< Ezekiel 35 >

1 Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá:
Ningĩ kiugo kĩa Jehova nĩkĩanginyĩrĩire, ngĩĩrwo atĩrĩ:
2 “Ọmọ ènìyàn kọjú sí òkè Seiri; sọtẹ́lẹ̀ sí i,
“Mũrũ wa mũndũ, erekeria ũthiũ waku Kĩrĩma gĩa Seiru: kĩrathĩre ũhoro wa gũgĩũkĩrĩra,
3 kí o sì sọ wí pé, ‘Èyí ni Olúwa Olódùmarè wí: Èmí lòdì sí ọ, òkè Seiri, Èmi yóò sì na ọwọ́ mi síta ní ìlòdì sí ọ, èmi yóò sì mú kí ó di ahoro.
ũkĩĩre atĩrĩ: ‘Mwathani Jehova ekuuga ũũ: Wee Kĩrĩma gĩa Seiru, nĩngũgũũkĩrĩra, na ngũtambũrũkĩrie guoko gwakwa nginya ndũme wanangĩke ũkire ihooru.
4 Èmi yóò pa àwọn ìlú rẹ run, ìwọ yóò sì di ahoro. Nígbà náà ni ìwọ yóò mọ̀ pé èmi ni Olúwa.
Nĩngatũma matũũra maku manangwo nawe nĩũgaakira ihooru. Hĩndĩ ĩyo nĩũkamenya atĩ niĩ nĩ niĩ Jehova.
5 “‘Nítorí ìwọ dá ààbò bo ọ̀tẹ̀ àtayébáyé, tí ìwọ sì fi Israẹli lé idà lọ́wọ́, ní àsìkò ìdààmú wọn, ní àsìkò tí ìjìyà wọn dé góńgó,
“‘Tondũ wee-rĩ, kuuma o matukũ ma tene nĩũtũũrĩtie muku na andũ a Isiraeli na ũkĩmaneana mooragwo na rũhiũ rwa njora, rĩrĩa maarĩ na mũtino, o hĩndĩ ĩrĩa iherithia rĩao rĩehĩrĩire,
6 nítorí náà bi mo ti wà láààyè, ni Olúwa Olódùmarè wí, èmi yóò fi ọ kalẹ̀ fún ìtàjẹ̀ sílẹ̀, ìtàjẹ̀ sílẹ̀ yóò sì lépa rẹ. Níwọ́n ìgbà tí ìwọ kò ti kórìíra ìtàjẹ̀ sílẹ̀, ìtàjẹ̀ sílẹ̀ yóò sì lépa rẹ.
nĩ ũndũ ũcio, Mwathani Jehova oigĩte atĩrĩ, ti-itherũ o ta ũrĩa niĩ ndũũraga muoyo-rĩ, nĩngakũneana ũitwo thakame, nayo nĩĩgathingatana nawe. Kuona atĩ ndwamenire ũiti wa thakame-rĩ, ũiti wa thakame nĩũgaathingatana nawe.
7 Èmi yóò mú kí òkè Seiri di ahoro; ọ̀fọ̀ gbogbo àwọn tí ó ń lọ tí ó ń bọ̀ ní èmi yóò gé kúrò lára rẹ.
Nakĩo Kĩrĩma gĩa Seiru nĩngatũma kĩanangwo gĩkire ihooru, na njũrage arĩa othe mokaga kuo na makoimagara.
8 Èmi yóò fi àwọn tí a pa kún orí òkè rẹ, àwọn tí a fi idà pa yóò ṣubú ní orí òkè rẹ, àti ní àárín àwọn òkè rẹ.
Nĩngaiyũria irĩma ciaku na arĩa moragĩtwo; arĩa moragĩtwo na rũhiũ rwa njora makaagũa tũrĩma-inĩ twaku, na ituamba-inĩ ciaku, o na mĩkuru-inĩ yaku yothe.
9 Èmi yóò mú kí ó di ahoro títí láé, kò ní sí olùgbé ní ìlú rẹ. Nígbà náà ni ìwọ yóò mọ̀ pé èmi ni Olúwa.
Nĩngatũma ũtũũre ũkirĩte ihooru nginya tene, namo matũũra maku matigatũũrwo. Hĩndĩ ĩyo nĩũkamenya atĩ niĩ nĩ niĩ Jehova.
10 “‘Nítorí tí ìwọ sọ pé, “Àwọn orílẹ̀-èdè àti ilẹ̀ méjì wọ̀nyí yóò jẹ́ tiwa, àwa yóò sì gbà wọ́n ní ìní,” bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé, Èmi Olúwa wà níbẹ̀,
“‘Tondũ uugĩte atĩrĩ, “Ndũrĩrĩ ici cierĩ na mabũrũri maya nĩigatuĩka ciitũ, na tũciĩgwatĩre,” o na gwatuĩka atĩ niĩ Jehova ndaarĩ kuo,
11 nítorí náà níwọ̀n ìgbà tí mo ti wà láààyè, ní Olúwa Olódùmarè wí, èmi yóò hùwà sí ọ ní ìbámu pẹ̀lú ìbínú àti owú tí o fihàn nínú ìkórìíra rẹ sí wọn, èmi yóò fi ara mi hàn ní àárín wọn, nígbà tí mo bá ṣe ìdájọ́ rẹ.
nĩ ũndũ ũcio, Mwathani Jehova oigĩte atĩrĩ, ti-itherũ o ta ũrĩa niĩ ndũũraga muoyo-rĩ, nĩngagwĩka maũndũ maringaine na marakara maku na ũiru waku, iria wonanirie ũrĩ na rũmena harĩo, na nĩngatũma menyeke gatagatĩ-inĩ kao hĩndĩ ĩrĩa ngaamũtuĩra ciira.
12 Nígbà náà ni ìwọ yóò mọ̀ pé, Èmi Olúwa ti gbọ́ gbogbo ohun ẹ̀gàn tí ìwọ ti sọ lòdì sí àwọn òkè Israẹli náà. Ìwọ wí pé, “A sọ wọ́n di ahoro, a sì fi wọ́n fún wa láti run.”
Hĩndĩ ĩyo nĩũkamenya atĩ niĩ Jehova nĩnjiguĩte maũndũ mothe ma kĩnyararo marĩa warĩtie ma gũũkĩrĩra irĩma cia bũrũri wa Isiraeli. Woigire atĩrĩ, “Nĩcianangĩtwo na ikaneanwo kũrĩ ithuĩ tũcitambuure.”
13 Ìwọ lérí sí mi, ó sì sọ̀rọ̀ lòdì sí mí láìsí ìdádúró, èmi sì gbọ́ ọ.
Nĩmwerahire na mũkĩaria maũndũ ma kũnjũkĩrĩra mũtekwĩgirĩrĩria na niĩ ngĩigua maũndũ macio.
14 Èyí ni Olúwa Olódùmarè wí: Nígbà tí gbogbo ayé bá ń yọ̀, èmi yóò mú kí ó di ahoro.
Mwathani Jehova ekuuga ũũ: Rĩrĩa thĩ yothe ĩgaakorwo ĩgĩcanjamũka, nĩngatũma ũkire ihooru.
15 Nítorí pé ìwọ ń yọ̀ nígbà tí ìní ilé Israẹli di ahoro, bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ ni èmi yóò ṣe hùwà sí ọ. Ìwọ yóò di ahoro, ìwọ òkè Seiri, ìwọ àti gbogbo ará Edomu. Nígbà náà, wọn yóò mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.’”
Tondũ nĩwakenire rĩrĩa igai rĩa andũ a nyũmba ya Isiraeli rĩanangirwo rĩgĩkira ihooru-rĩ, ũguo noguo ngagwĩka o nawe. Wee Kĩrĩma gĩa Seiru, nĩũgakirio ihooru, wee mwene o na bũrũri wa Edomu wothe. Hĩndĩ ĩyo nĩmakamenya atĩ niĩ nĩ niĩ Jehova.’”

< Ezekiel 35 >