< Ezekiel 33 >

1 Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá:
Ningĩ kiugo kĩa Jehova nĩkĩanginyĩrĩire, ngĩĩrwo atĩrĩ:
2 “Ọmọ ènìyàn sọ̀rọ̀ sí àwọn ènìyàn ilẹ̀ rẹ kí ó sì sọ fún wọn: ‘Nígbà tí mo bá fi idà kọlu ilẹ̀ kan, tí àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà yan ọ̀kan lára àwọn ọkùnrin wọn láti jẹ́ alóre wọn,
“Mũrũ wa mũndũ, arĩria andũ anyu, ũmeere atĩrĩ: ‘Hĩndĩ ĩrĩa ngaarehithia rũhiũ rwa njora rũũkĩrĩre bũrũri, nao andũ a bũrũri ũcio methuurĩre mũndũ ũmwe wao mamũtue mũrangĩri wao,
3 tí ó sì rí i pé idà ń bọ̀ lórí ilẹ̀ náà, tí ó sì fọn ìpè láti kìlọ̀ fún àwọn ènìyàn,
nake one rũhiũ rwa njora rũgĩũka gũũkĩrĩra bũrũri ũcio, nake ahuhe karumbeta nĩgeetha amenyithie andũ mehũũge-rĩ,
4 nígbà náà tí ẹnikẹ́ni bá gbọ́ ìpè ṣùgbọ́n tí kò gbọ́ ìkìlọ̀, tí idà náà wá tí ó sì gba ẹ̀mí rẹ̀, ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ yóò wà lórí ara rẹ̀.
hĩndĩ ĩyo mũndũ wothe ũrĩa ũkaigua karumbeta kau no aage kwĩhũga, naruo rũhiũ rũu rwa njora rũũke rũmũũrage-rĩ, nĩagacookererwo nĩ thakame yake mwene.
5 Nítorí tí ó gbọ́ ohùn ìpè ṣùgbọ́n tí kò sì gbọ́ ìkìlọ̀, ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ yóò wà ní orí ara rẹ̀. Tí ó bá gbọ́ ìkìlọ̀, òun ìbá ti gba ara rẹ̀ là.
Kuona atĩ nĩaiguire mũgambo wa karumbeta na akĩaga kwĩhũga-rĩ, nĩagacookererwo nĩ thakame yake mwene. Korwo nĩehũũgire-rĩ, nĩangĩehonokirie we mwene.
6 Ṣùgbọ́n bí alóre bá rí idà tí o ń bọ̀, tí kò sì fọn ìpè láti ki àwọn ènìyàn nílọ̀, tí idà náà wá, tí ó sì gba ẹ̀mí ọ̀kan nínú wọn, a yóò mú ọkùnrin náà lọ nítorí ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀, ṣùgbọ́n èmi yóò béèrè ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ lọ́wọ́ rẹ̀.’
No rĩrĩ, mũrangĩri ũcio angĩona rũhiũ rũu rwa njora rũgĩũka, na aage kũhuha karumbeta nĩgeetha andũ mehũũge, naruo rũhiũ rũu rwa njora rũũke rũũrage ũmwe wao, mũndũ ũcio agaakua tondũ wa wĩhia wake, no niĩ-rĩ, nĩngooria mũrangĩri ũcio thakame ya mũndũ ũcio.’
7 “Ọmọ ènìyàn, èmi fi ọ ṣe alóre fún ilé Israẹli; nítorí náà gbọ́ ọ̀rọ̀ tí mo sọ, kí o sì fún wọn ni ìkìlọ̀ láti ọ̀dọ̀ mi.
“Mũrũ wa mũndũ, nĩngũtuĩte mũrangĩri wa andũ a nyũmba ya Isiraeli; nĩ ũndũ ũcio, igua kiugo kĩrĩa ngwaria na ũmahe ũhoro kuuma harĩ niĩ atĩ mehũũge.
8 Nígbà ti mo bá sọ fún ẹni búburú pé, ‘A! Ẹni búburú, ìwọ yóò kú dandan,’ ti ìwọ kò sì sọ̀rọ̀ síta láti yí i lọ́kàn padà kúrò ni ọ̀nà rẹ̀ gbogbo, ẹni búburú náà yóò kú nínú ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀, èmi yóò sì béèrè ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ lọ́wọ́ rẹ.
Hĩndĩ ĩrĩa ndeera mũndũ mwaganu atĩrĩ, ‘Wee mũndũ ũyũ mwaganu, ti-itherũ nĩũgũkua,’ nawe wage kũmũringĩrĩria atigane na mĩthiĩre ĩyo yake-rĩ, mũndũ ũcio mwaganu nĩagaakua tondũ wa wĩhia wake, no wee nĩwe ngooria thakame yake.
9 Ṣùgbọ́n bí ìwọ bá kìlọ̀ fún ẹni búburú láti yí padà kúrò ni ọ̀nà rẹ̀ gbogbo, tí òun kò sì ṣe bẹ́ẹ̀, òun yóò kú nítorí ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀, ṣùgbọ́n ìwọ ti gba ọkàn rẹ̀ là.
No rĩrĩ, ũngĩĩra mũndũ ũcio mwaganu ehũũge atigane na mĩthiĩre ĩyo yake, nake aage gwĩka ũguo-rĩ, nĩagaakua nĩ ũndũ wa wĩhia wake, no wee nĩũkahonokia muoyo waku.
10 “Ọmọ ènìyàn; sọ fún ilé Israẹli, ‘Èyí yìí ní ìwọ sọ: “Àwọn ìrékọjá àti ẹ̀ṣẹ̀ wa tẹ orí wa ba, àwa sì ń ṣòfò dànù nítorí wọn. Bá wó wa ni a ṣe lè yè?”’
“Mũrũ wa mũndũ, ĩra andũ a nyũmba ya Isiraeli atĩrĩ, ‘Inyuĩ mũroiga atĩrĩ: “Mahĩtia na mehia maitũ nĩmatũritũhĩire, na ithuĩ tũkahwererekera nĩ ũndũ wamo. Twakĩhota atĩa gũtũũra muoyo?”’
11 Sọ fún wọn pé, ‘Níwọ́n ìgbà tí mo wà láààyè ni Olúwa Olódùmarè wí, èmi kò ní inú dídùn sí ikú ènìyàn búburú, ṣùgbọ́n dípò bẹ́ẹ̀, kí wọ̀nyí padà kúrò ní ọ̀nà wọn gbogbo kì wọn kì ó sì yè. Yí! Yípadà kúrò ni ọ̀nà búburú gbogbo! Kí ló dé tí ìwọ yóò kú ẹ̀yin ènìyàn Israẹli?’
Meere ũũ, ‘Mwathani Jehova ekuuga atĩrĩ: Ti-itherũ o ta ũrĩa niĩ ndũũraga muoyo-rĩ, ndikenagio nĩ gĩkuũ kĩa andũ arĩa aaganu, no nĩ kaba magarũrũke matigane na mĩthiĩre ĩyo yao, nĩguo matũũre muoyo. Garũrũkai! Garũrũkai, mũtigane na mĩthiĩre ĩyo yanyu mĩũru! Mũgũgĩkua nĩkĩ, inyuĩ andũ a nyũmba ya Isiraeli?’
12 “Nítorí náà, ọmọ ènìyàn, sọ fún àwọn ènìyàn ilẹ̀ rẹ, ‘Ìṣòdodo ti olódodo ènìyàn kì yóò gbà á nígbà tí òun bá ṣe àìgbọ́ràn, ìwà búburú ènìyàn búburú kì yóò mú kí o ṣubú nígbà tí ó bá yí padà kúrò nínú rẹ̀. Bí olódodo ènìyàn bá ṣẹ̀, a kò ni jẹ́ kí ó yè nítorí òdodo rẹ̀ ti tẹ́lẹ̀.’
“Nĩ ũndũ ũcio, wee mũrũ wa mũndũ, ĩra andũ anyu atĩrĩ, ‘Ũthingu wa mũndũ ũrĩa mũthingu ndũkamũhonokia rĩrĩa akaaga gwathĩka, naguo waganu wa mũndũ ũrĩa mwaganu-rĩ, ndũgatũma agwe rĩrĩa akaagarũrũka atigane naguo. Mũndũ ũrĩa mũthingu angĩĩhia-rĩ, ndagetĩkĩrio atũũre muoyo nĩ ũndũ wa ũthingu ũrĩa ararĩ naguo.’
13 Bí mo bá sọ fún olódodo ènìyàn pé òun yóò yè, ṣùgbọ́n nígbà náà tí ó gbẹ́kẹ̀lé òdodo rẹ̀ tí ó sì ṣe búburú, a kò ní rántí nǹkan kan nínú iṣẹ́ òdodo tí o ti ṣe sẹ́yìn; òun yóò kú nítorí búburú tí ó ṣe.
Ingĩĩra mũndũ ũrĩa mũthingu atĩ ti-itherũ nĩegũtũũra muoyo, no hĩndĩ ĩyo we mwene ehie ehokete ũthingu ũcio wake, gũtirĩ gĩĩko kĩa ũthingu o na kĩmwe kĩa iria aneeka gĩkaaririkanwo; agaakua nĩ ũndũ wa ũũru ũcio ekĩte.
14 Bí mo bá sọ fún ènìyàn búburú pé, ‘Ìwọ yóò kú dandan,’ ṣùgbọ́n tí ó bá yípadà kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀, ti o sì ṣe èyí tí ó tọ́ àti èyí tí o yẹ.
Ningĩ ingĩĩra mũndũ ũrĩa mwaganu atĩrĩ, ‘Ti-itherũ nĩũgũkua,’ nowe agarũrũke atigane na mehia make, eke maũndũ marĩa marĩ ma kĩhooto na magĩrĩire,
15 Tí ó bá mu ògo padà, tí o sì da ohun tí o ti jí gbé padà, tí ó sì tẹ̀lé òfin tí ó ń fún ni ní ìyè, tí kò sì ṣe búburú, òun yóò yè dandan; òun kì yóò kú.
angĩcookia kĩrĩa ooete gĩa kũrũgamĩrĩra thiirĩ, na acookie kĩrĩa aiyĩte, na arũmagĩrĩre irĩra cia watho wa kũrũmĩrĩrwo iria iheanaga muoyo, na ndageke ũndũ mũũru-rĩ, ti-itherũ nĩagatũũra muoyo; ndagakua.
16 A kò ní rántí ọ̀kan nínú ẹ̀ṣẹ̀ tí ó ti dá. Ó ti ṣe èyí tí ó tọ àti èyí tí o yẹ; òun yóò sì yè dájúdájú.
Gũtirĩ rĩĩhia o na rĩmwe ekĩte rĩgaacooka kũririkanwo nĩguo orio. Nĩekĩte maũndũ marĩa marĩ ma kĩhooto na magĩrĩire; ti-itherũ nĩagatũũra muoyo.
17 “Síbẹ̀ àwọn ènìyàn ilẹ̀ rẹ sọ pé, ‘Ọ̀nà Olúwa kò tọ́.’ Ṣùgbọ́n ọ̀nà tí àwọn ní ó tọ́.
“No andũ anyu moigaga atĩrĩ, ‘Njĩra ya Mwathani ti ya kĩhooto.’ No nĩ njĩra yao ĩtarĩ ya kĩhooto.
18 Bí olódodo ènìyàn ba yípadà kúrò nínú òdodo rẹ̀, tí o sì ṣe búburú, òun yóò kú nítorí rẹ̀.
Mũndũ mũthingu angĩtigana na ũthingu wake eeke maũndũ mooru-rĩ, nĩagaakua nĩ ũndũ wamo.
19 Bí ènìyàn búburú bá yípadà kúrò nínú búburú rẹ̀, tí ó sì ṣe èyí tí ó tọ́ àti èyí tí ó yẹ, òun yóò yè nípa ṣíṣe bẹ́ẹ̀.
Nake mũndũ mwaganu angĩgarũrũka atigane na waganu wake, eeke maũndũ marĩa marĩ ma kĩhooto na magĩrĩire-rĩ, nĩagatũũra muoyo nĩ ũndũ wa gwĩka ũguo.
20 Síbẹ̀, ilé Israẹli ìwọ wí pé, ‘Ọ̀nà Olúwa ki i ṣe òtítọ́.’ Ṣùgbọ́n èmi yóò ṣe ìdájọ́ ẹnìkọ̀ọ̀kan gẹ́gẹ́ bí ọ̀nà rẹ̀ ṣe rí.”
No rĩrĩ, inyuĩ andũ a nyũmba ya Isiraeli, mugaga atĩrĩ, ‘Njĩra ya Mwathani ti ya kĩhooto.’ No rĩrĩ, niĩ ngaatuĩra o mũndũ wanyu ciira kũringana na mĩthiĩre yake we mwene.”
21 Ní ọjọ́ karùn-ún oṣù kẹwàá, ọdún kejìlá ìkólọ wa, ọkùnrin kan tí ó sá kúrò ni Jerusalẹmu wá sọ́dọ̀ mi, ó sì wí pé, “Ìlú ńlá náà ti ṣubú!”
Mwaka-inĩ wa ikũmi na ĩĩrĩ kuuma twathaamio, mũthenya wa ĩtano wa mweri wa ikũmi-rĩ, mũndũ worĩte kuuma Jerusalemu agĩũka kũrĩ niĩ, akĩnjĩĩra atĩrĩ, “Itũũra rĩrĩa inene nĩrĩgwĩte!”
22 Ní ìrọ̀lẹ́ ọjọ́ tí ó ku ọ̀la tí ẹni tí ó sálọ náà yóò dé, ọwọ́ Olúwa sì níbẹ̀ lára mi, o sì ya ẹnu mi ki ọkùnrin náà tó wá sọ́dọ̀ mi ní òwúrọ̀. Ẹnu mí sì ṣí, èmi kò sì yadi mọ́.
Na rĩrĩ, hwaĩ-wa-ira, mũndũ ũcio ataanakinya, guoko kwa Jehova kwarĩ igũrũ rĩakwa, nake akĩhingũra kanua gakwa, mũndũ ũcio atanooka kũrĩ niĩ rũciinĩ. Nĩ ũndũ ũcio ngĩtumũrwo kanua, na ndiacookire gũkira.
23 Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá:
Ningĩ kiugo kĩa Jehova gĩkĩnginyĩrĩra, ngĩĩrwo atĩrĩ:
24 “Ọmọ ènìyàn, àwọn ènìyàn tí ó ń gbé nínú ìparun ní ilẹ̀ Israẹli ń wí pé, ‘Abrahamu jẹ́ ọkùnrin kan, síbẹ̀ o gba ilẹ̀ ìní náà. Ṣùgbọ́n àwa pọ̀, lóòótọ́ a ti fi ilẹ̀ náà fún wa gẹ́gẹ́ bí ìní wa.’
“Mũrũ wa mũndũ, andũ acio matũũraga kũu kwanangĩku bũrũri-inĩ wa Isiraeli maroiga atĩrĩ, ‘Iburahĩmu aarĩ o mũndũ ũmwe, no nĩegwatĩire bũrũri ũyũ. No ithuĩ tũrĩ aingĩ; ti-itherũ bũrũri ũyũ nĩ ithuĩ tũheetwo ũtuĩke igai riitũ.’
25 Nítorí náà, sọ fún wọn pé, ‘Èyí yìí ní Olúwa Olódùmarè wí: Níwọ́n ìgbà tí ẹ̀yin jẹ ẹran pẹ̀lú ẹ̀jẹ̀ ni inú rẹ̀, tí ẹ̀yin sì wó àwọn ère yín, tí ẹ sì ta ẹ̀jẹ̀ sílẹ̀, ẹ̀yin yóò ha gba ilẹ̀ náà?
Nĩ ũndũ ũcio meere atĩrĩ, ‘Mwathani Jehova ekuuga ũũ: Kuona atĩ inyuĩ mũrĩĩaga nyama irĩ o na thakame, na mũkainamĩrĩra mĩhianano yanyu, na mũgaitithia thakame-rĩ, inyuĩ no mũkĩĩgwatĩre bũrũri ũyũ ũtuĩke wanyu?
26 Ẹ̀yin gbẹ́kẹ̀lé idà yín, ẹ̀yin ṣe nǹkan ìríra, ẹnìkọ̀ọ̀kan nínú yín ba á obìnrin aládùúgbò rẹ̀ jẹ́. Ẹ̀yin yóò ha gba ilẹ̀ náà?’
Inyuĩ mwĩhokaga rũhiũ rwanyu rwa njora, na mũgeeka maũndũ marĩ magigi, na o mũndũ wanyu agathaahia mũtumia wa mũndũ ũrĩa ũngĩ. Inyuĩ no mũkĩĩgwatĩre bũrũri ũyũ ũtuĩke wanyu?’
27 “Sọ èyí fún wọn: ‘Èyí yìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Bí mo ti wà láààyè, àwọn tí ó kúrò nínú ìparun yóò ti ipa idà ṣubú, àwọn tí ẹranko búburú yóò pajẹ, àwọn tí ó sì wà ní ilé ìṣọ́ àti inú ihò òkúta ni àjàkálẹ̀-ààrùn yóò pa.
“Meere atĩrĩ: ‘Mwathani Jehova ekuuga ũũ: Ti-itherũ o ta ũrĩa niĩ ndũũraga muoyo, acio matigaire kũu kwanangĩku makaaniinwo na rũhiũ rwa njora, nao arĩa marĩ mĩgũnda-inĩ ngaamaneana kũrĩ nyamũ cia gĩthaka imatambuurange, nao arĩa marĩ ciĩhitho-inĩ nũmu na ngurunga-inĩ makooragwo nĩ mũthiro.
28 Èmi yóò mú kí ilẹ̀ náà di ahoro, ọ̀ṣọ́ ńlá agbára rẹ̀ kì yóò sí mọ́, àwọn òkè Israẹli yóò sì di ahoro, tí ẹnikẹ́ni kò ní le là á kọjá.
Nĩngatũma bũrũri ũcio wanangĩke ũkire ihooru, naguo hinya ũrĩa wĩtĩĩagĩra nĩũgaathira, na irĩma icio cia Isiraeli nĩigakirio ihooru, kwage mũndũ ũngĩtuĩkanĩria kuo.
29 Nígbà náà, wọn yóò mọ̀ pé èmi ni Olúwa, nígbà tí mo bá mú ilẹ̀ náà di ahoro nítorí gbogbo ohun ìríra tí wọ́n ti ṣe.’
Hĩndĩ ĩyo nĩmakamenya atĩ niĩ nĩ niĩ Jehova, rĩrĩa ngaananga bũrũri ũcio ũkire ihooru, nĩ ũndũ wa maũndũ marĩa mothe marĩ magigi maneeka.’
30 “Ní tìrẹ, ọmọ ènìyàn, àwọn ènìyàn ìlú n sọ̀rọ̀ nípa rẹ ní ẹ̀gbẹ́ ògiri àti ní ẹnu-ọ̀nà ilé wọn, wọ́n ń sọ sí ara wọn wí pé, ‘Ẹ wá gbọ́ iṣẹ́ ti a ran láti ọ̀dọ̀ Olúwa wá.’
“No wee mũrũ wa mũndũ-rĩ, andũ anyu maraaranĩria ũhoro waku marĩ thingo-inĩ, na mĩrango-inĩ ya nyũmba, makeerana atĩrĩ, ‘Ũkaai mũigue ndũmĩrĩri ĩrĩa yũkĩte kuuma kũrĩ Jehova.’
31 Àwọn ènìyàn mi wá sọ́dọ̀ rẹ, gẹ́gẹ́ bí wọn ṣe ń ṣe, wọn sì jókòó níwájú rẹ láti fetísí ọ̀rọ̀ rẹ, ṣùgbọ́n wọn kò mú wá sí ìṣe. Ẹnu wọn ni wọ́n fi n sọ̀rọ̀ ìfọkànsìn, ṣùgbọ́n ọkàn wọn ní ìwọra èrè tí kò tọ́.
Andũ akwa mokaga kũrĩ we, o ta ũrĩa mamenyerete gwĩka, na magaikara thĩ mbere yaku mathikĩrĩrie ciugo ciaku, no rĩrĩ, matiĩkaga ũrĩa ciugĩte. Merutagĩra na tũnua twao, no ngoro ciao ikorokagĩra uumithio ũtarĩ wa kĩhooto.
32 Nítòótọ́ lójú wọn, ìwọ jẹ́ ẹni kan tí ó ń kọrin ìfẹ́ pẹ̀lú ohun dídára àti ohun èlò orin kíkọ, nítorí wọ́n gbọ́ ọ̀rọ̀ rẹ ṣùgbọ́n wọn kò mu wá sí ìṣe.
Ti-itherũ harĩ o-rĩ, wee ũtuĩkĩte o ta mũndũ ũrĩa ũinaga nyĩmbo cia wendo arĩ na mũgambo mwega, na akahũũra kĩnanda wega, nĩgũkorwo nĩmaiguaga ciugo ciaku no matiĩkaga ũrĩa ciugĩte.
33 “Nígbà tí gbogbo ìwọ̀nyí bá ṣẹ tí yóò sì ṣẹ dandan, nígbà náà wọn yóò mọ̀ pé wòlíì kan ti wa láàrín wọn rí.”
“Hĩndĩ ĩrĩa maũndũ macio mothe makaahinga, na ti-itherũ nĩmakahinga, hĩndĩ ĩyo nĩmakamenya atĩ thĩinĩ wao nĩ kwarĩ na mũnabii.”

< Ezekiel 33 >