< Ezekiel 30 >
1 Ọ̀rọ̀ Olúwa tún tọ̀ mí wá: wí pé:
Kiugo kĩa Jehova nĩkĩanginyĩrĩire, ngĩĩrwo atĩrĩ
2 “Ọmọ ènìyàn, sọtẹ́lẹ̀ kí o sì wí pé: ‘Báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí: “‘Hu, kí o sì wí pé, “Ó ṣe fún ọjọ́ náà!”
“Mũrũ wa mũndũ, ratha ũhoro, uuge atĩrĩ: ‘Mwathani Jehova ekuuga ũũ: “‘Girĩkai, muuge atĩrĩ, “Kaĩ mũthenya ũcio ũrĩ na haaro-ĩ!”
3 Nítorí ọjọ́ náà súnmọ́ tòsí àní ọjọ́ Olúwa súnmọ́ tòsí, ọjọ́ tí ọjọ́ ìkùùkuu ṣú dúdú, àsìkò ìparun fún àwọn kèfèrí.
Nĩgũkorwo mũthenya ũcio nĩũkuhĩrĩirie, mũthenya wa Jehova nĩũkuhĩrĩirie, mũthenya ũrĩ na matu, mũthenya ũrĩ na mũthiro harĩ ndũrĩrĩ.
4 Idà yóò wá sórí Ejibiti ìrora ńlá yóò sì wá sórí Kuṣi. Nígbà tí àwọn tí a pa yóò ṣubú ní Ejibiti wọn yóò kò ọrọ̀ rẹ̀ lọ ìpìlẹ̀ rẹ̀ yóò sì wó lulẹ̀.
Rũhiũ rwa njora nĩrũgookĩrĩra bũrũri wa Misiri, naruo ruo rwa ngoro rũkinyĩrĩre Kushi. Rĩrĩa arĩa moragĩtwo makaagũa kũu bũrũri wa Misiri, ũtonga wakuo nĩũgakuuo, nayo mĩthingi yakuo ĩmomorwo.
5 Kuṣi àti Puti, Libia, Ludi àti gbogbo Arabia, Kubu àti àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà tí ó mulẹ̀ yóò ṣubú nípa idà pẹ̀lú Ejibiti.
Andũ a Kushi na Putu, na Ludu, na Arabia guothe, na Lubia, na andũ a bũrũri wa kĩrĩkanĩro, makooragwo na rũhiũ rwa njora marĩ hamwe na andũ a Misiri.
6 “‘Èyí yìí ní Olúwa wí: “‘Àwọn àlejò Ejibiti yóò ṣubú agbára ìgbéraga rẹ yóò kùnà láti Migdoli títí dé Siene, wọn yóò ti ipa idà ṣubú nínú rẹ; ní Olúwa Olódùmarè wí.
“‘Jehova ekuuga ũũ: “‘Arata a Misiri nĩmakooragwo, naguo hinya wake ũrĩa etĩĩaga naguo nĩũgaathira. Kuuma Migidoli o nginya Aswani, makooragĩrwo kuo thĩinĩ na rũhiũ rwa njora, ũguo nĩguo Mwathani Jehova ekuuga.
7 Wọn yóò sì wà lára àwọn ilẹ̀ tí ó di ahoro, ìlú rẹ yóò sì wà ní ara àwọn ìlú tí ó di ahoro.
“‘Nĩmagakira ihooru, marĩ gatagatĩ-inĩ ka mabũrũri marĩa manangĩtwo, magakira ihooru, namo matũũra mao manene magaakorwo marĩ thĩinĩ wa matũũra manene marĩa manangĩku.
8 Lẹ́yìn náà wọn yóò mọ̀ pé èmi ní Olúwa, nígbà tí mo bá gbé iná kalẹ̀ ní Ejibiti tí gbogbo àwọn olùrànlọ́wọ́ rẹ̀ bá parun.
Hĩndĩ ĩyo nĩmakamenya atĩ niĩ nĩ niĩ Jehova, rĩrĩa ngaacina bũrũri wa Misiri na mwaki, nao arĩa othe maamateithagia mahehenjwo.
9 “‘Ní ọjọ́ náà oníṣẹ́ yóò ti ọ̀dọ̀ mi jáde nínú ọkọ̀ ojú omi láti dẹ́rùbà Kuṣi tí ó wà nínú àlàáfíà. Ìrora yóò wá sórí wọn gẹ́gẹ́ bí ti ọjọ́ ìparun Ejibiti. Kíyèsi i, ó dé.
“‘Mũthenya ũcio-rĩ, nĩngatũma andũ moime harĩ niĩ marĩ na marikabu, mathiĩ makahahũre andũ a Kushi, moime mwĩcaaro-inĩ wao. Nĩmakanyiitwo nĩ ruo rwa ngoro mũthenya ũcio bũrũri wa Misiri ũkaaniinwo, nĩgũkorwo ti-itherũ nĩũgakinya.
10 “‘Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí: “‘Èmi yóò mú òpin bá ọ̀gọ̀ọ̀rọ̀ àwọn ènìyàn Ejibiti láti ọwọ́ Nebukadnessari ọba Babeli.
“‘Mwathani Jehova ekuuga ũũ: “‘Nĩnganiina kĩrĩndĩ kĩa Misiri, hũthĩrĩte guoko kwa Nebukadinezaru, mũthamaki wa Babuloni.
11 Òun àti àwọn ológun rẹ̀ ẹ̀rù àwọn orílẹ̀-èdè ní a o mú wá láti pa ilẹ̀ náà run. Wọn yóò fa idà wọn yọ sí Ejibiti ilẹ̀ náà yóò sì kún fún àwọn tí a pa.
We na mbũtũ ciake cia ita, o mbũtũ icio ikĩrĩtie ndũrĩrĩ iria ingĩ ciothe kwaga tha, nĩcio ikaarehwo, iniine bũrũri ũcio. Nĩigacomora hiũ ciao cia njora, ciũkĩrĩre bũrũri wa Misiri na ciyũrie bũrũri ũcio andũ arĩa moragĩtwo.
12 Èmi yóò mú kí àwọn odò Naili gbẹ, Èmi yóò sì ta ilẹ̀ náà fún àwọn ènìyàn búburú: láti ọwọ́ àwọn àjèjì ènìyàn, Èmi yóò jẹ́ kí ilẹ̀ náà àti gbogbo ohun tí ó wá nínú rẹ ṣòfò. Èmi Olúwa ni ó ti sọ ọ́.
Nĩngatũma tũrũũĩ tuothe twa Rũũĩ rwa Nili tũhwe, naguo bũrũri ũcio ndĩwenderie andũ aaganu; ngaawananga na moko ma andũ a kũngĩ, guo mwene, o hamwe na kĩrĩa gĩothe kĩrĩ kuo. Niĩ Jehova nĩ niĩ njarĩtie.
13 “‘Báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí: “‘Èmi yóò pa àwọn òrìṣà run, Èmi yóò sì mú kí òpin dé bá ère gbígbẹ́ ni Memfisi. Kò ní sí ọmọ-aládé mọ́ ní Ejibiti, Èmi yóò mú kí ìbẹ̀rù gba gbogbo ilẹ̀ náà.
“‘Mwathani Jehova ekuuga ũũ: “‘Nĩngathũkangia ngai cia mĩhianano na niine mĩhiano ĩrĩa ĩrĩ Nofu. Gũtigacooka kũgĩa mũthamaki kũu bũrũri wa Misiri, na nĩngaiyũria bũrũri ũcio wothe guoya.
14 Èmi yóò sì mú kí Paturosi di ahoro, èmi yóò fi iná sí Ṣoani, èmi yóò sì fi ìyà jẹ Tebesi.
O nakuo Pathirosi nĩngakwananga, na ngwatie mwaki kũu Zoani, o na herithanie kũu Thebesi.
15 Èmi yóò tú ìbínú mi jáde sórí Pelusiumu ìlú odi Ejibiti èmi yóò sì ké àkójọpọ̀ Tebesi kúrò.
O nakuo Pelusiumu nĩngagũitĩrĩria mangʼũrĩ makwa, o kũu kĩĩgitĩro kĩa hinya kĩa bũrũri wa Misiri, na njeherie kĩrĩndĩ gĩa kũu Thebesi.
16 Èmi yóò ti iná bọ Ejibiti Pelusiumu yóò japoró ní ìrora. Ìjì líle yóò jà ní Tebesi Memfisi yóò wà ìpọ́njú ní ìgbà gbogbo.
Nĩngagwatia mwaki kũu bũrũri wa Misiri, nakuo Pelusiumu nĩgũkeehũũrithania nĩ ruo. Thebesi nĩgũgatharĩkĩrwo. Nofu nĩgũgakorwo na mĩnyamaro ĩtegũtigithĩria.
17 Àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin ní Heliopolisi àti Bubasiti yóò ti ipa idà ṣubú wọn yóò sì kó àwọn ìlú wọn ní ìgbèkùn.
Aanake a Heliopoli na a Bubasiti makooragwo na rũhiũ rwa njora, nao andũ a matũũra macio manene matahwo.
18 Ojú ọjọ́ yóò ṣókùnkùn ní Tafanesi nígbà tí mo bá já àjàgà Ejibiti kúrò; níbẹ̀ agbára iyì rẹ̀ yóò dópin wọn yóò fi ìkùùkuu bò ó àwọn abúlé rẹ ní wọn yóò lọ sí ìgbèkùn.
Mũthenya nĩũkagĩa nduma kũu Tehafunehasu rĩrĩa ngoinanga icooki rĩa Misiri; kũu nĩkuo hinya wake ũcio etĩĩaga naguo ũgaathirĩra. Nĩakahumbĩrwo nĩ matu, namo matũũra make nĩmagatahwo.
19 Nítorí náà, Èmi yóò mú ki ìjìyà wá sórí Ejibiti, wọn yóò sì mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.’”
Nĩ ũndũ ũcio nĩngaherithia bũrũri wa Misiri, nao nĩmakamenya atĩ niĩ nĩ niĩ Jehova.’”
20 Ní ọjọ́ keje oṣù kìn-ín-ní ọdún kọkànlá ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá,
Mwaka-inĩ wa ikũmi na ũmwe, mũthenya wa mũgwanja wa mweri wa mbere, kiugo kĩa Jehova nĩkĩanginyĩrĩire, ngĩĩrwo atĩrĩ:
21 “Ọmọ ènìyàn, Èmi ti ṣẹ́ apá Farao ọba Ejibiti. A kò ì tí ì di apá náà papọ̀ láti mu kí ó san, a kò sì ti di i si àárín igi pẹlẹbẹ kí o lè ni agbára tó láti di idà mú.
“Mũrũ wa mũndũ, nĩnyunĩte guoko kwa Firaũni, mũthamaki wa Misiri. Gũtiohetwo na taama ũrĩ na ndawa nĩguo kũhone, kana gũkoohanio na mĩtĩ nĩguo kũgwate kũgĩe na hinya wa kuoya rũhiũ rwa njora.
22 Nítorí náà, báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí: Èmi lòdì sí Farao ọba Ejibiti. Èmi yóò sẹ́ apá rẹ̀ méjèèjì, èyí tí ó dára àti èyí tí a ti ṣẹ́ pẹ̀lú, yóò sì mú kí idà bọ́ sọnù ní ọwọ́ rẹ̀.
Nĩ ũndũ ũcio, Mwathani Jehova ekuuga ũũ: Niĩ nĩngũũkĩrĩra Firaũni mũthamaki wa bũrũri wa Misiri. Nĩngũmuuna moko meerĩ, kũrĩa kũgima na kũrĩa kuunĩku, na ndũme rũhiũ rwa njora ruume guoko-inĩ gwake rũgwe thĩ.
23 Èmi yóò sì fọ́n àwọn ènìyàn Ejibiti ká sí àárín àwọn orílẹ̀-èdè, èmi yóò sì tú wọn ká gbogbo ilẹ̀.
Nĩngahurunja andũ a Misiri ndũrĩrĩ-inĩ, na ndĩmaharaganĩrie mabũrũri-inĩ.
24 Èmi yóò mú kí apá ọba Babeli ní agbára, èmi yóò sì fi idà mi sí ọwọ́ rẹ, ṣùgbọ́n èmi yóò ṣẹ́ apá Farao, yóò sì kérora níwájú rẹ̀ bí ọkùnrin tí a sá ní àṣápa.
Nĩngekĩra moko ma mũthamaki wa Babuloni hinya, na ndĩmũnengere rũhiũ rwakwa rwa njora arũnyiite na guoko, no nĩngoina moko ma Firaũni, nake acaaĩre hau mbere yake, o ta mũndũ ũgurarĩtio nguraro ya gĩkuũ.
25 Èmi yóò mú kí apá ọba Babeli lé, ṣùgbọ́n apá Farao yóò sì rọ. Nígbà náà wọn yóò mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa, nígbà tí mo bá mú idà mi sí ọwọ́ ọba Babeli yóò sì fi idà náà kọlu Ejibiti.
Nĩngekĩra moko ma mũthamaki wa Babuloni hinya, no moko ma Firaũni nĩmakaaga hinya. Hĩndĩ ĩyo nĩmakamenya atĩ niĩ nĩ niĩ Jehova, rĩrĩa ngaanengera mũthamaki wa Babuloni rũhiũ rwakwa rwa njora arũnyiite na guoko, nake arũhiũrie okĩrĩre bũrũri wa Misiri.
26 Èmi yóò fọ́n àwọn ara Ejibiti ká sí àárín orílẹ̀-èdè, èmi yóò sì tú wọn ká sí àárín orílẹ̀-èdè, èmi yóò sì tú wọn ká sí gbogbo ilẹ̀. Nígbà náà wọn yóò mọ̀ pé èmi ni Olúwa.”
Nĩngahurunja andũ a Misiri ndũrĩrĩ-inĩ, na ndĩmaharaganĩrie mabũrũri-inĩ. Hĩndĩ ĩyo nĩmakamenya atĩ niĩ nĩ niĩ Jehova.”