaepvai lamloh ka coi vetih amih te amamih khohmuen la ka pawk puei ni.
22 Èmi yóò ṣe wọ́n ní orílẹ̀-èdè kan ní ilẹ̀ náà, ní orí òkè Israẹli, ọba kan ni yóò wà lórí gbogbo wọn, wọn kì yóò sì jẹ́ orílẹ̀-èdè méjì mọ́, tàbí kí a pín wọn sí ìjọba méjì.
Amih te Israel tlang kah khohmuen ah namtu pakhat la ka khueh ni. Manghai pakhat te amih boeih soah manghai la om ni. Namtu te panit la koep om rhoe om mahpawh. Ram te panit la koep koep boel uh mahpawh.
23 Wọn kì yóò sì tún fi àwọn òrìṣà wọn ba ara wọn jẹ́ mọ́, tàbí ohun ìríra wọn, tàbí ohun ìrékọjá wọn: ṣùgbọ́n èmi yóò gbà wọn là kúrò nínú gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ àgàbàgebè wọn, èmi yóò sì wẹ̀ wọn mọ́. Wọn yóò jẹ́ ènìyàn mi, Èmi yóò sì jẹ́ Ọlọ́run wọn.
A mueirhol neh, a sarhingkoi neh, a boekoek boeih neh koep poeih uh mahpawh. Amih te a tolrhum cungkuem lamloh ka khang ni. Te nen te tholh uh cakhaw amih te ka caihcil ni. Kamah taengah pilnam la om uh vetih kai khaw amih taengah Pathen la ka om ni.
24 “‘Dafidi ìránṣẹ́ mi ni yóò jẹ ọba lórí wọn, gbogbo wọn yóò sì ní olùṣọ àgùntàn kan. Wọn yóò sì tẹ̀lé òfin mi, wọn yóò sì ṣe àníyàn láti pa àṣẹ mi mọ́.
Ka sal David tah amih soah manghai tih amih boeih aka dawn te pakhat ni a om eh. Te vaengah ka laitloeknah dongah pongpa uh vetih ka khosing te ngaithuen neh a saii uh ni.
25 Wọn yóò gbé ní ilẹ̀ tí mo fún Jakọbu ìránṣẹ́ mi, ilẹ̀ tí àwọn baba yín ń gbé. Àwọn àti àwọn ọmọ wọn àti àwọn ọmọ ọmọ wọn ni yóò máa gbé ibẹ̀ láéláé, ìránṣẹ́ mi Dafidi ni yóò jẹ́ Ọmọ-aládé wọn láéláé.
Ka sal Jakob taengah ka paek khohmuen ah kho a sak uh ni. Te ah te ni na pa rhoek loh kho a sak uh. A khuiah amih neh a ca rhoek khaw, a ca rhoek kah ca rhoek khaw kumhal duela kho a sak ni. Ka sal David amih kah kumhal khoboei la om ni.
26 Èmi yóò dá májẹ̀mú àlàáfíà pẹ̀lú wọn, yóò sì jẹ́ májẹ̀mú títí ayérayé. Èmi yóò gbé wọn kalẹ̀, èmi yóò sì sọ wọ́n di púpọ̀ ní iye, èmi yóò sì gbé ilé mímọ́ mi kalẹ̀ ní àárín wọn títí láé.
Amih neh rhoepnah paipi ka saii vetih amih taengah kumhal kah paipi la om ni. Amih te ka khueh tih ka ping sak phoeiah ka rhokso te kumhal due amih lakli ah ka khueh ni.
27 Ibùgbé mí yóò wà pẹ̀lú wọn, Èmi yóò jẹ́ Ọlọ́run wọn, wọn yóò sì jẹ́ ènìyàn mi.
Ka dungtlungim tah amih neh om ni. Amih taengah Pathen la ka om vetih amih khaw kamah taengah pilnam la om uh ni.
28 Nígbà náà ni àwọn orílẹ̀-èdè yóò mọ̀ pé, Èmi Olúwa sọ Israẹli di mímọ́, nígbà tí ibi mímọ́ mi bá wà ní àárín wọn títí ayérayé.’”
Te vaengah namtom loh kai he BOEIPA la a ming uh ni. Israel te ka ciim phoeiah tah ka rhokso he amih lakli ah ni kumhal due a om eh,” a ti.

< Ezekiel 37 >