< Ezekiel 30 >

1 Ọ̀rọ̀ Olúwa tún tọ̀ mí wá: wí pé:
Cuvântul DOMNULUI a venit din nou la mine, spunând:
2 “Ọmọ ènìyàn, sọtẹ́lẹ̀ kí o sì wí pé: ‘Báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí: “‘Hu, kí o sì wí pé, “Ó ṣe fún ọjọ́ náà!”
Fiu al omului, profețește și spune: Astfel spune Domnul DUMNEZEU: Urlați: Vai ce zi!
3 Nítorí ọjọ́ náà súnmọ́ tòsí àní ọjọ́ Olúwa súnmọ́ tòsí, ọjọ́ tí ọjọ́ ìkùùkuu ṣú dúdú, àsìkò ìparun fún àwọn kèfèrí.
Pentru că ziua [este] aproape, chiar ziua DOMNULUI [este] aproape, o zi noroasă; va fi timpul păgânilor.
4 Idà yóò wá sórí Ejibiti ìrora ńlá yóò sì wá sórí Kuṣi. Nígbà tí àwọn tí a pa yóò ṣubú ní Ejibiti wọn yóò kò ọrọ̀ rẹ̀ lọ ìpìlẹ̀ rẹ̀ yóò sì wó lulẹ̀.
Și sabia va veni asupra Egiptului și mare durere va fi în Etiopia, când cei uciși vor cădea în Egipt și ei vor lua mulțimea lui și temeliile lui vor fi dărâmate.
5 Kuṣi àti Puti, Libia, Ludi àti gbogbo Arabia, Kubu àti àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà tí ó mulẹ̀ yóò ṣubú nípa idà pẹ̀lú Ejibiti.
Etiopia și Libia și Lidia și tot poporul amestecat și Cub și bărbații țării care este în alianță, vor cădea cu ei prin sabie.
6 “‘Èyí yìí ní Olúwa wí: “‘Àwọn àlejò Ejibiti yóò ṣubú agbára ìgbéraga rẹ yóò kùnà láti Migdoli títí dé Siene, wọn yóò ti ipa idà ṣubú nínú rẹ; ní Olúwa Olódùmarè wí.
Astfel spune DOMNUL: De asemenea cei care sprijină Egiptul vor cădea; și mândria puterii lui va coborî; din turnul de la Siene vor cădea în el prin sabie, spune Domnul DUMNEZEU.
7 Wọn yóò sì wà lára àwọn ilẹ̀ tí ó di ahoro, ìlú rẹ yóò sì wà ní ara àwọn ìlú tí ó di ahoro.
Și vor fi pustiiți în mijlocul țărilor [care sunt] pustiite, iar cetățile lui vor fi în mijlocul cetăților [care sunt] risipite.
8 Lẹ́yìn náà wọn yóò mọ̀ pé èmi ní Olúwa, nígbà tí mo bá gbé iná kalẹ̀ ní Ejibiti tí gbogbo àwọn olùrànlọ́wọ́ rẹ̀ bá parun.
Și vor cunoaște că eu [sunt] DOMNUL, când voi fi pus un foc în Egipt și [când] toți care îl ajută vor fi nimiciți.
9 “‘Ní ọjọ́ náà oníṣẹ́ yóò ti ọ̀dọ̀ mi jáde nínú ọkọ̀ ojú omi láti dẹ́rùbà Kuṣi tí ó wà nínú àlàáfíà. Ìrora yóò wá sórí wọn gẹ́gẹ́ bí ti ọjọ́ ìparun Ejibiti. Kíyèsi i, ó dé.
În acea zi vor ieși mesageri dinaintea mea, în corăbii, pentru a înspăimânta pe etiopienii cei nepăsători; și mare durere va veni asupra lor, ca în ziua Egiptului, pentru că, iată, vine.
10 “‘Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí: “‘Èmi yóò mú òpin bá ọ̀gọ̀ọ̀rọ̀ àwọn ènìyàn Ejibiti láti ọwọ́ Nebukadnessari ọba Babeli.
Astfel spune Domnul DUMNEZEU: Voi face de asemenea mulțimea Egiptului să înceteze prin mâna lui Nebucadnețar, împăratul Babilonului.
11 Òun àti àwọn ológun rẹ̀ ẹ̀rù àwọn orílẹ̀-èdè ní a o mú wá láti pa ilẹ̀ náà run. Wọn yóò fa idà wọn yọ sí Ejibiti ilẹ̀ náà yóò sì kún fún àwọn tí a pa.
El și poporul lui împreună cu el, tiranii națiunilor, vor fi aduși ca să distrugă țara; și ei își vor scoate săbiile împotriva Egiptului și vor umple țara cu cei uciși.
12 Èmi yóò mú kí àwọn odò Naili gbẹ, Èmi yóò sì ta ilẹ̀ náà fún àwọn ènìyàn búburú: láti ọwọ́ àwọn àjèjì ènìyàn, Èmi yóò jẹ́ kí ilẹ̀ náà àti gbogbo ohun tí ó wá nínú rẹ ṣòfò. Èmi Olúwa ni ó ti sọ ọ́.
Și voi usca râurile și voi vinde țara în mâna celor stricați; și voi risipi țara și tot ce este în ea, prin mâna străinilor; eu DOMNUL am vorbit [aceasta.]
13 “‘Báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí: “‘Èmi yóò pa àwọn òrìṣà run, Èmi yóò sì mú kí òpin dé bá ère gbígbẹ́ ni Memfisi. Kò ní sí ọmọ-aládé mọ́ ní Ejibiti, Èmi yóò mú kí ìbẹ̀rù gba gbogbo ilẹ̀ náà.
Astfel spune Domnul DUMNEZEU: Voi distruge de asemenea idolii și voi face să înceteze chipurile [lor] din Nof; și nu va mai fi prinț din țara Egiptului; și voi pune frică în țara Egiptului.
14 Èmi yóò sì mú kí Paturosi di ahoro, èmi yóò fi iná sí Ṣoani, èmi yóò sì fi ìyà jẹ Tebesi.
Și voi pustii Patrosul și voi pune foc în Țoan și voi face judecăți în No.
15 Èmi yóò tú ìbínú mi jáde sórí Pelusiumu ìlú odi Ejibiti èmi yóò sì ké àkójọpọ̀ Tebesi kúrò.
Și îmi voi turna furia asupra Sinului, tăria Egiptului; și voi stârpi mulțimea din No.
16 Èmi yóò ti iná bọ Ejibiti Pelusiumu yóò japoró ní ìrora. Ìjì líle yóò jà ní Tebesi Memfisi yóò wà ìpọ́njú ní ìgbà gbogbo.
Și voi pune un foc în Egipt; Sinul va avea mare durere și No va fi sfâșiat în două și zilnic Noful [va avea] strâmtorări.
17 Àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin ní Heliopolisi àti Bubasiti yóò ti ipa idà ṣubú wọn yóò sì kó àwọn ìlú wọn ní ìgbèkùn.
Tinerii din Aven și din Pi-Beset vor cădea prin sabie; iar aceste [cetăți] vor merge în captivitate.
18 Ojú ọjọ́ yóò ṣókùnkùn ní Tafanesi nígbà tí mo bá já àjàgà Ejibiti kúrò; níbẹ̀ agbára iyì rẹ̀ yóò dópin wọn yóò fi ìkùùkuu bò ó àwọn abúlé rẹ ní wọn yóò lọ sí ìgbèkùn.
La Tahpanes de asemenea se va întuneca ziua când voi sfărâma acolo jugurile Egiptului; și fastul tăriei lui va înceta în el; cât despre el, un nor îl va acoperi, iar fiicele lui vor merge în captivitate.
19 Nítorí náà, Èmi yóò mú ki ìjìyà wá sórí Ejibiti, wọn yóò sì mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.’”
Astfel voi face judecăți în Egipt; și vor cunoaște că eu [sunt] DOMNUL.
20 Ní ọjọ́ keje oṣù kìn-ín-ní ọdún kọkànlá ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá,
Și s-a întâmplat în al unsprezecelea an, în [luna] întâi, în [ziua] a șaptea a lunii, [că] a venit la mine cuvântul DOMNULUI, spunând:
21 “Ọmọ ènìyàn, Èmi ti ṣẹ́ apá Farao ọba Ejibiti. A kò ì tí ì di apá náà papọ̀ láti mu kí ó san, a kò sì ti di i si àárín igi pẹlẹbẹ kí o lè ni agbára tó láti di idà mú.
Fiu al omului, eu am frânt brațul lui Faraon, împăratul Egiptului; și, iată, acesta nu va fi legat pentru a se vindeca, pentru a-i pune un bandaj ca să îl lege, pentru a-l face tare să țină sabia.
22 Nítorí náà, báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí: Èmi lòdì sí Farao ọba Ejibiti. Èmi yóò sẹ́ apá rẹ̀ méjèèjì, èyí tí ó dára àti èyí tí a ti ṣẹ́ pẹ̀lú, yóò sì mú kí idà bọ́ sọnù ní ọwọ́ rẹ̀.
De aceea astfel spune Domnul DUMNEZEU: Iată, eu [sunt] împotriva lui Faraon, împăratul Egiptului; și îi voi frânge brațele, cel tare și pe cel frânt; și voi face să cadă sabia din mâna lui.
23 Èmi yóò sì fọ́n àwọn ènìyàn Ejibiti ká sí àárín àwọn orílẹ̀-èdè, èmi yóò sì tú wọn ká gbogbo ilẹ̀.
Și voi împrăștia pe egipteni printre națiuni și îi voi risipi prin țări.
24 Èmi yóò mú kí apá ọba Babeli ní agbára, èmi yóò sì fi idà mi sí ọwọ́ rẹ, ṣùgbọ́n èmi yóò ṣẹ́ apá Farao, yóò sì kérora níwájú rẹ̀ bí ọkùnrin tí a sá ní àṣápa.
Și voi întări brațele împăratului Babilonului și voi pune sabia mea în mâna lui; dar voi frânge brațele lui Faraon, iar el va geme înaintea lui cu gemetele [omului] rănit de moarte.
25 Èmi yóò mú kí apá ọba Babeli lé, ṣùgbọ́n apá Farao yóò sì rọ. Nígbà náà wọn yóò mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa, nígbà tí mo bá mú idà mi sí ọwọ́ ọba Babeli yóò sì fi idà náà kọlu Ejibiti.
Dar voi întări brațele împăratului Babilonului, iar brațele lui Faraon vor cădea; și vor cunoaște că eu [sunt] DOMNUL, când voi pune sabia mea în mâna împăratului Babilonului și el o va întinde asupra țării Egiptului.
26 Èmi yóò fọ́n àwọn ara Ejibiti ká sí àárín orílẹ̀-èdè, èmi yóò sì tú wọn ká sí àárín orílẹ̀-èdè, èmi yóò sì tú wọn ká sí gbogbo ilẹ̀. Nígbà náà wọn yóò mọ̀ pé èmi ni Olúwa.”
Și voi împrăștia pe egipteni printre națiuni și îi voi risipi prin țări; și vor cunoaște că eu [sunt] DOMNUL.

< Ezekiel 30 >