< Ezekiel 35 >

1 Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá:
Poleg tega je prišla k meni Gospodova beseda, rekoč:
2 “Ọmọ ènìyàn kọjú sí òkè Seiri; sọtẹ́lẹ̀ sí i,
»Človeški sin, naravnaj svoj obraz proti gori Seír in prerokuj zoper njo
3 kí o sì sọ wí pé, ‘Èyí ni Olúwa Olódùmarè wí: Èmí lòdì sí ọ, òkè Seiri, Èmi yóò sì na ọwọ́ mi síta ní ìlòdì sí ọ, èmi yóò sì mú kí ó di ahoro.
ter ji reci: ›Tako govori Gospod Bog: ›Glej, oh gora Seír, jaz sem zoper tebe in zoper tebe bom iztegnil svojo roko in naredil te bom najbolj zapuščeno.
4 Èmi yóò pa àwọn ìlú rẹ run, ìwọ yóò sì di ahoro. Nígbà náà ni ìwọ yóò mọ̀ pé èmi ni Olúwa.
Tvoja mesta bom opustošil in zapuščena boš in vedela boš, da jaz sem Gospod.
5 “‘Nítorí ìwọ dá ààbò bo ọ̀tẹ̀ àtayébáyé, tí ìwọ sì fi Israẹli lé idà lọ́wọ́, ní àsìkò ìdààmú wọn, ní àsìkò tí ìjìyà wọn dé góńgó,
Ker si imela neprestano sovraštvo in si s silo meča prelila kri Izraelovih otrok v času njihove katastrofe, v času, ko je njihova krivičnost imela konec.
6 nítorí náà bi mo ti wà láààyè, ni Olúwa Olódùmarè wí, èmi yóò fi ọ kalẹ̀ fún ìtàjẹ̀ sílẹ̀, ìtàjẹ̀ sílẹ̀ yóò sì lépa rẹ. Níwọ́n ìgbà tí ìwọ kò ti kórìíra ìtàjẹ̀ sílẹ̀, ìtàjẹ̀ sílẹ̀ yóò sì lépa rẹ.
Zato kakor jaz živim, ‹ govori Gospod Bog, ›te bom pripravil za kri in kri te bo zasledovala. Ker nisi sovražila krvi, te bo celo kri zasledovala.
7 Èmi yóò mú kí òkè Seiri di ahoro; ọ̀fọ̀ gbogbo àwọn tí ó ń lọ tí ó ń bọ̀ ní èmi yóò gé kúrò lára rẹ.
Tako bom goro Seír naredil najbolj zapuščeno in iz nje iztrebil tistega, ki gre skozi in tistega, ki se vrača.
8 Èmi yóò fi àwọn tí a pa kún orí òkè rẹ, àwọn tí a fi idà pa yóò ṣubú ní orí òkè rẹ, àti ní àárín àwọn òkè rẹ.
Njene gore bom napolnil z njenimi umorjenimi možmi. Na tvojih hribih in v tvojih dolinah in v vseh tvojih rekah bodo padli, ki so umorjeni z mečem.
9 Èmi yóò mú kí ó di ahoro títí láé, kò ní sí olùgbé ní ìlú rẹ. Nígbà náà ni ìwọ yóò mọ̀ pé èmi ni Olúwa.
Naredil te bom za neprestana opustošenja in tvoja mesta se ne bodo vrnila. In spoznali boste, da jaz sem Gospod.‹
10 “‘Nítorí tí ìwọ sọ pé, “Àwọn orílẹ̀-èdè àti ilẹ̀ méjì wọ̀nyí yóò jẹ́ tiwa, àwa yóò sì gbà wọ́n ní ìní,” bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé, Èmi Olúwa wà níbẹ̀,
Ker si rekla: ›Ta dva naroda in ti dve deželi bosta moji in mi bomo to vzeli v last; medtem ko je bil tam Gospod.
11 nítorí náà níwọ̀n ìgbà tí mo ti wà láààyè, ní Olúwa Olódùmarè wí, èmi yóò hùwà sí ọ ní ìbámu pẹ̀lú ìbínú àti owú tí o fihàn nínú ìkórìíra rẹ sí wọn, èmi yóò fi ara mi hàn ní àárín wọn, nígbà tí mo bá ṣe ìdájọ́ rẹ.
Zatorej, kakor jaz živim, ‹ govori Gospod Bog, ›storil bom celo glede na tvojo jezo in glede na tvojo zavist, ki si jo uporabila iz svojega sovraštva zoper njih; in jaz se bom med njimi dal spoznati, ko sem te sodil.
12 Nígbà náà ni ìwọ yóò mọ̀ pé, Èmi Olúwa ti gbọ́ gbogbo ohun ẹ̀gàn tí ìwọ ti sọ lòdì sí àwọn òkè Israẹli náà. Ìwọ wí pé, “A sọ wọ́n di ahoro, a sì fi wọ́n fún wa láti run.”
Vedela boš, da jaz sem Gospod in da sem slišal vsa tvoja bogokletja, ki si jih govorila zoper Izraelove gore, rekoč: ›Zapuščene so, dane so nam, da jih použijemo.‹
13 Ìwọ lérí sí mi, ó sì sọ̀rọ̀ lòdì sí mí láìsí ìdádúró, èmi sì gbọ́ ọ.
Tako ste se s svojimi usti bahali zoper mene in pomnožili svoje besede zoper mene. Jaz sem jih slišal. ‹
14 Èyí ni Olúwa Olódùmarè wí: Nígbà tí gbogbo ayé bá ń yọ̀, èmi yóò mú kí ó di ahoro.
Tako govori Gospod Bog: ›Ko se vsa zemlja razveseljuje, bom jaz tebe naredil zapuščeno.
15 Nítorí pé ìwọ ń yọ̀ nígbà tí ìní ilé Israẹli di ahoro, bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ ni èmi yóò ṣe hùwà sí ọ. Ìwọ yóò di ahoro, ìwọ òkè Seiri, ìwọ àti gbogbo ará Edomu. Nígbà náà, wọn yóò mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.’”
Kakor si se ti razveseljeval ob dediščini Izraelove hiše, ker je bila zapuščena, tako bom jaz storil tebi. Zapuščena boš, oh gora Seír in ves Edóm, celó ves. In spoznali bodo, da jaz sem Gospod.‹«

< Ezekiel 35 >