< Ezekiel 30 >

1 Ọ̀rọ̀ Olúwa tún tọ̀ mí wá: wí pé:
Ja minulle tuli tämä Herran sana:
2 “Ọmọ ènìyàn, sọtẹ́lẹ̀ kí o sì wí pé: ‘Báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí: “‘Hu, kí o sì wí pé, “Ó ṣe fún ọjọ́ náà!”
"Ihmislapsi, ennusta ja sano: Näin sanoo Herra, Herra: Valittakaa: 'Voi sitä päivää!'
3 Nítorí ọjọ́ náà súnmọ́ tòsí àní ọjọ́ Olúwa súnmọ́ tòsí, ọjọ́ tí ọjọ́ ìkùùkuu ṣú dúdú, àsìkò ìparun fún àwọn kèfèrí.
Sillä lähellä on päivä, lähellä Herran päivä; se on pilvinen päivä, pakanakansojen aika.
4 Idà yóò wá sórí Ejibiti ìrora ńlá yóò sì wá sórí Kuṣi. Nígbà tí àwọn tí a pa yóò ṣubú ní Ejibiti wọn yóò kò ọrọ̀ rẹ̀ lọ ìpìlẹ̀ rẹ̀ yóò sì wó lulẹ̀.
Miekka yllättää Egyptin, ja Etiopialla on tuska, kun surmattuja kaatuu Egyptissä, kun siltä otetaan pois tavarain paljous ja revitään perustukset.
5 Kuṣi àti Puti, Libia, Ludi àti gbogbo Arabia, Kubu àti àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà tí ó mulẹ̀ yóò ṣubú nípa idà pẹ̀lú Ejibiti.
Etiopia, Puut ja Luud, kaikki sekakansa, Kuub ja liittoutuneen maan miehet kaatuvat heidän kanssansa miekkaan.
6 “‘Èyí yìí ní Olúwa wí: “‘Àwọn àlejò Ejibiti yóò ṣubú agbára ìgbéraga rẹ yóò kùnà láti Migdoli títí dé Siene, wọn yóò ti ipa idà ṣubú nínú rẹ; ní Olúwa Olódùmarè wí.
Näin sanoo Herra: Egyptin tuet kaatuvat, ja sen ylpeä uhma alenee. Migdolista Seveneen asti he siellä kaatuvat miekkaan, sanoo Herra, Herra.
7 Wọn yóò sì wà lára àwọn ilẹ̀ tí ó di ahoro, ìlú rẹ yóò sì wà ní ara àwọn ìlú tí ó di ahoro.
Autioiksi he joutuvat autioiksi tehtyjen maitten joukossa, ja heidän kaupunkinsa tulevat olemaan raunioiksi pantujen kaupunkien joukossa.
8 Lẹ́yìn náà wọn yóò mọ̀ pé èmi ní Olúwa, nígbà tí mo bá gbé iná kalẹ̀ ní Ejibiti tí gbogbo àwọn olùrànlọ́wọ́ rẹ̀ bá parun.
Ja he tulevat tietämään, että minä olen Herra, kun minä sytytän Egyptin tuleen ja kaikki sen auttajat murtuvat.
9 “‘Ní ọjọ́ náà oníṣẹ́ yóò ti ọ̀dọ̀ mi jáde nínú ọkọ̀ ojú omi láti dẹ́rùbà Kuṣi tí ó wà nínú àlàáfíà. Ìrora yóò wá sórí wọn gẹ́gẹ́ bí ti ọjọ́ ìparun Ejibiti. Kíyèsi i, ó dé.
Sinä päivänä lähtee minun tyköäni laivoilla lähettiläitä peljästyttämään levossa elävää Etiopiaa, ja heille tulee tuska niinkuin Egyptin päivänä; sillä katso, se tulee.
10 “‘Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí: “‘Èmi yóò mú òpin bá ọ̀gọ̀ọ̀rọ̀ àwọn ènìyàn Ejibiti láti ọwọ́ Nebukadnessari ọba Babeli.
Näin sanoo Herra, Herra: Minä teen lopun Egyptin meluavista joukoista Baabelin kuninkaan Nebukadressarin käden kautta.
11 Òun àti àwọn ológun rẹ̀ ẹ̀rù àwọn orílẹ̀-èdè ní a o mú wá láti pa ilẹ̀ náà run. Wọn yóò fa idà wọn yọ sí Ejibiti ilẹ̀ náà yóò sì kún fún àwọn tí a pa.
Hän ja hänen väkensä hänen kanssaan, julmimmat pakanoista, tuodaan hävittämään maata, ja he paljastavat miekkansa Egyptiä vastaan ja täyttävät maan surmatuilla.
12 Èmi yóò mú kí àwọn odò Naili gbẹ, Èmi yóò sì ta ilẹ̀ náà fún àwọn ènìyàn búburú: láti ọwọ́ àwọn àjèjì ènìyàn, Èmi yóò jẹ́ kí ilẹ̀ náà àti gbogbo ohun tí ó wá nínú rẹ ṣòfò. Èmi Olúwa ni ó ti sọ ọ́.
Minä panen virrat kuiville ja myyn maan pahojen käsiin ja teen autioksi maan ja kaiken, mitä siinä on, muukalaisten käden kautta. Minä, Herra, olen puhunut.
13 “‘Báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí: “‘Èmi yóò pa àwọn òrìṣà run, Èmi yóò sì mú kí òpin dé bá ère gbígbẹ́ ni Memfisi. Kò ní sí ọmọ-aládé mọ́ ní Ejibiti, Èmi yóò mú kí ìbẹ̀rù gba gbogbo ilẹ̀ náà.
Näin sanoo Herra, Herra: Minä tuhoan kivijumalat ja lopetan epäjumalat Noofista ja ruhtinaat Egyptistä: niitä ei ole enää oleva; ja minä saatan Egyptin maan pelon valtaan.
14 Èmi yóò sì mú kí Paturosi di ahoro, èmi yóò fi iná sí Ṣoani, èmi yóò sì fi ìyà jẹ Tebesi.
Minä teen Patroksen autioksi, sytytän Sooanin tuleen ja panen toimeen tuomiot Noossa.
15 Èmi yóò tú ìbínú mi jáde sórí Pelusiumu ìlú odi Ejibiti èmi yóò sì ké àkójọpọ̀ Tebesi kúrò.
Minä vuodatan kiivauteni Siiniin, Egyptin linnoitukseen, hävitän Noon meluavat joukot
16 Èmi yóò ti iná bọ Ejibiti Pelusiumu yóò japoró ní ìrora. Ìjì líle yóò jà ní Tebesi Memfisi yóò wà ìpọ́njú ní ìgbà gbogbo.
ja sytytän Egyptin tuleen. Siin kierii tuskassa, Noo valloitetaan, ja Noof-ahdistajia selvällä päivällä!
17 Àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin ní Heliopolisi àti Bubasiti yóò ti ipa idà ṣubú wọn yóò sì kó àwọn ìlú wọn ní ìgbèkùn.
Aavenin ja Piibesetin nuorukaiset kaatuvat miekkaan, ja ne itse menevät vankeuteen.
18 Ojú ọjọ́ yóò ṣókùnkùn ní Tafanesi nígbà tí mo bá já àjàgà Ejibiti kúrò; níbẹ̀ agbára iyì rẹ̀ yóò dópin wọn yóò fi ìkùùkuu bò ó àwọn abúlé rẹ ní wọn yóò lọ sí ìgbèkùn.
Tehafneheessa päivä pimenee, kun minä siellä särjen Egyptin ikeen, ja siinä saa lopun sen ylpeä uhma. Sen itsensä peittää pilvi, ja sen tyttäret menevät vankeuteen.
19 Nítorí náà, Èmi yóò mú ki ìjìyà wá sórí Ejibiti, wọn yóò sì mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.’”
Niin minä panen tuomiot toimeen Egyptissä, ja he tulevat tietämään, että minä olen Herra."
20 Ní ọjọ́ keje oṣù kìn-ín-ní ọdún kọkànlá ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá,
Yhdentenätoista vuotena, ensimmäisessä kuussa, kuukauden seitsemäntenä päivänä tuli minulle tämä Herran sana:
21 “Ọmọ ènìyàn, Èmi ti ṣẹ́ apá Farao ọba Ejibiti. A kò ì tí ì di apá náà papọ̀ láti mu kí ó san, a kò sì ti di i si àárín igi pẹlẹbẹ kí o lè ni agbára tó láti di idà mú.
"Ihmislapsi, minä olen murskannut faraon, Egyptin kuninkaan, käsivarren, ja katso, sitä ei sidota, ei parannella, ei panna kääreeseen, että se sidottuna vahvistuisi tarttuaksensa miekkaan.
22 Nítorí náà, báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí: Èmi lòdì sí Farao ọba Ejibiti. Èmi yóò sẹ́ apá rẹ̀ méjèèjì, èyí tí ó dára àti èyí tí a ti ṣẹ́ pẹ̀lú, yóò sì mú kí idà bọ́ sọnù ní ọwọ́ rẹ̀.
Sentähden, näin sanoo Herra, Herra: Katso, minä käyn faraon, Egyptin kuninkaan, kimppuun ja murskaan häneltä käsivarret, sekä voimakkaan että murskatun käden, ja pudotan miekan hänen kädestänsä.
23 Èmi yóò sì fọ́n àwọn ènìyàn Ejibiti ká sí àárín àwọn orílẹ̀-èdè, èmi yóò sì tú wọn ká gbogbo ilẹ̀.
Minä hajotan egyptiläiset kansojen sekaan ja sirotan heidät muihin maihin.
24 Èmi yóò mú kí apá ọba Babeli ní agbára, èmi yóò sì fi idà mi sí ọwọ́ rẹ, ṣùgbọ́n èmi yóò ṣẹ́ apá Farao, yóò sì kérora níwájú rẹ̀ bí ọkùnrin tí a sá ní àṣápa.
Baabelin kuninkaan käsivarret minä vahvistan ja annan miekkani hänen käteensä; mutta faraolta minä murskaan käsivarret, ja hän voihkii hänen edessänsä, niinkuin kaadettu voihkii.
25 Èmi yóò mú kí apá ọba Babeli lé, ṣùgbọ́n apá Farao yóò sì rọ. Nígbà náà wọn yóò mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa, nígbà tí mo bá mú idà mi sí ọwọ́ ọba Babeli yóò sì fi idà náà kọlu Ejibiti.
Niin, minä vahvistan Baabelin kuninkaan käsivarret, mutta faraon käsivarret vaipuvat alas. Ja he tulevat tietämään, että minä olen Herra, kun minä annan miekkani Baabelin kuninkaan käteen, että hän ojentaa sen Egyptin maata vastaan.
26 Èmi yóò fọ́n àwọn ara Ejibiti ká sí àárín orílẹ̀-èdè, èmi yóò sì tú wọn ká sí àárín orílẹ̀-èdè, èmi yóò sì tú wọn ká sí gbogbo ilẹ̀. Nígbà náà wọn yóò mọ̀ pé èmi ni Olúwa.”
Ja minä hajotan egyptiläiset kansojen sekaan ja sirotan heidät muihin maihin. Ja he tulevat tietämään, että minä olen Herra."

< Ezekiel 30 >