< Ezekiel 29 >
1 Ní ọjọ́ kejìlá, oṣù kẹwàá, ọdún kẹwàá, ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé:
Године десете, десетог месеца, дванаестог дана, дође ми реч Господња говорећи:
2 “Ọmọ ènìyàn, kọjú sí Farao ọba Ejibiti kí ó sì sọ àsọtẹ́lẹ̀ sí i àti sí gbogbo Ejibiti.
Сине човечји, окрени лице своје према Фараону цару мисирском, и пророкуј против њега и против свега Мисира.
3 Sọ̀rọ̀, kí ó sì wí pé, ‘Báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí: “‘Èmi lòdì sí ọ, Farao ọba Ejibiti ìwọ ẹ̀mí búburú ńlá inú òkun tí ó dùbúlẹ̀ sí àárín àwọn odò ṣíṣàn rẹ. Èyí tí ó sọ wí pé, “Tèmi ni odò Naili; èmi ni ó sì ṣe é fún ara mi.”
Говори и реци: Овако вели Господ Господ: ево ме на те, Фараоне царе мисирски, змају велики што лежиш усред река својих, који рече: Моја је река; ја сам је начинио себи.
4 Ṣùgbọ́n èmi yóò fi ìwọ̀ mú ẹnu rẹ èmi yóò sì mú ẹja inú odò rẹ gbogbo lẹ̀ mọ́ ìpẹ́ ara rẹ. Èmi yóò fà ọ́ síta kúrò láàrín àwọn odò rẹ, àti gbogbo ẹja odò rẹ yóò lẹ̀ mọ́ ìpẹ́ ara rẹ.
Зато ћу ти метнути у чељусти удицу, и учинићу да се рибе у рекама твојим нахватају на крљушти твоје; и извући ћу те из река твојих и све рибе из река твојих нахватане на крљушти твоје.
5 Èmi yóò sọ ọ́ nù sí aginjù ìwọ àti gbogbo ẹja inú odò rẹ: ìwọ yóò ṣubú sí gbangba oko a kì yóò sì ṣà ọ́ jọ tàbí gbé ọ sókè. Èmi ti fi ọ ṣe oúnjẹ fún àwọn ẹranko igbó àti fún àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run láti jẹ.
И оставићу у пустињи тебе и све рибе из твојих река, и пашћеш на земљу и нећеш се покупити ни сабрати, зверима земаљским и птицама небеским даћу те да те једу.
6 Nígbà náà gbogbo àwọn olùgbé ni Ejibiti yóò mọ pé, Èmi ni Olúwa. “‘Ìwọ ti jẹ́ ọ̀pá ìyè fún ilé Israẹli.
И сви ће становници мисирски познати да сам ја Господ; јер су штап од трске дому Израиљевом.
7 Nígbà tí wọn fi ọwọ́ agbára wọn dì ọ́ mú. Ìwọ fọ́, ìwọ sì ya gbogbo èjìká wọn; nígbà tí wọn fi ara tì ọ́, ìwọ sẹ́, ìwọ sì mú gbogbo ẹ̀gbẹ́ wọn gbọ̀n.
Кад те ухватише у руку, ти се сломи и расече им све раме; а кад се наслонише на те, ти се преби и прободе им сва бедра.
8 “‘Nítorí náà, èyí ní Olúwa Olódùmarè wí: Kíyèsi, Èmi yóò mú idà kan wá sórí rẹ tí yóò sì gé ènìyàn àti ẹran kúrò nínú rẹ.
Зато овако вели Господ Господ: Ево, ја ћу пустити на те мач, и истребићу из тебе људе и стоку.
9 Ilẹ̀ Ejibiti yóò di aginjù àti ahoro, nígbà náà ní wọn yóò sì mọ̀ wí pé èmi ní Olúwa. “‘Nítorí tí ìwọ wí pé, “Tèmi ni odò Naili, Èmi ni mo ṣe é,”
И земља ће се мисирска опустошити и бити пуста, и познаће се да сам ја Господ, јер рече: Моја је река, и ја сам је начинио.
10 nítorí náà, mo lòdì sí ọ àti sí àwọn odò rẹ, èmi yóò sì mú kí ilẹ̀ Ejibiti di píparun àti ahoro, pátápátá, láti Migdoli lọ dé Siene, dé ààlà ilẹ̀ Kuṣi.
Зато ево ме на тебе и на реке твоје, и обратићу земљу мисирску у пустош и саму пустињу, од куле синске до међе етиопске.
11 Kò sí ẹsẹ̀ ènìyàn tàbí tí ẹranko tí yóò gba ibẹ̀ kọjá; ẹni kankan kò ní gbé ibẹ̀ fún ogójì ọdún.
Неће прелазити преко ње ногом својом човек, нити ће живинче ногом својом прелазити преко ње, и неће се живети у њој четрдесет година.
12 Èmi yóò sọ ilẹ̀ Ejibiti di ọ̀kan ní àárín àwọn ìlú tí ó di ahoro, fún ogójì ọdún, Èmi yóò sì fọ́n àwọn ara Ejibiti ká sáàárín àwọn orílẹ̀-èdè, èmi yóò sì tú wọn ká sáàárín gbogbo ilẹ̀.
И учинићу од земље мисирске пустош међу земљама опустошеним, и градови ће њени међу пустим градовима бити пустош четрдесет година, и расејаћу Мисирце међу народе и разасућу их по земљама.
13 “‘Ṣùgbọ́n báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí: Ní òpin ogójì ọdún, èmi yóò ṣa àwọn ará Ejibiti jọ láti ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn níbi tí a fọ́n wọn ká sí.
Јер овако вели Господ Господ: После четрдесет година скупићу Мисирце из народа у које буду расејани.
14 Èmi yóò sì tún mú ìgbèkùn Ejibiti padà bọ̀, èmi yóò sì dá wọn padà sí ilẹ̀ Paturosi, ilẹ̀ àwọn baba ńlá wọn. Wọn yóò wà níbẹ̀ bí ìjọba tí a rẹ̀ sílẹ̀.
И повратићу робље мисирско, и довешћу их опет у земљу Патрос, на постојбину њихову, и онде ће бити мало царство.
15 Ibẹ̀ yóò jẹ́ ìjọba tí ó rẹlẹ̀ jùlọ nínú àwọn ìjọba, kì yóò sì gbé ara rẹ̀ ga mọ́ sórí àwọn orílẹ̀-èdè: nítorí èmi ni ó dín wọn kù, tiwọn kì yóò fi ṣe olórí àwọn orílẹ̀-èdè yòókù mọ́.
Мало ће бити мимо осталих царстава, нити ће се више уздигнути над народе, јер ћу их смањити да не владају народима.
16 Ejibiti kí yóò sì jẹ orísun ìgbẹ́kẹ̀lé fún ilé Israẹli mọ́ ṣùgbọ́n, yóò jẹ́ ìrántí fún àìṣedéédéé wọn, nígbà tí yóò bá wò wọ́n fún ìrànlọ́wọ́. Nígbà náà, wọn yóò mọ̀ pé èmi ni Olúwa Olódùmarè.’”
И неће више бити дому Израиљевом узданица да напомиње безакоње кад би гледали за њима; и познаће да сам ја Господ Господ.
17 Ó sì ṣe ní ọjọ́ kìn-ín-ní, oṣù kìn-ín-ní, ọdún kẹtàdínlọ́gbọ̀n, ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé:
А двадесет седме године, првог месеца, првог дана, дође ми реч Господња говорећи:
18 “Ọmọ ènìyàn, Nebukadnessari ọba Babeli mú kí ogun rẹ sin ìrú ńlá fún Tire. Gbogbo orí pá, àti gbogbo èjìká bó, síbẹ̀, òun àti àwọn ogun rẹ̀, kò rí owó ọ̀yà gbà láti Tire fún wa, fún ìrú ti a ti sìn.
Сине човечји, Навуходоносор цар вавилонски зададе војсци својој тешку службу против Тира; свака глава оћелави и свако се раме одре, а плате не би ни њему ни војсци његовој од Тира за службу којом служише против њега.
19 Nítorí náà, báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Kíyèsi i, Èmi yóò fi Ejibiti fún Nebukadnessari ọba Babeli, òun yóò sì kó ọrọ̀ rẹ̀ lọ. Òun yóò bo ilé, yóò sì ṣe ìkógun ilẹ̀ náà gẹ́gẹ́ bí owó iṣẹ́ tí a san fún ológun rẹ̀.
Зато овако вели Господ Господ: Ево ја дајем Навуходоносору цару вавилонском земљу мисирску, и он ће одвести народ и однети плен и пограбити грабеж, и то ће бити плата његовој војсци.
20 Èmi ti fi Ejibiti fún un gẹ́gẹ́ bí èrè wàhálà rẹ̀ nítorí òun àti àwọn ológun rẹ ṣe é fún mi, ni Olúwa Olódùmarè wí.
За труд којим се трудио око тога дадох му земљу мисирску, јер се за ме трудише, говори Господ Господ.
21 “Ní ọjọ́ náà, èmi yóò mú kí ìwo Israẹli ru jáde, èmi yóò sì fún ọ ní ẹnu ọ̀rọ̀ ní àárín wọn. Nígbà náà ni wọn yóò mọ̀ pé èmi ni Olúwa.”
У онај ћу дан учинити да нарасте рог дому Израиљевом, и теби ћу отворити уста међу њима, и знаће да сам ја Господ.