< Ezekiel 36 >

1 “Ọmọ ènìyàn, sọtẹ́lẹ̀ sí àwọn òkè gíga Israẹli kí o sì wí pé, ‘Ẹ̀yin òkè gíga Israẹli gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa.
Toi, fils de l'homme, prophétise aux montagnes d'Israël, et dis: « Montagnes d'Israël, écoutez la parole de Yahvé.
2 Èyí yìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Àwọn ọ̀tá sọ nípa yín pé, “Háà! Àwọn ibi gíga ìgbàanì ti di ohun ìní wa.”’
Le Seigneur Yahvé dit: Parce que l'ennemi a dit contre vous: « Ah! » et « Les anciens hauts lieux sont à nous ».
3 Nítorí náà, sọtẹ́lẹ̀ kí ó sì wí pé, ‘Èyí yìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Nítorí pé wọn sọ ọ di ahoro, tí wọn sì ń dọdẹ rẹ ní gbogbo ọ̀nà kí ìwọ kí ó lè di ìní fún àwọn orílẹ̀-èdè tí ó kù, àti ohun ti àwọn ènìyàn ń sọ ọ̀rọ̀ ìríra àti ìdíbàjẹ́ sí,
prophétise donc, et dis: « Le Seigneur Yahvé dit: « Parce que, parce qu'on t'a dévasté, parce qu'on t'a englouti de toutes parts, afin que tu sois un bien pour le reste des nations, parce que tu es sur les lèvres des bavards, sur les mauvaises langues des peuples »
4 nítorí náà, ẹ̀yin òkè gíga Israẹli gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa Olódùmarè, èyí yìí ní Olúwa Olódùmarè wí fún àwọn òkè gíga àti àwọn òkè kéékèèké, fún àfonífojì ńlá àti àfonífojì kéékèèké, fún àwọn ibi ìsọdahoro ìparun àti fún àwọn ìlú tí a ti kọ̀sílẹ̀ tí a ti kó tí àwọn orílẹ̀-èdè tí ó kù ní àyíká sì fi ṣe ẹlẹ́yà,
c'est pourquoi, montagnes d'Israël, écoutez la parole du Seigneur Yahvé: Le Seigneur Yahvé dit aux montagnes et aux collines, aux cours d'eau et aux vallées, aux déserts et aux villes abandonnées, qui sont devenues la proie et la risée du reste des nations d'alentour;
5 èyí yìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Ní ìgbóná ọkàn ní mo sọ̀rọ̀ sí àwọn kèfèrí yòókù, àti sí Edomu, nítorí pẹ̀lú ìbínú àti ìjowú ní ọkàn wọn ni wọ́n sọ ilé mi di ohun ìní wọn, kí wọn kí o lè kó pápá oko tútù rẹ̀.’
c'est pourquoi le Seigneur Yahvé dit: « Certes, dans le feu de ma jalousie, j'ai parlé contre le reste des nations et contre tout Édom, qui se sont attribué mon pays pour en faire une possession, avec la joie de tout leur cœur, avec le dépit de l'âme, pour le jeter en proie. »'
6 Nítorí náà, sọtẹ́lẹ̀ nípa ilẹ̀ Israẹli náà kí o sì sọ sí àwọn òkè gíga náà àti àwọn òkè kéékèèké, sí àwọn àfonífojì ńlá àti sí àwọn àfonífojì kéékèèké, ‘Èyí yìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Èmi sọ̀rọ̀ nínú ìrunú owú mi nítorí pé ìwọ ti jìyà ìfiṣẹ̀sín àwọn orílẹ̀-èdè.
C'est pourquoi prophétise sur le pays d'Israël, et dis aux montagnes, aux collines, aux cours d'eau et aux vallées: « Le Seigneur Yahvé dit: « Voici que je parle dans ma jalousie et dans ma colère, parce que vous avez porté l'opprobre des nations. »
7 Nítorí náà, èyí yìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Èmi ṣe ìbúra nípa nína ọwọ́ mi sókè pé; àwọn orílẹ̀-èdè àyíká rẹ náà yóò jìyà ìfiṣẹ̀sín.
C'est pourquoi le Seigneur Yahvé dit: « J'ai juré: « Les nations qui sont autour de toi porteront leur honte.
8 “‘Ṣùgbọ́n ìwọ, òkè gíga Israẹli, yóò mú ẹ̀ka àti èso fún àwọn ènìyàn mi Israẹli, nítorí wọn yóò wá sílé ní àìpẹ́ yìí.
"''Mais vous, montagnes d'Israël, vous pousserez vos rameaux et vous donnerez votre fruit à mon peuple d'Israël, car il est tout près de venir.
9 Èmi ń ṣe àníyàn fún ọ, èmi yóò sì fi rere wọ̀ ọ́; àwa yóò tu ọ́, àwa yóò sì gbìn ọ́,
Car voici, je suis pour vous, je viendrai chez vous, et vous serez cultivés et ensemencés.
10 èmi yóò sì sọ iye àwọn ènìyàn di púpọ̀ nínú rẹ àti gbogbo ilé Israẹli. Àwọn ìlú yóò di ibùgbé, a yóò sì tún àwọn ibi ìparun kọ́.
Je multiplierai les hommes sur vous, toute la maison d'Israël, toute la maison d'Israël. Les villes seront habitées et les ruines seront bâties.
11 Èmi yóò sọ iye ènìyàn àti ẹran dì púpọ̀ nínú yín, wọn yóò sì so èso, wọn yóò sì di púpọ̀ yanturu. Èmi yóò mú kí àwọn ènìyàn máa gbé nínú rẹ bí ti àtẹ̀yìnwá, èmi yóò sì mú kí o ṣe rere ju ìgbà àtijọ́ lọ. Nígbà náà ni ìwọ yóò mọ pé èmi ni Olúwa.
Je multiplierai sur toi les hommes et les animaux. Ils se multiplieront et seront féconds. Je te ferai habiter comme avant, et tu feras mieux qu'à tes débuts. Alors vous saurez que je suis Yahvé.
12 Èmi yóò mú kí àwọn ènìyàn, àní àwọn ènìyàn Israẹli, rìn lórí rẹ̀. Wọn yóò gbà ọ́, ìwọ yóò sì di ogún ìní wọn; ìwọ kì yóò sì gba àwọn ọmọ wọn lọ́wọ́ wọn mọ́.
Oui, je ferai en sorte que des hommes marchent sur toi, mon peuple Israël. Ils te posséderont, tu seras leur héritage, et tu ne les priveras plus jamais de leurs enfants. »
13 “‘Èyí yìí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: Nítorí pé àwọn ènìyàn sọ fún ọ pé, “Ìwọ pa àwọn ènìyàn run, ìwọ sì gba àwọn ọmọ orílẹ̀-èdè lọ́wọ́ wọn,”
"'Le Seigneur Yahvé dit: « Parce qu'on te dit: 'Tu es un dévoreur d'hommes, et tu as été un endeuillé de ta nation';
14 nítorí náà ìwọ kì yóò pa àwọn ènìyàn run tàbí mú kì orílẹ̀-èdè di aláìlọ́mọ mọ́, ni Olúwa Olódùmarè wí.
c'est pourquoi tu ne dévoreras plus d'hommes, et tu n'endeuilleras plus ta nation, dit le Seigneur Yahvé.
15 Èmi kì yóò mú ki ó gbọ́ ọ̀rọ̀ ẹ̀gàn láti ọ̀dọ̀ àwọn orílẹ̀-èdè mọ́, ìwọ kì yóò jìyà ọ̀rọ̀ ìfiṣẹ̀sín láti ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn tàbí mú kí orílẹ̀-èdè rẹ ṣubú, ni Olúwa Olódùmarè wí.’”
« Je ne te laisserai plus entendre la honte des nations. Tu ne porteras plus l'opprobre des peuples, et tu ne feras plus trébucher ta nation, dit le Seigneur Yahvé.'"
16 Síwájú sí i ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá:
La parole de Yahvé me fut adressée, en ces termes:
17 “Ọmọ ènìyàn, nígbà tí àwọn ènìyàn Israẹli ń gbé ní ilẹ̀ wọn, wọ́n bà á jẹ́ nípa ìwà àti ìṣe wọn. Ìwà wọn dàbí nǹkan àkókò àwọn obìnrin ni ojú mi.
« Fils d'homme, lorsque la maison d'Israël habitait dans son pays, elle l'a souillé par ses voies et par ses actes. Leur conduite devant moi était comme la souillure d'une femme dans son impureté.
18 Nítorí náà mo tú ìbínú mi jáde sórí wọn nítorí wọn ti ta ẹ̀jẹ̀ sílẹ̀ àti nítorí pé wọ́n ti fi ère wọn ba a jẹ́.
C'est pourquoi j'ai répandu ma colère sur eux, à cause du sang qu'ils ont versé sur le pays, et parce qu'ils l'ont souillé par leurs idoles.
19 Mo tú wọn ká sí àárín àwọn orílẹ̀-èdè, a sì fọ́n wọn ká sí àwọn ìlú; mo ṣe ìdájọ́ wọn gẹ́gẹ́ bí ìwà àti ìṣe wọn.
Je les ai dispersés parmi les nations, et ils se sont dispersés dans les pays. Je les ai jugés selon leur voie et selon leurs actes.
20 Gbogbo ibi tí wọ́n lọ ní àárín àwọn orílẹ̀-èdè ni wọn ti sọ orúkọ mímọ́ mi di aláìmọ́, nítorí tí a sọ nípa wọn pé, ‘Ìwọ̀nyí ni àwọn ènìyàn Olúwa, síbẹ̀ wọn ní láti fi ilẹ̀ náà sílẹ̀.’
Lorsqu'ils arrivèrent dans les nations où ils allèrent, ils profanèrent mon saint nom, car on disait d'eux: « C'est le peuple de l'Éternel, et ils ont quitté son pays ».
21 Orúkọ mímọ́ mi jẹ́ mi lógún, èyí tí ilé Israẹli sọ di aláìmọ́ ni àárín àwọn orílẹ̀-èdè tí wọ́n ti lọ.
Mais moi, j'ai eu égard à mon saint nom, que la maison d'Israël avait profané parmi les nations où elle était allée.
22 “Nítorí náà, sọ fún ilé Israẹli, ‘Èyí ni Olúwa Olódùmarè wí: Kì í ṣe nítorí rẹ, ìwọ ilé Israẹli, ni èmi yóò ṣe ṣe àwọn nǹkan wọ̀nyí, ṣùgbọ́n nítorí orúkọ mímọ́ mi, èyí ti ìwọ ti sọ di aláìmọ́ ní àárín àwọn orílẹ̀-èdè tí ìwọ ti lọ.
« C'est pourquoi tu diras à la maison d'Israël: Le Seigneur Yahvé dit: « Je ne fais pas cela à cause de toi, maison d'Israël, mais à cause de mon saint nom, que tu as profané parmi les nations où tu es allé.
23 Èmi yóò fi jíjẹ́ mímọ́ orúkọ ńlá mi, èyí tí a ti sọ di aláìmọ́ hàn ni àárín àwọn orílẹ̀-èdè, orúkọ tí ìwọ ti sọ di aláìmọ́ ni àárín wọn. Nígbà náà àwọn orílẹ̀-èdè yóò mọ̀ pé èmi ni Olúwa, ni Olúwa Olódùmarè wí, nígbà tí mo bá fi ara mi hàn ni mímọ́ nípasẹ̀ yín ni iwájú wọn.
Je sanctifierai mon grand nom, qui a été profané parmi les nations, que vous avez profané parmi elles. Alors les nations sauront que je suis Yahvé, dit le Seigneur Yahvé, quand je serai sanctifié en vous sous leurs yeux.
24 “‘Nítorí èmi yóò mú yín jáde kúrò ni àwọn orílẹ̀-èdè náà; Èmi yóò ṣà yín jọ kúrò ní gbogbo àwọn ìlú náà; Èmi yóò sì mú yín padà sí ilẹ̀ ẹ̀yin tìkára yín.
"''Car je vous prendrai d'entre les nations, je vous rassemblerai de tous les pays, et je vous amènerai dans votre pays.
25 Èmi yóò wọ́n omi tó mọ́ sí yín lára ẹ̀yin yóò sì mọ́; Èmi yóò sì fọ̀ yín mọ́ kúrò nínú gbogbo ìwà èérí yin gbogbo àti kúrò nínú gbogbo òrìṣà yin.
Je ferai sur vous une aspersion d'eau pure, et vous serez purs. Je vous purifierai de toutes vos souillures et de toutes vos idoles.
26 Èmi yóò fún yín ni ọkàn tuntun, èmi yóò sì fi ẹ̀mí tuntun sínú yín; Èmi yóò sì mú ọkàn òkúta kúrò nínú yín, èmi yóò sì fi ọkàn ẹran fún yín.
Je vous donnerai un cœur nouveau et je mettrai en vous un esprit nouveau. J'ôterai de votre chair le cœur de pierre, et je vous donnerai un cœur de chair.
27 Èmi yóò fi ẹ̀mí mi sínú yín, èmi yóò sì mú ki ẹ tẹ̀lé àṣẹ mi, kí ẹ sì fiyèsí àti pa òfin mi mọ́.
Je mettrai mon esprit en vous, et je ferai en sorte que vous marchiez selon mes lois. Tu observeras mes ordonnances et tu les mettras en pratique.
28 Ẹ̀yin yóò sì máa gbé ilẹ̀ náà tí mo ti fi fún àwọn baba ńlá yín; ẹ̀yin yóò sì jẹ́ ènìyàn mi èmi yóò sì jẹ́ Ọlọ́run yín.
Vous habiterez dans le pays que j'ai donné à vos pères. Vous serez mon peuple, et je serai votre Dieu.
29 Èmi yóò sì gbà yín kúrò nínú gbogbo ìwà àìmọ́ yín. Èmi yóò pèsè ọkà, èmi yóò sì mú kí ó pọ̀ yanturu, èmi kì yóò sì mú ìyàn wá sí orí yín.
Je vous délivrerai de toutes vos impuretés. J'appellerai le blé et je le multiplierai, et je ne vous imposerai pas la famine.
30 Èmi yóò sọ èso àwọn igi yín àti ohun ọ̀gbìn oko yín di púpọ̀, nítorí kí ẹ̀yin kí ó má ṣe jìyà ìdójútì mọ́ láàrín àwọn orílẹ̀-èdè náà nítorí ìyàn.
Je multiplierai les fruits des arbres et les produits des champs, afin que vous n'ayez plus à souffrir de la famine parmi les nations.
31 Nígbà náà ni ẹ̀yin yóò rántí àwọn ọ̀nà búburú àti àwọn ìwà ìkà yín, ẹ̀yin yóò sì kórìíra ara yín fún ẹ̀ṣẹ̀ yín, ìwà tí kò bójúmu.
"''Alors vous vous souviendrez de vos mauvaises voies, de vos actions qui n'étaient pas bonnes, et vous vous dégoûterez à vos propres yeux de vos iniquités et de vos abominations.
32 Mo fẹ́ kí ẹ mọ̀ pé ń kò ṣe nǹkan wọ̀nyí nítorí yín, ni Olúwa Olódùmarè wí. Jẹ kí ojú kí ó tì yín, kí ẹ sì gba ẹ̀tẹ́ nítorí ìwà yín ẹ̀yin ilé Israẹli!
Je ne fais pas cela à cause de vous, dit le Seigneur Yahvé. « Que cela vous soit connu. Soyez honteux et confus de vos voies, maison d'Israël. »
33 “‘Èyí yìí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: Ní ọjọ́ tí mo wẹ̀ yín kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ yín gbogbo, èmi yóò ṣe àtúnṣe àwọn ìlú yín, wọn yóò sì ṣe àtúnkọ́ ìwólulẹ̀.
"'Le Seigneur Yahvé dit: « Le jour où je vous purifierai de toutes vos iniquités, je ferai en sorte que les villes soient habitées et que les ruines soient bâties.
34 Ilẹ̀ ahoro náà ní àwa yóò tún kọ́ ti kì yóò wà ní ahoro lójú àwọn tí ó ń gba ibẹ̀ kọjá mọ́.
Le pays qui était dévasté sera cultivé au lieu d'être une désolation aux yeux de tous ceux qui passaient par là.
35 Wọn yóò sọ wí pé, “Ilẹ̀ yìí tí ó ti wà ní ahoro tẹ́lẹ̀ ti dàbí ọgbà Edeni; àwọn ìlú tí ó wà ní wíwó lulẹ̀, ahoro tí a ti parun, ni àwa yóò mọdi sí tí yóò sì wà fún gbígbé ni ìsinsin yìí.”
Ils diront: « Cette terre désolée est devenue comme le jardin d'Eden ». Les villes désertes, désolées et en ruines sont fortifiées et habitées.'
36 Nígbà náà àwọn orílẹ̀-èdè tí ó wà ní àyíká yín tí ó kù yóò mọ̀ pé, Èmi Olúwa ti tún àwọn ohun tí ó bàjẹ́ kọ́, mo sì ti tún ohun tí ó di ìṣòfo gbìn. Èmi Olúwa ti sọ̀rọ̀, èmi yóò sì ṣe e?’
Alors les nations qui resteront autour de toi sauront que moi, Yahvé, j'ai bâti les ruines et planté les ruines. Moi, Yahvé, je l'ai dit et je le ferai. »
37 “Èyí yìí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè sọ: Lẹ́ẹ̀kan sí i èmi yóò yí sí ilé Israẹli, èmi yóò sì ṣe èyí fún wọn. Èmi yóò mú kí àwọn ènìyàn yín pọ̀ lọ́pọ̀lọ́pọ̀ bí àgùntàn,
"'Le Seigneur Yahvé dit: « Pour cela, d'ailleurs, je serai sollicité par la maison d'Israël, pour le faire pour eux: Je les multiplierai en hommes comme un troupeau.
38 kí ó pọ̀ lọ́pọ̀lọ́pọ̀ bí ọ̀wọ́ ẹran fún ìrúbọ ní Jerusalẹmu ní àsìkò àjọ̀dún tí a yàn. Ìlú ti a parun yóò wá kún fún agbo àwọn ènìyàn. Nígbà náà ni wọn yóò mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.”
Comme le troupeau pour les sacrifices, comme le troupeau de Jérusalem lors de ses fêtes, ainsi les villes désertes seront remplies de troupeaux d'hommes. Alors ils sauront que je suis Yahvé.'"

< Ezekiel 36 >