< Ezekiel 35 >

1 Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá:
HIKI mai la ka olelo a Iehova ia'u, i mai la,
2 “Ọmọ ènìyàn kọjú sí òkè Seiri; sọtẹ́lẹ̀ sí i,
E ke keiki a ke kanaka, e hooku e oe i kou maka ia mauna Seira, a e wanana ku e aku ia ia.
3 kí o sì sọ wí pé, ‘Èyí ni Olúwa Olódùmarè wí: Èmí lòdì sí ọ, òkè Seiri, Èmi yóò sì na ọwọ́ mi síta ní ìlòdì sí ọ, èmi yóò sì mú kí ó di ahoro.
A e olelo aku ia ia, Ke i mai nei Iehova ka Haku, penei; Eia hoi, ke ku e nei au ia oe, e mauna Seira, a e kikoo ku e aku au i kuu lima ia oe, a e hooneoneo loa aku au ia oe.
4 Èmi yóò pa àwọn ìlú rẹ run, ìwọ yóò sì di ahoro. Nígbà náà ni ìwọ yóò mọ̀ pé èmi ni Olúwa.
E hooneoneo aku au i kou mau kulanakauhale, a e neoneo oe; a e ike no oe owau no Iehova.
5 “‘Nítorí ìwọ dá ààbò bo ọ̀tẹ̀ àtayébáyé, tí ìwọ sì fi Israẹli lé idà lọ́wọ́, ní àsìkò ìdààmú wọn, ní àsìkò tí ìjìyà wọn dé góńgó,
No ka mea, he huhu mau kou, a ua hookahe oe i ke koko o na mamo a Iseraela, ma na lima o ka pahikaua i ko lakou wa popilikia, i ka wa i oki ai ko lakou hewa.
6 nítorí náà bi mo ti wà láààyè, ni Olúwa Olódùmarè wí, èmi yóò fi ọ kalẹ̀ fún ìtàjẹ̀ sílẹ̀, ìtàjẹ̀ sílẹ̀ yóò sì lépa rẹ. Níwọ́n ìgbà tí ìwọ kò ti kórìíra ìtàjẹ̀ sílẹ̀, ìtàjẹ̀ sílẹ̀ yóò sì lépa rẹ.
Nolaila, ma ko'u ola ana, wahi a Iehova ka Haku, e hoomakaukau aku au ia oe no ke koko, a hahai ke koko ia oe: i kou hoowahawaha ole i ke koko, e hahai ke koko ia oe.
7 Èmi yóò mú kí òkè Seiri di ahoro; ọ̀fọ̀ gbogbo àwọn tí ó ń lọ tí ó ń bọ̀ ní èmi yóò gé kúrò lára rẹ.
A e hoolilo aku au ia mauna Seira i neoneo loa, a e oki aku au mai laila aku i ka mea hele aku, a me ka mea hoi mai.
8 Èmi yóò fi àwọn tí a pa kún orí òkè rẹ, àwọn tí a fi idà pa yóò ṣubú ní orí òkè rẹ, àti ní àárín àwọn òkè rẹ.
A e hoopaapu i kona mauna i kona poe i pepehiia; ma kou mau puu, a ma kou mau papu, a ma kou mau muliwai a pau, e haule ai ka poe i pepehiia i ka pahikaua.
9 Èmi yóò mú kí ó di ahoro títí láé, kò ní sí olùgbé ní ìlú rẹ. Nígbà náà ni ìwọ yóò mọ̀ pé èmi ni Olúwa.
E hoolilo au ia oe i mau wahi neoneo mau, aole hoi e hoi mai koumau kulanakauhale; a e ike oukou owau no Iehova.
10 “‘Nítorí tí ìwọ sọ pé, “Àwọn orílẹ̀-èdè àti ilẹ̀ méjì wọ̀nyí yóò jẹ́ tiwa, àwa yóò sì gbà wọ́n ní ìní,” bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé, Èmi Olúwa wà níbẹ̀,
No ka mea, ua olelo oe, No'u no keia mau lahuikanaka elua, a me keia mau aina elua, a e hoolilo ia mea no makou; malaila no nae o Iehova:
11 nítorí náà níwọ̀n ìgbà tí mo ti wà láààyè, ní Olúwa Olódùmarè wí, èmi yóò hùwà sí ọ ní ìbámu pẹ̀lú ìbínú àti owú tí o fihàn nínú ìkórìíra rẹ sí wọn, èmi yóò fi ara mi hàn ní àárín wọn, nígbà tí mo bá ṣe ìdájọ́ rẹ.
Nolaila, ma ko'u ola ana, wahi a Iehova ka Haku, e hana aku wau e like me kou huhu, a e like me kou huahua au i hana ai no kou hoowahawaha ia lakou; a e hoike au ia'u iho iwaena o lakou, aia lilo no oe i ka hoopaiia e au.
12 Nígbà náà ni ìwọ yóò mọ̀ pé, Èmi Olúwa ti gbọ́ gbogbo ohun ẹ̀gàn tí ìwọ ti sọ lòdì sí àwọn òkè Israẹli náà. Ìwọ wí pé, “A sọ wọ́n di ahoro, a sì fi wọ́n fún wa láti run.”
A e ike oe owau no Iehova, a ua lohe hoi au i na olelo hoino wale au i hoino ai i na mauna o ka Iseraela, i ka i ana, Ua hooneoneoia lakou, ua haawiia mai lakou no makou e pau i ka aiia.
13 Ìwọ lérí sí mi, ó sì sọ̀rọ̀ lòdì sí mí láìsí ìdádúró, èmi sì gbọ́ ọ.
Pela hoi, me ko oukou waha ua haanou ku e oukou ia'u, ua hoonui oukou i ka oukou mau olelo ku e ia'u; a ua lohe no hoi au ia mau mea.
14 Èyí ni Olúwa Olódùmarè wí: Nígbà tí gbogbo ayé bá ń yọ̀, èmi yóò mú kí ó di ahoro.
Ke i mai nei Iehova ka Haku, penei; Aia hauoli ka honua a pau, e hooneoneo aku au ia oe.
15 Nítorí pé ìwọ ń yọ̀ nígbà tí ìní ilé Israẹli di ahoro, bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ ni èmi yóò ṣe hùwà sí ọ. Ìwọ yóò di ahoro, ìwọ òkè Seiri, ìwọ àti gbogbo ará Edomu. Nígbà náà, wọn yóò mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.’”
Me oe i hanoli ai i ka hooilina o ka ohana a Iseraela no kona neoneo ana, pela e hana aku ai au ia oe; e neoneo auanei oe, e mauna Seira, a me Edoma a pau, pau pu ia; a e ike no lakou owau no Iehova.

< Ezekiel 35 >