< Ezekiel 33 >
Och HERRENS ord kom till mig; han sade:
2 “Ọmọ ènìyàn sọ̀rọ̀ sí àwọn ènìyàn ilẹ̀ rẹ kí ó sì sọ fún wọn: ‘Nígbà tí mo bá fi idà kọlu ilẹ̀ kan, tí àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà yan ọ̀kan lára àwọn ọkùnrin wọn láti jẹ́ alóre wọn,
Du människobarn, tala till dina landsmän och säg till dem: Om jag vill låta svärdet komma över ett land, och folket i landet har utsett bland sig en man som det har gjort till sin väktare,
3 tí ó sì rí i pé idà ń bọ̀ lórí ilẹ̀ náà, tí ó sì fọn ìpè láti kìlọ̀ fún àwọn ènìyàn,
och denne ser svärdet komma över landet och stöter i basunen och varnar folket,
4 nígbà náà tí ẹnikẹ́ni bá gbọ́ ìpè ṣùgbọ́n tí kò gbọ́ ìkìlọ̀, tí idà náà wá tí ó sì gba ẹ̀mí rẹ̀, ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ yóò wà lórí ara rẹ̀.
men den som får höra basunljudet ända icke låter varna sig, och svärdet sedan kommer och tager honom bort, då kommer hans blod över hans eget huvud.
5 Nítorí tí ó gbọ́ ohùn ìpè ṣùgbọ́n tí kò sì gbọ́ ìkìlọ̀, ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ yóò wà ní orí ara rẹ̀. Tí ó bá gbọ́ ìkìlọ̀, òun ìbá ti gba ara rẹ̀ là.
Ty han hörde ju basunljudet, men lät icke varna sig; därför kommer hans blod över honom själv. Om han hade låtit varna sig, så hade han räddat sitt liv. --
6 Ṣùgbọ́n bí alóre bá rí idà tí o ń bọ̀, tí kò sì fọn ìpè láti ki àwọn ènìyàn nílọ̀, tí idà náà wá, tí ó sì gba ẹ̀mí ọ̀kan nínú wọn, a yóò mú ọkùnrin náà lọ nítorí ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀, ṣùgbọ́n èmi yóò béèrè ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ lọ́wọ́ rẹ̀.’
Men om väktaren ser svärdet komma och icke stöter i basunen och folket så icke bliver varnat, och svärdet sedan kommer och tager bort någon bland dem, då bliver visserligen denne borttagen genom sin egen missgärning, men hans blod skall jag utkräva av väktarens hand.
7 “Ọmọ ènìyàn, èmi fi ọ ṣe alóre fún ilé Israẹli; nítorí náà gbọ́ ọ̀rọ̀ tí mo sọ, kí o sì fún wọn ni ìkìlọ̀ láti ọ̀dọ̀ mi.
Dig, du människobarn, har jag satt till en väktare för Israels hus, för att du å mina vägnar skall varna dem, när du hör ett ord från min mun.
8 Nígbà ti mo bá sọ fún ẹni búburú pé, ‘A! Ẹni búburú, ìwọ yóò kú dandan,’ ti ìwọ kò sì sọ̀rọ̀ síta láti yí i lọ́kàn padà kúrò ni ọ̀nà rẹ̀ gbogbo, ẹni búburú náà yóò kú nínú ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀, èmi yóò sì béèrè ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ lọ́wọ́ rẹ.
Om jag säger till den ogudaktige: "Du ogudaktige, du måste dö", och du då icke säger något till att varna den ogudaktige för hans väg, så skall väl den ogudaktige dö genom sin missgärning, men hans blod skall jag utkräva av din hand.
9 Ṣùgbọ́n bí ìwọ bá kìlọ̀ fún ẹni búburú láti yí padà kúrò ni ọ̀nà rẹ̀ gbogbo, tí òun kò sì ṣe bẹ́ẹ̀, òun yóò kú nítorí ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀, ṣùgbọ́n ìwọ ti gba ọkàn rẹ̀ là.
Men om du varnar den ogudaktige för hans väg, på det att han må vända om ifrån den, och han likväl icke vänder om ifrån sin väg, då skall visserligen han dö genom sin missgärning, men du själv har räddat din själ.
10 “Ọmọ ènìyàn; sọ fún ilé Israẹli, ‘Èyí yìí ní ìwọ sọ: “Àwọn ìrékọjá àti ẹ̀ṣẹ̀ wa tẹ orí wa ba, àwa sì ń ṣòfò dànù nítorí wọn. Bá wó wa ni a ṣe lè yè?”’
Och du, människobarn, säg till Israels hus: I sägen så: "Våra överträdelser och synder tynga på oss och vi försmäkta genom dem. Huru kunna vi då bliva vid liv?"
11 Sọ fún wọn pé, ‘Níwọ́n ìgbà tí mo wà láààyè ni Olúwa Olódùmarè wí, èmi kò ní inú dídùn sí ikú ènìyàn búburú, ṣùgbọ́n dípò bẹ́ẹ̀, kí wọ̀nyí padà kúrò ní ọ̀nà wọn gbogbo kì wọn kì ó sì yè. Yí! Yípadà kúrò ni ọ̀nà búburú gbogbo! Kí ló dé tí ìwọ yóò kú ẹ̀yin ènìyàn Israẹli?’
Men svara dem: Så sant jag lever, säger Herren, HERREN, jag har ingen lust till den ogudaktiges död, utan fastmer därtill att den ogudaktige vänder om från sin väg och får leva. Så vänden då om, ja, vänden om från edra onda vägar; ty icke viljen I väl dö, I av Israels hus?
12 “Nítorí náà, ọmọ ènìyàn, sọ fún àwọn ènìyàn ilẹ̀ rẹ, ‘Ìṣòdodo ti olódodo ènìyàn kì yóò gbà á nígbà tí òun bá ṣe àìgbọ́ràn, ìwà búburú ènìyàn búburú kì yóò mú kí o ṣubú nígbà tí ó bá yí padà kúrò nínú rẹ̀. Bí olódodo ènìyàn bá ṣẹ̀, a kò ni jẹ́ kí ó yè nítorí òdodo rẹ̀ ti tẹ́lẹ̀.’
Men du, människobarn, säg till dina landsmän: Den rättfärdiges rättfärdighet skall icke rädda honom, när han begår överträdelser; och den ogudaktige skall icke komma på fall genom sin ogudaktighet, när han vänder om från sin ogudaktighet, lika litet som den rättfärdige skall kunna leva genom sin rättfärdighet, när han syndar.
13 Bí mo bá sọ fún olódodo ènìyàn pé òun yóò yè, ṣùgbọ́n nígbà náà tí ó gbẹ́kẹ̀lé òdodo rẹ̀ tí ó sì ṣe búburú, a kò ní rántí nǹkan kan nínú iṣẹ́ òdodo tí o ti ṣe sẹ́yìn; òun yóò kú nítorí búburú tí ó ṣe.
Om jag säger till den rättfärdige att han skall få leva, och han sedan i förlitande på sin rättfärdighet gör vad orätt är, så skall intet ihågkommas av all hans rättfärdighet, utan genom det orätta som han gör skall han dö.
14 Bí mo bá sọ fún ènìyàn búburú pé, ‘Ìwọ yóò kú dandan,’ ṣùgbọ́n tí ó bá yípadà kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀, ti o sì ṣe èyí tí ó tọ́ àti èyí tí o yẹ.
Och om jag säger till den ogudaktige: "Du måste dö", och han sedan vänder om från sin synd och övar rätt och rättfärdighet,
15 Tí ó bá mu ògo padà, tí o sì da ohun tí o ti jí gbé padà, tí ó sì tẹ̀lé òfin tí ó ń fún ni ní ìyè, tí kò sì ṣe búburú, òun yóò yè dandan; òun kì yóò kú.
så att han, den ogudaktige, give tillbaka den pant han har fått och ersätter vad han har rövat och vandrar efter livets stadgar, så att han icke gör vad orätt är, då skall han förvisso leva och icke dö.
16 A kò ní rántí ọ̀kan nínú ẹ̀ṣẹ̀ tí ó ti dá. Ó ti ṣe èyí tí ó tọ àti èyí tí o yẹ; òun yóò sì yè dájúdájú.
Ingen av de synder han har begått skall då tillräknas honom; han har övat rätt och rättfärdighet, därför skall han förvisso få leva. --
17 “Síbẹ̀ àwọn ènìyàn ilẹ̀ rẹ sọ pé, ‘Ọ̀nà Olúwa kò tọ́.’ Ṣùgbọ́n ọ̀nà tí àwọn ní ó tọ́.
Men nu säga dina landsmän: "Herrens väg är icke alltid densamma", då det fastmer är deras egen väg som icke alltid är densamma.
18 Bí olódodo ènìyàn ba yípadà kúrò nínú òdodo rẹ̀, tí o sì ṣe búburú, òun yóò kú nítorí rẹ̀.
Om den rättfärdige vänder om från sin rättfärdighet och gör vad orätt är, så måste han just därför dö.
19 Bí ènìyàn búburú bá yípadà kúrò nínú búburú rẹ̀, tí ó sì ṣe èyí tí ó tọ́ àti èyí tí ó yẹ, òun yóò yè nípa ṣíṣe bẹ́ẹ̀.
Men om den ogudaktige vänder om från sin ogudaktighet och övar rätt och rättfärdighet, då skall han just därför få leva.
20 Síbẹ̀, ilé Israẹli ìwọ wí pé, ‘Ọ̀nà Olúwa ki i ṣe òtítọ́.’ Ṣùgbọ́n èmi yóò ṣe ìdájọ́ ẹnìkọ̀ọ̀kan gẹ́gẹ́ bí ọ̀nà rẹ̀ ṣe rí.”
Och ändå sägen I: "Herrens väg är icke alltid densamma." Jo, jag skall döma var och en av eder efter hans vägar, I av Israels hus.
21 Ní ọjọ́ karùn-ún oṣù kẹwàá, ọdún kejìlá ìkólọ wa, ọkùnrin kan tí ó sá kúrò ni Jerusalẹmu wá sọ́dọ̀ mi, ó sì wí pé, “Ìlú ńlá náà ti ṣubú!”
I det tolfte året sedan vi hade blivit bortförda i fångenskap, på femte dagen i tionde månaden, kom en flykting ifrån Jerusalem till mig med budskapet: "Staden är intagen."
22 Ní ìrọ̀lẹ́ ọjọ́ tí ó ku ọ̀la tí ẹni tí ó sálọ náà yóò dé, ọwọ́ Olúwa sì níbẹ̀ lára mi, o sì ya ẹnu mi ki ọkùnrin náà tó wá sọ́dọ̀ mi ní òwúrọ̀. Ẹnu mí sì ṣí, èmi kò sì yadi mọ́.
Nu hade på aftonen före flyktingens ankomst HERRENS hand kommit över mig; men på morgonen öppnade han åter min mun, just före mannens ankomst, så att jag, då nu min mun blev öppnad, upphörde att vara stum.
23 Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá:
Och HERRENS ord kom till mig; han sade:
24 “Ọmọ ènìyàn, àwọn ènìyàn tí ó ń gbé nínú ìparun ní ilẹ̀ Israẹli ń wí pé, ‘Abrahamu jẹ́ ọkùnrin kan, síbẹ̀ o gba ilẹ̀ ìní náà. Ṣùgbọ́n àwa pọ̀, lóòótọ́ a ti fi ilẹ̀ náà fún wa gẹ́gẹ́ bí ìní wa.’
Du människobarn, de som bo ibland ruinerna där borta i Israels land säga "Abraham var en ensam man, och han fick dock landet till besittning. Vi äro många, oss måste väl landet då vara givet till besittning!"
25 Nítorí náà, sọ fún wọn pé, ‘Èyí yìí ní Olúwa Olódùmarè wí: Níwọ́n ìgbà tí ẹ̀yin jẹ ẹran pẹ̀lú ẹ̀jẹ̀ ni inú rẹ̀, tí ẹ̀yin sì wó àwọn ère yín, tí ẹ sì ta ẹ̀jẹ̀ sílẹ̀, ẹ̀yin yóò ha gba ilẹ̀ náà?
Säg därför till dem: Så säger Herren, HERREN: I äten kött med blodet i, I upplyften edra ögon till edra eländiga avgudar, och I utgjuten blod; och likväl skullen I få hava landet till besittning!
26 Ẹ̀yin gbẹ́kẹ̀lé idà yín, ẹ̀yin ṣe nǹkan ìríra, ẹnìkọ̀ọ̀kan nínú yín ba á obìnrin aládùúgbò rẹ̀ jẹ́. Ẹ̀yin yóò ha gba ilẹ̀ náà?’
I trotsen på edra svärd, I bedriven vad styggeligt är, I skänden varandras hustrur; och likväl skullen I få hava landet till besittning!
27 “Sọ èyí fún wọn: ‘Èyí yìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Bí mo ti wà láààyè, àwọn tí ó kúrò nínú ìparun yóò ti ipa idà ṣubú, àwọn tí ẹranko búburú yóò pajẹ, àwọn tí ó sì wà ní ilé ìṣọ́ àti inú ihò òkúta ni àjàkálẹ̀-ààrùn yóò pa.
Nej; så skall du säga till dem: Så säger Herren, HERREN: Så sant jag lever, de som bo där bland ruinerna skola falla för svärd; och dem som bo på landsbygden skall jag giva till mat åt de vilda djuren, och de som bo i bergfästen eller i grottor skola dö genom pest.
28 Èmi yóò mú kí ilẹ̀ náà di ahoro, ọ̀ṣọ́ ńlá agbára rẹ̀ kì yóò sí mọ́, àwọn òkè Israẹli yóò sì di ahoro, tí ẹnikẹ́ni kò ní le là á kọjá.
Jag skall göra landet öde och tomt, och dess stolta makt skall få en ände; och Israels berg skola ödeläggas, så att ingen går där fram.
29 Nígbà náà, wọn yóò mọ̀ pé èmi ni Olúwa, nígbà tí mo bá mú ilẹ̀ náà di ahoro nítorí gbogbo ohun ìríra tí wọ́n ti ṣe.’
Och de skola förnimma att jag är HERREN, när jag gör landet öde och tomt, för alla de styggelsers skull som de hava bedrivit.
30 “Ní tìrẹ, ọmọ ènìyàn, àwọn ènìyàn ìlú n sọ̀rọ̀ nípa rẹ ní ẹ̀gbẹ́ ògiri àti ní ẹnu-ọ̀nà ilé wọn, wọ́n ń sọ sí ara wọn wí pé, ‘Ẹ wá gbọ́ iṣẹ́ ti a ran láti ọ̀dọ̀ Olúwa wá.’
Men du, människobarn, dina landsmän, som orda om dig invid väggarna och i ingångarna till husen, de tala sinsemellan, den ene med den andre, och säga: "Kom, låt oss höra vad det är för ett ord som nu utgår från HERREN."
31 Àwọn ènìyàn mi wá sọ́dọ̀ rẹ, gẹ́gẹ́ bí wọn ṣe ń ṣe, wọn sì jókòó níwájú rẹ láti fetísí ọ̀rọ̀ rẹ, ṣùgbọ́n wọn kò mú wá sí ìṣe. Ẹnu wọn ni wọ́n fi n sọ̀rọ̀ ìfọkànsìn, ṣùgbọ́n ọkàn wọn ní ìwọra èrè tí kò tọ́.
Och de komma till dig, såsom gällde det en folkförsamling, och sätta sig hos dig såsom mitt folk; och de höra dina ord, men göra icke efter dem. Ty väl hopgöra de med munnen ljuvliga ord, men deras hjärtan stå blott efter egen vinning.
32 Nítòótọ́ lójú wọn, ìwọ jẹ́ ẹni kan tí ó ń kọrin ìfẹ́ pẹ̀lú ohun dídára àti ohun èlò orin kíkọ, nítorí wọ́n gbọ́ ọ̀rọ̀ rẹ ṣùgbọ́n wọn kò mu wá sí ìṣe.
Och se, du är för dem, såsom när någon som har vacker röst och spelar väl sjunger en kärleksvisa; de höra väl dina ord, men göra icke efter dem.
33 “Nígbà tí gbogbo ìwọ̀nyí bá ṣẹ tí yóò sì ṣẹ dandan, nígbà náà wọn yóò mọ̀ pé wòlíì kan ti wa láàrín wọn rí.”
Men när det kommer -- ty se det kommer! -- då skola de förnimma att en profet har varit ibland dem.