< Ezekiel 36 >

1 “Ọmọ ènìyàn, sọtẹ́lẹ̀ sí àwọn òkè gíga Israẹli kí o sì wí pé, ‘Ẹ̀yin òkè gíga Israẹli gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa.
Na ko koe e te tama a te tangata, poropiti atu ki nga maunga o Iharaira, mea atu, E nga maunga o Iharaira, whakarongo ki te kupu a Ihowa.
2 Èyí yìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Àwọn ọ̀tá sọ nípa yín pé, “Háà! Àwọn ibi gíga ìgbàanì ti di ohun ìní wa.”’
Ko te kupu tenei a te Ariki, a Ihowa; Na, kua mea nei te hoariri ki a koutou, Ha! na, Kua riro mai hoki mo tatou nga pukepuke onamata:
3 Nítorí náà, sọtẹ́lẹ̀ kí ó sì wí pé, ‘Èyí yìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Nítorí pé wọn sọ ọ di ahoro, tí wọn sì ń dọdẹ rẹ ní gbogbo ọ̀nà kí ìwọ kí ó lè di ìní fún àwọn orílẹ̀-èdè tí ó kù, àti ohun ti àwọn ènìyàn ń sọ ọ̀rọ̀ ìríra àti ìdíbàjẹ́ sí,
Mo reira, poropiti atu, mea atu, Ko te kupu tenei a te Ariki, a Ihowa; Na, kua meinga na koutou e ratou kia tu kau, kua horomia i tetahi taha, i tetahi taha, i riro ai koutou ma nga toenga o nga iwi, i hapainga ake ai e nga ngutu o nga arero kape tau, i korerotia kinotia ai e te iwi:
4 nítorí náà, ẹ̀yin òkè gíga Israẹli gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa Olódùmarè, èyí yìí ní Olúwa Olódùmarè wí fún àwọn òkè gíga àti àwọn òkè kéékèèké, fún àfonífojì ńlá àti àfonífojì kéékèèké, fún àwọn ibi ìsọdahoro ìparun àti fún àwọn ìlú tí a ti kọ̀sílẹ̀ tí a ti kó tí àwọn orílẹ̀-èdè tí ó kù ní àyíká sì fi ṣe ẹlẹ́yà,
Mo reira, e nga maunga o Iharaira whakarongo ki te kupu a te Ariki, a Ihowa; Ko te kupu tenei a te Ariki, a Ihowa, ki nga maunga, ki nga pukepuke, ki nga awa, ki nga awaawa, ki nga ururua kua takoto kau, ki nga pa kua mahue, kua riro nei hei pahu atanga, hei katanga ma nga toenga o nga iwi a tawhio noa.
5 èyí yìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Ní ìgbóná ọkàn ní mo sọ̀rọ̀ sí àwọn kèfèrí yòókù, àti sí Edomu, nítorí pẹ̀lú ìbínú àti ìjowú ní ọkàn wọn ni wọ́n sọ ilé mi di ohun ìní wọn, kí wọn kí o lè kó pápá oko tútù rẹ̀.’
Na reira ko te kupu tenei a te Ariki, a Ihowa, He pono he ahi toku hae, i ahau i korero ai i te he mo nga toenga o nga iwi, mo Eroma katoa ano; mo ta ratou meatanga i toku whenua hei kainga mo ratou, pau katoa te ngakau ki te koa, kino tonu te hi nengaro, mo tera kia peia atu, kia waiho hei taonga parau.
6 Nítorí náà, sọtẹ́lẹ̀ nípa ilẹ̀ Israẹli náà kí o sì sọ sí àwọn òkè gíga náà àti àwọn òkè kéékèèké, sí àwọn àfonífojì ńlá àti sí àwọn àfonífojì kéékèèké, ‘Èyí yìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Èmi sọ̀rọ̀ nínú ìrunú owú mi nítorí pé ìwọ ti jìyà ìfiṣẹ̀sín àwọn orílẹ̀-èdè.
Na reira poropititia te whenua o Iharaira, ki atu ki nga maunga, ki nga pukepuke, ki nga awa, ki nga awaawa, Ko te kupu tenei a te Ariki, a Ihowa; Nana, kua korero ahau i runga i toku hae, i toku weriweri, no te mea e mau ana ki a koutou te whaka ma o nga tauiwi:
7 Nítorí náà, èyí yìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Èmi ṣe ìbúra nípa nína ọwọ́ mi sókè pé; àwọn orílẹ̀-èdè àyíká rẹ náà yóò jìyà ìfiṣẹ̀sín.
Na reira ko te kupu tenei a te Ariki, a Ihowa; Kua ara toku ringa kua mea, He pono, ko nga iwi i tetahi taha o koutou, i tetahi taha, ka mau ki a ratou to ratou whakama.
8 “‘Ṣùgbọ́n ìwọ, òkè gíga Israẹli, yóò mú ẹ̀ka àti èso fún àwọn ènìyàn mi Israẹli, nítorí wọn yóò wá sílé ní àìpẹ́ yìí.
Ko koutou ia, e nga maunga o Iharaira, ka wana o koutou manga, ka whai hua koutou ma taku iwi, ma Iharaira; ka tata hoki ratou te puta.
9 Èmi ń ṣe àníyàn fún ọ, èmi yóò sì fi rere wọ̀ ọ́; àwa yóò tu ọ́, àwa yóò sì gbìn ọ́,
No te mea, nana, ka aro ahau ki a koutou, ka tahuri ki a koutou, a ka ngakia koutou, ka whakatokia.
10 èmi yóò sì sọ iye àwọn ènìyàn di púpọ̀ nínú rẹ àti gbogbo ilé Israẹli. Àwọn ìlú yóò di ibùgbé, a yóò sì tún àwọn ibi ìparun kọ́.
Ka tini ano i ahau nga tangata ki a koutou, te whare katoa o Iharaira, ratou katoa, a ka mohoia nga pa, ka hanga ano nga ururua.
11 Èmi yóò sọ iye ènìyàn àti ẹran dì púpọ̀ nínú yín, wọn yóò sì so èso, wọn yóò sì di púpọ̀ yanturu. Èmi yóò mú kí àwọn ènìyàn máa gbé nínú rẹ bí ti àtẹ̀yìnwá, èmi yóò sì mú kí o ṣe rere ju ìgbà àtijọ́ lọ. Nígbà náà ni ìwọ yóò mọ pé èmi ni Olúwa.
Ka tini ano i ahau nga tangata ki a koutou, me nga kararehe; a ka tini ratou, ka hua; ka meinga hoki koutou e ahau kia nohoia, kia pera me to mua, a ka pai atu taku e mea ai ki a koutou i to o koutou timatanga: a ka mohio koutou ko Ihowa ahau.
12 Èmi yóò mú kí àwọn ènìyàn, àní àwọn ènìyàn Israẹli, rìn lórí rẹ̀. Wọn yóò gbà ọ́, ìwọ yóò sì di ogún ìní wọn; ìwọ kì yóò sì gba àwọn ọmọ wọn lọ́wọ́ wọn mọ́.
Ae ra, ka meinga koutou e ahau kia haereerea e te tangata, e taku iwi, e Iharaira; ka riro koe i a ratou, ka waiho hoki koe hei kainga tupu mo ratou, a heoi ano matenga o a ratou tamariki i a koe.
13 “‘Èyí yìí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: Nítorí pé àwọn ènìyàn sọ fún ọ pé, “Ìwọ pa àwọn ènìyàn run, ìwọ sì gba àwọn ọmọ orílẹ̀-èdè lọ́wọ́ wọn,”
Ko te kupu tenei a te Ariki, a Ihowa; Na, kua korerotia nei ki a koutou, He kai tangata koe, e te whenua, e whakamate ana i nga tamariki a tou iwi;
14 nítorí náà ìwọ kì yóò pa àwọn ènìyàn run tàbí mú kì orílẹ̀-èdè di aláìlọ́mọ mọ́, ni Olúwa Olódùmarè wí.
Na reira e kore koe e kai tangata a muri ake nei, e kore ano e hinga i a koe ou iwi a muri nei, e ai ta te Ariki, ta Ihowa.
15 Èmi kì yóò mú ki ó gbọ́ ọ̀rọ̀ ẹ̀gàn láti ọ̀dọ̀ àwọn orílẹ̀-èdè mọ́, ìwọ kì yóò jìyà ọ̀rọ̀ ìfiṣẹ̀sín láti ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn tàbí mú kí orílẹ̀-èdè rẹ ṣubú, ni Olúwa Olódùmarè wí.’”
Heoi ano aku meatanga kia rangona ki a koe te numinumi i nga iwi, e kore ano e mau ki a koe i nga wa i muri te tawai a nga iwi; e kore ano koe e mea i nga waewae o ou iwi kia tutuki a ake ake, e ai ta te Ariki, ta Ihowa.
16 Síwájú sí i ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá:
I puta mai ano te kupu a Ihowa ki ahau, i mea,
17 “Ọmọ ènìyàn, nígbà tí àwọn ènìyàn Israẹli ń gbé ní ilẹ̀ wọn, wọ́n bà á jẹ́ nípa ìwà àti ìṣe wọn. Ìwà wọn dàbí nǹkan àkókò àwọn obìnrin ni ojú mi.
E te tama a te tangata, i te nohoanga o te whare o Iharaira i to ratou oneone, i whakapokea a reira e ratou ki to ratou ara, ki a ratou mahi: ko to ratou ara i toku aroaro, rite tonu ki te poke o te wahine e paheke ana.
18 Nítorí náà mo tú ìbínú mi jáde sórí wọn nítorí wọn ti ta ẹ̀jẹ̀ sílẹ̀ àti nítorí pé wọ́n ti fi ère wọn ba a jẹ́.
Heoi ringihia ana e ahau toku weriweri ki runga ki a ratou, mo te toto i tahoroa e ratou ki runga ki te whenua, mo a ratou whakapakoko hoki i whakapokea ai a reira e ratou.
19 Mo tú wọn ká sí àárín àwọn orílẹ̀-èdè, a sì fọ́n wọn ká sí àwọn ìlú; mo ṣe ìdájọ́ wọn gẹ́gẹ́ bí ìwà àti ìṣe wọn.
A whakamararatia atu ana ratou e ahau ki roto ki nga iwi, titaria atu ana ki nga whenua; rite tonu ki to ratou ara, ki a ratou mahi taku whakarite mo ratou.
20 Gbogbo ibi tí wọ́n lọ ní àárín àwọn orílẹ̀-èdè ni wọn ti sọ orúkọ mímọ́ mi di aláìmọ́, nítorí tí a sọ nípa wọn pé, ‘Ìwọ̀nyí ni àwọn ènìyàn Olúwa, síbẹ̀ wọn ní láti fi ilẹ̀ náà sílẹ̀.’
A, i to ratou taenga ki nga iwi i haere atu ai ratou, whakanoatia ana e ratou toku ingoa tapu, i a ratou i ki ra mo ratou, Ko te iwi tenei a Ihowa, a kua puta atu ratou i tona whenua.
21 Orúkọ mímọ́ mi jẹ́ mi lógún, èyí tí ilé Israẹli sọ di aláìmọ́ ni àárín àwọn orílẹ̀-èdè tí wọ́n ti lọ.
Otiia i whai whakaaro ahau ki toku ingoa tapu i whakanoatia nei e te whare o Iharaira i roto i nga tauiwi i haere atu ai ratou.
22 “Nítorí náà, sọ fún ilé Israẹli, ‘Èyí ni Olúwa Olódùmarè wí: Kì í ṣe nítorí rẹ, ìwọ ilé Israẹli, ni èmi yóò ṣe ṣe àwọn nǹkan wọ̀nyí, ṣùgbọ́n nítorí orúkọ mímọ́ mi, èyí ti ìwọ ti sọ di aláìmọ́ ní àárín àwọn orílẹ̀-èdè tí ìwọ ti lọ.
Mo reira ki atu ki te whare o Iharaira; Ko te kupu tenei a te Ariki, a Ihowa; Ehara i te mea he whakaaro ki a koutou i mahi ai ahau i tenei, e te whare o Iharaira; engari ki toku ingoa tapu i whakanoatia nei e koutou i roto i nga tauiwi i haere atu ai koutou.
23 Èmi yóò fi jíjẹ́ mímọ́ orúkọ ńlá mi, èyí tí a ti sọ di aláìmọ́ hàn ni àárín àwọn orílẹ̀-èdè, orúkọ tí ìwọ ti sọ di aláìmọ́ ni àárín wọn. Nígbà náà àwọn orílẹ̀-èdè yóò mọ̀ pé èmi ni Olúwa, ni Olúwa Olódùmarè wí, nígbà tí mo bá fi ara mi hàn ni mímọ́ nípasẹ̀ yín ni iwájú wọn.
Ka whakatapua ano e ahau toku ingoa nui i whakanoatia nei i roto i nga tauiwi, ko ta koutou ra i whakanoa ai i roto i a ratou; a ka mohio nga tauiwi ko Ihowa ahau, e ai ta te Ariki, ta Ihowa, ina whakatapua ahau i roto i a koutou i to ratou aroa ro.
24 “‘Nítorí èmi yóò mú yín jáde kúrò ni àwọn orílẹ̀-èdè náà; Èmi yóò ṣà yín jọ kúrò ní gbogbo àwọn ìlú náà; Èmi yóò sì mú yín padà sí ilẹ̀ ẹ̀yin tìkára yín.
Ka tangohia mai hoki koutou e ahau i roto i nga tauiwi, ka whakaminea i nga whenua katoa, ka kawea mai ano ki to koutou oneone.
25 Èmi yóò wọ́n omi tó mọ́ sí yín lára ẹ̀yin yóò sì mọ́; Èmi yóò sì fọ̀ yín mọ́ kúrò nínú gbogbo ìwà èérí yin gbogbo àti kúrò nínú gbogbo òrìṣà yin.
Ka tauhiuhia ano koutou e ahau ki te wai ma, a ka ma koutou: ka purea koutou e ahau, a kore iho o koutou poke katoa, a koutou whakapakoko katoa.
26 Èmi yóò fún yín ni ọkàn tuntun, èmi yóò sì fi ẹ̀mí tuntun sínú yín; Èmi yóò sì mú ọkàn òkúta kúrò nínú yín, èmi yóò sì fi ọkàn ẹran fún yín.
Ka hoatu ano e ahau he ngakau hou ki a koutou, ka hoatu ano e ahau he wairua hou ki roto ki a koutou; ka tangohia ano e ahau te ngakau kohatu i roto i o koutou kikokiko, a ka hoatu he ngakau kikokiko ki a koutou.
27 Èmi yóò fi ẹ̀mí mi sínú yín, èmi yóò sì mú ki ẹ tẹ̀lé àṣẹ mi, kí ẹ sì fiyèsí àti pa òfin mi mọ́.
Na ka hoatu e ahau toku wairua ki roto ki a koutou, a ka meinga koutou e ahau kia haere i runga i aku tikanga, ka puritia ano e koutou aku ritenga, ka mahia.
28 Ẹ̀yin yóò sì máa gbé ilẹ̀ náà tí mo ti fi fún àwọn baba ńlá yín; ẹ̀yin yóò sì jẹ́ ènìyàn mi èmi yóò sì jẹ́ Ọlọ́run yín.
A ka noho koutou ki te whenua i hoatu e ahau ki o koutou matua, ko koutou hoki hei iwi maku, ko ahau hei Atua mo koutou.
29 Èmi yóò sì gbà yín kúrò nínú gbogbo ìwà àìmọ́ yín. Èmi yóò pèsè ọkà, èmi yóò sì mú kí ó pọ̀ yanturu, èmi kì yóò sì mú ìyàn wá sí orí yín.
Ka whakaorangia ano koutou e ahau i o koutou poke katoa: ka karangatia hoki e ahau te witi, ka whakanuia hoki e ahau, e kore ano te hemokai e tukua e ahau ki a koutou.
30 Èmi yóò sọ èso àwọn igi yín àti ohun ọ̀gbìn oko yín di púpọ̀, nítorí kí ẹ̀yin kí ó má ṣe jìyà ìdójútì mọ́ láàrín àwọn orílẹ̀-èdè náà nítorí ìyàn.
A ka meinga e ahau kia maha nga hua o te rakau me nga mau o te mara, a heoi ano te tawai hemokai mo koutou i roto i nga tauiwi.
31 Nígbà náà ni ẹ̀yin yóò rántí àwọn ọ̀nà búburú àti àwọn ìwà ìkà yín, ẹ̀yin yóò sì kórìíra ara yín fún ẹ̀ṣẹ̀ yín, ìwà tí kò bójúmu.
Katahi koutou ka mahara ki o koutou ara kino, ki a koutou mahi kahore nei e pai; a ka anuanu koutou ki a koutou ano i o koutou aroaro mo o koutou kino, mo a koutou mea whakarihariha hoki.
32 Mo fẹ́ kí ẹ mọ̀ pé ń kò ṣe nǹkan wọ̀nyí nítorí yín, ni Olúwa Olódùmarè wí. Jẹ kí ojú kí ó tì yín, kí ẹ sì gba ẹ̀tẹ́ nítorí ìwà yín ẹ̀yin ilé Israẹli!
Ehara i te mea he whakaaro ki a koutou i mahi ai ahau i tenei, e ai ta te Ariki, ta Ihowa, kia mohio koutou: kia whakama koutou, kia numinumi kau ki o koutou ara, e te whare o Iharaira.
33 “‘Èyí yìí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: Ní ọjọ́ tí mo wẹ̀ yín kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ yín gbogbo, èmi yóò ṣe àtúnṣe àwọn ìlú yín, wọn yóò sì ṣe àtúnkọ́ ìwólulẹ̀.
Ko te kupu tenei a te Ariki, a Ihowa; I te ra e purea ai e ahau o koutou he katoa, ka meinga e ahau nga pa kia nohoia, a ka hanga nga ururua.
34 Ilẹ̀ ahoro náà ní àwa yóò tún kọ́ ti kì yóò wà ní ahoro lójú àwọn tí ó ń gba ibẹ̀ kọjá mọ́.
Na, ko te whenua i takoto kau ra, ka ngakia; he ururua ra hoki i mua ki te titiro a te hunga katoa e tika ana na reira.
35 Wọn yóò sọ wí pé, “Ilẹ̀ yìí tí ó ti wà ní ahoro tẹ́lẹ̀ ti dàbí ọgbà Edeni; àwọn ìlú tí ó wà ní wíwó lulẹ̀, ahoro tí a ti parun, ni àwa yóò mọdi sí tí yóò sì wà fún gbígbé ni ìsinsin yìí.”
A ka korerotia, Ko tenei whenua i takoto kau ra, kua rite ki te kari o Erene; na, ko nga pa kua ururuatia, ko era i takoto kau ra, ko nga mea pakura, kua oti te taiepa, e nohoia ana.
36 Nígbà náà àwọn orílẹ̀-èdè tí ó wà ní àyíká yín tí ó kù yóò mọ̀ pé, Èmi Olúwa ti tún àwọn ohun tí ó bàjẹ́ kọ́, mo sì ti tún ohun tí ó di ìṣòfo gbìn. Èmi Olúwa ti sọ̀rọ̀, èmi yóò sì ṣe e?’
Katahi ka mohio nga iwi kua mahue i tetahi taha o koutou, i tetahi taha, kua hanga e ahau, e Ihowa, nga wahi i pakaru, a kua whakatokia e ahau nga wahi kua ururuatia: naku, na Ihowa te kupu, maku ano e mahi.
37 “Èyí yìí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè sọ: Lẹ́ẹ̀kan sí i èmi yóò yí sí ilé Israẹli, èmi yóò sì ṣe èyí fún wọn. Èmi yóò mú kí àwọn ènìyàn yín pọ̀ lọ́pọ̀lọ́pọ̀ bí àgùntàn,
Ko te kupu tenei a te Ariki, a Ihowa; Tenei ake ka uia tenei ki ahau e te whare o Iharaira, kia meatia ki a ratou; ka tokomaha ratou i ahau, me e mea he kahui te tangata.
38 kí ó pọ̀ lọ́pọ̀lọ́pọ̀ bí ọ̀wọ́ ẹran fún ìrúbọ ní Jerusalẹmu ní àsìkò àjọ̀dún tí a yàn. Ìlú ti a parun yóò wá kún fún agbo àwọn ènìyàn. Nígbà náà ni wọn yóò mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.”
Ka rite ki te kahui mo te whakahere, ki te kahui o Hiruharama i ona hakari nunui; ka pena ano nga pa kua ururuatia, ka kapi i nga kahui tangata; a ka mohio ratou ko Ihowa ahau.

< Ezekiel 36 >