< Ezekiel 36 >

1 “Ọmọ ènìyàn, sọtẹ́lẹ̀ sí àwọn òkè gíga Israẹli kí o sì wí pé, ‘Ẹ̀yin òkè gíga Israẹli gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa.
A ty synu człowieczy! prorokuj o górach Izraelskich, a mów: Góry Izraelskie! słuchajcie słowa Pańskiego;
2 Èyí yìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Àwọn ọ̀tá sọ nípa yín pé, “Háà! Àwọn ibi gíga ìgbàanì ti di ohun ìní wa.”’
Tak mówi panujący Pan: Przeto, iż nieprzyjaciel rzekł o was: Hej, hej! i wysokości wieczne dostały się nam w dziedzictwo;
3 Nítorí náà, sọtẹ́lẹ̀ kí ó sì wí pé, ‘Èyí yìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Nítorí pé wọn sọ ọ di ahoro, tí wọn sì ń dọdẹ rẹ ní gbogbo ọ̀nà kí ìwọ kí ó lè di ìní fún àwọn orílẹ̀-èdè tí ó kù, àti ohun ti àwọn ènìyàn ń sọ ọ̀rọ̀ ìríra àti ìdíbàjẹ́ sí,
Przetoż prorokuj a mów: Tak mówi panujący Pan: Dlatego, dlatego, mówię, iż was zburzyli, a pochłonęli zewsząd, i staliście się dziedzictwem pozostałym narodom, i przyszliście na język i na obmowisko ludzkie;
4 nítorí náà, ẹ̀yin òkè gíga Israẹli gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa Olódùmarè, èyí yìí ní Olúwa Olódùmarè wí fún àwọn òkè gíga àti àwọn òkè kéékèèké, fún àfonífojì ńlá àti àfonífojì kéékèèké, fún àwọn ibi ìsọdahoro ìparun àti fún àwọn ìlú tí a ti kọ̀sílẹ̀ tí a ti kó tí àwọn orílẹ̀-èdè tí ó kù ní àyíká sì fi ṣe ẹlẹ́yà,
Przetoż, góry Izraelskie! słuchajcie słowa panującego Pana. Tak mówi panujący Pan górom i pagórkom, strumieniom i dolinom, pustyniom, obalinom, i miastom opuszczonym, które są na splundrowanie, i na pośmiewisko ostatkowi narodów okolicznych.
5 èyí yìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Ní ìgbóná ọkàn ní mo sọ̀rọ̀ sí àwọn kèfèrí yòókù, àti sí Edomu, nítorí pẹ̀lú ìbínú àti ìjowú ní ọkàn wọn ni wọ́n sọ ilé mi di ohun ìní wọn, kí wọn kí o lè kó pápá oko tútù rẹ̀.’
Dlatego, tak mówi panujący Pan, zaprawdę w ogniu zapalczywości mojej mówić będę przeciw ostatkom tych narodów, i przeciwko wszystkiej ziemi Edomskiej, którzy sobie przywłaszczyli ziemię moję za dziedzictwo z weselem całego serca, i z ochotnem pust oszeniem, aby siedlisko wygnanych jego było na rozszarpanie,
6 Nítorí náà, sọtẹ́lẹ̀ nípa ilẹ̀ Israẹli náà kí o sì sọ sí àwọn òkè gíga náà àti àwọn òkè kéékèèké, sí àwọn àfonífojì ńlá àti sí àwọn àfonífojì kéékèèké, ‘Èyí yìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Èmi sọ̀rọ̀ nínú ìrunú owú mi nítorí pé ìwọ ti jìyà ìfiṣẹ̀sín àwọn orílẹ̀-èdè.
Przetoż prorokuj o ziemi Izrelskiej, a mów górom, i pagórkom, strumieniom i dolinom: Tak mówi panujący Pan: Oto Ja w zapalczywości mojej, i w popędliwości mojej mówię, dlatego, iż hańbę od narodów ponosicie.
7 Nítorí náà, èyí yìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Èmi ṣe ìbúra nípa nína ọwọ́ mi sókè pé; àwọn orílẹ̀-èdè àyíká rẹ náà yóò jìyà ìfiṣẹ̀sín.
Przetoż tak mówi panujący Pan: Jam podniósł rękę moję, iż te narody, które są zewsząd około was, sami hańbę swoję poniosą.
8 “‘Ṣùgbọ́n ìwọ, òkè gíga Israẹli, yóò mú ẹ̀ka àti èso fún àwọn ènìyàn mi Israẹli, nítorí wọn yóò wá sílé ní àìpẹ́ yìí.
A wy, góry Izraelskie! wypuście gałązki swe, i owoc swój przynieście ludowi memu Izraelskiemu, gdy się przybliżą a przyjdą.
9 Èmi ń ṣe àníyàn fún ọ, èmi yóò sì fi rere wọ̀ ọ́; àwa yóò tu ọ́, àwa yóò sì gbìn ọ́,
Bo oto Ja idę do was, i nawrócę się do was, a uprawiane i posiewane będziecie;
10 èmi yóò sì sọ iye àwọn ènìyàn di púpọ̀ nínú rẹ àti gbogbo ilé Israẹli. Àwọn ìlú yóò di ibùgbé, a yóò sì tún àwọn ibi ìparun kọ́.
I rozmnożę na was ludzi, wszystek zgoła dom Izarelski; i będą mieszkać w miastach, a miejsca zburzone pobudowane będą.
11 Èmi yóò sọ iye ènìyàn àti ẹran dì púpọ̀ nínú yín, wọn yóò sì so èso, wọn yóò sì di púpọ̀ yanturu. Èmi yóò mú kí àwọn ènìyàn máa gbé nínú rẹ bí ti àtẹ̀yìnwá, èmi yóò sì mú kí o ṣe rere ju ìgbà àtijọ́ lọ. Nígbà náà ni ìwọ yóò mọ pé èmi ni Olúwa.
Rozmnożę, mówię, na was ludzi i dobytek, a rozmnożą się i urosną; i sprawię, że mieszkać będziecie jako za dawnych czasów waszych, i lepiej wam czynić będę niż przedtem, i dowiecie się, żem Ja Pan.
12 Èmi yóò mú kí àwọn ènìyàn, àní àwọn ènìyàn Israẹli, rìn lórí rẹ̀. Wọn yóò gbà ọ́, ìwọ yóò sì di ogún ìní wọn; ìwọ kì yóò sì gba àwọn ọmọ wọn lọ́wọ́ wọn mọ́.
Bo przyprowadzę na was ludzi, lud mój Izraelski, i posiądą cię, i będziesz im dziedzictwem, a więcej ich nie osierocisz.
13 “‘Èyí yìí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: Nítorí pé àwọn ènìyàn sọ fún ọ pé, “Ìwọ pa àwọn ènìyàn run, ìwọ sì gba àwọn ọmọ orílẹ̀-èdè lọ́wọ́ wọn,”
Tak mówi panujący Pan: Dlatego, że o was powiadają: Tyś jest ta ziemia, która pożerasz ludzi, i osieracasz narody twoje;
14 nítorí náà ìwọ kì yóò pa àwọn ènìyàn run tàbí mú kì orílẹ̀-èdè di aláìlọ́mọ mọ́, ni Olúwa Olódùmarè wí.
Przetoż nie będziesz więcej ludzi pożerała, ani narodów twoich więcej osieracała, mówi panujący Pan.
15 Èmi kì yóò mú ki ó gbọ́ ọ̀rọ̀ ẹ̀gàn láti ọ̀dọ̀ àwọn orílẹ̀-èdè mọ́, ìwọ kì yóò jìyà ọ̀rọ̀ ìfiṣẹ̀sín láti ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn tàbí mú kí orílẹ̀-èdè rẹ ṣubú, ni Olúwa Olódùmarè wí.’”
I nie dopuszczę w tobie więcej słyszeć hańby narodów, ani zelżywości ludzkiej nie poniesiesz więcej, i narodów twoich nie przywiedziesz więcej do upadku, mówi panujący Pan.
16 Síwájú sí i ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá:
I stało się słowo Pańskie do mnie, mówiąc:
17 “Ọmọ ènìyàn, nígbà tí àwọn ènìyàn Israẹli ń gbé ní ilẹ̀ wọn, wọ́n bà á jẹ́ nípa ìwà àti ìṣe wọn. Ìwà wọn dàbí nǹkan àkókò àwọn obìnrin ni ojú mi.
Synu człowieczy! dom Izrelski mieszkając w ziemi swej splugawiał ją drogami swemi i sprawami swemi, tak, że droga ich przed obliczem mojem była jako nieczystość niewiasty odłączonej.
18 Nítorí náà mo tú ìbínú mi jáde sórí wọn nítorí wọn ti ta ẹ̀jẹ̀ sílẹ̀ àti nítorí pé wọ́n ti fi ère wọn ba a jẹ́.
Przetoż wylałem gniew mój na nich dla krwi, którą wylali na ziemię, i dla plugawych bałwanów ich, któremi ją splugawili.
19 Mo tú wọn ká sí àárín àwọn orílẹ̀-èdè, a sì fọ́n wọn ká sí àwọn ìlú; mo ṣe ìdájọ́ wọn gẹ́gẹ́ bí ìwà àti ìṣe wọn.
I rozproszyłem ich między narody, a rozwiani są po ziemiach; według dróg ich i według spraw ich sądziłem ich.
20 Gbogbo ibi tí wọ́n lọ ní àárín àwọn orílẹ̀-èdè ni wọn ti sọ orúkọ mímọ́ mi di aláìmọ́, nítorí tí a sọ nípa wọn pé, ‘Ìwọ̀nyí ni àwọn ènìyàn Olúwa, síbẹ̀ wọn ní láti fi ilẹ̀ náà sílẹ̀.’
A gdy weszli do narodów, do których przyszli, pomazali tam imię świątobliwości mojej, gdy o nich mówiono: Lud to Pański, a z ziemi jego wyszli.
21 Orúkọ mímọ́ mi jẹ́ mi lógún, èyí tí ilé Israẹli sọ di aláìmọ́ ni àárín àwọn orílẹ̀-èdè tí wọ́n ti lọ.
Alem im sfolgował dla imienia świętobliwości mojej, które splugawił dom Izraelski między narodami, do których przyszli;
22 “Nítorí náà, sọ fún ilé Israẹli, ‘Èyí ni Olúwa Olódùmarè wí: Kì í ṣe nítorí rẹ, ìwọ ilé Israẹli, ni èmi yóò ṣe ṣe àwọn nǹkan wọ̀nyí, ṣùgbọ́n nítorí orúkọ mímọ́ mi, èyí ti ìwọ ti sọ di aláìmọ́ ní àárín àwọn orílẹ̀-èdè tí ìwọ ti lọ.
Przetoż mów do domu Izraelskiego: Tak mówi panujący Pan: Nie dla was Ja to czynię, o domie Izraelski! ale dla imienia świętobliwości mojej, któreście splugawili między narodami, do którycheście przyszli;
23 Èmi yóò fi jíjẹ́ mímọ́ orúkọ ńlá mi, èyí tí a ti sọ di aláìmọ́ hàn ni àárín àwọn orílẹ̀-èdè, orúkọ tí ìwọ ti sọ di aláìmọ́ ni àárín wọn. Nígbà náà àwọn orílẹ̀-èdè yóò mọ̀ pé èmi ni Olúwa, ni Olúwa Olódùmarè wí, nígbà tí mo bá fi ara mi hàn ni mímọ́ nípasẹ̀ yín ni iwájú wọn.
Abym poświęcił wielkie imię moje, które było splugawione między narodami, któreście wy zmazali w pośrodku ich; i dowiedzą się narody, żem Ja Pan, mówi panujący Pan, gdy poświęcony będę w was przed oczyma ich;
24 “‘Nítorí èmi yóò mú yín jáde kúrò ni àwọn orílẹ̀-èdè náà; Èmi yóò ṣà yín jọ kúrò ní gbogbo àwọn ìlú náà; Èmi yóò sì mú yín padà sí ilẹ̀ ẹ̀yin tìkára yín.
Bo was zbiorę z narodów, i zgromadzę was ze wszystkich ziem, i przywiodę was do ziemi waszej;
25 Èmi yóò wọ́n omi tó mọ́ sí yín lára ẹ̀yin yóò sì mọ́; Èmi yóò sì fọ̀ yín mọ́ kúrò nínú gbogbo ìwà èérí yin gbogbo àti kúrò nínú gbogbo òrìṣà yin.
I pokropię was wodą czystą, a oczyszczeni będziecie od wszystkich nieczystót waszych, i od wszystkich plugawych bałwanów waszych oczyszczę was;
26 Èmi yóò fún yín ni ọkàn tuntun, èmi yóò sì fi ẹ̀mí tuntun sínú yín; Èmi yóò sì mú ọkàn òkúta kúrò nínú yín, èmi yóò sì fi ọkàn ẹran fún yín.
I dam wam serce nowe, a ducha nowego dam do wnętrzności waszych, i odejmę serce kamienne z ciała waszego, a dam wam serce mięsiste.
27 Èmi yóò fi ẹ̀mí mi sínú yín, èmi yóò sì mú ki ẹ tẹ̀lé àṣẹ mi, kí ẹ sì fiyèsí àti pa òfin mi mọ́.
Ducha mego, mówię, dam do wnętrzności waszej, a uczynię, że w ustawach moich chodzić, a sądów moich przestrzegać, i czynić je będziecie.
28 Ẹ̀yin yóò sì máa gbé ilẹ̀ náà tí mo ti fi fún àwọn baba ńlá yín; ẹ̀yin yóò sì jẹ́ ènìyàn mi èmi yóò sì jẹ́ Ọlọ́run yín.
A będziecie mieszkać w ziemi, którąm dał ojcom waszym, i będziecie ludem moim, a Ja będę Bogiem waszym.
29 Èmi yóò sì gbà yín kúrò nínú gbogbo ìwà àìmọ́ yín. Èmi yóò pèsè ọkà, èmi yóò sì mú kí ó pọ̀ yanturu, èmi kì yóò sì mú ìyàn wá sí orí yín.
Bo was wyzwolę od wszystkich nieczystót waszych, i przywołam zboża, i rozmnożę je, a nie dopuszczę na was głodu.
30 Èmi yóò sọ èso àwọn igi yín àti ohun ọ̀gbìn oko yín di púpọ̀, nítorí kí ẹ̀yin kí ó má ṣe jìyà ìdójútì mọ́ láàrín àwọn orílẹ̀-èdè náà nítorí ìyàn.
Rozmnożę też owoc drzew, i urodzaje polne, abyście więcej nie nosili hańby głodu między narodami.
31 Nígbà náà ni ẹ̀yin yóò rántí àwọn ọ̀nà búburú àti àwọn ìwà ìkà yín, ẹ̀yin yóò sì kórìíra ara yín fún ẹ̀ṣẹ̀ yín, ìwà tí kò bójúmu.
I wspomnicie na złe drogi wasze, i na sprawy wasze, które nie były dobre, i omierzniecie sami sobie w oczach swoich dla nieprawości waszych i dla obrzydliwości waszych.
32 Mo fẹ́ kí ẹ mọ̀ pé ń kò ṣe nǹkan wọ̀nyí nítorí yín, ni Olúwa Olódùmarè wí. Jẹ kí ojú kí ó tì yín, kí ẹ sì gba ẹ̀tẹ́ nítorí ìwà yín ẹ̀yin ilé Israẹli!
Nie dla wasci Ja to czynię, mówi panujący Pan, niech wam to jawno będzie; sromajcie się, a wstydźcie się za drogi wasze, o domie Izraelski!
33 “‘Èyí yìí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: Ní ọjọ́ tí mo wẹ̀ yín kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ yín gbogbo, èmi yóò ṣe àtúnṣe àwọn ìlú yín, wọn yóò sì ṣe àtúnkọ́ ìwólulẹ̀.
Tak mówi panujący Pan: Którego was dnia oczyszczę od wszystkich nieprawości waszych, osadzę miasta, a miejsca zburzone będą pobudowane.
34 Ilẹ̀ ahoro náà ní àwa yóò tún kọ́ ti kì yóò wà ní ahoro lójú àwọn tí ó ń gba ibẹ̀ kọjá mọ́.
A tak ziemia spustoszała sprawowana będzie, która przedtem była spustoszona przed oczyma wszystkich przechodzących.
35 Wọn yóò sọ wí pé, “Ilẹ̀ yìí tí ó ti wà ní ahoro tẹ́lẹ̀ ti dàbí ọgbà Edeni; àwọn ìlú tí ó wà ní wíwó lulẹ̀, ahoro tí a ti parun, ni àwa yóò mọdi sí tí yóò sì wà fún gbígbé ni ìsinsin yìí.”
I rzeką: Ziemia ta spustoszała stała się jako ogród Eden; także miasta puste i opuszczone i rozwalone, obronne są i osadzone.
36 Nígbà náà àwọn orílẹ̀-èdè tí ó wà ní àyíká yín tí ó kù yóò mọ̀ pé, Èmi Olúwa ti tún àwọn ohun tí ó bàjẹ́ kọ́, mo sì ti tún ohun tí ó di ìṣòfo gbìn. Èmi Olúwa ti sọ̀rọ̀, èmi yóò sì ṣe e?’
I dowiedzą się narody, którekolwiek zostną około was, żem Ja Pan pobudował rozwaliny, a nasadził miejsca spustoszone. Ja Pan mówiłem, i uczynię.
37 “Èyí yìí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè sọ: Lẹ́ẹ̀kan sí i èmi yóò yí sí ilé Israẹli, èmi yóò sì ṣe èyí fún wọn. Èmi yóò mú kí àwọn ènìyàn yín pọ̀ lọ́pọ̀lọ́pọ̀ bí àgùntàn,
Tak mówi panujący Pan: Jeszcze tego będzie u mnie szukał dom Izraelski, abym to im uczynił, abym ich rozmnożył w ludzi jako trzodę.
38 kí ó pọ̀ lọ́pọ̀lọ́pọ̀ bí ọ̀wọ́ ẹran fún ìrúbọ ní Jerusalẹmu ní àsìkò àjọ̀dún tí a yàn. Ìlú ti a parun yóò wá kún fún agbo àwọn ènìyàn. Nígbà náà ni wọn yóò mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.”
Jako trzodę na ofiary, jako trzodę Jeruzalemską na święta jego uroczyste, tak spustoszone miasta będą napełnione trzodami ludzi; i dowiedzą się, żem Ja Pan.

< Ezekiel 36 >