< Ezekiel 35 >

1 Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá:
And the word of the Lord was maad to me,
2 “Ọmọ ènìyàn kọjú sí òkè Seiri; sọtẹ́lẹ̀ sí i,
and he seide, Thou, sone of man, sette thi face ayens the hil of Seir; and thou schalt profesie to it, and thou schalt seie to it,
3 kí o sì sọ wí pé, ‘Èyí ni Olúwa Olódùmarè wí: Èmí lòdì sí ọ, òkè Seiri, Èmi yóò sì na ọwọ́ mi síta ní ìlòdì sí ọ, èmi yóò sì mú kí ó di ahoro.
The Lord God seith these thingis, Thou hil of Seir, lo! Y to thee; Y schal stretche forth myn hond on thee, and Y schal yyue thee desolat and forsakun.
4 Èmi yóò pa àwọn ìlú rẹ run, ìwọ yóò sì di ahoro. Nígbà náà ni ìwọ yóò mọ̀ pé èmi ni Olúwa.
Y schal distrie thi citees, and thou schalt be forsakun; and thou schalt wite, that Y am the Lord.
5 “‘Nítorí ìwọ dá ààbò bo ọ̀tẹ̀ àtayébáyé, tí ìwọ sì fi Israẹli lé idà lọ́wọ́, ní àsìkò ìdààmú wọn, ní àsìkò tí ìjìyà wọn dé góńgó,
For thou were an enemye euerlastynge, and closidist togidere the sonis of Israel in to the hondis of swerd, in the tyme of her turment, in the tyme of the laste wickidnesse;
6 nítorí náà bi mo ti wà láààyè, ni Olúwa Olódùmarè wí, èmi yóò fi ọ kalẹ̀ fún ìtàjẹ̀ sílẹ̀, ìtàjẹ̀ sílẹ̀ yóò sì lépa rẹ. Níwọ́n ìgbà tí ìwọ kò ti kórìíra ìtàjẹ̀ sílẹ̀, ìtàjẹ̀ sílẹ̀ yóò sì lépa rẹ.
therfor Y lyue, seith the Lord God, for Y schal yyue thee to blood, and blood schal pursue thee; and sithen thou hatidist blood, blood schal pursue thee.
7 Èmi yóò mú kí òkè Seiri di ahoro; ọ̀fọ̀ gbogbo àwọn tí ó ń lọ tí ó ń bọ̀ ní èmi yóò gé kúrò lára rẹ.
And Y schal yyue the hil of Seir desolat and forsakun, and Y schal take awei fro it a goere and a comere ayen;
8 Èmi yóò fi àwọn tí a pa kún orí òkè rẹ, àwọn tí a fi idà pa yóò ṣubú ní orí òkè rẹ, àti ní àárín àwọn òkè rẹ.
and Y schal fille the hillis therof with the careyns of her slayn men. Men slayn by swerd schulen falle doun in thi litle hillis, and in thi valeys, and in thi strondis.
9 Èmi yóò mú kí ó di ahoro títí láé, kò ní sí olùgbé ní ìlú rẹ. Nígbà náà ni ìwọ yóò mọ̀ pé èmi ni Olúwa.
Y schal yyue thee in to euerlastynge wildirnessis, and thi citees schulen not be enhabitid; and ye schulen wite, that Y am the Lord God.
10 “‘Nítorí tí ìwọ sọ pé, “Àwọn orílẹ̀-èdè àti ilẹ̀ méjì wọ̀nyí yóò jẹ́ tiwa, àwa yóò sì gbà wọ́n ní ìní,” bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé, Èmi Olúwa wà níbẹ̀,
For thou seidist, Twei folkis and twei londis schulen be myne, and Y schal welde tho bi eritage, whanne the Lord was there;
11 nítorí náà níwọ̀n ìgbà tí mo ti wà láààyè, ní Olúwa Olódùmarè wí, èmi yóò hùwà sí ọ ní ìbámu pẹ̀lú ìbínú àti owú tí o fihàn nínú ìkórìíra rẹ sí wọn, èmi yóò fi ara mi hàn ní àárín wọn, nígbà tí mo bá ṣe ìdájọ́ rẹ.
therfor Y lyue, seith the Lord God, for Y schal do bi thi wraththe, and bi thin enuye, which thou didist, hatinge hem, and Y schal be made knowun bi hem, whanne Y schal deme thee;
12 Nígbà náà ni ìwọ yóò mọ̀ pé, Èmi Olúwa ti gbọ́ gbogbo ohun ẹ̀gàn tí ìwọ ti sọ lòdì sí àwọn òkè Israẹli náà. Ìwọ wí pé, “A sọ wọ́n di ahoro, a sì fi wọ́n fún wa láti run.”
and thou schalt wite, that Y am the Lord. Y herde alle thi schenschipis, whiche thou spakist of the hillis of Israel, and seidist, The hillis of Israel ben forsakun, and ben youun to vs, for to deuoure.
13 Ìwọ lérí sí mi, ó sì sọ̀rọ̀ lòdì sí mí láìsí ìdádúró, èmi sì gbọ́ ọ.
And ye han rise on me with youre mouth, and ye han deprauyd ayens me; Y herde youre wordis.
14 Èyí ni Olúwa Olódùmarè wí: Nígbà tí gbogbo ayé bá ń yọ̀, èmi yóò mú kí ó di ahoro.
The Lord God seith these thingis, While al the lond is glad, Y schal turne thee in to wildernesse.
15 Nítorí pé ìwọ ń yọ̀ nígbà tí ìní ilé Israẹli di ahoro, bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ ni èmi yóò ṣe hùwà sí ọ. Ìwọ yóò di ahoro, ìwọ òkè Seiri, ìwọ àti gbogbo ará Edomu. Nígbà náà, wọn yóò mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.’”
As thou haddist ioie on the eritage of the hous of Israel, for it was distried, so Y schal do to thee; the hil of Seir schal be distried, and al Ydumee; and thei schulen wite, that Y am the Lord.

< Ezekiel 35 >