< Ezekiel 34 >

1 Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ́ mi wá:
És lőn az Úrnak beszéde hozzám, mondván:
2 “Ọmọ ènìyàn, fi àsọtẹ́lẹ̀ tako Olùṣọ́-àgùntàn Israẹli; sọtẹ́lẹ̀ fún wọn pé: ‘Èyí yìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Ègbé ni fún olùṣọ́-àgùntàn Israẹli tí ó ń tọ́jú ara wọn nìkan! Ṣé ó dára kí olùṣọ́-àgùntàn ṣaláì tọ́jú agbo ẹran?
Embernek fia! prófétálj Izráel pásztorai felől, prófétálj és mondjad nékik, a pásztoroknak: Így szól az Úr Isten: Jaj Izráel pásztorainak, a kik önmagokat legeltették! Avagy nem a nyájat kell-é legeltetni a pásztoroknak?
3 Ìwọ jẹ wàrà. O sì wọ aṣọ olówùú sí ara rẹ, o sì ń pa ẹran tí ó wù ọ́, ṣùgbọ́n ìwọ kò tọ́jú agbo ẹran.
A tejet megettétek, és a gyapjúval ruházkodtatok, a hízottat megöltétek; a nyájat nem legeltettétek.
4 Ìwọ kò ì tí ì mú aláìlágbára lára le tàbí wo aláìsàn sàn tàbí di ọgbẹ́ fún ẹni tí o fi ara pa. Ìwọ kò í tí ì mú aṣáko padà tàbí wá ẹni tí ó nù. Ìwọ ṣe àkóso wọn ní ọ̀nà lílé pẹ̀lú ìwà òǹrorò.
A gyöngéket nem erősítettétek, és a beteget nem gyógyítottátok, s a megtöröttet nem kötözgettétek, s az elűzöttet vissza nem hoztátok és az elveszettet meg nem kerestétek, hanem keményen és kegyetlenül uralkodtatok rajtok;
5 Nítorí náà wọn fọ́n káàkiri nítorí àìsí olùṣọ́-àgùntàn, nígbà tí wọ́n fọ́nká tán wọn di ìjẹ fún gbogbo ẹranko búburú.
Szétszóródtak hát pásztor nélkül, és lőnek mindenféle mezei vadak eledelévé, és szétszóródtak;
6 Àgùntàn mi n rin ìrìn àrè kiri ní gbogbo àwọn òkè gíga àti òkè kékeré. A fọ́n wọn ká gbogbo orí ilẹ̀ ẹni kankan kò sì wá wọn.
Tévelygett nyájam minden hegyen s minden magas halmon, és az egész föld színén szétszóródott az én nyájam, s nem volt, a ki keresné, sem a ki tudakozódnék utána.
7 “‘Nítorí náà, ìwọ olùṣọ́-àgùntàn, gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa.
Annakokáért, ti pásztorok, halljátok meg az Úr beszédét:
8 Níwọ́n ìgbà tí mo wà láààyè ní Olúwa Olódùmarè wí, nítorí pé agbo ẹran mi kò ní olùṣọ́-àgùntàn nítorí tí a kọ̀ wọ́n, tì wọ́n sì di ìjẹ fún ẹranko búburú gbogbo àti pé, nítorí tí àwọn olùṣọ́-àgùntàn mi kò ṣe àwárí agbo ẹran mi, ṣùgbọ́n wọn ń ṣe ìtọ́jú ara wọn dípò ìtọ́jú agbo ẹran mi,
Élek én, ezt mondja az Úr Isten, mivelhogy az én nyájam ragadománynyá lőn, és lőn az én nyájam mindenféle mezei vadak eledelévé, pásztor hiányában, és nem keresték az én pásztoraim az én nyájamat, hanem legeltették a pásztorok önmagokat, és az én nyájamat nem legeltették;
9 nítorí náà, ẹ̀yin olùṣọ́-àgùntàn, gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa.
Ennekokáért, ti pásztorok, halljátok meg az Úr beszédét:
10 Èyí yìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Èmi ṣe ìlòdì sí àwọn Olùṣọ́-àgùntàn, èmi yóò sì béèrè agbo ẹran mi lọ́wọ́ wọn. Èmi yóò sì mú wọn dẹ́kun àti máa darí agbo ẹran mi, tí àwọn olùṣọ́-àgùntàn náà kò sì ní lè bọ́ ara wọn mọ́. Èmi yóò gba agbo ẹran mi kúrò ni ẹnu wọn, kì yóò sì jẹ́ oúnjẹ fún wọn mọ́.
Így szól az Úr Isten: Ímé, megyek a pásztorok ellen, és előkérem nyájamat az ő kezökből, s megszüntetem őket a nyáj legeltetésétől, és nem legeltetik többé a pásztorok önmagokat, s kiragadom juhaimat szájokból, hogy ne legyenek nékik ételül.
11 “‘Nítorí èyí ni Olúwa Olódùmarè wí: Èmi fúnra mi yóò wá àgùntàn mi kiri, èmi yóò sì ṣe àwárí wọn.
Mert így szól az Úr Isten: Ímé, én magam keresem meg nyájamat, és magam tudakozódom utána.
12 Gẹ́gẹ́ bí olùṣọ́-àgùntàn ṣe fojú tó agbo ẹran rẹ̀ tí ó fọ́nká nígbà tí ó wà pẹ̀lú wọn, bẹ́ẹ̀ ni èmi yóò ṣe fojú tó àgùntàn mi. Èmi yóò gbá wọn kúrò ni gbogbo ibi tí wọ́n fọ́nká sí ni ọjọ́ ìkùùkuu àti òkùnkùn.
Miképen a pásztor tudakozódik nyája után, a mely napon ott áll elszéledt juhai között; így tudakozódom nyájam után, és kiszabadítom őket minden helyről, a hova szétszóródtak a felhőnek s borúnak napján.
13 Èmi yóò mú wọn jáde kúrò ní àwọn orílẹ̀-èdè, èmi yóò sì kó wọn jọ láti inú àwọn ìlú, èmi yóò sì mú wọn wá sí ilẹ̀ ara wọn. Èmi yóò mú wọn jẹ ni orí àwọn òkè gíga Israẹli, ni àárín àwọn òkè àti ní gbogbo ibùdó ilẹ̀ náà.
És kihozom őket a népek közül s egybegyűjtöm a földekről, és beviszem őket az ő földjökre, és legeltetem őket Izráel hegyein, a mélységekben s a föld minden lakóhelyén.
14 Èmi yóò ṣe ìtọ́jú wọn ní pápá oko tútù dáradára, àní orí àwọn òkè gíga ti Israẹli ni yóò jẹ́ ilẹ̀ ìjẹ koríko wọ́n. Níbẹ̀ wọn yóò dùbúlẹ̀ ní ilẹ̀ ìjẹ koríko dídára, níbẹ̀ wọn yóò jẹun ní pápá oko tútù tí ó dara ní orí òkè ti Israẹli.
Jó legelőn legeltetem őket, és Izráel magasságos hegyein leszen akluk, ott feküsznek jó akolban, s kövér legelőn legelnek Izráel hegyein.
15 Èmi fúnra mi yóò darí àgùntàn mi, èmi yóò mú wọn dùbúlẹ̀, ni Olúwa Olódùmarè wí.
Én magam legeltetem nyájamat, s én nyugosztom meg őket, ezt mondja az Úr Isten;
16 Èmi yóò ṣe àwárí àwọn tí ó nú, èmi yóò mú àwọn tí ó ń rin ìrìn àrè kiri padà. Èmi yóò di ọgbẹ́ àwọn tí ó fi ara pa, èmi yóò sì fún àwọn aláìlágbára ni okun, ṣùgbọ́n àwọn tí ó sanra tí ó sì ni agbára ní èmi yóò parun. Èmi yóò ṣe olùṣọ́ àwọn agbo ẹran náà pẹ̀lú òdodo.
Az elveszettet megkeresem, s az elűzöttet visszahozom, s a megtöröttet kötözgetem, s a beteget erősítem; és a kövéret s erőset elvesztem, és legeltetem őket úgy, mint illik.
17 “‘Ní tìrẹ, agbo ẹran mi, èyí yìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Èmi yóò ṣe ìdájọ́ láàrín àgùntàn kan àti òmíràn, àti láàrín àgbò àti ewúrẹ́.
Ti pedig, én juhaim, így szól az Úr Isten, ímé én ítéletet teszek juh és juh között, a kosok és bakok közt.
18 Ṣé oúnjẹ jíjẹ ní pápá oko tútù dídára kò tó yín! Ṣé ó jẹ́ dandan fún ọ láti fi ẹsẹ̀ tẹ pápá oko tútù rẹ tí ó kù? Ṣé omi tí ó tòrò kò tó fún yín ní mímu? Ṣe dandan ni kí ó fi ẹrẹ̀ yí ẹsẹ̀ yín?
Avagy kevés-é néktek, hogy a jó legelőt legelitek, hogy még legelőitek maradékát lábaitokkal eltapodjátok? és hogy a víz tisztáját iszszátok, hogy még a maradékát lábaitokkal felzavarjátok?
19 Ṣé dandan ni kí agbo ẹran mi jẹ́ koríko tí ẹ ti tẹ̀ mọ́lẹ̀, kí wọn sì mú omi tí wọ́n ti fi ẹsẹ̀ wọn sọ di ẹrẹ̀?
És az én juhaim a ti lábaitok tapodását legelik, s lábaitok zavarását iszszák!
20 “‘Nítorí náà, èyí yìí ni Olúwa Olódùmarè wí fún wọn: Wò ó, èmi fúnra mi yóò ṣe ìdájọ́ láàrín àgùntàn tí ó sanra àti èyí tí ó rù.
Annakokáért így szól az Úr Isten hozzájok: Ímé én, én teszek ítéletet kövér és ösztövér juh között,
21 Nítorí ti ìwọ sún síwájú pẹ̀lú ìhà àti èjìká, tí ìwọ sì kan aláìlágbára àgùntàn pẹ̀lú ìwo rẹ títí ìwọ fi lé wọn lọ,
Mivelhogy oldallal és vállal eltaszíttok és szarvaitokkal elökleltek minden erőtelent, míg szétszórván, azokat kiűzitek;
22 Èmi yóò gba agbo ẹran mi là, a kì yóò sì kò wọ́n tì mọ́. Èmi yóò ṣe ìdájọ́ láàrín àgùntàn kan àti òmíràn.
És megtartom az én juhaimat, hogy többé ne legyenek zsákmányul, és ítéletet teszek juh és juh között.
23 Èmi yóò fi Olùṣọ́-àgùntàn kan ṣe olórí wọn, ìránṣẹ́ mi Dafidi, òun yóò sì tọ́jú wọn; òun yóò bọ́ wọn yóò sì jẹ́ Olùṣọ́-àgùntàn wọn.
És állatok föléjök egyetlenegy pásztort, hogy legeltesse őket: az én szolgámat, Dávidot, ő legelteti őket s ő lesz nékik pásztoruk.
24 Èmi Olúwa yóò sì jẹ́ Ọlọ́run wọn, ìránṣẹ́ mi Dafidi yóò jẹ́ ọmọ-aládé láàrín wọn. Èmi Olúwa ní o sọ̀rọ̀.
Én pedig, az Úr, leszek nékik Istenök, és az én szolgám, Dávid, fejedelem közöttök. Én, az Úr mondottam.
25 “‘Èmi yóò dá májẹ̀mú àlàáfíà pẹ̀lú wọn, èmi yóò sì gba ilẹ̀ náà kúrò lọ́wọ́ ẹranko búburú, kí wọn kí o lè gbé ní aṣálẹ̀, kí àgùntàn sì gbé ní inú igbó ní àìléwu.
És szerzek ő velök békességnek frigyét, és megszüntetem a gonosz vadakat a földről, hogy bátorságosan lakhassanak a pusztában és alhassanak az erdőkben.
26 Èmi yóò bùkún wọn àti ibi agbègbè ti ó yí òkè mi ká. Èmi yóò rán ọ̀wààrà òjò ni àkókò; òjò ìbùkún yóò sì wà.
És adok reájok és az én magaslatom környékére áldást, és bocsátom az esőt idejében; áldott esők lesznek.
27 Àwọn igi igbó yóò mú èso wọn jáde, ilẹ̀ yóò sì mu irúgbìn jáde; A yóò sì dá ààbò bo àwọn ènìyàn ní ilẹ̀ náà. Wọn yóò mọ̀ pé èmi ni Olúwa, nígbà tí mo bá já àwọn ohun tí ó ṣe okùnfà àjàgà, tí mo sì gbà wọ́n kúrò lọ́wọ́ àwọn tí ó fi wọ́n ṣe ẹrú.
A mező fája megadja gyümölcsét s a föld megadja termését, és lesznek földjökön bátorságosan, és megtudják, hogy én vagyok az Úr, mikor eltöröm jármok keresztfáit, és kimentem őket azok kezéből, kik őket szolgáltatják.
28 Àwọn orílẹ̀-èdè kì yóò lè kó wọn ní ẹrú mọ́, àwọn ẹranko búburú kì yóò lè pa wọn mọ́. Wọn yóò gbé ni àìléwu, kò sì ṣí ẹni kankan tí yóò le dẹ́rùbà wọ́n.
És nem lesznek többé prédául a pogányoknak, s a föld vadai nem eszik meg őket; és laknak bátorságosan, s nem lesz, a ki felijeszsze őket.
29 Èmi yóò pèsè ilẹ̀ ti o ní oríyìn fún èso rẹ̀ fún wọn, wọn kì yóò sì jìyà nípasẹ̀ ìyàn mọ́ ni ilẹ̀ náà tàbí ru ẹ̀gàn àwọn orílẹ̀-èdè.
És támasztok nékik drága plántaföldet, hogy többé meg ne emésztessenek éhség miatt a földön, s ne viseljék többé a pogányok gyalázatát;
30 Nígbà náà ni wọn yóò mọ̀ pé, èmi ni Olúwa Ọlọ́run wọn, èmi wà pẹ̀lú wọn àti pé, àwọn ilé Israẹli jẹ́ ènìyàn mi, ni Olúwa Olódùmarè wí.
És megismerik, hogy én, az Úr, az ő Istenök, velök vagyok, és ők népem, Izráel háza, ezt mondja az Úr Isten;
31 Ìwọ àgùntàn mi, àgùntàn pápá mi; ni ènìyàn, èmi sì ni Ọlọ́run rẹ; ni Olúwa Olódùmarè wí.’”
Ti pedig az én juhaim, legelőm nyája vagytok, emberek vagytok, én pedig Istenetek, ezt mondja az Úr Isten.

< Ezekiel 34 >