< Ezekiel 36 >

1 “Ọmọ ènìyàn, sọtẹ́lẹ̀ sí àwọn òkè gíga Israẹli kí o sì wí pé, ‘Ẹ̀yin òkè gíga Israẹli gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa.
Un tu cilvēka bērns, sludini par Israēla kalniem un saki: Israēla kalni, klausiet Tā Kunga vārdu.
2 Èyí yìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Àwọn ọ̀tá sọ nípa yín pé, “Háà! Àwọn ibi gíga ìgbàanì ti di ohun ìní wa.”’
Tā saka Tas Kungs Dievs: tādēļ ka ienaidnieks par jums saka: redzi, tie mūžīgie kalni mums ir tikuši par mantību,
3 Nítorí náà, sọtẹ́lẹ̀ kí ó sì wí pé, ‘Èyí yìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Nítorí pé wọn sọ ọ di ahoro, tí wọn sì ń dọdẹ rẹ ní gbogbo ọ̀nà kí ìwọ kí ó lè di ìní fún àwọn orílẹ̀-èdè tí ó kù, àti ohun ti àwọn ènìyàn ń sọ ọ̀rọ̀ ìríra àti ìdíbàjẹ́ sí,
Tādēļ sludini un saki: tā saka Tas Kungs Dievs: Tāpēc ka jūs visapkārt esat postīti un aprīti, ka jūs tiem atlikušiem pagāniem esat par mantību un esat nākuši ļaužu mēlēs un valodās,
4 nítorí náà, ẹ̀yin òkè gíga Israẹli gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa Olódùmarè, èyí yìí ní Olúwa Olódùmarè wí fún àwọn òkè gíga àti àwọn òkè kéékèèké, fún àfonífojì ńlá àti àfonífojì kéékèèké, fún àwọn ibi ìsọdahoro ìparun àti fún àwọn ìlú tí a ti kọ̀sílẹ̀ tí a ti kó tí àwọn orílẹ̀-èdè tí ó kù ní àyíká sì fi ṣe ẹlẹ́yà,
Tāpēc, Israēla kalni, klausiet Tā Kunga Dieva vārdu. Tā saka Tas Kungs Dievs uz kalniem un pakalniem, gravām un ielejām, tukšām posta vietām un atstātām pilsētām, kas ir palikušas par laupījumu un apsmieklu visām atlikušām tautām visapkārt, -
5 èyí yìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Ní ìgbóná ọkàn ní mo sọ̀rọ̀ sí àwọn kèfèrí yòókù, àti sí Edomu, nítorí pẹ̀lú ìbínú àti ìjowú ní ọkàn wọn ni wọ́n sọ ilé mi di ohun ìní wọn, kí wọn kí o lè kó pápá oko tútù rẹ̀.’
Tāpēc tā saka Tas Kungs Dievs: tiešām, Es Sava karstuma ugunī runāju pret tām atlikušām tautām un pret visu Edomu, kas Manu zemi sev ņēmuši par mantību ar visas sirds prieku, ar lielu nicināšanu, to izpostīt un aplaupīt.
6 Nítorí náà, sọtẹ́lẹ̀ nípa ilẹ̀ Israẹli náà kí o sì sọ sí àwọn òkè gíga náà àti àwọn òkè kéékèèké, sí àwọn àfonífojì ńlá àti sí àwọn àfonífojì kéékèèké, ‘Èyí yìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Èmi sọ̀rọ̀ nínú ìrunú owú mi nítorí pé ìwọ ti jìyà ìfiṣẹ̀sín àwọn orílẹ̀-èdè.
Tāpēc sludini Israēla zemei un saki uz kalniem un pakalniem, gravām un ielejām: tā saka Tas Kungs Dievs: redzi, Es Savā karstumā un Savā bardzībā esmu runājis, tāpēc ka jums apsmiekls bija jānes no pagāniem.
7 Nítorí náà, èyí yìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Èmi ṣe ìbúra nípa nína ọwọ́ mi sókè pé; àwọn orílẹ̀-èdè àyíká rẹ náà yóò jìyà ìfiṣẹ̀sín.
Tādēļ Tas Kungs Dievs tā saka: Es, Es paceļu Savu roku, tiešām, tām tautām, kas visapkārt ap jums, pašām būs nest savu apsmieklu.
8 “‘Ṣùgbọ́n ìwọ, òkè gíga Israẹli, yóò mú ẹ̀ka àti èso fún àwọn ènìyàn mi Israẹli, nítorí wọn yóò wá sílé ní àìpẹ́ yìí.
Bet jūs, jūs Israēla kalni, atkal zaļosiet un nesīsiet savus augļus Maniem Israēla ļaudīm, jo īsā laikā tie pārnāks.
9 Èmi ń ṣe àníyàn fún ọ, èmi yóò sì fi rere wọ̀ ọ́; àwa yóò tu ọ́, àwa yóò sì gbìn ọ́,
Jo redzi, Es būšu pie jums, un Es skatīšos uz jums, un jūs tapsiet kopti un apsēti.
10 èmi yóò sì sọ iye àwọn ènìyàn di púpọ̀ nínú rẹ àti gbogbo ilé Israẹli. Àwọn ìlú yóò di ibùgbé, a yóò sì tún àwọn ibi ìparun kọ́.
Un Es vairošu pie jums cilvēkus, visu Israēla namu visnotaļ: un pilsētās dzīvos un postītas vietas uztaisīs.
11 Èmi yóò sọ iye ènìyàn àti ẹran dì púpọ̀ nínú yín, wọn yóò sì so èso, wọn yóò sì di púpọ̀ yanturu. Èmi yóò mú kí àwọn ènìyàn máa gbé nínú rẹ bí ti àtẹ̀yìnwá, èmi yóò sì mú kí o ṣe rere ju ìgbà àtijọ́ lọ. Nígbà náà ni ìwọ yóò mọ pé èmi ni Olúwa.
Un Es pie jums vairošu cilvēkus un lopus, tie vairosies un vaislosies, un Es iekš jums likšu dzīvot kā jūsu vecos laikos, un Es jums darīšu vairāk labuma nekā jūsu senajos laikos, un jūs samanīsiet, ka Es esmu Tas Kungs.
12 Èmi yóò mú kí àwọn ènìyàn, àní àwọn ènìyàn Israẹli, rìn lórí rẹ̀. Wọn yóò gbà ọ́, ìwọ yóò sì di ogún ìní wọn; ìwọ kì yóò sì gba àwọn ọmọ wọn lọ́wọ́ wọn mọ́.
Un Es pie jums atvedīšu cilvēkus, Savus Israēla ļaudis, tie tevi iemantos, un tu tiem būsi par mantību un tiem vairs nelaupīsi bērnus.
13 “‘Èyí yìí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: Nítorí pé àwọn ènìyàn sọ fún ọ pé, “Ìwọ pa àwọn ènìyàn run, ìwọ sì gba àwọn ọmọ orílẹ̀-èdè lọ́wọ́ wọn,”
Tā saka Tas Kungs Dievs: tādēļ ka uz jums saka: tu esi cilvēku rijēja un savu ļaužu bērnu aplaupītāja,
14 nítorí náà ìwọ kì yóò pa àwọn ènìyàn run tàbí mú kì orílẹ̀-èdè di aláìlọ́mọ mọ́, ni Olúwa Olódùmarè wí.
Tādēļ tu cilvēkus vairs nerīsi un saviem ļaudīm vairs nelaupīsi bērnus, saka Tas Kungs Dievs.
15 Èmi kì yóò mú ki ó gbọ́ ọ̀rọ̀ ẹ̀gàn láti ọ̀dọ̀ àwọn orílẹ̀-èdè mọ́, ìwọ kì yóò jìyà ọ̀rọ̀ ìfiṣẹ̀sín láti ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn tàbí mú kí orílẹ̀-èdè rẹ ṣubú, ni Olúwa Olódùmarè wí.’”
Un Es tev vairs nelikšu dzirdēt pagānu apsmieklu, un tu nenesīsi vairs tautu negodu un saviem ļaudīm vairs nelaupīsi bērnus, saka Tas Kungs Dievs.
16 Síwájú sí i ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá:
Atkal Tā Kunga vārds uz mani notika sacīdams:
17 “Ọmọ ènìyàn, nígbà tí àwọn ènìyàn Israẹli ń gbé ní ilẹ̀ wọn, wọ́n bà á jẹ́ nípa ìwà àti ìṣe wọn. Ìwà wọn dàbí nǹkan àkókò àwọn obìnrin ni ojú mi.
Cilvēka bērns, Israēla nams, kad tie savā zemē dzīvoja, tad tie to sagānīja ar savu ceļu un ar saviem darbiem; viņu ceļš bija Manā priekšā kā sārņainas sievas nešķīstība.
18 Nítorí náà mo tú ìbínú mi jáde sórí wọn nítorí wọn ti ta ẹ̀jẹ̀ sílẹ̀ àti nítorí pé wọ́n ti fi ère wọn ba a jẹ́.
Tādēļ Es Savu bardzību pār viņiem izgāzu to asiņu dēļ, ko tie tai zemē bija izlējuši, un viņu elku dēļ ar ko to bija sagānījuši.
19 Mo tú wọn ká sí àárín àwọn orílẹ̀-èdè, a sì fọ́n wọn ká sí àwọn ìlú; mo ṣe ìdájọ́ wọn gẹ́gẹ́ bí ìwà àti ìṣe wọn.
Un Es tos izkaisīju starp tautām, un tie tapa izputināti pa valstīm, Es tos sodīju pēc viņu ceļa un pēc viņu darbiem.
20 Gbogbo ibi tí wọ́n lọ ní àárín àwọn orílẹ̀-èdè ni wọn ti sọ orúkọ mímọ́ mi di aláìmọ́, nítorí tí a sọ nípa wọn pé, ‘Ìwọ̀nyí ni àwọn ènìyàn Olúwa, síbẹ̀ wọn ní láti fi ilẹ̀ náà sílẹ̀.’
Kad tie nu pie tām tautām nonāca, kurp tie bija gājuši, tad tie sagānīja manu svēto vārdu, tāpēc ka no tiem tapa sacīts: šie ir Tā Kunga ļaudis un izgājuši no viņa zemes.
21 Orúkọ mímọ́ mi jẹ́ mi lógún, èyí tí ilé Israẹli sọ di aláìmọ́ ni àárín àwọn orílẹ̀-èdè tí wọ́n ti lọ.
Bet Man ir žēl Sava svētā Vārda, ko Israēla bērni sagānījuši starp tām tautām, kur tie bija nākuši.
22 “Nítorí náà, sọ fún ilé Israẹli, ‘Èyí ni Olúwa Olódùmarè wí: Kì í ṣe nítorí rẹ, ìwọ ilé Israẹli, ni èmi yóò ṣe ṣe àwọn nǹkan wọ̀nyí, ṣùgbọ́n nítorí orúkọ mímọ́ mi, èyí ti ìwọ ti sọ di aláìmọ́ ní àárín àwọn orílẹ̀-èdè tí ìwọ ti lọ.
Tāpēc saki uz Israēla namu: tā saka Tas Kungs Dievs: Es to nedaru jūsu dēļ, Israēla nams, bet Sava svētā Vārda dēļ, ko jūs esat sagānījuši starp tām tautām, kur esat nākuši.
23 Èmi yóò fi jíjẹ́ mímọ́ orúkọ ńlá mi, èyí tí a ti sọ di aláìmọ́ hàn ni àárín àwọn orílẹ̀-èdè, orúkọ tí ìwọ ti sọ di aláìmọ́ ni àárín wọn. Nígbà náà àwọn orílẹ̀-èdè yóò mọ̀ pé èmi ni Olúwa, ni Olúwa Olódùmarè wí, nígbà tí mo bá fi ara mi hàn ni mímọ́ nípasẹ̀ yín ni iwájú wọn.
Jo Es pagodināšu Savu lielo Vārdu, kas starp pagāniem ir sagānīts, ko jūs viņu vidū esat sagānījuši. Un pagāni samanīs, ka Es esmu Tas Kungs, saka Tas Kungs Dievs, kad Es pie jums svēts parādīšos priekš viņu acīm.
24 “‘Nítorí èmi yóò mú yín jáde kúrò ni àwọn orílẹ̀-èdè náà; Èmi yóò ṣà yín jọ kúrò ní gbogbo àwọn ìlú náà; Èmi yóò sì mú yín padà sí ilẹ̀ ẹ̀yin tìkára yín.
Jo Es jūs atvedīšu no tām tautām un jūs sapulcināšu no visām valstīm, un Es jūs atvedīšu atkal jūsu zemē.
25 Èmi yóò wọ́n omi tó mọ́ sí yín lára ẹ̀yin yóò sì mọ́; Èmi yóò sì fọ̀ yín mọ́ kúrò nínú gbogbo ìwà èérí yin gbogbo àti kúrò nínú gbogbo òrìṣà yin.
Un Es uz jums slacināšu šķīstu ūdeni, ka topat šķīsti; no visas jūsu nešķīstības un no visiem jūsu elkiem Es jūs šķīstīšu.
26 Èmi yóò fún yín ni ọkàn tuntun, èmi yóò sì fi ẹ̀mí tuntun sínú yín; Èmi yóò sì mú ọkàn òkúta kúrò nínú yín, èmi yóò sì fi ọkàn ẹran fún yín.
Un Es jums došu jaunu sirdi un došu jums jaunu garu, un atņemšu to akmens sirdi no jūsu miesām un došu jums miesīgu sirdi.
27 Èmi yóò fi ẹ̀mí mi sínú yín, èmi yóò sì mú ki ẹ tẹ̀lé àṣẹ mi, kí ẹ sì fiyèsí àti pa òfin mi mọ́.
Un Es jums došu Savu Garu un darīšu, ka jūs staigāsiet Manos likumos un sargāsiet un darīsiet Manas tiesas.
28 Ẹ̀yin yóò sì máa gbé ilẹ̀ náà tí mo ti fi fún àwọn baba ńlá yín; ẹ̀yin yóò sì jẹ́ ènìyàn mi èmi yóò sì jẹ́ Ọlọ́run yín.
Un jūs dzīvosiet tai zemē, ko Es jūsu tēviem esmu devis, un jūs Man būsiet par ļaudīm, un Es jums būšu par Dievu.
29 Èmi yóò sì gbà yín kúrò nínú gbogbo ìwà àìmọ́ yín. Èmi yóò pèsè ọkà, èmi yóò sì mú kí ó pọ̀ yanturu, èmi kì yóò sì mú ìyàn wá sí orí yín.
Un Es jūs atpestīšu no visas jūsu nešķīstības un aicināšu labību un to vairošu un nevedīšu pār jums badu.
30 Èmi yóò sọ èso àwọn igi yín àti ohun ọ̀gbìn oko yín di púpọ̀, nítorí kí ẹ̀yin kí ó má ṣe jìyà ìdójútì mọ́ láàrín àwọn orílẹ̀-èdè náà nítorí ìyàn.
Un Es vairošu koku augļus un tīruma augļus, ka jūs bada dēļ starp tautām vairs netopat nicināti.
31 Nígbà náà ni ẹ̀yin yóò rántí àwọn ọ̀nà búburú àti àwọn ìwà ìkà yín, ẹ̀yin yóò sì kórìíra ara yín fún ẹ̀ṣẹ̀ yín, ìwà tí kò bójúmu.
Tad jūs pieminēsiet savus ļaunos ceļus un savus nelabos darbus un būsiet paši sev riebīgi par saviem noziegumiem un par savām negantībām.
32 Mo fẹ́ kí ẹ mọ̀ pé ń kò ṣe nǹkan wọ̀nyí nítorí yín, ni Olúwa Olódùmarè wí. Jẹ kí ojú kí ó tì yín, kí ẹ sì gba ẹ̀tẹ́ nítorí ìwà yín ẹ̀yin ilé Israẹli!
Un to Es nedaru jūsu dēļ, saka Tas Kungs Dievs, to jums būs zināt. Kaunaties un nosarkstiet savu ceļu dēļ, jūs, Israēla nams!
33 “‘Èyí yìí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: Ní ọjọ́ tí mo wẹ̀ yín kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ yín gbogbo, èmi yóò ṣe àtúnṣe àwọn ìlú yín, wọn yóò sì ṣe àtúnkọ́ ìwólulẹ̀.
Tā saka Tas Kungs Dievs: tai dienā, kad Es jūs šķīstīšu no visas jūsu nešķīstības, tad Es pilsētās likšu dzīvot, un postažas taps uztaisītas.
34 Ilẹ̀ ahoro náà ní àwa yóò tún kọ́ ti kì yóò wà ní ahoro lójú àwọn tí ó ń gba ibẹ̀ kọjá mọ́.
Un tā tukšā zeme atkal taps apkopta, kur posts bija priekš ikviena acīm, kas gāja garām.
35 Wọn yóò sọ wí pé, “Ilẹ̀ yìí tí ó ti wà ní ahoro tẹ́lẹ̀ ti dàbí ọgbà Edeni; àwọn ìlú tí ó wà ní wíwó lulẹ̀, ahoro tí a ti parun, ni àwa yóò mọdi sí tí yóò sì wà fún gbígbé ni ìsinsin yìí.”
Un sacīs: šī zeme, kas bija postā, ir palikusi kā Ēdenes dārzs, un tās iztukšotās un izpostītās un sagruvušās pilsētas ir stipras un apdzīvotas.
36 Nígbà náà àwọn orílẹ̀-èdè tí ó wà ní àyíká yín tí ó kù yóò mọ̀ pé, Èmi Olúwa ti tún àwọn ohun tí ó bàjẹ́ kọ́, mo sì ti tún ohun tí ó di ìṣòfo gbìn. Èmi Olúwa ti sọ̀rọ̀, èmi yóò sì ṣe e?’
Tad tās tautas, kas atlikušas visapkārt ap jums, samanīs, ka Es, Tas Kungs, uztaisu sagruvušas vietas un apdēstu, kas ir izpostīts; Es, Tas Kungs, to esmu runājis, un Es to darīšu.
37 “Èyí yìí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè sọ: Lẹ́ẹ̀kan sí i èmi yóò yí sí ilé Israẹli, èmi yóò sì ṣe èyí fún wọn. Èmi yóò mú kí àwọn ènìyàn yín pọ̀ lọ́pọ̀lọ́pọ̀ bí àgùntàn,
Tā saka Tas Kungs Dievs: Es ļaušos atkal pielūgties no Israēla nama, ka Es tiem parādos; Es vairošu tos ļaudis kā ganāmu pulku.
38 kí ó pọ̀ lọ́pọ̀lọ́pọ̀ bí ọ̀wọ́ ẹran fún ìrúbọ ní Jerusalẹmu ní àsìkò àjọ̀dún tí a yàn. Ìlú ti a parun yóò wá kún fún agbo àwọn ènìyàn. Nígbà náà ni wọn yóò mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.”
Tā kā tās svētās avis, kā Jeruzālemes avis savos svētkos, tā būs tās tukšās vietas ar cilvēkiem kā ar ganāmu pulku pilnas, un tie samanīs, ka Es esmu Tas Kungs.

< Ezekiel 36 >