< Ezekiel 30 >

1 Ọ̀rọ̀ Olúwa tún tọ̀ mí wá: wí pé:
RAB bana şöyle seslendi:
2 “Ọmọ ènìyàn, sọtẹ́lẹ̀ kí o sì wí pé: ‘Báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí: “‘Hu, kí o sì wí pé, “Ó ṣe fún ọjọ́ náà!”
“İnsanoğlu, peygamberlik et ve de ki, ‘Egemen RAB şöyle diyor: “‘Ah o gün diye haykır.
3 Nítorí ọjọ́ náà súnmọ́ tòsí àní ọjọ́ Olúwa súnmọ́ tòsí, ọjọ́ tí ọjọ́ ìkùùkuu ṣú dúdú, àsìkò ìparun fún àwọn kèfèrí.
Çünkü o gün yakın. RAB'bin günü yakın, Bulutların günü, Ulusların yıkım zamanı.
4 Idà yóò wá sórí Ejibiti ìrora ńlá yóò sì wá sórí Kuṣi. Nígbà tí àwọn tí a pa yóò ṣubú ní Ejibiti wọn yóò kò ọrọ̀ rẹ̀ lọ ìpìlẹ̀ rẹ̀ yóò sì wó lulẹ̀.
Bir kılıç Mısır'a karşı çıkacak. Kûş'u acılar saracak. Mısır'da vurulanlar yere serilince Ülkenin serveti alınıp götürülecek, Temelleri yok edilecek.
5 Kuṣi àti Puti, Libia, Ludi àti gbogbo Arabia, Kubu àti àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà tí ó mulẹ̀ yóò ṣubú nípa idà pẹ̀lú Ejibiti.
Mısır'la birlikte Kûş, Pût, Lud, Arabistan, Kuv ve antlaşma yaptığım halkım Kılıçtan geçirilecek.
6 “‘Èyí yìí ní Olúwa wí: “‘Àwọn àlejò Ejibiti yóò ṣubú agbára ìgbéraga rẹ yóò kùnà láti Migdoli títí dé Siene, wọn yóò ti ipa idà ṣubú nínú rẹ; ní Olúwa Olódùmarè wí.
“‘RAB şöyle diyor: Mısır'ı destekleyenler öldürülecek, Mısır'ın övündüğü ordu çökecek, Migdol'dan Asvan'a dek kılıçtan geçirilecekler. Böyle diyor Egemen RAB.
7 Wọn yóò sì wà lára àwọn ilẹ̀ tí ó di ahoro, ìlú rẹ yóò sì wà ní ara àwọn ìlú tí ó di ahoro.
Kimsesiz kalmış ülkeler arasında Kimsesiz kalacaklar. Kentleri viran olmuş kentler gibi olacak.
8 Lẹ́yìn náà wọn yóò mọ̀ pé èmi ní Olúwa, nígbà tí mo bá gbé iná kalẹ̀ ní Ejibiti tí gbogbo àwọn olùrànlọ́wọ́ rẹ̀ bá parun.
Mısır'ı ateşe verdiğimde, Onu destekleyenler ezildiğinde, Benim RAB olduğumu anlayacaklar.
9 “‘Ní ọjọ́ náà oníṣẹ́ yóò ti ọ̀dọ̀ mi jáde nínú ọkọ̀ ojú omi láti dẹ́rùbà Kuṣi tí ó wà nínú àlàáfíà. Ìrora yóò wá sórí wọn gẹ́gẹ́ bí ti ọjọ́ ìparun Ejibiti. Kíyèsi i, ó dé.
“‘O gün kaygısız Kûşlular'ı korkutmak için gemilerle ulaklar göndereceğim. Mısır'ın yıkım günü geldiğinde korkuya kapılacaklar. İşte o gün geliyor.
10 “‘Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí: “‘Èmi yóò mú òpin bá ọ̀gọ̀ọ̀rọ̀ àwọn ènìyàn Ejibiti láti ọwọ́ Nebukadnessari ọba Babeli.
“‘Egemen RAB şöyle diyor: Babil Kralı Nebukadnessar aracılığıyla Mısır'ın zenginliğine son vereceğim.
11 Òun àti àwọn ológun rẹ̀ ẹ̀rù àwọn orílẹ̀-èdè ní a o mú wá láti pa ilẹ̀ náà run. Wọn yóò fa idà wọn yọ sí Ejibiti ilẹ̀ náà yóò sì kún fún àwọn tí a pa.
O ve ordusu, ulusların en acımasızı, Ülkeyi yerle bir etmek için gelecekler. Mısır'a karşı kılıçlarını çekecek, Ülkeyi öldürülenlerle dolduracaklar.
12 Èmi yóò mú kí àwọn odò Naili gbẹ, Èmi yóò sì ta ilẹ̀ náà fún àwọn ènìyàn búburú: láti ọwọ́ àwọn àjèjì ènìyàn, Èmi yóò jẹ́ kí ilẹ̀ náà àti gbogbo ohun tí ó wá nínú rẹ ṣòfò. Èmi Olúwa ni ó ti sọ ọ́.
Nil'in kanallarını kurutup Ülkeyi kötü kişilere teslim edeceğim, Ülkeyi de içindeki her şeyi de Yabancılar eliyle viran edeceğim. Bunu ben RAB söylüyorum.
13 “‘Báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí: “‘Èmi yóò pa àwọn òrìṣà run, Èmi yóò sì mú kí òpin dé bá ère gbígbẹ́ ni Memfisi. Kò ní sí ọmọ-aládé mọ́ ní Ejibiti, Èmi yóò mú kí ìbẹ̀rù gba gbogbo ilẹ̀ náà.
Egemen RAB şöyle diyor: Putları yok edecek, Nof'taki değersiz putlara son vereceğim. Mısır'da artık önder olmayacak, Ülkeye korku salacağım.
14 Èmi yóò sì mú kí Paturosi di ahoro, èmi yóò fi iná sí Ṣoani, èmi yóò sì fi ìyà jẹ Tebesi.
Patros'u viraneye çevirecek, Soan'ı ateşe verecek, No Kenti'ni cezalandıracağım.
15 Èmi yóò tú ìbínú mi jáde sórí Pelusiumu ìlú odi Ejibiti èmi yóò sì ké àkójọpọ̀ Tebesi kúrò.
Öfkemi Mısır'ın kalesi Sin üzerine boşaltacak, Kalabalık No halkına son vereceğim.
16 Èmi yóò ti iná bọ Ejibiti Pelusiumu yóò japoró ní ìrora. Ìjì líle yóò jà ní Tebesi Memfisi yóò wà ìpọ́njú ní ìgbà gbogbo.
Mısır'ı ateşe vereceğim, Sin acıdan kıvranacak, No Kenti'nin surları yarılacak, Nof sürekli tedirgin olacak.
17 Àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin ní Heliopolisi àti Bubasiti yóò ti ipa idà ṣubú wọn yóò sì kó àwọn ìlú wọn ní ìgbèkùn.
On Kenti ve Pi-Beset gençleri Kılıçtan geçirilecek, Oradaki halk sürgüne gönderilecek.
18 Ojú ọjọ́ yóò ṣókùnkùn ní Tafanesi nígbà tí mo bá já àjàgà Ejibiti kúrò; níbẹ̀ agbára iyì rẹ̀ yóò dópin wọn yóò fi ìkùùkuu bò ó àwọn abúlé rẹ ní wọn yóò lọ sí ìgbèkùn.
Tahpanhes'te Mısır'ın boyunduruğunu kırdığım zaman, Orada gündüz geceye dönecek, Övündüğü orduya son verilecek, Kent bulutlarla kaplanacak, Köylerindeki halk sürgüne gönderilecek.
19 Nítorí náà, Èmi yóò mú ki ìjìyà wá sórí Ejibiti, wọn yóò sì mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.’”
Mısır'ı böyle cezalandırdığımda Benim RAB olduğumu anlayacaklar.’”
20 Ní ọjọ́ keje oṣù kìn-ín-ní ọdún kọkànlá ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá,
Sürgünlüğümüzün on birinci yılı, birinci ayın yedinci günü RAB bana şöyle seslendi:
21 “Ọmọ ènìyàn, Èmi ti ṣẹ́ apá Farao ọba Ejibiti. A kò ì tí ì di apá náà papọ̀ láti mu kí ó san, a kò sì ti di i si àárín igi pẹlẹbẹ kí o lè ni agbára tó láti di idà mú.
“İnsanoğlu, firavunun kolunu kırdım. İyileşmesin, kılıç tutacak kadar güçlenmesin diye kimse onu bağlamadı, sargı beziyle sarmadı.
22 Nítorí náà, báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí: Èmi lòdì sí Farao ọba Ejibiti. Èmi yóò sẹ́ apá rẹ̀ méjèèjì, èyí tí ó dára àti èyí tí a ti ṣẹ́ pẹ̀lú, yóò sì mú kí idà bọ́ sọnù ní ọwọ́ rẹ̀.
Bu yüzden Egemen RAB şöyle diyor: Firavuna karşıyım. Her iki kolunu, sağlam olanı da kırık olanı da kıracağım. Kılıcı elinden düşüreceğim.
23 Èmi yóò sì fọ́n àwọn ènìyàn Ejibiti ká sí àárín àwọn orílẹ̀-èdè, èmi yóò sì tú wọn ká gbogbo ilẹ̀.
Mısırlılar'ı uluslar arasına gönderecek, ülkelere dağıtacağım.
24 Èmi yóò mú kí apá ọba Babeli ní agbára, èmi yóò sì fi idà mi sí ọwọ́ rẹ, ṣùgbọ́n èmi yóò ṣẹ́ apá Farao, yóò sì kérora níwájú rẹ̀ bí ọkùnrin tí a sá ní àṣápa.
Babil Kralı'nın kollarını güçlendirip kılıcımı onun eline vereceğim. Firavunun ise kollarını kıracağım. Babil Kralı'nın önünde ağır yaralı biri gibi inleyecek.
25 Èmi yóò mú kí apá ọba Babeli lé, ṣùgbọ́n apá Farao yóò sì rọ. Nígbà náà wọn yóò mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa, nígbà tí mo bá mú idà mi sí ọwọ́ ọba Babeli yóò sì fi idà náà kọlu Ejibiti.
Babil Kralı'nın gücüne güç katacak, firavunun gücünü zayıflatacağım. Kılıcımı Babil Kralı'nın eline verdiğimde ve o kılıcı Mısır'a doğru uzattığında, benim RAB olduğumu anlayacaklar.
26 Èmi yóò fọ́n àwọn ara Ejibiti ká sí àárín orílẹ̀-èdè, èmi yóò sì tú wọn ká sí àárín orílẹ̀-èdè, èmi yóò sì tú wọn ká sí gbogbo ilẹ̀. Nígbà náà wọn yóò mọ̀ pé èmi ni Olúwa.”
Mısırlılar'ı uluslar arasına gönderecek, ülkelere dağıtacağım. O zaman benim RAB olduğumu anlayacaklar.”

< Ezekiel 30 >