< Ezekiel 31 >

1 Ní ọjọ́ kìn-ín-ní, oṣù kẹta ọdún kọkànlá, ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá:
Potem, w jedenastym roku, w trzecim [miesiącu], pierwszego [dnia] tego miesiąca, doszło do mnie słowo PANA mówiące:
2 “Ọmọ ènìyàn, sọ fún Farao ọba Ejibiti àti sí ìjọ rẹ̀: “‘Ta ní a le fiwé ọ ní ọláńlá?
Synu człowieczy, mów do faraona, króla Egiptu, i do jego ludu: Do kogo jesteś podobny w swojej wielkości?
3 Kíyèsi Asiria, tí ó jẹ́ igi kedari ni Lebanoni ní ìgbà kan rí, pẹ̀lú àwọn ẹ̀ka dáradára tí ó ṣẹ́ ìji bo igbó náà; tí ó ga sókè, òkè rẹ̀ lókè ni ewé tí ó nípọn wà.
Oto Assur [był] jak cedr na Libanie, o pięknych gałęziach i szeroko rzucającym cieniu, o wysokim wzroście, a jego wierzchołek był wśród gęstych gałęzi.
4 Omi mú un dàgbàsókè: orísun omi tí ó jinlẹ̀ mú kí o dàgbàsókè; àwọn odo rẹ̀ ń sàn yí ìdí rẹ̀ ká, ó sì rán ìṣàn omi rẹ̀ sí gbogbo igi orí pápá.
Wody dodały mu wzrostu i głębiny go wywyższyły, ich rzeki roztoczyły dokoła jego korzeń i puściły swoje strumienie ku wszystkim drzewom polnym.
5 Nítorí náà ó ga sí òkè fíofío ju gbogbo igi orí pápá lọ; ẹ̀ka rẹ̀ pọ̀ sí i àwọn ẹ̀ka rẹ̀ sì gùn, wọn tẹ́ rẹrẹ nítorí ọ̀pọ̀lọpọ̀ omi.
Dlatego swym wzrostem przewyższył wszystkie drzewa polne i jego konary rozkrzewiły się, a dzięki obfitości wód rozszerzyły się jego gałęzie, które wypuścił.
6 Ẹyẹ ojú ọ̀run kọ ilé sí ẹ̀ka rẹ̀ gbogbo ẹranko igbó ń bímọ ní abẹ́ ẹ̀ka rẹ̀; gbogbo orílẹ̀-èdè ńlá ń gbé abẹ́ ìji rẹ̀.
Na jego gałęziach uwiło sobie gniazda wszelkie ptactwo niebieskie, pod jego gałęziami rodziły się wszelkie zwierzęta polne i w jego cieniu siadały wszystkie wielkie narody.
7 Ọláńlá ní ẹwà rẹ̀ jẹ́, pẹ̀lú títẹ́ rẹrẹ ẹ̀ka rẹ̀, nítorí gbòǹgbò rẹ̀ lọ sí ìsàlẹ̀ sí ibi tí ọ̀pọ̀lọpọ̀ omi wà.
Był piękny w swojej wielkości przez długość swoich gałęzi, gdyż jego korzeń był nad obfitymi wodami.
8 Àwọn igi kedari nínú ọgbà Ọlọ́run kò lè è bò ó mọ́lẹ̀; tàbí kí àwọn igi junifa ṣe déédé pẹ̀lú ẹ̀ka rẹ̀, tàbí kí a fi igi títẹ́ rẹrẹ wé ẹ̀ka rẹ̀, kò sí igi nínú ọgbà Ọlọ́run tí ó dà bí rẹ̀ ní ẹwà rẹ̀.
Cedry w ogrodzie Bożym nie przewyższały go. Cyprysy nie były podobne do jego gałęzi i drzewa kasztanowe nie były podobne do jego konarów. Żadne drzewo w ogrodzie Bożym nie dorównało mu swoją pięknością.
9 Mo mú kí ó ní ẹwà pẹ̀lú ẹ̀ka lọ́pọ̀lọ́pọ̀ tó fi jẹ́ ìlara àwọn igi gbogbo ní Edeni tí í ṣe ọgbà Ọlọ́run.
Ja uczyniłem go pięknym przez mnóstwo jego gałęzi. Zazdrościły mu wszystkie drzewa Edenu, które [były] w ogrodzie Bożym.
10 “‘Nítorí náà, èyí yìí ní Olúwa Olódùmarè wí: Nítorí pé ó ga lọ sókè fíofío, tí ó sì gbé òkè rẹ̀ ga ju ewé tí ó nípọn lọ, àti nítorí pé gíga rẹ mú kí ó gbéraga,
Dlatego tak mówi Pan BÓG: Ponieważ wysoko wyrósł, wywyższył swój wierzchołek wśród gęstych gałęzi i jego serce podniosło się z powodu jego wysokości;
11 mo fi lé alákòóso àwọn orílẹ̀-èdè náà lọ́wọ́, fún un láti fi ṣe ẹ̀tọ́ fún un gẹ́gẹ́ bí ìwà búburú rẹ̀. Mo pa á tì sí ẹ̀gbẹ́ kan,
Wydałem go w rękę najmocniejszego z narodów, aby się z nim srogo obszedł. Odrzuciłem go z powodu jego niegodziwości.
12 àwọn orílẹ̀-èdè àjèjì aláìláàánú jùlọ ké e lulẹ̀, wọn sì fi kalẹ̀. Àwọn ẹ̀ka rẹ̀ ṣubú sórí òkè àti sí gbogbo àárín àwọn òkè; àwọn ẹ̀ka rẹ̀ tí ó ṣẹ nà sílẹ̀ ní gbogbo àlàfo jíjìn ilẹ̀. Gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè ilẹ̀ ayé jáde kúrò ní abẹ́ ìji rẹ̀ wọn sì fi sílẹ̀.
A cudzoziemcy, ci najsrożsi z narodów, wycięli go i porzucili. Jego gałęzie padły na górach i we wszystkich dolinach i jego konary połamały się nad wszystkimi strumieniami tej ziemi. Wszystkie ludy ziemi ustąpiły spod jego cienia i opuściły go.
13 Gbogbo àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run ṣe àtìpó ni orí igi tí ó ṣubú lulẹ̀ náà, gbogbo àwọn ẹranko igbó wà ní àárín ẹ̀ka rẹ̀.
Na jego powalonym [pniu] osiądzie wszelkie ptactwo niebieskie i na jego gałęziach będzie wszelki zwierz polny;
14 Nítorí náà kò sí igi mìíràn lẹ́gbẹ̀ẹ́ omi tí ó lè fi ìgbéraga ga sókè fíofío, tí yóò sì gbé sókè rẹ̀ ga ju ewé tí ó nípọn lọ. Kò sí igi mìíràn tí ó ní omi tó bẹ́ẹ̀ tí ó lè ga tó bẹ́ẹ̀; gbogbo wọn ni a kádàrá ikú fún, fún ìsàlẹ̀ ilẹ̀, ní àárín àwọn alààyè ènìyàn, pẹ̀lú àwọn tí o lọ sí ọ̀gbun ní ìsàlẹ̀.
Aby żadne drzewo [stojące] nad wodami nie wynosiło się z powodu swego wzrostu i nie wypuszczało swoich wierzchołków wśród gęstych gałęzi, i nie pyszniło się swoją wysokością żadne drzewo, które pije wodę. Ci wszyscy bowiem są wydani na śmierć, wrzuceni do najgłębszych stron ziemi, wśród synów ludzkich wraz z tymi, którzy zstępują do dołu.
15 “‘Èyí ni Olúwa Olódùmarè wí: Ní ọjọ́ ti a mú u wá sí isà òkú mo fi ọ̀fọ̀ ṣíṣe bo orísun omi jíjìn náà, mo dá àwọn ìṣàn omi rẹ̀ dúró, àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ omi rẹ̀ ní a dí lọ́nà. Nítorí rẹ̀ mo fi ìwúwo ọkàn wọ Lebanoni ní aṣọ, gbogbo igi igbó gbẹ dànù. (Sheol h7585)
Tak mówi Pan BÓG: W dniu, kiedy zstąpił do grobu, wzbudziłem lament, zamknąłem dla niego głębinę i wstrzymałem jej strumienie, i zastawiłem wielkie wody. Sprawiłem, że Liban okrył się ciemnością z jego powodu i z jego powodu wszystkie drzewa polne zemdlały. (Sheol h7585)
16 Mo mú kí orílẹ̀-èdè wárìrì sì ìró ìṣubú rẹ̀ nígbà tí mo mú un wá sí ìsàlẹ̀ isà òkú pẹ̀lú àwọn tí ó lọ sí ọ̀gbun ìsàlẹ̀. Nígbà náà gbogbo igi Edeni, àṣàyàn àti èyí tí ó dára jùlọ nínú Lebanoni, gbogbo igi tí ó ní omi dáradára ni a tù nínú ni ayé ìsàlẹ̀. (Sheol h7585)
Na huk jego upadku zadrżały narody, gdy go wrzucałem do piekła z tymi, co do dołu zstępują. Wszystkie drzewa Edenu, najwyborniejsze i najlepsze z Libanu, które piją wodę, doznają pociechy w najgłębszych stronach ziemi. (Sheol h7585)
17 Àwọn tí ó ń gbé ní abẹ́ òjìji rẹ̀, àwọn àjèjì rẹ ní àárín àwọn orílẹ̀-èdè náà, ti lọ sí ìsàlẹ̀ isà òkú pẹ̀lú rẹ̀, ní dídárapọ̀ mọ́ àwọn tí a fi idà pa. (Sheol h7585)
One także zstąpiły z nim do piekła, do zabitych mieczem, którzy byli jego ramieniem i którzy mieszkali w jego cieniu wśród narodów. (Sheol h7585)
18 “‘Èwo lára igi Edeni ní a lè fiwé ọ ní dídán àti ọláńlá? Síbẹ̀ ìwọ, gan an wá sílẹ̀ pẹ̀lú àwọn igi Edeni lọ sí ìsàlẹ̀ ilẹ̀; ìwọ yóò sùn ni àárín àwọn aláìkọlà, pẹ̀lú àwọn tí a fi idà pa. “‘Èyí yìí ní Farao àti ìjọ rẹ̀, ní Olúwa Olódùmarè wí.’”
Do kogo byłeś podobny chwałą i wielkością między drzewami Edenu? Oto zostaniesz zrzucony wraz z drzewami Edenu do najgłębszych stron ziemi. Będziesz leżał wśród nieobrzezanych wraz z pobitymi mieczem. To jest z faraonem i całą jego rzeszą – mówi Pan BÓG.

< Ezekiel 31 >