< Ezekiel 29 >

1 Ní ọjọ́ kejìlá, oṣù kẹwàá, ọdún kẹwàá, ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé:
Kum rha dongkah hla rha hnin hlai nit vaengah BOEIPA ol te kai taengla ha pawk tih,
2 “Ọmọ ènìyàn, kọjú sí Farao ọba Ejibiti kí ó sì sọ àsọtẹ́lẹ̀ sí i àti sí gbogbo Ejibiti.
“Hlang capa aw, Egypt manghai Pharaoh te na maelhmai khueh thil lamtah amah neh Egypt boeih te tonghma thil.
3 Sọ̀rọ̀, kí ó sì wí pé, ‘Báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí: “‘Èmi lòdì sí ọ, Farao ọba Ejibiti ìwọ ẹ̀mí búburú ńlá inú òkun tí ó dùbúlẹ̀ sí àárín àwọn odò ṣíṣàn rẹ. Èyí tí ó sọ wí pé, “Tèmi ni odò Naili; èmi ni ó sì ṣe é fún ara mi.”
Voek lamtah ka Boeipa Yahovah loh a thui he thui pah. A sokko tuilung ah aka kol tuihnam puei, Egypt manghai Pharaoh nang kam pai thil coeng ne. Amah long tah kai taengah, 'Ka sokko he kai loh kamah kah la ka khueh,’ a ti.
4 Ṣùgbọ́n èmi yóò fi ìwọ̀ mú ẹnu rẹ èmi yóò sì mú ẹja inú odò rẹ gbogbo lẹ̀ mọ́ ìpẹ́ ara rẹ. Èmi yóò fà ọ́ síta kúrò láàrín àwọn odò rẹ, àti gbogbo ẹja odò rẹ yóò lẹ̀ mọ́ ìpẹ́ ara rẹ.
Thisum, thisum neh na kam ah kan dueh vetih na sokko kah nga te na lip dongah ka ben ni. Na sokko khui lamloh nang kan doek vetih na sokko kah nga boeih khaw na lip dongah kap ni.
5 Èmi yóò sọ ọ́ nù sí aginjù ìwọ àti gbogbo ẹja inú odò rẹ: ìwọ yóò ṣubú sí gbangba oko a kì yóò sì ṣà ọ́ jọ tàbí gbé ọ sókè. Èmi ti fi ọ ṣe oúnjẹ fún àwọn ẹranko igbó àti fún àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run láti jẹ.
Namah neh na sokko nga boeih khaw na khuikah khosoek ah kam phap vetih, lohma tlai ah na cungku ni. Nang n'khoem pawt vetih n'coi mahpawh. Diklai mulhing ham neh vaan kah vaa ham nang te cakok la kam paek ni.
6 Nígbà náà gbogbo àwọn olùgbé ni Ejibiti yóò mọ pé, Èmi ni Olúwa. “‘Ìwọ ti jẹ́ ọ̀pá ìyè fún ilé Israẹli.
Te vaengah Egypt khosa boeih loh BOEIPA kamah ni tila a ming uh ni. Amih te Israel imkhui kah capu conghol la om coeng.
7 Nígbà tí wọn fi ọwọ́ agbára wọn dì ọ́ mú. Ìwọ fọ́, ìwọ sì ya gbogbo èjìká wọn; nígbà tí wọn fi ara tì ọ́, ìwọ sẹ́, ìwọ sì mú gbogbo ẹ̀gbẹ́ wọn gbọ̀n.
Amih loh nang te na kut, kut ah n'tuuk vaengah na paep tih amih kah laengpang boeih na phen pah. Nang dongah a hangdang vaengah nim te na khaem sumsoek tih amih kah cinghen boeih na phit sak.
8 “‘Nítorí náà, èyí ní Olúwa Olódùmarè wí: Kíyèsi, Èmi yóò mú idà kan wá sórí rẹ tí yóò sì gé ènìyàn àti ẹran kúrò nínú rẹ.
Te dongah ka Boeipa Yahovah loh he ni a thui. Kai loh nang taengah cunghang kang khuen vetih nang lamkah hlang neh rhamsa khaw ka thup ni.
9 Ilẹ̀ Ejibiti yóò di aginjù àti ahoro, nígbà náà ní wọn yóò sì mọ̀ wí pé èmi ní Olúwa. “‘Nítorí tí ìwọ wí pé, “Tèmi ni odò Naili, Èmi ni mo ṣe é,”
Tedae, 'Sokko te kamah ham tih kamah loh ka saii,’ a ti dongah Egypt khohmuen te khopong neh imrhong la a poeh vaengah BOEIPA kamah he a ming uh bitni.
10 nítorí náà, mo lòdì sí ọ àti sí àwọn odò rẹ, èmi yóò sì mú kí ilẹ̀ Ejibiti di píparun àti ahoro, pátápátá, láti Migdoli lọ dé Siene, dé ààlà ilẹ̀ Kuṣi.
Te dongah namah neh na sokko khaw ka pai thil coeng ne. Egypt kho te Syene Migdol lamloh Kusah khorhi due kholing khopong kah imrhong la ka khueh ni.
11 Kò sí ẹsẹ̀ ènìyàn tàbí tí ẹranko tí yóò gba ibẹ̀ kọjá; ẹni kankan kò ní gbé ibẹ̀ fún ogójì ọdún.
Te longah hlang kho loh paan pawt vetih rhamsa kho long khaw, te longah paan mahpawh. Kum sawmli khuiah khosa om mahpawh.
12 Èmi yóò sọ ilẹ̀ Ejibiti di ọ̀kan ní àárín àwọn ìlú tí ó di ahoro, fún ogójì ọdún, Èmi yóò sì fọ́n àwọn ara Ejibiti ká sáàárín àwọn orílẹ̀-èdè, èmi yóò sì tú wọn ká sáàárín gbogbo ilẹ̀.
Egypt khohmuen te khopong la ka khueh vaengah diklai hman ah pong ni. A khopuei rhoek khaw khopuei rhoek lakli ah a khah vetih kum sawmli khopong la om ni. Egypt te namtom taengla ka taek ka yak vetih amih te diklai ah ka haeh ni.
13 “‘Ṣùgbọ́n báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí: Ní òpin ogójì ọdún, èmi yóò ṣa àwọn ará Ejibiti jọ láti ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn níbi tí a fọ́n wọn ká sí.
Tedae ka Boeipa Yahovah loh he ni a thui. Kum sawmli a thok vaengah Egypt te ka taek ka yak nah pilnam taeng lamloh pahoi ka coi ni.
14 Èmi yóò sì tún mú ìgbèkùn Ejibiti padà bọ̀, èmi yóò sì dá wọn padà sí ilẹ̀ Paturosi, ilẹ̀ àwọn baba ńlá wọn. Wọn yóò wà níbẹ̀ bí ìjọba tí a rẹ̀ sílẹ̀.
Egypt thongtla te ka mael puei vetih amih te amah tuikong khohmuen kah Parthros khohmuen la ka bal sak ni. Te vaengah tlarhoel ram la pahoi om uh ni.
15 Ibẹ̀ yóò jẹ́ ìjọba tí ó rẹlẹ̀ jùlọ nínú àwọn ìjọba, kì yóò sì gbé ara rẹ̀ ga mọ́ sórí àwọn orílẹ̀-èdè: nítorí èmi ni ó dín wọn kù, tiwọn kì yóò fi ṣe olórí àwọn orílẹ̀-èdè yòókù mọ́.
Ram tom lakah tlarhoel la om vetih namtom soah koep cungphoek mahpawh. Amih te ka muei sak daengah ni namtom soah a taemrhai pawt eh.
16 Ejibiti kí yóò sì jẹ orísun ìgbẹ́kẹ̀lé fún ilé Israẹli mọ́ ṣùgbọ́n, yóò jẹ́ ìrántí fún àìṣedéédéé wọn, nígbà tí yóò bá wò wọ́n fún ìrànlọ́wọ́. Nígbà náà, wọn yóò mọ̀ pé èmi ni Olúwa Olódùmarè.’”
Te vaengah a taengla amamih hooi uh tih thaesainah aka poek rhoek kah pangtungnah la Israel imkhui he om voel mahpawh. Te phoeiah Kai he, ka Boeipa Yahovah ni tila a ming uh bitni,” a ti.
17 Ó sì ṣe ní ọjọ́ kìn-ín-ní, oṣù kìn-ín-ní, ọdún kẹtàdínlọ́gbọ̀n, ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé:
Kum kul kum rhih, hla lamhma hnin at dongla a om vaengah BOEIPA ol kai taengla ha pawk tih,
18 “Ọmọ ènìyàn, Nebukadnessari ọba Babeli mú kí ogun rẹ sin ìrú ńlá fún Tire. Gbogbo orí pá, àti gbogbo èjìká bó, síbẹ̀, òun àti àwọn ogun rẹ̀, kò rí owó ọ̀yà gbà láti Tire fún wa, fún ìrú ti a ti sìn.
“Hlang capa aw, Babylon manghai Nebukhanezar loh Tyre te a caem kah thohtatnah a len neh a thohtat sak coeng. A lu khaw boeih tlong tih laengpang boeih thool coeng. Tedae amah ham neh a caem ham thapang om hae pawh. Tyre lamkah thohtatnah lamloh a taengah a thohtat sak.
19 Nítorí náà, báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Kíyèsi i, Èmi yóò fi Ejibiti fún Nebukadnessari ọba Babeli, òun yóò sì kó ọrọ̀ rẹ̀ lọ. Òun yóò bo ilé, yóò sì ṣe ìkógun ilẹ̀ náà gẹ́gẹ́ bí owó iṣẹ́ tí a san fún ológun rẹ̀.
Te dongah ka Boeipa Yahovah loh he ni a thui. Kai loh Babylon manghai Nebukhanezar taengah Egypt khohmuen ka paek coeng he. Te vaengah a hlangping te a khuen pah vetih a kutbuem khaw a buem pah ni. A maeh te a poelyoe pah vetih a caem ham thapang la om ni.
20 Èmi ti fi Ejibiti fún un gẹ́gẹ́ bí èrè wàhálà rẹ̀ nítorí òun àti àwọn ológun rẹ ṣe é fún mi, ni Olúwa Olódùmarè wí.
A taengah a thohtat te khaw kai ham a saii uh dongah, a thaphu la anih te Egypt khohmuen ka paek. He tah ka Boeipa Yahovah kah olphong ni.
21 “Ní ọjọ́ náà, èmi yóò mú kí ìwo Israẹli ru jáde, èmi yóò sì fún ọ ní ẹnu ọ̀rọ̀ ní àárín wọn. Nígbà náà ni wọn yóò mọ̀ pé èmi ni Olúwa.”
Te khohnin ah Israel imkhui ham ki cawn ni. Te vaengah nang te amih lakli ah ka ongnah ka paek vetih BOEIPA kamah he m'ming uh ni,” a ti.

< Ezekiel 29 >