< Ezekiel 36 >
1 “Ọmọ ènìyàn, sọtẹ́lẹ̀ sí àwọn òkè gíga Israẹli kí o sì wí pé, ‘Ẹ̀yin òkè gíga Israẹli gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa.
Ту, фиул омулуй, пророчеште асупра мунцилор луй Исраел ши спуне: ‘Мунць ай луй Исраел, аскултаць кувынтул Домнулуй!
2 Èyí yìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Àwọn ọ̀tá sọ nípa yín pé, “Háà! Àwọn ibi gíga ìgbàanì ti di ohun ìní wa.”’
Аша ворбеште Домнул Думнезеу: «Пентру кэ врэжмашул а зис деспре вой: ‹Ха! Ха! Ачесте ынэлцимь вешниче ау ажунс моштениря ноастрэ!›»’,
3 Nítorí náà, sọtẹ́lẹ̀ kí ó sì wí pé, ‘Èyí yìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Nítorí pé wọn sọ ọ di ahoro, tí wọn sì ń dọdẹ rẹ ní gbogbo ọ̀nà kí ìwọ kí ó lè di ìní fún àwọn orílẹ̀-èdè tí ó kù, àti ohun ti àwọn ènìyàn ń sọ ọ̀rọ̀ ìríra àti ìdíbàjẹ́ sí,
пророчеште ши зи: ‘Аша ворбеште Домнул Думнезеу: «Да, пентру кэ дин тоате пэрциле ау воит сэ вэ пустияскэ ши сэ вэ ынгитэ, ка сэ ажунӂець моштениря алтор нямурь, ши пентру кэ аць фост де батжокура ши де окара попоарелор,
4 nítorí náà, ẹ̀yin òkè gíga Israẹli gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa Olódùmarè, èyí yìí ní Olúwa Olódùmarè wí fún àwọn òkè gíga àti àwọn òkè kéékèèké, fún àfonífojì ńlá àti àfonífojì kéékèèké, fún àwọn ibi ìsọdahoro ìparun àti fún àwọn ìlú tí a ti kọ̀sílẹ̀ tí a ti kó tí àwọn orílẹ̀-èdè tí ó kù ní àyíká sì fi ṣe ẹlẹ́yà,
де ачея, мунць ай луй Исраел, аскултаць кувынтул Домнулуй Думнезеу! Аша ворбеште Домнул Думнезеул мунцилор ши дялурилор, рыурилор ши вэилор, дэрымэтурилор пустий ши четэцилор пэрэсите, каре ау ажунс де прада ши де рысул челорлалте нямурь димпрежур,
5 èyí yìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Ní ìgbóná ọkàn ní mo sọ̀rọ̀ sí àwọn kèfèrí yòókù, àti sí Edomu, nítorí pẹ̀lú ìbínú àti ìjowú ní ọkàn wọn ni wọ́n sọ ilé mi di ohun ìní wọn, kí wọn kí o lè kó pápá oko tútù rẹ̀.’
аша ворбеште Домнул Думнезеу: ‹Да, ын фокул ӂелозией Меле, ворбеск ымпотрива челорлалте нямурь ши ымпотрива ынтрегулуй Едом, каре шь-ау ынсушит цара Мя ши с-ау букурат дин тоатэ инима лор ши ку тот диспрецул суфлетулуй лор, ка сэ-й жефуяскэ роаделе.›»’
6 Nítorí náà, sọtẹ́lẹ̀ nípa ilẹ̀ Israẹli náà kí o sì sọ sí àwọn òkè gíga náà àti àwọn òkè kéékèèké, sí àwọn àfonífojì ńlá àti sí àwọn àfonífojì kéékèèké, ‘Èyí yìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Èmi sọ̀rọ̀ nínú ìrunú owú mi nítorí pé ìwọ ti jìyà ìfiṣẹ̀sín àwọn orílẹ̀-èdè.
Де ачея, пророчеште деспре цара луй Исраел ши спуне мунцилор ши дялурилор, рыурилор ши вэилор: ‘Аша ворбеште Домнул Думнезеу: «Ятэ, ворбеск ын ӂелозия ши урӂия Мя, пентру кэ суфериць окарэ дин партя нямурилор!»
7 Nítorí náà, èyí yìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Èmi ṣe ìbúra nípa nína ọwọ́ mi sókè pé; àwọn orílẹ̀-èdè àyíká rẹ náà yóò jìyà ìfiṣẹ̀sín.
Де ачея, аша ворбеште Домнул Думнезеу: «Ымь ридик мына ши жур кэ нямуриле каре вэ ынконжоарэ ышь вор пурта еле ынселе окара!
8 “‘Ṣùgbọ́n ìwọ, òkè gíga Israẹli, yóò mú ẹ̀ka àti èso fún àwọn ènìyàn mi Israẹli, nítorí wọn yóò wá sílé ní àìpẹ́ yìí.
Яр вой, мунць ай луй Исраел, вець да кренӂь ши вэ вець пурта роаделе пентру попорул Меу Исраел, кэч лукруриле ачестя сунт апроапе сэ се ынтымпле.
9 Èmi ń ṣe àníyàn fún ọ, èmi yóò sì fi rere wọ̀ ọ́; àwa yóò tu ọ́, àwa yóò sì gbìn ọ́,
Ятэ кэ вой фи биневоитор, Мэ вой ынтоарче спре вой ши вець фи лукраць ши семэнаць.
10 èmi yóò sì sọ iye àwọn ènìyàn di púpọ̀ nínú rẹ àti gbogbo ilé Israẹli. Àwọn ìlú yóò di ibùgbé, a yóò sì tún àwọn ibi ìparun kọ́.
Вой пуне сэ локуяскэ пе вой оамень ын маре нумэр, тоатэ каса луй Исраел, пе тоць! Четэциле вор фи локуите ши се вор зиди ярэшь дэрымэтуриле.
11 Èmi yóò sọ iye ènìyàn àti ẹran dì púpọ̀ nínú yín, wọn yóò sì so èso, wọn yóò sì di púpọ̀ yanturu. Èmi yóò mú kí àwọn ènìyàn máa gbé nínú rẹ bí ti àtẹ̀yìnwá, èmi yóò sì mú kí o ṣe rere ju ìgbà àtijọ́ lọ. Nígbà náà ni ìwọ yóò mọ pé èmi ni Olúwa.
Вой ынмулци пе вой оамений ши вителе каре вор креште ши се вор ынмулци; вой фаче сэ фиць локуиць ка ши май ынаинте ши вэ вой фаче май мулт бине декыт одиниоарэ ши вець шти кэ Еу сунт Домнул.
12 Èmi yóò mú kí àwọn ènìyàn, àní àwọn ènìyàn Israẹli, rìn lórí rẹ̀. Wọn yóò gbà ọ́, ìwọ yóò sì di ogún ìní wọn; ìwọ kì yóò sì gba àwọn ọmọ wọn lọ́wọ́ wọn mọ́.
Вой фаче сэ умбле пе вой оамень, ши ануме попорул Меу Исраел; ей те вор стэпыни ши ту вей фи моштениря лор ши ну-й вей май нимичи.»
13 “‘Èyí yìí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: Nítorí pé àwọn ènìyàn sọ fún ọ pé, “Ìwọ pa àwọn ènìyàn run, ìwọ sì gba àwọn ọmọ orílẹ̀-èdè lọ́wọ́ wọn,”
Аша ворбеште Домнул Думнезеу: «Пентру кэ ци се зиче: ‹Ту, царэ, ай мынкат оамень, ць-ай нимичит кяр ши нямул тэу›,
14 nítorí náà ìwọ kì yóò pa àwọn ènìyàn run tàbí mú kì orílẹ̀-èdè di aláìlọ́mọ mọ́, ni Olúwa Olódùmarè wí.
дин причина ачаста де акум ынколо ну вей май мынка оамень ши ну-ць вей май нимичи нямул», зиче Домнул Думнезеу.
15 Èmi kì yóò mú ki ó gbọ́ ọ̀rọ̀ ẹ̀gàn láti ọ̀dọ̀ àwọn orílẹ̀-èdè mọ́, ìwọ kì yóò jìyà ọ̀rọ̀ ìfiṣẹ̀sín láti ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn tàbí mú kí orílẹ̀-èdè rẹ ṣubú, ni Olúwa Olódùmarè wí.’”
«Де акум, ну те вой май фаче сэ аузь батжокуриле нямурилор ши ну вей май пурта окара попоарелор; ну-ць вей май нимичи нямул», зиче Домнул Думнезеу.’”
16 Síwájú sí i ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá:
Кувынтул Домнулуй мь-а ворбит астфел:
17 “Ọmọ ènìyàn, nígbà tí àwọn ènìyàn Israẹli ń gbé ní ilẹ̀ wọn, wọ́n bà á jẹ́ nípa ìwà àti ìṣe wọn. Ìwà wọn dàbí nǹkan àkókò àwọn obìnrin ni ojú mi.
„Фиул омулуй, чей дин каса луй Исраел, кынд локуяу ын цара лор, ау спуркат-о прин пуртаря лор ши прин фаптеле лор; аша кэ пуртаря лор а фост ынаинтя Мя ка спуркэчуня уней фемей ын тимпул некурэцией ей.
18 Nítorí náà mo tú ìbínú mi jáde sórí wọn nítorí wọn ti ta ẹ̀jẹ̀ sílẹ̀ àti nítorí pé wọ́n ti fi ère wọn ba a jẹ́.
Атунч Мь-ам вэрсат урӂия песте ей дин причина сынӂелуй пе каре-л вэрсасерэ ын царэ ши дин причина идолилор ку каре о спуркасерэ.
19 Mo tú wọn ká sí àárín àwọn orílẹ̀-èdè, a sì fọ́n wọn ká sí àwọn ìlú; mo ṣe ìdájọ́ wọn gẹ́gẹ́ bí ìwà àti ìṣe wọn.
Й-ам рисипит принтре нямурь ши ау фост ымпрэштияць ын фелурите цэрь; й-ам жудекат дупэ пуртаря ши фаптеле лор реле.
20 Gbogbo ibi tí wọ́n lọ ní àárín àwọn orílẹ̀-èdè ni wọn ti sọ orúkọ mímọ́ mi di aláìmọ́, nítorí tí a sọ nípa wọn pé, ‘Ìwọ̀nyí ni àwọn ènìyàn Olúwa, síbẹ̀ wọn ní láti fi ilẹ̀ náà sílẹ̀.’
Кынд ау венит принтре нямурь, орьынкотро се дучяу, пынгэряу Нумеле Меу чел сфынт, аша ынкыт се зичя деспре ей: ‘Ачеста есте попорул Домнулуй, ей ау требуит сэ ясэ дин цара лор.’
21 Orúkọ mímọ́ mi jẹ́ mi lógún, èyí tí ilé Israẹli sọ di aláìmọ́ ni àárín àwọn orílẹ̀-èdè tí wọ́n ti lọ.
Ши ам врут сэ скап чинстя Нумелуй Меу челуй сфынт, пе каре-л пынгэря каса луй Исраел принтре нямуриле ла каре се дусесе.
22 “Nítorí náà, sọ fún ilé Israẹli, ‘Èyí ni Olúwa Olódùmarè wí: Kì í ṣe nítorí rẹ, ìwọ ilé Israẹli, ni èmi yóò ṣe ṣe àwọn nǹkan wọ̀nyí, ṣùgbọ́n nítorí orúkọ mímọ́ mi, èyí ti ìwọ ti sọ di aláìmọ́ ní àárín àwọn orílẹ̀-èdè tí ìwọ ti lọ.
Де ачея, спуне касей луй Исраел: ‘Аша ворбеште Домнул Думнезеу: «Ну дин причина воастрэ фак ачесте лукрурь, каса луй Исраел, чи дин причина Нумелуй Меу челуй сфынт, пе каре л-аць пынгэрит принтре нямуриле ла каре аць мерс.
23 Èmi yóò fi jíjẹ́ mímọ́ orúkọ ńlá mi, èyí tí a ti sọ di aláìmọ́ hàn ni àárín àwọn orílẹ̀-èdè, orúkọ tí ìwọ ti sọ di aláìmọ́ ni àárín wọn. Nígbà náà àwọn orílẹ̀-èdè yóò mọ̀ pé èmi ni Olúwa, ni Olúwa Olódùmarè wí, nígbà tí mo bá fi ara mi hàn ni mímọ́ nípasẹ̀ yín ni iwájú wọn.
Де ачея вой сфинци Нумеле Меу чел маре, каре а фост пынгэрит принтре нямурь, пе каре л-аць пынгэрит ын мижлокул лор. Ши нямуриле вор куноаште кэ Еу сунт Домнул», зиче Домнул Думнезеу, «кынд вой фи сфинцит ын вой суб окий лор.
24 “‘Nítorí èmi yóò mú yín jáde kúrò ni àwọn orílẹ̀-èdè náà; Èmi yóò ṣà yín jọ kúrò ní gbogbo àwọn ìlú náà; Èmi yóò sì mú yín padà sí ilẹ̀ ẹ̀yin tìkára yín.
Кэч вэ вой скоате динтре нямурь, вэ вой стрынӂе дин тоате цэриле ши вэ вой адуче ярэшь ын цара воастрэ.
25 Èmi yóò wọ́n omi tó mọ́ sí yín lára ẹ̀yin yóò sì mọ́; Èmi yóò sì fọ̀ yín mọ́ kúrò nínú gbogbo ìwà èérí yin gbogbo àti kúrò nínú gbogbo òrìṣà yin.
Вэ вой стропи ку апэ куратэ ши вець фи курэциць; вэ вой курэци де тоате спуркэчуниле воастре ши де тоць идолий воштри.
26 Èmi yóò fún yín ni ọkàn tuntun, èmi yóò sì fi ẹ̀mí tuntun sínú yín; Èmi yóò sì mú ọkàn òkúta kúrò nínú yín, èmi yóò sì fi ọkàn ẹran fún yín.
Вэ вой да о инимэ ноуэ ши вой пуне ын вой ун дух ноу; вой скоате дин трупул востру инима де пятрэ ши вэ вой да о инимэ де карне.
27 Èmi yóò fi ẹ̀mí mi sínú yín, èmi yóò sì mú ki ẹ tẹ̀lé àṣẹ mi, kí ẹ sì fiyèsí àti pa òfin mi mọ́.
Вой пуне Духул Меу ын вой ши вэ вой фаче сэ урмаць порунчиле Меле ши сэ пэзиць ши сэ ымплиниць леӂиле Меле.
28 Ẹ̀yin yóò sì máa gbé ilẹ̀ náà tí mo ti fi fún àwọn baba ńlá yín; ẹ̀yin yóò sì jẹ́ ènìyàn mi èmi yóò sì jẹ́ Ọlọ́run yín.
Вець локуи ын цара пе каре ам дат-о пэринцилор воштри; вой вець фи попорул Меу ши Еу вой фи Думнезеул востру.
29 Èmi yóò sì gbà yín kúrò nínú gbogbo ìwà àìmọ́ yín. Èmi yóò pèsè ọkà, èmi yóò sì mú kí ó pọ̀ yanturu, èmi kì yóò sì mú ìyàn wá sí orí yín.
Вэ вой избэви де тоате некурэцииле воастре. Вой кема грыул ши-л вой ынмулци; ну вой май тримите фоаметя песте вой.
30 Èmi yóò sọ èso àwọn igi yín àti ohun ọ̀gbìn oko yín di púpọ̀, nítorí kí ẹ̀yin kí ó má ṣe jìyà ìdójútì mọ́ láàrín àwọn orílẹ̀-èdè náà nítorí ìyàn.
Вой ынмулци родул помилор ши венитул кымпулуй, ка сэ ну май пуртаць окара фоаметей принтре нямурь.
31 Nígbà náà ni ẹ̀yin yóò rántí àwọn ọ̀nà búburú àti àwọn ìwà ìkà yín, ẹ̀yin yóò sì kórìíra ara yín fún ẹ̀ṣẹ̀ yín, ìwà tí kò bójúmu.
Атунч вэ вець адуче аминте де пуртаря воастрэ чя ря ши де фаптеле воастре каре ну ерау буне; вэ ва фи скырбэ де вой ыншивэ дин причина нелеӂюирилор ши урычунилор воастре.
32 Mo fẹ́ kí ẹ mọ̀ pé ń kò ṣe nǹkan wọ̀nyí nítorí yín, ni Olúwa Olódùmarè wí. Jẹ kí ojú kí ó tì yín, kí ẹ sì gba ẹ̀tẹ́ nítorí ìwà yín ẹ̀yin ilé Israẹli!
Ши тоате ачесте лукрурь ну ле фак дин причина воастрэ», зиче Домнул Думнезеу, «сэ штиць! Рушинаци-вэ ши рошиць де пуртаря воастрэ, каса луй Исраел!»
33 “‘Èyí yìí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: Ní ọjọ́ tí mo wẹ̀ yín kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ yín gbogbo, èmi yóò ṣe àtúnṣe àwọn ìlú yín, wọn yóò sì ṣe àtúnkọ́ ìwólulẹ̀.
Аша ворбеште Домнул Думнезеу: «Ын зиуа кынд вэ вой курэци де тоате нелеӂюириле воастре, вой фаче ка четэциле воастре сэ фие локуите ши дэрымэтуриле вор фи зидите дин ноу;
34 Ilẹ̀ ahoro náà ní àwa yóò tún kọ́ ti kì yóò wà ní ahoro lójú àwọn tí ó ń gba ibẹ̀ kọjá mọ́.
цара пустиитэ ва фи лукратэ ярэшь, де унде пынэ аич ера пустие ын окий тутурор трекэторилор.
35 Wọn yóò sọ wí pé, “Ilẹ̀ yìí tí ó ti wà ní ahoro tẹ́lẹ̀ ti dàbí ọgbà Edeni; àwọn ìlú tí ó wà ní wíwó lulẹ̀, ahoro tí a ti parun, ni àwa yóò mọdi sí tí yóò sì wà fún gbígbé ni ìsinsin yìí.”
Ши се ва спуне атунч: ‹Цара ачаста пустиитэ а ажунс ка о грэдинэ а Еденулуй ши четэциле ачестя дэрымате, каре ерау пустий ши сурпате, сунт ынтэрите ши локуите!›
36 Nígbà náà àwọn orílẹ̀-èdè tí ó wà ní àyíká yín tí ó kù yóò mọ̀ pé, Èmi Olúwa ti tún àwọn ohun tí ó bàjẹ́ kọ́, mo sì ti tún ohun tí ó di ìṣòfo gbìn. Èmi Olúwa ti sọ̀rọ̀, èmi yóò sì ṣe e?’
Ши нямуриле каре вор май рэмыне ын журул востру вор шти кэ Еу, Домнул, ам зидит дин ноу че ера сурпат ши ам сэдит че ера пустиит. Еу, Домнул, ам ворбит ши вой ши фаче.»
37 “Èyí yìí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè sọ: Lẹ́ẹ̀kan sí i èmi yóò yí sí ilé Israẹli, èmi yóò sì ṣe èyí fún wọn. Èmi yóò mú kí àwọn ènìyàn yín pọ̀ lọ́pọ̀lọ́pọ̀ bí àgùntàn,
Аша ворбеште Домнул Думнезеу: «Ятэ ын че привинцэ Мэ вой лэса ындуплекат де каса луй Исраел ши ятэ че вой фаче пентру ей: вой ынмулци пе оамень ка пе о турмэ де ой.
38 kí ó pọ̀ lọ́pọ̀lọ́pọ̀ bí ọ̀wọ́ ẹran fún ìrúbọ ní Jerusalẹmu ní àsìkò àjọ̀dún tí a yàn. Ìlú ti a parun yóò wá kún fún agbo àwọn ènìyàn. Nígbà náà ni wọn yóò mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.”
Четэциле дэрымате се вор умпле ку турме де оамень, ка турмеле ынкинате Домнулуй, ку турме каре сунт адусе ла Иерусалим ын тимпул сэрбэторилор челор марь. Ши вор шти кэ Еу сунт Домнул.»’”