< Ezekiel 34 >

1 Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ́ mi wá:
And the word of the Lord was maad to me,
2 “Ọmọ ènìyàn, fi àsọtẹ́lẹ̀ tako Olùṣọ́-àgùntàn Israẹli; sọtẹ́lẹ̀ fún wọn pé: ‘Èyí yìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Ègbé ni fún olùṣọ́-àgùntàn Israẹli tí ó ń tọ́jú ara wọn nìkan! Ṣé ó dára kí olùṣọ́-àgùntàn ṣaláì tọ́jú agbo ẹran?
and he seide, Sone of man, profesie thou of the schepherdis of Israel, profesie thou; and thou schalt seie to the schepherdis, The Lord God seith these thingis, Wo to the schepherdis of Israel, that fedden hym silf; whether flockis ben not fed of schepherdis?
3 Ìwọ jẹ wàrà. O sì wọ aṣọ olówùú sí ara rẹ, o sì ń pa ẹran tí ó wù ọ́, ṣùgbọ́n ìwọ kò tọ́jú agbo ẹran.
Ye eeten mylk, and weren hilid with wollis, and ye killiden that that was fat; but ye fedden not my floc.
4 Ìwọ kò ì tí ì mú aláìlágbára lára le tàbí wo aláìsàn sàn tàbí di ọgbẹ́ fún ẹni tí o fi ara pa. Ìwọ kò í tí ì mú aṣáko padà tàbí wá ẹni tí ó nù. Ìwọ ṣe àkóso wọn ní ọ̀nà lílé pẹ̀lú ìwà òǹrorò.
Ye maden not sad that that was vnstidfast, and ye maden not hool that that was sijk; ye bounden not that that was brokun, and ye brouyten not ayen that that was cast awei, and ye souyten not that that perischide; but ye comaundiden to hem with sturnenesse, and with power.
5 Nítorí náà wọn fọ́n káàkiri nítorí àìsí olùṣọ́-àgùntàn, nígbà tí wọ́n fọ́nká tán wọn di ìjẹ fún gbogbo ẹranko búburú.
And my scheep weren scaterid, for no sheepherde was; and thei weren maad in to deuouryng of alle beestis of the feeld, and thei weren scaterid.
6 Àgùntàn mi n rin ìrìn àrè kiri ní gbogbo àwọn òkè gíga àti òkè kékeré. A fọ́n wọn ká gbogbo orí ilẹ̀ ẹni kankan kò sì wá wọn.
My flockis erriden in alle mounteyns, and in ech hiy hil, and my flockis weren scaterid on al the face of erthe, and noon was that souyte.
7 “‘Nítorí náà, ìwọ olùṣọ́-àgùntàn, gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa.
Therfor, scheepherdis, here ye the word of the Lord;
8 Níwọ́n ìgbà tí mo wà láààyè ní Olúwa Olódùmarè wí, nítorí pé agbo ẹran mi kò ní olùṣọ́-àgùntàn nítorí tí a kọ̀ wọ́n, tì wọ́n sì di ìjẹ fún ẹranko búburú gbogbo àti pé, nítorí tí àwọn olùṣọ́-àgùntàn mi kò ṣe àwárí agbo ẹran mi, ṣùgbọ́n wọn ń ṣe ìtọ́jú ara wọn dípò ìtọ́jú agbo ẹran mi,
Y lyue, seith the Lord God, for whi for that that my flockis ben maad in to raueyn, and my scheep in to deuouryng of alle beestis of the feeld, for that that no scheepherde was, for the scheepherdis souyten not my floc, but the scheepherdis fedden hem silf, and fedden not my flockis; therfor,
9 nítorí náà, ẹ̀yin olùṣọ́-àgùntàn, gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa.
scheepherdis, here ye the word of the Lord,
10 Èyí yìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Èmi ṣe ìlòdì sí àwọn Olùṣọ́-àgùntàn, èmi yóò sì béèrè agbo ẹran mi lọ́wọ́ wọn. Èmi yóò sì mú wọn dẹ́kun àti máa darí agbo ẹran mi, tí àwọn olùṣọ́-àgùntàn náà kò sì ní lè bọ́ ara wọn mọ́. Èmi yóò gba agbo ẹran mi kúrò ni ẹnu wọn, kì yóò sì jẹ́ oúnjẹ fún wọn mọ́.
The Lord God seith these thingis, Lo! Y my silf am ouer scheepherdis; Y schal seke my floc of the hond of hem, and Y schal make hem to ceesse, that thei fede no more my flok, and that the scheepherdis feede no more hem silf. And Y schal delyuere my floc fro the mouth of hem, and it schal no more be in to mete to hem.
11 “‘Nítorí èyí ni Olúwa Olódùmarè wí: Èmi fúnra mi yóò wá àgùntàn mi kiri, èmi yóò sì ṣe àwárí wọn.
For the Lord God seith these thingis, Lo! Y my silf schal seke my scheep, and Y schal visite hem.
12 Gẹ́gẹ́ bí olùṣọ́-àgùntàn ṣe fojú tó agbo ẹran rẹ̀ tí ó fọ́nká nígbà tí ó wà pẹ̀lú wọn, bẹ́ẹ̀ ni èmi yóò ṣe fojú tó àgùntàn mi. Èmi yóò gbá wọn kúrò ni gbogbo ibi tí wọ́n fọ́nká sí ni ọjọ́ ìkùùkuu àti òkùnkùn.
As a scheepherde visitith his floc, in the dai whanne he is in the myddis of hise scheep `that ben scaterid, so Y schal visite my scheep; and Y schal delyuere hem fro alle places in whiche thei weren scaterid, in the dai of cloude, and of derknesse.
13 Èmi yóò mú wọn jáde kúrò ní àwọn orílẹ̀-èdè, èmi yóò sì kó wọn jọ láti inú àwọn ìlú, èmi yóò sì mú wọn wá sí ilẹ̀ ara wọn. Èmi yóò mú wọn jẹ ni orí àwọn òkè gíga Israẹli, ni àárín àwọn òkè àti ní gbogbo ibùdó ilẹ̀ náà.
And Y schal leede hem out of puplis, and Y schal gadere hem fro londis, and Y schal brynge hem in to her lond, and Y schal feede hem in the hillis of Israel, in ryueris, and in alle seetis of erthe.
14 Èmi yóò ṣe ìtọ́jú wọn ní pápá oko tútù dáradára, àní orí àwọn òkè gíga ti Israẹli ni yóò jẹ́ ilẹ̀ ìjẹ koríko wọ́n. Níbẹ̀ wọn yóò dùbúlẹ̀ ní ilẹ̀ ìjẹ koríko dídára, níbẹ̀ wọn yóò jẹun ní pápá oko tútù tí ó dara ní orí òkè ti Israẹli.
Y schal feede hem in moost plenteouse pasturis, and the lesewis of hem schulen be in the hiy hillis of Israel; there thei schulen reste in greene eerbis, and in fatte lesewis thei schulen be fed on the hillis of Israel.
15 Èmi fúnra mi yóò darí àgùntàn mi, èmi yóò mú wọn dùbúlẹ̀, ni Olúwa Olódùmarè wí.
Y schal fede my scheep, and Y schal make hem to ligge, seith the Lord God.
16 Èmi yóò ṣe àwárí àwọn tí ó nú, èmi yóò mú àwọn tí ó ń rin ìrìn àrè kiri padà. Èmi yóò di ọgbẹ́ àwọn tí ó fi ara pa, èmi yóò sì fún àwọn aláìlágbára ni okun, ṣùgbọ́n àwọn tí ó sanra tí ó sì ni agbára ní èmi yóò parun. Èmi yóò ṣe olùṣọ́ àwọn agbo ẹran náà pẹ̀lú òdodo.
I schal seke that that perischide, and Y schal brynge ayen that that was cast awei; and Y schal bynde that that was brokun, and Y schal make sad that that was sijk; and Y schal kepe that that was fat and strong; and Y schal feede hem in doom;
17 “‘Ní tìrẹ, agbo ẹran mi, èyí yìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Èmi yóò ṣe ìdájọ́ láàrín àgùntàn kan àti òmíràn, àti láàrín àgbò àti ewúrẹ́.
forsothe ye ben my flockis. The Lord God seith these thingis, Lo! Y deme bitwixe beeste and beeste, and a wethir and a buc of geet.
18 Ṣé oúnjẹ jíjẹ ní pápá oko tútù dídára kò tó yín! Ṣé ó jẹ́ dandan fún ọ láti fi ẹsẹ̀ tẹ pápá oko tútù rẹ tí ó kù? Ṣé omi tí ó tòrò kò tó fún yín ní mímu? Ṣe dandan ni kí ó fi ẹrẹ̀ yí ẹsẹ̀ yín?
Whether it was not enowy to you to deuoure good pasturis? Ferthermore and ye defouliden with youre feet the remenauntis of youre lesewis, and whanne ye drunken clereste watir, ye disturbliden the residue with youre feet.
19 Ṣé dandan ni kí agbo ẹran mi jẹ́ koríko tí ẹ ti tẹ̀ mọ́lẹ̀, kí wọn sì mú omi tí wọ́n ti fi ẹsẹ̀ wọn sọ di ẹrẹ̀?
And my scheep weren fed with tho thingis that weren defoulid with youre feet; and thei drunken these thingis, that youre feet hadden troblid.
20 “‘Nítorí náà, èyí yìí ni Olúwa Olódùmarè wí fún wọn: Wò ó, èmi fúnra mi yóò ṣe ìdájọ́ láàrín àgùntàn tí ó sanra àti èyí tí ó rù.
Therfor the Lord God seith these thingis to you, Lo! Y my silf deme bitwixe a fat beeste and a leene beeste.
21 Nítorí ti ìwọ sún síwájú pẹ̀lú ìhà àti èjìká, tí ìwọ sì kan aláìlágbára àgùntàn pẹ̀lú ìwo rẹ títí ìwọ fi lé wọn lọ,
For that that ye hurliden with sidis, and schuldris, and wyndewiden with youre hornes alle sike beestis, til tho weren scaterid withoutforth, I schal saue my floc,
22 Èmi yóò gba agbo ẹran mi là, a kì yóò sì kò wọ́n tì mọ́. Èmi yóò ṣe ìdájọ́ láàrín àgùntàn kan àti òmíràn.
and it schal no more be in to raueyn. And Y schal deme bitwixe beeste and beeste;
23 Èmi yóò fi Olùṣọ́-àgùntàn kan ṣe olórí wọn, ìránṣẹ́ mi Dafidi, òun yóò sì tọ́jú wọn; òun yóò bọ́ wọn yóò sì jẹ́ Olùṣọ́-àgùntàn wọn.
and Y schal reise on tho o sheepherde, my seruaunt Dauid, that schal fede tho; he schal fede tho, and he schal be `in to a sheepherde to hem.
24 Èmi Olúwa yóò sì jẹ́ Ọlọ́run wọn, ìránṣẹ́ mi Dafidi yóò jẹ́ ọmọ-aládé láàrín wọn. Èmi Olúwa ní o sọ̀rọ̀.
Forsothe Y the Lord schal be in to God to hem, and my seruaunt Dauid schal be prince in the myddis of hem; Y the Lord spak.
25 “‘Èmi yóò dá májẹ̀mú àlàáfíà pẹ̀lú wọn, èmi yóò sì gba ilẹ̀ náà kúrò lọ́wọ́ ẹranko búburú, kí wọn kí o lè gbé ní aṣálẹ̀, kí àgùntàn sì gbé ní inú igbó ní àìléwu.
And Y schal make with hem a couenaunt of pees, and Y schal make worste beestis to ceesse fro erthe; and thei that dwellen in desert, schulen slepe sikur in forestis.
26 Èmi yóò bùkún wọn àti ibi agbègbè ti ó yí òkè mi ká. Èmi yóò rán ọ̀wààrà òjò ni àkókò; òjò ìbùkún yóò sì wà.
And Y schal sette hem blessyng in the cumpas of my litle hil, and Y schal lede doun reyn in his tyme. And reynes of blessyng schulen be,
27 Àwọn igi igbó yóò mú èso wọn jáde, ilẹ̀ yóò sì mu irúgbìn jáde; A yóò sì dá ààbò bo àwọn ènìyàn ní ilẹ̀ náà. Wọn yóò mọ̀ pé èmi ni Olúwa, nígbà tí mo bá já àwọn ohun tí ó ṣe okùnfà àjàgà, tí mo sì gbà wọ́n kúrò lọ́wọ́ àwọn tí ó fi wọ́n ṣe ẹrú.
and the tre of the feeld schal yyue his fruyt, and the erthe schal yyue his seed. And thei schulen be in her lond with out drede; and thei schulen wite, that Y am the Lord, whanne Y schal al to-breke the chaynes of her yok, and schal delyuere hem fro the hond of hem that comaunden to hem.
28 Àwọn orílẹ̀-èdè kì yóò lè kó wọn ní ẹrú mọ́, àwọn ẹranko búburú kì yóò lè pa wọn mọ́. Wọn yóò gbé ni àìléwu, kò sì ṣí ẹni kankan tí yóò le dẹ́rùbà wọ́n.
And thei schulen no more be in to raueyn in to hethene men, nether the beestis of erthe schulen deuoure hem, but thei schulen dwelle tristili with outen ony drede.
29 Èmi yóò pèsè ilẹ̀ ti o ní oríyìn fún èso rẹ̀ fún wọn, wọn kì yóò sì jìyà nípasẹ̀ ìyàn mọ́ ni ilẹ̀ náà tàbí ru ẹ̀gàn àwọn orílẹ̀-èdè.
And Y schal reise to hem a iust buriownyng named; and thei schulen no more be maad lesse for hunger in erthe, and thei schulen no more bere the schenschipis of hethene men.
30 Nígbà náà ni wọn yóò mọ̀ pé, èmi ni Olúwa Ọlọ́run wọn, èmi wà pẹ̀lú wọn àti pé, àwọn ilé Israẹli jẹ́ ènìyàn mi, ni Olúwa Olódùmarè wí.
And thei schulen wite, that Y am her Lord God with hem, and thei ben my puple, the hous of Israel, seith the Lord God.
31 Ìwọ àgùntàn mi, àgùntàn pápá mi; ni ènìyàn, èmi sì ni Ọlọ́run rẹ; ni Olúwa Olódùmarè wí.’”
Forsothe ye my flockis ben men, the flockis of my lesewe; and Y am youre Lord God, seith the Lord God.

< Ezekiel 34 >