< Ezekiel 31 >

1 Ní ọjọ́ kìn-ín-ní, oṣù kẹta ọdún kọkànlá, ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá:
Și s-a întâmplat [că], în al unsprezecelea an, în [luna] a treia, în [ziua] întâi a lunii, cuvântul DOMNULUI a venit la mine, spunând:
2 “Ọmọ ènìyàn, sọ fún Farao ọba Ejibiti àti sí ìjọ rẹ̀: “‘Ta ní a le fiwé ọ ní ọláńlá?
Fiu al omului, vorbește lui Faraon, împăratul Egiptului, și mulțimii lui: Ca cine ești tu în măreția ta?
3 Kíyèsi Asiria, tí ó jẹ́ igi kedari ni Lebanoni ní ìgbà kan rí, pẹ̀lú àwọn ẹ̀ka dáradára tí ó ṣẹ́ ìji bo igbó náà; tí ó ga sókè, òkè rẹ̀ lókè ni ewé tí ó nípọn wà.
Iată, asirianul [era] un cedru în Liban cu crengi frumoase și frunziș umbros și de o statură înaltă; și vârful lui era printre ramurile dese.
4 Omi mú un dàgbàsókè: orísun omi tí ó jinlẹ̀ mú kí o dàgbàsókè; àwọn odo rẹ̀ ń sàn yí ìdí rẹ̀ ká, ó sì rán ìṣàn omi rẹ̀ sí gbogbo igi orí pápá.
Apele îl făceau mare, adâncul l-a înălțat sus cu râurile lui curgând de jur împrejurul plantelor lui și își trimitea râulețele la toți copacii câmpului.
5 Nítorí náà ó ga sí òkè fíofío ju gbogbo igi orí pápá lọ; ẹ̀ka rẹ̀ pọ̀ sí i àwọn ẹ̀ka rẹ̀ sì gùn, wọn tẹ́ rẹrẹ nítorí ọ̀pọ̀lọpọ̀ omi.
De aceea înălțimea lui era înălțată deasupra tuturor copacilor câmpului și ramurile lui erau înmulțite și crengile lui s-au lungit datorită mulțimii apelor, când creștea repede.
6 Ẹyẹ ojú ọ̀run kọ ilé sí ẹ̀ka rẹ̀ gbogbo ẹranko igbó ń bímọ ní abẹ́ ẹ̀ka rẹ̀; gbogbo orílẹ̀-èdè ńlá ń gbé abẹ́ ìji rẹ̀.
Toate păsările cerului își făceau cuiburile în ramurile lui; și sub crengile lui toate fiarele câmpului își nășteau puii și la umbra lui locuiau toate națiunile mari.
7 Ọláńlá ní ẹwà rẹ̀ jẹ́, pẹ̀lú títẹ́ rẹrẹ ẹ̀ka rẹ̀, nítorí gbòǹgbò rẹ̀ lọ sí ìsàlẹ̀ sí ibi tí ọ̀pọ̀lọpọ̀ omi wà.
Astfel era el frumos în măreția lui, în lungimea crengilor lui, pentru că rădăcina lui era lângă ape mari.
8 Àwọn igi kedari nínú ọgbà Ọlọ́run kò lè è bò ó mọ́lẹ̀; tàbí kí àwọn igi junifa ṣe déédé pẹ̀lú ẹ̀ka rẹ̀, tàbí kí a fi igi títẹ́ rẹrẹ wé ẹ̀ka rẹ̀, kò sí igi nínú ọgbà Ọlọ́run tí ó dà bí rẹ̀ ní ẹwà rẹ̀.
Cedrii din grădina lui Dumnezeu nu puteau să îl ascundă; brazii nu erau asemenea ramurilor lui și castanii nu erau precum crengile lui; nici vreun copac din grădina lui Dumnezeu nu îi era asemenea în frumusețea lui.
9 Mo mú kí ó ní ẹwà pẹ̀lú ẹ̀ka lọ́pọ̀lọ́pọ̀ tó fi jẹ́ ìlara àwọn igi gbogbo ní Edeni tí í ṣe ọgbà Ọlọ́run.
Eu îl făcusem frumos prin mulțimea crengilor lui; astfel încât toți copacii Edenului care [erau] în grădina lui Dumnezeu, îl invidiau.
10 “‘Nítorí náà, èyí yìí ní Olúwa Olódùmarè wí: Nítorí pé ó ga lọ sókè fíofío, tí ó sì gbé òkè rẹ̀ ga ju ewé tí ó nípọn lọ, àti nítorí pé gíga rẹ mú kí ó gbéraga,
De aceea, astfel spune Domnul DUMNEZEU: Pentru că te-ai înălțat în înălțime și el și-a crescut repede vârful printre ramurile dese și inima lui s-a înălțat în înălțimea lui;
11 mo fi lé alákòóso àwọn orílẹ̀-èdè náà lọ́wọ́, fún un láti fi ṣe ẹ̀tọ́ fún un gẹ́gẹ́ bí ìwà búburú rẹ̀. Mo pa á tì sí ẹ̀gbẹ́ kan,
Eu de aceea l-am dat în mâna celui puternic dintre păgâni; el într-adevăr va avea de a face cu el: l-am alungat pentru stricăciunea lui.
12 àwọn orílẹ̀-èdè àjèjì aláìláàánú jùlọ ké e lulẹ̀, wọn sì fi kalẹ̀. Àwọn ẹ̀ka rẹ̀ ṣubú sórí òkè àti sí gbogbo àárín àwọn òkè; àwọn ẹ̀ka rẹ̀ tí ó ṣẹ nà sílẹ̀ ní gbogbo àlàfo jíjìn ilẹ̀. Gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè ilẹ̀ ayé jáde kúrò ní abẹ́ ìji rẹ̀ wọn sì fi sílẹ̀.
Și străinii, tiranii națiunilor, l-au stârpit și l-au părăsit; crengile lui au căzut pe munți și în toate văile și ramurile lui sunt rupte prin toate râurile țării; și toate popoarele pământului au coborât de la umbra lui și l-au părăsit.
13 Gbogbo àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run ṣe àtìpó ni orí igi tí ó ṣubú lulẹ̀ náà, gbogbo àwọn ẹranko igbó wà ní àárín ẹ̀ka rẹ̀.
Peste ruina lui toate păsările cerului vor rămâne și toate fiarele câmpului vor fi peste crengile lui;
14 Nítorí náà kò sí igi mìíràn lẹ́gbẹ̀ẹ́ omi tí ó lè fi ìgbéraga ga sókè fíofío, tí yóò sì gbé sókè rẹ̀ ga ju ewé tí ó nípọn lọ. Kò sí igi mìíràn tí ó ní omi tó bẹ́ẹ̀ tí ó lè ga tó bẹ́ẹ̀; gbogbo wọn ni a kádàrá ikú fún, fún ìsàlẹ̀ ilẹ̀, ní àárín àwọn alààyè ènìyàn, pẹ̀lú àwọn tí o lọ sí ọ̀gbun ní ìsàlẹ̀.
Ca niciunul dintre toți copacii de lângă ape să nu se înalțe pe ei înșiși pentru înălțimea lor, nici să nu își crească repede vârful printre ramurile dese, nici copacii lor să nu stea drepți în înălțimea lor, toți care beau apă, pentru că toți sunt dați morții, în părțile de jos ale pământului, în mijlocul copiilor oamenilor, cu cei care coboară în groapă.
15 “‘Èyí ni Olúwa Olódùmarè wí: Ní ọjọ́ ti a mú u wá sí isà òkú mo fi ọ̀fọ̀ ṣíṣe bo orísun omi jíjìn náà, mo dá àwọn ìṣàn omi rẹ̀ dúró, àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ omi rẹ̀ ní a dí lọ́nà. Nítorí rẹ̀ mo fi ìwúwo ọkàn wọ Lebanoni ní aṣọ, gbogbo igi igbó gbẹ dànù. (Sheol h7585)
Astfel spune Domnul DUMNEZEU: În ziua când el a coborât în mormânt eu am pus să se facă o jelire; am acoperit adâncul pentru el și am oprit potopurile lui și apele cele mari au fost oprite; și am făcut Libanul să jelească pentru el și toți copacii câmpului s-au topit pentru el. (Sheol h7585)
16 Mo mú kí orílẹ̀-èdè wárìrì sì ìró ìṣubú rẹ̀ nígbà tí mo mú un wá sí ìsàlẹ̀ isà òkú pẹ̀lú àwọn tí ó lọ sí ọ̀gbun ìsàlẹ̀. Nígbà náà gbogbo igi Edeni, àṣàyàn àti èyí tí ó dára jùlọ nínú Lebanoni, gbogbo igi tí ó ní omi dáradára ni a tù nínú ni ayé ìsàlẹ̀. (Sheol h7585)
Am făcut națiunile să se zguduie la sunetul căderii lui, când l-am aruncat jos în iad cu cei care coboară în groapă; și toți copacii Edenului, cei mai aleși și cei mai buni ai Libanului, toți cei care beau apă, vor fi mângâiați în părțile de jos ale pământului. (Sheol h7585)
17 Àwọn tí ó ń gbé ní abẹ́ òjìji rẹ̀, àwọn àjèjì rẹ ní àárín àwọn orílẹ̀-èdè náà, ti lọ sí ìsàlẹ̀ isà òkú pẹ̀lú rẹ̀, ní dídárapọ̀ mọ́ àwọn tí a fi idà pa. (Sheol h7585)
Ei de asemenea au coborât cu el în iad la cei uciși cu sabia; și [cei care erau] brațul lui, [care] locuiau sub umbra lui în mijlocul păgânilor. (Sheol h7585)
18 “‘Èwo lára igi Edeni ní a lè fiwé ọ ní dídán àti ọláńlá? Síbẹ̀ ìwọ, gan an wá sílẹ̀ pẹ̀lú àwọn igi Edeni lọ sí ìsàlẹ̀ ilẹ̀; ìwọ yóò sùn ni àárín àwọn aláìkọlà, pẹ̀lú àwọn tí a fi idà pa. “‘Èyí yìí ní Farao àti ìjọ rẹ̀, ní Olúwa Olódùmarè wí.’”
Astfel, cu cine ești tu asemenea în glorie și în măreție printre copacii Edenului? Totuși vei fi coborât cu copacii Edenului în părțile de jos ale pământului; te vei culca în mijlocul celor necircumciși, cu cei uciși de sabie. Acesta [este] Faraon și toată mulțimea lui, spune Domnul DUMNEZEU.

< Ezekiel 31 >