< Ezekiel 30 >

1 Ọ̀rọ̀ Olúwa tún tọ̀ mí wá: wí pé:
LEUM GOD El sifil kaskas nu sik ac fahk,
2 “Ọmọ ènìyàn, sọtẹ́lẹ̀ kí o sì wí pé: ‘Báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí: “‘Hu, kí o sì wí pé, “Ó ṣe fún ọjọ́ náà!”
“Mwet sukawil moul la, palye ac fahkak kas su nga, LEUM GOD Fulatlana, fahk inge. Kom in wowoyak ac fahk kas inge: Sie len aksangeng summa!
3 Nítorí ọjọ́ náà súnmọ́ tòsí àní ọjọ́ Olúwa súnmọ́ tòsí, ọjọ́ tí ọjọ́ ìkùùkuu ṣú dúdú, àsìkò ìparun fún àwọn kèfèrí.
Len sac apkuranme, len se ma LEUM GOD El ac mukuila, Sie len lohsrlosr ke pukunyeng, ac len in lokoalok nu sin mutunfacl uh.
4 Idà yóò wá sórí Ejibiti ìrora ńlá yóò sì wá sórí Kuṣi. Nígbà tí àwọn tí a pa yóò ṣubú ní Ejibiti wọn yóò kò ọrọ̀ rẹ̀ lọ ìpìlẹ̀ rẹ̀ yóò sì wó lulẹ̀.
Ac fah oasr mweun in facl Egypt Ac ongoiya lulap in acn Ethiopia. Mwet puspis in acn Egypt ac fah anwuki. Facl sac ac fah kunausyukla Ac ma nukewa we fah musalla.
5 Kuṣi àti Puti, Libia, Ludi àti gbogbo Arabia, Kubu àti àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà tí ó mulẹ̀ yóò ṣubú nípa idà pẹ̀lú Ejibiti.
“Mwet mweun nukewa ma utuku liki acn Ethiopia, Libya, Lydia, Arabia, Kub, ac oayapa liki inmasrlon mwet luk sifacna, ac fah misa ke mweun sac.”
6 “‘Èyí yìí ní Olúwa wí: “‘Àwọn àlejò Ejibiti yóò ṣubú agbára ìgbéraga rẹ yóò kùnà láti Migdoli títí dé Siene, wọn yóò ti ipa idà ṣubú nínú rẹ; ní Olúwa Olódùmarè wí.
LEUM GOD El fahk, “Liki acn Migdol layen epang, nwe in acn Aswan layen eir, mwet nukewa ma loango acn Egypt ac fah anwuki ke mweun uh. Un mwet mweun watwen lun acn Egypt ac fah kunausyukla. Nga, LEUM GOD Fulatlana, pa fahk ma inge.
7 Wọn yóò sì wà lára àwọn ilẹ̀ tí ó di ahoro, ìlú rẹ yóò sì wà ní ara àwọn ìlú tí ó di ahoro.
Facl sac ac fah arulana sikiyukla yohk liki acn nukewa faclu, ac siti we uh ac fah oan arulana musalsalu.
8 Lẹ́yìn náà wọn yóò mọ̀ pé èmi ní Olúwa, nígbà tí mo bá gbé iná kalẹ̀ ní Ejibiti tí gbogbo àwọn olùrànlọ́wọ́ rẹ̀ bá parun.
Ke nga ac esukak acn Egypt, ac mwet loango acn we nukewa misa uh, na elos ac fah etu lah nga pa LEUM GOD.
9 “‘Ní ọjọ́ náà oníṣẹ́ yóò ti ọ̀dọ̀ mi jáde nínú ọkọ̀ ojú omi láti dẹ́rùbà Kuṣi tí ó wà nínú àlàáfíà. Ìrora yóò wá sórí wọn gẹ́gẹ́ bí ti ọjọ́ ìparun Ejibiti. Kíyèsi i, ó dé.
“Ke len se ma kunanula acn Egypt, nga ac fah supwala mwet utuk kas in oayak som nu Ethiopia, in okasak mwet we su tiana etu ke ma sikyak inge, ac elos ac fah arulana tuninfongla. Len sacn akuranna tuku!”
10 “‘Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí: “‘Èmi yóò mú òpin bá ọ̀gọ̀ọ̀rọ̀ àwọn ènìyàn Ejibiti láti ọwọ́ Nebukadnessari ọba Babeli.
LEUM GOD Fulatlana El fahk, “Nga ac fah orekmakunul Tokosra Nebuchadnezzar lun acn Babylonia in tulokinya mwe kasrup lun Egypt.
11 Òun àti àwọn ológun rẹ̀ ẹ̀rù àwọn orílẹ̀-èdè ní a o mú wá láti pa ilẹ̀ náà run. Wọn yóò fa idà wọn yọ sí Ejibiti ilẹ̀ náà yóò sì kún fún àwọn tí a pa.
El, ac mwet mweun sulallal lal, ac fah tuku ac sukela acn we. Elos ac fah mweuni acn Egypt ke cutlass, na facl sac ac fah sessesla ke monin mwet misa.
12 Èmi yóò mú kí àwọn odò Naili gbẹ, Èmi yóò sì ta ilẹ̀ náà fún àwọn ènìyàn búburú: láti ọwọ́ àwọn àjèjì ènìyàn, Èmi yóò jẹ́ kí ilẹ̀ náà àti gbogbo ohun tí ó wá nínú rẹ ṣòfò. Èmi Olúwa ni ó ti sọ ọ́.
Nga ac fah oru Infacl Nile in paola, ac sang facl Egypt nu inpoun mwet koluk. Mwet in mutunfacl saya ac fah arulana kunausla acn we nufon. Nga, LEUM GOD, pa fahk ma inge.”
13 “‘Báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí: “‘Èmi yóò pa àwọn òrìṣà run, Èmi yóò sì mú kí òpin dé bá ère gbígbẹ́ ni Memfisi. Kò ní sí ọmọ-aládé mọ́ ní Ejibiti, Èmi yóò mú kí ìbẹ̀rù gba gbogbo ilẹ̀ náà.
Na LEUM GOD Fulatlana El fahk, “Nga ac fah kunausla ma sruloala ac god lusrongten nukewa in acn Memphis. Ac fah wangin mwet in leumi acn Egypt, ac nga fah oru tuh mwet nukewa in arulana sangeng.
14 Èmi yóò sì mú kí Paturosi di ahoro, èmi yóò fi iná sí Ṣoani, èmi yóò sì fi ìyà jẹ Tebesi.
Nga ac oru tuh siti Pathros layen eir in Egypt in sikiyukla, ac esukak siti Zoan layen epang. Nga ac fah kalyei Thebes, capital lun acn we.
15 Èmi yóò tú ìbínú mi jáde sórí Pelusiumu ìlú odi Ejibiti èmi yóò sì ké àkójọpọ̀ Tebesi kúrò.
Nga ac fah oru tuh Pelusium, su potiyukyak arulana ku, in pula kasrkusrak luk. Nga fah kunausla un mwet mweun lun acn Thebes.
16 Èmi yóò ti iná bọ Ejibiti Pelusiumu yóò japoró ní ìrora. Ìjì líle yóò jà ní Tebesi Memfisi yóò wà ìpọ́njú ní ìgbà gbogbo.
Nga fah esukak acn Egypt, ac siti Pelusium ac fah muta in keok lulap. Pot lun acn Thebes ac fah kunausyukla, ac siti uh ac fah sronoti.
17 Àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin ní Heliopolisi àti Bubasiti yóò ti ipa idà ṣubú wọn yóò sì kó àwọn ìlú wọn ní ìgbèkùn.
Mukul fusr in siti Heliopolis ac Bubastis ac fah misa ke mweun, ac mwet saya ac fah sruoh ac muta in kapir.
18 Ojú ọjọ́ yóò ṣókùnkùn ní Tafanesi nígbà tí mo bá já àjàgà Ejibiti kúrò; níbẹ̀ agbára iyì rẹ̀ yóò dópin wọn yóò fi ìkùùkuu bò ó àwọn abúlé rẹ ní wọn yóò lọ sí ìgbèkùn.
Lohsr lulap ac fah putati nu fin Tahpanhes ke nga ac kunausla ku lun acn Egypt ac aksafyela ku se ma elos konkin kac. Sie pukunyeng ac fah afinya facl Egypt, ac mwet in siti nukewa we ac fah sruoh ac muta in kapir.
19 Nítorí náà, Èmi yóò mú ki ìjìyà wá sórí Ejibiti, wọn yóò sì mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.’”
Ke nga ac kalyei acn Egypt in lumah se inge, elos ac fah etu lah nga pa LEUM GOD.”
20 Ní ọjọ́ keje oṣù kìn-ín-ní ọdún kọkànlá ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá,
Ke len akitkosr in malem se meet ke yac aksingoul sie in sruoh lasr, LEUM GOD El kaskas nu sik ac fahk,
21 “Ọmọ ènìyàn, Èmi ti ṣẹ́ apá Farao ọba Ejibiti. A kò ì tí ì di apá náà papọ̀ láti mu kí ó san, a kò sì ti di i si àárín igi pẹlẹbẹ kí o lè ni agbára tó láti di idà mú.
“Mwet sukawil, nga koteya poun tokosra lun Egypt. Wanginna mwet kapriya ku lohsak in mahla tuh elan ku in sifil sruok cutlass natul.
22 Nítorí náà, báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí: Èmi lòdì sí Farao ọba Ejibiti. Èmi yóò sẹ́ apá rẹ̀ méjèèjì, èyí tí ó dára àti èyí tí a ti ṣẹ́ pẹ̀lú, yóò sì mú kí idà bọ́ sọnù ní ọwọ́ rẹ̀.
Na pa inge ma nga, LEUM GOD Fulatlana, ac fahk uh: Nga lainul tokosra lun Egypt. Nga ac fah kotalik paol kewa — lacpo ma srakna wo, ac layen ma musalla tari — na cutlass natul ac fah putatla liki paol.
23 Èmi yóò sì fọ́n àwọn ènìyàn Ejibiti ká sí àárín àwọn orílẹ̀-èdè, èmi yóò sì tú wọn ká gbogbo ilẹ̀.
Nga ac fah akfahsryelik mwet Egypt nu fin faclu nufon.
24 Èmi yóò mú kí apá ọba Babeli ní agbára, èmi yóò sì fi idà mi sí ọwọ́ rẹ, ṣùgbọ́n èmi yóò ṣẹ́ apá Farao, yóò sì kérora níwájú rẹ̀ bí ọkùnrin tí a sá ní àṣápa.
Na nga ac fah akkeye poun tokosra lun Babylonia, ac sang nu inpaol cutlass nutik uh. Tusruktu nga ac koteya poun tokosra lun Egypt, ac el ac fah sasao ac misa ye mutun mwet lokoalok lal.
25 Èmi yóò mú kí apá ọba Babeli lé, ṣùgbọ́n apá Farao yóò sì rọ. Nígbà náà wọn yóò mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa, nígbà tí mo bá mú idà mi sí ọwọ́ ọba Babeli yóò sì fi idà náà kọlu Ejibiti.
Aok, nga fah akmunasyal, ac akkeye tokosra lun Babylonia. Ke nga ac sang cutlass nutik uh nu sel ac el kolla nu facl Egypt, mwet nukewa ac fah etu lah nga pa LEUM GOD.
26 Èmi yóò fọ́n àwọn ara Ejibiti ká sí àárín orílẹ̀-èdè, èmi yóò sì tú wọn ká sí àárín orílẹ̀-èdè, èmi yóò sì tú wọn ká sí gbogbo ilẹ̀. Nígbà náà wọn yóò mọ̀ pé èmi ni Olúwa.”
Nga ac akfahsryelik mwet Egypt nu fin faclu nufon. Na elos ac fah etu lah nga pa LEUM GOD.”

< Ezekiel 30 >