< Ezekiel 35 >

1 Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá:
És lőn az Úr beszéde hozzám, mondván:
2 “Ọmọ ènìyàn kọjú sí òkè Seiri; sọtẹ́lẹ̀ sí i,
Embernek fia! vesd tekintetedet Seir hegyére, és prófétálj ellene.
3 kí o sì sọ wí pé, ‘Èyí ni Olúwa Olódùmarè wí: Èmí lòdì sí ọ, òkè Seiri, Èmi yóò sì na ọwọ́ mi síta ní ìlòdì sí ọ, èmi yóò sì mú kí ó di ahoro.
És mondjad néki: Ezt mondja az Úr Isten: Ímé, én ellened megyek, Seir hegye, és kinyújtom kezemet reád, s teszlek pusztaságok pusztaságává.
4 Èmi yóò pa àwọn ìlú rẹ run, ìwọ yóò sì di ahoro. Nígbà náà ni ìwọ yóò mọ̀ pé èmi ni Olúwa.
Városaidat pusztaságra vetem, és te pusztulásra jutsz, és megtudod, hogy én vagyok az Úr.
5 “‘Nítorí ìwọ dá ààbò bo ọ̀tẹ̀ àtayébáyé, tí ìwọ sì fi Israẹli lé idà lọ́wọ́, ní àsìkò ìdààmú wọn, ní àsìkò tí ìjìyà wọn dé góńgó,
Mivelhogy örökkévaló gyűlölséget tartasz, és odaadád Izráel fiait a fegyver kezébe veszedelmök idején, az utolsó vétek idején;
6 nítorí náà bi mo ti wà láààyè, ni Olúwa Olódùmarè wí, èmi yóò fi ọ kalẹ̀ fún ìtàjẹ̀ sílẹ̀, ìtàjẹ̀ sílẹ̀ yóò sì lépa rẹ. Níwọ́n ìgbà tí ìwọ kò ti kórìíra ìtàjẹ̀ sílẹ̀, ìtàjẹ̀ sílẹ̀ yóò sì lépa rẹ.
Ennekokáért élek én, ezt mondja az Úr Isten, hogy vérré teszlek téged, és vér kergessen téged. Te nem gyűlölted a vért, a vér kergessen hát téged.
7 Èmi yóò mú kí òkè Seiri di ahoro; ọ̀fọ̀ gbogbo àwọn tí ó ń lọ tí ó ń bọ̀ ní èmi yóò gé kúrò lára rẹ.
És teszem Seir hegyét pusztaságok pusztaságává, és kiirtom belőle az átmenőt és visszatérőt.
8 Èmi yóò fi àwọn tí a pa kún orí òkè rẹ, àwọn tí a fi idà pa yóò ṣubú ní orí òkè rẹ, àti ní àárín àwọn òkè rẹ.
És betöltöm hegyeit megölöttjeivel; halmaid és völgyeid és minden mélységed: fegyverrel megölöttek hullanak beléjök.
9 Èmi yóò mú kí ó di ahoro títí láé, kò ní sí olùgbé ní ìlú rẹ. Nígbà náà ni ìwọ yóò mọ̀ pé èmi ni Olúwa.
Örök pusztasággá teszlek, és városaidat ne lakják, és megtudjátok, hogy én vagyok az Úr.
10 “‘Nítorí tí ìwọ sọ pé, “Àwọn orílẹ̀-èdè àti ilẹ̀ méjì wọ̀nyí yóò jẹ́ tiwa, àwa yóò sì gbà wọ́n ní ìní,” bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé, Èmi Olúwa wà níbẹ̀,
Mivelhogy ezt mondod: Az a két nemzet és az a két föld enyém lesz és örökségül bírjuk, holott az Úr ott volt;
11 nítorí náà níwọ̀n ìgbà tí mo ti wà láààyè, ní Olúwa Olódùmarè wí, èmi yóò hùwà sí ọ ní ìbámu pẹ̀lú ìbínú àti owú tí o fihàn nínú ìkórìíra rẹ sí wọn, èmi yóò fi ara mi hàn ní àárín wọn, nígbà tí mo bá ṣe ìdájọ́ rẹ.
Annakokáért élek én, ezt mondja az Úr Isten, hogy a te haragod és fölgerjedésed szerint cselekszem veled, a melylyel te cselekedtél irántok való gyűlölségedből; és megjelentem magamat közöttök, mikor megítéllek.
12 Nígbà náà ni ìwọ yóò mọ̀ pé, Èmi Olúwa ti gbọ́ gbogbo ohun ẹ̀gàn tí ìwọ ti sọ lòdì sí àwọn òkè Israẹli náà. Ìwọ wí pé, “A sọ wọ́n di ahoro, a sì fi wọ́n fún wa láti run.”
És megtudod, hogy én, az Úr, meghallottam minden szidalmadat, melyeket Izráel hegyei ellen mondtál, mondván: Elpusztultak, nékünk adattak ételül;
13 Ìwọ lérí sí mi, ó sì sọ̀rọ̀ lòdì sí mí láìsí ìdádúró, èmi sì gbọ́ ọ.
Így kérkedtetek ellenem szátokkal, s szórtátok ellenem beszédeiteket: én meghallottam!
14 Èyí ni Olúwa Olódùmarè wí: Nígbà tí gbogbo ayé bá ń yọ̀, èmi yóò mú kí ó di ahoro.
Így szól az Úr Isten: Az egész föld örömére pusztulást hozok rád.
15 Nítorí pé ìwọ ń yọ̀ nígbà tí ìní ilé Israẹli di ahoro, bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ ni èmi yóò ṣe hùwà sí ọ. Ìwọ yóò di ahoro, ìwọ òkè Seiri, ìwọ àti gbogbo ará Edomu. Nígbà náà, wọn yóò mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.’”
A mint te örültél Izráel háza örökségén azért, hogy elpusztult, úgy cselekszem veled; pusztává légy Seir hegye és mind egészen Edom, és megtudják, hogy én vagyok az Úr!

< Ezekiel 35 >