< Ezekiel 35 >

1 Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá:
Yahweh gave me another message. He said,
2 “Ọmọ ènìyàn kọjú sí òkè Seiri; sọtẹ́lẹ̀ sí i,
“You human, turn toward Edom and prophesy what will happen to its people. Say that this is what Yahweh says to them:
3 kí o sì sọ wí pé, ‘Èyí ni Olúwa Olódùmarè wí: Èmí lòdì sí ọ, òkè Seiri, Èmi yóò sì na ọwọ́ mi síta ní ìlòdì sí ọ, èmi yóò sì mú kí ó di ahoro.
‘You who live near Seir Mountain [in Edom], I am opposed to you, and I will use my power [MTY] to strike you and cause your country to become a wasteland.
4 Èmi yóò pa àwọn ìlú rẹ run, ìwọ yóò sì di ahoro. Nígbà náà ni ìwọ yóò mọ̀ pé èmi ni Olúwa.
I will cause your country to be ruined and desolate. When that happens, people will know that I, Yahweh, [have the power to do what I say that I will do].
5 “‘Nítorí ìwọ dá ààbò bo ọ̀tẹ̀ àtayébáyé, tí ìwọ sì fi Israẹli lé idà lọ́wọ́, ní àsìkò ìdààmú wọn, ní àsìkò tí ìjìyà wọn dé góńgó,
You have always been enemies of the Israeli people. You [rejoiced] when they experienced a great disaster: [their enemies attacked them with] swords, when I punished them [for the sins that they had committed].
6 nítorí náà bi mo ti wà láààyè, ni Olúwa Olódùmarè wí, èmi yóò fi ọ kalẹ̀ fún ìtàjẹ̀ sílẹ̀, ìtàjẹ̀ sílẹ̀ yóò sì lépa rẹ. Níwọ́n ìgbà tí ìwọ kò ti kórìíra ìtàjẹ̀ sílẹ̀, ìtàjẹ̀ sílẹ̀ yóò sì lépa rẹ.
Therefore, I, Yahweh the Lord, declare that as surely as I am alive, I will allow [your enemies] to slaughter [MTY] you and continue to slaughter you. You were happy when [LIT] others were slaughtered;
7 Èmi yóò mú kí òkè Seiri di ahoro; ọ̀fọ̀ gbogbo àwọn tí ó ń lọ tí ó ń bọ̀ ní èmi yóò gé kúrò lára rẹ.
so I will cause Seir Mountain to be abandoned/deserted, and I will get rid of anyone who enters it or leaves it.
8 Èmi yóò fi àwọn tí a pa kún orí òkè rẹ, àwọn tí a fi idà pa yóò ṣubú ní orí òkè rẹ, àti ní àárín àwọn òkè rẹ.
I will cause your mountains to be filled with [the corpses of] those who have been killed. The corpses of those who have been killed by [your enemies’] swords will lie on your hills and in your valleys and in all your ravines.
9 Èmi yóò mú kí ó di ahoro títí láé, kò ní sí olùgbé ní ìlú rẹ. Nígbà náà ni ìwọ yóò mọ̀ pé èmi ni Olúwa.
I will cause your land to be deserted forever. No one will live in your towns again. When that happens, you will know that I, Yahweh, [have the power to do what I say that I will do].
10 “‘Nítorí tí ìwọ sọ pé, “Àwọn orílẹ̀-èdè àti ilẹ̀ méjì wọ̀nyí yóò jẹ́ tiwa, àwa yóò sì gbà wọ́n ní ìní,” bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé, Èmi Olúwa wà níbẹ̀,
You people said, “Israel and Judah will become ours. We will take over their territory!” You said that even though I, Yahweh, was still there [and protecting them].
11 nítorí náà níwọ̀n ìgbà tí mo ti wà láààyè, ní Olúwa Olódùmarè wí, èmi yóò hùwà sí ọ ní ìbámu pẹ̀lú ìbínú àti owú tí o fihàn nínú ìkórìíra rẹ sí wọn, èmi yóò fi ara mi hàn ní àárín wọn, nígbà tí mo bá ṣe ìdájọ́ rẹ.
Therefore, I, Yahweh the Lord, declare that as surely as I am alive, I will punish [MTY] you for being angry with my people, envying them, and hating them.
12 Nígbà náà ni ìwọ yóò mọ̀ pé, Èmi Olúwa ti gbọ́ gbogbo ohun ẹ̀gàn tí ìwọ ti sọ lòdì sí àwọn òkè Israẹli náà. Ìwọ wí pé, “A sọ wọ́n di ahoro, a sì fi wọ́n fún wa láti run.”
Then you will know that I, Yahweh, have heard all the disgusting things that you have said about the mountains in Israel. You said that they have been ruined/devastated, and that they have been given to you to occupy [MET].
13 Ìwọ lérí sí mi, ó sì sọ̀rọ̀ lòdì sí mí láìsí ìdádúró, èmi sì gbọ́ ọ.
When you insulted me, I heard all that you said about me.
14 Èyí ni Olúwa Olódùmarè wí: Nígbà tí gbogbo ayé bá ń yọ̀, èmi yóò mú kí ó di ahoro.
So this is what I, Yahweh the Lord, say: You people who live on Seir Mountain and in all the other places in Edom, when I cause your land to become desolate, everyone in the entire world will rejoice.
15 Nítorí pé ìwọ ń yọ̀ nígbà tí ìní ilé Israẹli di ahoro, bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ ni èmi yóò ṣe hùwà sí ọ. Ìwọ yóò di ahoro, ìwọ òkè Seiri, ìwọ àti gbogbo ará Edomu. Nígbà náà, wọn yóò mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.’”
You were happy when the land [MTY] of the Israeli people became desolate, so I will cause your land to become desolate. When that happens, people will know that I, Yahweh, [have the power to do what I say that I will do].’”

< Ezekiel 35 >