< Ezekiel 3 >
1 Síwájú sí i, ó sọ fún mi pé, “Ọmọ ènìyàn, jẹ ohun tí ó wà níwájú rẹ, jẹ ìwé kíká yìí; kí o sì lọ fi bá ilé Israẹli sọ̀rọ̀.”
Och han sade till mig: "Du människobarn, ät vad du här finner, ät upp denna rulle, och gå sedan åstad och tala till Israels hus."
2 Mo sì ya ẹnu mi, ó sì mú mi jẹ ìwé kíká náà.
Då öppnade jag min mun, och han gav mig rullen att äta.
3 Ó tún sọ fún mi pé, “Ọmọ ènìyàn, jẹ ìwé kíká tí mo fún ọ yìí, fi bọ́ inú àti ikùn rẹ.” Nígbà náà ni mo jẹ ẹ́, dídùn rẹ̀ dàbí oyin ní ẹnu mi.
Och han sade till mig: "Du människobarn, du måste mätta din buk och fylla dina inälvor med den rulle som jag nu giver dig." Och jag åt, och den var i min mun söt såsom honung.
4 Ó sì tún sọ fún mi pé, “Ọmọ ènìyàn, lọ ni ìsinsin yìí bá mi sọ ọ̀rọ̀ mi fún ilé Israẹli.
Och han sade till mig: "Du människobarn, gå bort till Israels hus och tala till dem med mina ord.
5 A kò rán ọ sí àwọn tó ń sọ èdè àjèjì tàbí tí èdè wọn ṣòro láti gbọ́, ṣùgbọ́n orílẹ̀-èdè Israẹli ni mo rán ọ sí
Ty du bliver ju icke sänd till ett folk med obegripligt språk och trög tunga, utan till Israels hus,
6 kì í ṣe sí ọ̀pọ̀ ènìyàn tó ń sọ àjèjì èdè tàbí tí èdè wọn ṣòro láti gbọ́, àwọn tí ọ̀rọ̀ wọn le fún ọ láti gbọ́ yé. Dájúdájú bí mo bá rán ọ sí wọn, wọn ìbá sì fetísílẹ̀ sí ọ.
icke till mångahanda folk med obegripligt språk och trög tunga, vilkas tal du icke förstår; sannerligen, sände jag dig till sådana, så skulle de höra på dig
7 Ṣùgbọ́n ilé Israẹli kò fẹ́ gbọ́ tìrẹ nítorí pé wọn kò fẹ́ láti gbọ́ tèmi, torí pé aláìgbọ́ràn àti ọlọ́kàn líle ni gbogbo ilé Israẹli.
Men Israels hus vill icke höra på dig, ty de vilja icke höra på mig; hela Israels hus har hårda pannor och förhärdade hjärtan.
8 Ṣùgbọ́n bí i tiwọn lèmi náà yóò ṣe jẹ́ kí ojú àti ọkàn rẹ le.
Men se, jag gör ditt ansikte hårt såsom deras ansikten, och din panna hård såsom deras pannor.
9 Èmi yóò ṣe iwájú orí rẹ bí òkúta tó le jùlọ, ànító le ju òkúta-ìbọn lọ. Má ṣe bẹ̀rù wọn tàbí jẹ́ kí wọn ó dáyà já ọ. Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ìdílé ọlọ̀tẹ̀ ni wọ́n.”
Ja, jag gör din panna hård såsom diamant, hårdare än flinta. Du skall icke frukta för dem och icke förfäras för dem, då de nu äro ett gensträvigt släkte."
10 Ó sì sọ fún mi pé, “Ọmọ ènìyàn, gbọ́ gbogbo ọ̀rọ̀ tí mo ń sọ, kí o sì gba gbogbo ọ̀rọ̀ yìí sí ọkàn rẹ.
Och han sade till mig: "Du människobarn, allt vad jag talar till dig skall du upptaga i ditt hjärta och höra med dina öron.
11 Lọ nísinsin yìí sí ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn rẹ tó wà ní ìgbèkùn. Sọ fún wọn pé báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí yálà wọ́n gbọ́ tàbí wọn kò gbọ́.”
Och gå bort till dina fångna landsmän, och tala till dem och säg till dem: 'Så säger Herren, HERREN' -- evad de nu höra därpå eller icke."
12 Nígbà náà ni ẹ̀mí gbé mi sókè, mo sì gbọ́ ohùn ìró ńlá lẹ́yìn mi tó sọ pé, kí a gbé ògo Olúwa ga láti ibùgbé rẹ̀ wá!
Och en andekraft lyfte upp mig, och jag hörde bakom mig ljudet av ett väldigt dån: "Lovad vare HERRENS härlighet, där varest den är!",
13 Bẹ́ẹ̀ ni mo tún gbọ́ ariwo ìyẹ́ apá àti kẹ̀kẹ́ àwọn ẹ̀dá alààyè náà pẹ̀lú ariwo tó dàbí àrá ńlá.
så ock ljudet av väsendenas vingar, som rörde vid varandra, och ljudet av hjulen jämte dem och ljudet av ett väldigt dån.
14 Ẹ̀mí náà sì gbé mi sókè, ó sì mú mi lọ, mo lọ pẹ̀lú ọkàn kíkorò àti ìbínú nínú ẹ̀mí mi, pẹ̀lú ọwọ́ líle Olúwa ni ara mi.
Och en andekraft lyfte upp mig och förde mig bort, och jag färdades åstad, bedrövad och upprörd i min ande, och HERRENS hand var stark över mig.
15 Nígbà náà ni mo lọ sí etí odò Kebari níbi tí àwọn ìgbèkùn ń gbé ni Teli-Abibu. Níbẹ̀ níbi tí wọ́n ń gbé, mo jókòó láàrín wọn pẹ̀lú ìyanu, fún ọjọ́ méje.
Och jag kom till de fångna i Tel-Abib, till dem som bodde vid strömmen Kebar, till den plats där de bodde; och jag satt där ibland dem i sju dagar, försänkt i djup sorg.
16 Lẹ́yìn ọjọ́ méje, ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé,
Men efter sju dagar kom HERRENS ord till mig; han sade:
17 “Ọmọ ènìyàn, mo ti fi ọ́ ṣe olùṣọ́ fún ilé Israẹli; nítorí náà gbọ́ ọ̀rọ̀ tí mo ń sọ, fún wọn ní ìkìlọ̀ láti ọ̀dọ̀ mi.
"Du människobarn, jag har satt dig till en väktare för Israels hus, för att du å mina vagnar skall varna dem, när du hör ett ord från min mun.
18 Bí mo bá sọ fún ènìyàn búburú pé, dájúdájú, ‘Ìwọ yóò kú,’ tí ìwọ kò sì kìlọ̀ fún ènìyàn búburú yìí láti dáwọ́ ìwà ibi rẹ̀ dúró, kí o sì gba ẹ̀mí rẹ̀ là, ènìyàn búburú náà yóò kú nínú ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀, ṣùgbọ́n ní ọwọ́ rẹ ni èmi yóò ti béèrè ẹ̀jẹ̀ rẹ̀.
Om jag säger till den ogudaktige: 'Du måste dö' och du då icke varnar honom, ja, om du icke säger något till att varna den ogudaktige för hans ogudaktiga väg och rädda hans liv, då skall väl den ogudaktige dö genom sin missgärning, men hans blod skall jag utkräva av din hand.
19 Ṣùgbọ́n bí o bá kìlọ̀ fún ènìyàn búburú, tí ó kọ̀ tí kò fi ìwà búburú rẹ̀ sílẹ̀, yóò kú sínú ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀; ṣùgbọ́n ọrùn tìrẹ ti mọ́.
Men om du varnar den ogudaktige och han likväl icke vänder om från sin ogudaktighet och sin ogudaktiga väg, då skall visserligen han dö genom sin missgärning, men du själv har räddat din själ.
20 “Bákan náà, bí olódodo kan bá yípadà, tó sì bẹ̀rẹ̀ sí í ṣe àìṣòdodo, tí mo sì fi ohun ìkọ̀sẹ̀ sí ọ̀nà rẹ̀, yóò kú sínú ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀. Nítorí pé ìwọ kọ̀ láti kìlọ̀ fún un, yóò kú sínú ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀, a ó gbàgbé gbogbo ìwà rere tó ti hù tẹ́lẹ̀, ṣùgbọ́n ní ọwọ́ rẹ̀ ni èmi yóò ti béèrè ẹ̀jẹ̀ rẹ̀.
Och om en rättfärdig man vänder om från sin rättfärdighet och gör vad orätt är, så skall jag lägga en stötesten i hans väg, och han skall dö. Om du då icke har varnat honom, så skall han väl dö genom sin synd, och den rättfärdighet som han förr har övat skall icke varda ihågkommen, men hans blod skall jag utkräva av din hand.
21 Ṣùgbọ́n bí o bá kìlọ̀ fún olódodo tó sì dáwọ́ ìwà ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ dúró, dájúdájú òun yóò yè nítorí pé ó ti gba ìkìlọ̀, ọrùn tìrẹ sì mọ́.”
Men om du har varnat den rättfärdige, för att han, den rättfärdige, icke skall synda, och han så avhåller sig från synd, då skall han förvisso få leva, därför att han lät varna sig, och du själv har då räddat din själ."
22 Ọwọ́ Olúwa wà lára mi níbẹ̀, ó sì wí fún mi pé, “Dìde, lọ sí ibi tí ó tẹ́jú, èmi yóò sì bá ọ sọ̀rọ̀ níbẹ̀.”
Och HERRENS hand kom där över mig, och han sade till mig: "Stå upp och gå ut på slätten; där skall jag tala med dig."
23 Mo sì dìde, mo lọ sí ibi tí ó tẹ́jú. Ògo Olúwa dúró níbẹ̀, ó dàbí irú ògo tí mo rí létí odò Kebari, mo sì dojúbolẹ̀.
Då stod jag upp och gick ut på slätten; och se, där stod HERRENS härlighet, alldeles sådan som jag hade sett den vid strömmen Kebar; och jag föll ned på mitt ansikte.
24 Nígbà náà ni Ẹ̀mí wọ inú mi, tí ó sì tún gbé mi dúró. Ó sì wí fún mi pé, “Lọ, ti ara rẹ mọ́ inú ilé rẹ
Men en andekraft kom i mig och reste upp mig på mina fötter. Och han talade med mig och sade till mig: "Gå och stäng dig inne i ditt hus.
25 ṣùgbọ́n ìwọ, ọmọ ènìyàn, wọn yóò fi okùn dè ọ́ mọ́lẹ̀; dé ibi pé ìwọ kò ní í le rìn káàkiri láàrín àwọn ènìyàn.
Och se, du människobarn, bojor skola läggas på dig, och du skall bliva bunden med sådana, så att du icke kan gå ut bland de andra.
26 Èmi yóò mú kí ahọ́n rẹ lẹ̀ mọ́ àjà ẹnu rẹ, tó bẹ́ẹ̀ ti ìwọ yóò wà ní ìdákẹ́ jẹ́ẹ́. Ìwọ kò sì ní lè bá wọn wí, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ọlọ̀tẹ̀ ilé ní wọn.
Och jag skall låta din tunga låda vid din gom, så att du bliver stum och icke kan bestraffa dem, då de nu äro ett gensträvigt släkte.
27 Ṣùgbọ́n nígbà tí èmi bá bá ọ sọ̀rọ̀, Èmi yóò ṣí ọ lẹ́nu, ìwọ yóò sì sọ fún wọn pé, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí.’ Ẹni tó bá fẹ́ kí ó gbọ́, ẹni tó bá fẹ́ kọ̀, kó kọ̀ nítorí ọlọ̀tẹ̀ ilé ni wọ́n.
Men när jag talar med dig, skall jag upplåta din mun, så att du kan säga till dem: 'Så säger Herren, HERREN.' Den som då vill höra, han höre, och den som icke vill, han höre icke, då de nu äro ett gensträvigt släkte."