< Ezekiel 31 >

1 Ní ọjọ́ kìn-ín-ní, oṣù kẹta ọdún kọkànlá, ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá:
Un vienpadsmitā gadā, trešā mēnesī, pirmā mēneša dienā Tā Kunga vārds uz mani notika sacīdams:
2 “Ọmọ ènìyàn, sọ fún Farao ọba Ejibiti àti sí ìjọ rẹ̀: “‘Ta ní a le fiwé ọ ní ọláńlá?
Cilvēka bērns, runā uz Faraonu, Ēģiptes ķēniņu, un uz viņa ļaužu pulku: kam tu esi līdzīgs savā augstībā?
3 Kíyèsi Asiria, tí ó jẹ́ igi kedari ni Lebanoni ní ìgbà kan rí, pẹ̀lú àwọn ẹ̀ka dáradára tí ó ṣẹ́ ìji bo igbó náà; tí ó ga sókè, òkè rẹ̀ lókè ni ewé tí ó nípọn wà.
Redzi, Asurs bija ciedra koks uz Lībanus, skaistiem zariem un kuplām lapām un slaiku augumu, un viņa galotne bija iekš mākoņiem.
4 Omi mú un dàgbàsókè: orísun omi tí ó jinlẹ̀ mú kí o dàgbàsókè; àwọn odo rẹ̀ ń sàn yí ìdí rẹ̀ ká, ó sì rán ìṣàn omi rẹ̀ sí gbogbo igi orí pápá.
Ūdens viņu darīja lielu, un jūras dziļumi viņu paaugstināja, viņa upes gāja apkārt ap dārziem, un savus ūdeņus tas sūtīja pie visiem lauka kokiem.
5 Nítorí náà ó ga sí òkè fíofío ju gbogbo igi orí pápá lọ; ẹ̀ka rẹ̀ pọ̀ sí i àwọn ẹ̀ka rẹ̀ sì gùn, wọn tẹ́ rẹrẹ nítorí ọ̀pọ̀lọpọ̀ omi.
Tāpēc viņa augums bija augstāks pār visiem lauka kokiem, un viņa zari vairojās un viņa zariņi plaukstot pagarinājās caur to lielo ūdeni.
6 Ẹyẹ ojú ọ̀run kọ ilé sí ẹ̀ka rẹ̀ gbogbo ẹranko igbó ń bímọ ní abẹ́ ẹ̀ka rẹ̀; gbogbo orílẹ̀-èdè ńlá ń gbé abẹ́ ìji rẹ̀.
Visi putni apakš debess taisīja ligzdas viņa zaros, un visi lauka zvēri vedās apakš viņa zariem, un visas lielās tautas sēdēja viņa pavēnī.
7 Ọláńlá ní ẹwà rẹ̀ jẹ́, pẹ̀lú títẹ́ rẹrẹ ẹ̀ka rẹ̀, nítorí gbòǹgbò rẹ̀ lọ sí ìsàlẹ̀ sí ibi tí ọ̀pọ̀lọpọ̀ omi wà.
Tā tas bija skaists savā lielumā un savu zaru garumā, jo viņa sakne bija pie daudz ūdeņiem.
8 Àwọn igi kedari nínú ọgbà Ọlọ́run kò lè è bò ó mọ́lẹ̀; tàbí kí àwọn igi junifa ṣe déédé pẹ̀lú ẹ̀ka rẹ̀, tàbí kí a fi igi títẹ́ rẹrẹ wé ẹ̀ka rẹ̀, kò sí igi nínú ọgbà Ọlọ́run tí ó dà bí rẹ̀ ní ẹwà rẹ̀.
Ciedru koki Dieva dārzā viņu neaptumšoja un priedes viņa zariem nelīdzinājās, un kļavu koki nebija tādi kā viņa zariņi, neviens koks Dieva dārzā viņam nelīdzinājās skaistumā.
9 Mo mú kí ó ní ẹwà pẹ̀lú ẹ̀ka lọ́pọ̀lọ́pọ̀ tó fi jẹ́ ìlara àwọn igi gbogbo ní Edeni tí í ṣe ọgbà Ọlọ́run.
Es viņu biju darījis tik skaistu caur viņa zaru pulku, ka visi Ēdenes koki Dieva dārzā viņu apskauda.
10 “‘Nítorí náà, èyí yìí ní Olúwa Olódùmarè wí: Nítorí pé ó ga lọ sókè fíofío, tí ó sì gbé òkè rẹ̀ ga ju ewé tí ó nípọn lọ, àti nítorí pé gíga rẹ mú kí ó gbéraga,
Tāpēc tā saka Tas Kungs Dievs: tādēļ ka tu tā biji cēlies garumā, un ka viņš savu galotni izstiepis līdz padebešiem, un viņa sirds sava augstuma dēļ lepojās,
11 mo fi lé alákòóso àwọn orílẹ̀-èdè náà lọ́wọ́, fún un láti fi ṣe ẹ̀tọ́ fún un gẹ́gẹ́ bí ìwà búburú rẹ̀. Mo pa á tì sí ẹ̀gbẹ́ kan,
Tāpēc Es viņu nodevu rokā tautu varenajam, ar viņu darīt pēc patikšanas; Es viņu izdzinu viņa bezdievības dēļ.
12 àwọn orílẹ̀-èdè àjèjì aláìláàánú jùlọ ké e lulẹ̀, wọn sì fi kalẹ̀. Àwọn ẹ̀ka rẹ̀ ṣubú sórí òkè àti sí gbogbo àárín àwọn òkè; àwọn ẹ̀ka rẹ̀ tí ó ṣẹ nà sílẹ̀ ní gbogbo àlàfo jíjìn ilẹ̀. Gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè ilẹ̀ ayé jáde kúrò ní abẹ́ ìji rẹ̀ wọn sì fi sílẹ̀.
Un sveši, tie tautu briesmīgākie, viņu nocirta un to nometa, viņa zari krita uz kalniem un pa visām ielejām, un viņa zariņi tapa nogāzti visās zemes gravās. Un visas zemes tautas aizgāja no viņa pavēņa un viņu atstāja.
13 Gbogbo àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run ṣe àtìpó ni orí igi tí ó ṣubú lulẹ̀ náà, gbogbo àwọn ẹranko igbó wà ní àárín ẹ̀ka rẹ̀.
Visi putni apakš debess nolaidās uz viņa, un visi lauka zvēri bija uz viņa zariem;
14 Nítorí náà kò sí igi mìíràn lẹ́gbẹ̀ẹ́ omi tí ó lè fi ìgbéraga ga sókè fíofío, tí yóò sì gbé sókè rẹ̀ ga ju ewé tí ó nípọn lọ. Kò sí igi mìíràn tí ó ní omi tó bẹ́ẹ̀ tí ó lè ga tó bẹ́ẹ̀; gbogbo wọn ni a kádàrá ikú fún, fún ìsàlẹ̀ ilẹ̀, ní àárín àwọn alààyè ènìyàn, pẹ̀lú àwọn tí o lọ sí ọ̀gbun ní ìsàlẹ̀.
Lai nekādi pie ūdens dēstīti koki nelepojās sava auguma pēc, un savu galotni nestiepj līdz mākoņiem, un nekādi no ūdens slacināti koki nepaļaujas uz sev pašiem sava augstuma dēļ; jo tie visi nāvei ir nodoti uz zemes apakšu, cilvēka bērnu vidū, pie tiem, kas grimst bedrē.
15 “‘Èyí ni Olúwa Olódùmarè wí: Ní ọjọ́ ti a mú u wá sí isà òkú mo fi ọ̀fọ̀ ṣíṣe bo orísun omi jíjìn náà, mo dá àwọn ìṣàn omi rẹ̀ dúró, àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ omi rẹ̀ ní a dí lọ́nà. Nítorí rẹ̀ mo fi ìwúwo ọkàn wọ Lebanoni ní aṣọ, gbogbo igi igbó gbẹ dànù. (Sheol h7585)
Tā saka Tas Kungs Dievs: tai dienā, kad tas ellē nogrima, tad Es cēlu bēdas, Es viņa dēļ apklāju dziļumus un aizturēju viņa upes, un tie varenie ūdeņi apstājās, un Es darīju, ka Lībanus viņa dēļ sērojās, un visi lauka koki nokalta viņa dēļ. (Sheol h7585)
16 Mo mú kí orílẹ̀-èdè wárìrì sì ìró ìṣubú rẹ̀ nígbà tí mo mú un wá sí ìsàlẹ̀ isà òkú pẹ̀lú àwọn tí ó lọ sí ọ̀gbun ìsàlẹ̀. Nígbà náà gbogbo igi Edeni, àṣàyàn àti èyí tí ó dára jùlọ nínú Lebanoni, gbogbo igi tí ó ní omi dáradára ni a tù nínú ni ayé ìsàlẹ̀. (Sheol h7585)
No viņa kritiena trokšņa Es pagānus darīju drebam, kad Es viņu ellē nogrūdu pie tiem, kas grimst bedrē. Un visi Ēdenes koki, tie izlasītie un labākie uz Lībanus, visi no ūdens slacinātie koki iepriecinājās zemes apakšā. (Sheol h7585)
17 Àwọn tí ó ń gbé ní abẹ́ òjìji rẹ̀, àwọn àjèjì rẹ ní àárín àwọn orílẹ̀-èdè náà, ti lọ sí ìsàlẹ̀ isà òkú pẹ̀lú rẹ̀, ní dídárapọ̀ mọ́ àwọn tí a fi idà pa. (Sheol h7585)
Tie nogrima arīdzan līdz ar viņu ellē pie tiem zobena nokautiem, kas kā viņa palīgi bija sēdējuši viņa pavēnī starp tautām. (Sheol h7585)
18 “‘Èwo lára igi Edeni ní a lè fiwé ọ ní dídán àti ọláńlá? Síbẹ̀ ìwọ, gan an wá sílẹ̀ pẹ̀lú àwọn igi Edeni lọ sí ìsàlẹ̀ ilẹ̀; ìwọ yóò sùn ni àárín àwọn aláìkọlà, pẹ̀lú àwọn tí a fi idà pa. “‘Èyí yìí ní Farao àti ìjọ rẹ̀, ní Olúwa Olódùmarè wí.’”
Kam starp Ēdenes kokiem tu tad esi līdzīgs godā un augstumā? Arī tu tapsi nogrūsts ar Ēdenes kokiem zemes apakšā, tu gulēsi vidū starp neapgraizītiem, pie zobenu nokautiem. Tas ir Faraons un viss viņa ļaužu pulks, saka Tas Kungs Dievs.

< Ezekiel 31 >