< Ezekiel 31 >

1 Ní ọjọ́ kìn-ín-ní, oṣù kẹta ọdún kọkànlá, ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá:
Eso age amola oubi osoda amola oda gida amo ninia mugululi misi esoga, Hina Gode da nama amane sia: i,
2 “Ọmọ ènìyàn, sọ fún Farao ọba Ejibiti àti sí ìjọ rẹ̀: “‘Ta ní a le fiwé ọ ní ọláńlá?
“Dunu egefe! Idibidi hina bagade amola ea fi dunu huluane ilima amane sia: mu, ‘Di da gasa bagade! Na da di adila defema: bela: ?
3 Kíyèsi Asiria, tí ó jẹ́ igi kedari ni Lebanoni ní ìgbà kan rí, pẹ̀lú àwọn ẹ̀ka dáradára tí ó ṣẹ́ ìji bo igbó náà; tí ó ga sókè, òkè rẹ̀ lókè ni ewé tí ó nípọn wà.
Di da dolo ifa Lebanone soge ganodini gala agoai. Ea amoda da hisi iaha amola sedadeba: le, mu mobi digisa.
4 Omi mú un dàgbàsókè: orísun omi tí ó jinlẹ̀ mú kí o dàgbàsókè; àwọn odo rẹ̀ ń sàn yí ìdí rẹ̀ ká, ó sì rán ìṣàn omi rẹ̀ sí gbogbo igi orí pápá.
Amo alema: ne, hano dialu. Amola osobo hagudu, e ha: i ima: ne hano galu. Amo hano da dolo ifa ea sogebi amola iwila ifa huluane amoma hano iasu.
5 Nítorí náà ó ga sí òkè fíofío ju gbogbo igi orí pápá lọ; ẹ̀ka rẹ̀ pọ̀ sí i àwọn ẹ̀ka rẹ̀ sì gùn, wọn tẹ́ rẹrẹ nítorí ọ̀pọ̀lọpọ̀ omi.
Dolo ifa ea sedade da ifa oda amo baligi, amola ea amoda da gadugagili gasa bagade alei. Bai hano bagade galuba: le.
6 Ẹyẹ ojú ọ̀run kọ ilé sí ẹ̀ka rẹ̀ gbogbo ẹranko igbó ń bímọ ní abẹ́ ẹ̀ka rẹ̀; gbogbo orílẹ̀-èdè ńlá ń gbé abẹ́ ìji rẹ̀.
Sio fi enoenoi huluane da ea amoda da: iya diasu bibisu. Sigua ohe ilia da ea ougiha mano lalelegesu. Osobo bagade fifi asi gala da ea ougiha helefisu.
7 Ọláńlá ní ẹwà rẹ̀ jẹ́, pẹ̀lú títẹ́ rẹrẹ ẹ̀ka rẹ̀, nítorí gbòǹgbò rẹ̀ lọ sí ìsàlẹ̀ sí ibi tí ọ̀pọ̀lọpọ̀ omi wà.
Amo ifa da ida: iwane ba: su. E da sedadedafa amola ea amoda da sedadedafa afufui. Ea difi da hano hagudu amoga dodoa sa: i.
8 Àwọn igi kedari nínú ọgbà Ọlọ́run kò lè è bò ó mọ́lẹ̀; tàbí kí àwọn igi junifa ṣe déédé pẹ̀lú ẹ̀ka rẹ̀, tàbí kí a fi igi títẹ́ rẹrẹ wé ẹ̀ka rẹ̀, kò sí igi nínú ọgbà Ọlọ́run tí ó dà bí rẹ̀ ní ẹwà rẹ̀.
Dolo ifa eno Gode Ea ifabi ganodini da e defemu hamedei. ‘Fe’ ifa huluane ilia amoda da amo dolo ifa ea amoda hame defei. Amola ‘baleini’ ifa huluane ilia amoda da ea amoda hame defei. Ifa eno Gode Ea ifabi ganodini da amo ea ida: iwane ba: su, amo defemu hamedei ba: i.
9 Mo mú kí ó ní ẹwà pẹ̀lú ẹ̀ka lọ́pọ̀lọ́pọ̀ tó fi jẹ́ ìlara àwọn igi gbogbo ní Edeni tí í ṣe ọgbà Ọlọ́run.
Na da amo ifa nina: hamoi. Ea amoda da: la afufui ba: i. E da ifa huluane Idini soge (Gode Ea ifabi) amo ganodini lelesulu amo baligisu.
10 “‘Nítorí náà, èyí yìí ní Olúwa Olódùmarè wí: Nítorí pé ó ga lọ sókè fíofío, tí ó sì gbé òkè rẹ̀ ga ju ewé tí ó nípọn lọ, àti nítorí pé gíga rẹ mú kí ó gbéraga,
Wali, Na, Ouligisudafa Hina Gode da dima amo ifa amo da alele, mu mobiga digi, hou da ema doaga: mu, dima olelemu. E da sedade alele, gilisili hidale dawa: i.
11 mo fi lé alákòóso àwọn orílẹ̀-èdè náà lọ́wọ́, fún un láti fi ṣe ẹ̀tọ́ fún un gẹ́gẹ́ bí ìwà búburú rẹ̀. Mo pa á tì sí ẹ̀gbẹ́ kan,
Amaiba: le, Na da ema higale, yolesi. Na da e ga fi ouligisu dunuma iagamu. Amo ifa da wadela: le bagade hamoiba: le, Ba: bilone hina bagade da ea hamoi defele, se bidi imunu.
12 àwọn orílẹ̀-èdè àjèjì aláìláàánú jùlọ ké e lulẹ̀, wọn sì fi kalẹ̀. Àwọn ẹ̀ka rẹ̀ ṣubú sórí òkè àti sí gbogbo àárín àwọn òkè; àwọn ẹ̀ka rẹ̀ tí ó ṣẹ nà sílẹ̀ ní gbogbo àlàfo jíjìn ilẹ̀. Gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè ilẹ̀ ayé jáde kúrò ní abẹ́ ìji rẹ̀ wọn sì fi sílẹ̀.
Ga fi sedigi dunu da amo ifa aba sanawane, yolesimu. Ea amoda dagai da goumi amola fago huluane soge ganodini amo da: iya legela dadafumu. Amola fifi asi gala ea ougiha esalu, huluane da afia: mu.
13 Gbogbo àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run ṣe àtìpó ni orí igi tí ó ṣubú lulẹ̀ náà, gbogbo àwọn ẹranko igbó wà ní àárín ẹ̀ka rẹ̀.
Sio da misini, ifa fili sa: i da: iya fimu. Amola sigua ohe da ea amoda giadofale masunu.
14 Nítorí náà kò sí igi mìíràn lẹ́gbẹ̀ẹ́ omi tí ó lè fi ìgbéraga ga sókè fíofío, tí yóò sì gbé sókè rẹ̀ ga ju ewé tí ó nípọn lọ. Kò sí igi mìíràn tí ó ní omi tó bẹ́ẹ̀ tí ó lè ga tó bẹ́ẹ̀; gbogbo wọn ni a kádàrá ikú fún, fún ìsàlẹ̀ ilẹ̀, ní àárín àwọn alààyè ènìyàn, pẹ̀lú àwọn tí o lọ sí ọ̀gbun ní ìsàlẹ̀.
Amaiba: le, wali winini ifa eno (hano i amowane) da amo ifa defele hame alemu, amola amo agoane mu mobi dodoa hame heda: mu. Amo huluane da dunu egefe ilia bogosu defele bogogia: le, dunu amo da musa: bogoi sogebi amoga sa: i, amo gilisimusa: sa: imu.”
15 “‘Èyí ni Olúwa Olódùmarè wí: Ní ọjọ́ ti a mú u wá sí isà òkú mo fi ọ̀fọ̀ ṣíṣe bo orísun omi jíjìn náà, mo dá àwọn ìṣàn omi rẹ̀ dúró, àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ omi rẹ̀ ní a dí lọ́nà. Nítorí rẹ̀ mo fi ìwúwo ọkàn wọ Lebanoni ní aṣọ, gbogbo igi igbó gbẹ dànù. (Sheol h7585)
Ouligisudafa Hina Gode da amane sia: sa, “Amo esoha ifa da bogoi sogebi amoga ahoasea, Na da didigia: su dawa: digisu hamoma: ne, hano hagudu amo e dedeboma: mu. Na hano huluane mae masa: ne, gagulaligimu. Amo ifa da bogobeba: le, Na da Lebanone Goumi amoga gasima: ne hamomu, amola iwila ifa huluane bioma: mu. (Sheol h7585)
16 Mo mú kí orílẹ̀-èdè wárìrì sì ìró ìṣubú rẹ̀ nígbà tí mo mú un wá sí ìsàlẹ̀ isà òkú pẹ̀lú àwọn tí ó lọ sí ọ̀gbun ìsàlẹ̀. Nígbà náà gbogbo igi Edeni, àṣàyàn àti èyí tí ó dára jùlọ nínú Lebanoni, gbogbo igi tí ó ní omi dáradára ni a tù nínú ni ayé ìsàlẹ̀. (Sheol h7585)
Na da amo ifa bogoi sogebi amoga asunasisia, ea dafasu ga: da fifi asi gala huluane fofogomu. Idini soge ifa huluane amola Lebanone ifa (amo da hano noga: le i, amola noga: idafa) amo huluane da hagudu sa: i dagoi - ilia huluane da ea dafai ba: sea, hahawane ba: mu. (Sheol h7585)
17 Àwọn tí ó ń gbé ní abẹ́ òjìji rẹ̀, àwọn àjèjì rẹ ní àárín àwọn orílẹ̀-èdè náà, ti lọ sí ìsàlẹ̀ isà òkú pẹ̀lú rẹ̀, ní dídárapọ̀ mọ́ àwọn tí a fi idà pa. (Sheol h7585)
Ilia da amo dolo ifa gilisili bogoi sogebiga, eno ifa musa: amoga sa: i amoma gilisimusa: sa: imu. Amola huluane da ea ougiha esalu, amo da fifi asi gala amoga esaloma: ne afagogolesi ba: mu. (Sheol h7585)
18 “‘Èwo lára igi Edeni ní a lè fiwé ọ ní dídán àti ọláńlá? Síbẹ̀ ìwọ, gan an wá sílẹ̀ pẹ̀lú àwọn igi Edeni lọ sí ìsàlẹ̀ ilẹ̀; ìwọ yóò sùn ni àárín àwọn aláìkọlà, pẹ̀lú àwọn tí a fi idà pa. “‘Èyí yìí ní Farao àti ìjọ rẹ̀, ní Olúwa Olódùmarè wí.’”
Amo dolo da fedege Idibidi hina bagade amola ea fi dunu huluane. Idini soge ifa da ea sedade amola noga: i ba: su defele hame ba: i. Be wali, Idini soge ifa defele, e da bogoi sogebi amoga gudu sa: ili, amola Gode Ea hou hame lalegagui dunu amola gegesu ganodini fane legei dunu ilima gilisimu. Na da sia: i dagoi,” Ouligisu Hina Gode da amane sia: sa.

< Ezekiel 31 >