< Ezekiel 28 >
1 Ọ̀rọ̀ Olúwa tún tọ̀ mí wá wí pé:
Cuvântul DOMNULUI a venit din nou la mine, spunând:
2 “Ọmọ ènìyàn, sọ fún ọmọ-aládé Tire pé, ‘Báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí: “‘Nítorí tí ọkàn rẹ gbé sókè sí mi, ìwọ wí pé, “Èmi ni Ọlọ́run; Èmi jókòó sí orí ìtẹ́ òrìṣà, ní àárín gbùngbùn Òkun.” Ṣùgbọ́n ènìyàn ni ọ́, kì i ṣe òrìṣà, bí ó tilẹ̀ jẹ́ wí pé ìwọ rò pé ìwọ gbọ́n bí Ọlọ́run.
Fiu al omului, spune prințului Tirului: Astfel spune Domnul DUMNEZEU: Pentru că inima ta s-a înălțat și tu ai spus: Eu [sunt] Dumnezeu, eu șed [în] scaunul lui Dumnezeu, în mijlocul mărilor; totuși tu [ești] om și nu Dumnezeu, deși îți pui inima precum inima lui Dumnezeu:
3 Ìwọ gbọ́n ju Daniẹli lọ bí? Ṣé kò sí àṣírí kan tí ó pamọ́ fún ọ?
Iată, tu [ești] mai înțelept decât Daniel; nu este nicio taină pe care ei să o poată ascunde de tine;
4 Pẹ̀lú ọgbọ́n àti ìmọ̀ rẹ, ìwọ tí jèrè ọrọ̀ fún ara rẹ, àti àkójọpọ̀ wúrà àti fàdákà, nínú àwọn ilé ìṣúra rẹ.
Cu înțelepciunea ta și cu înțelegerea ta ți-ai obținut bogățiile și ai obținut aur și argint în tezaurele tale;
5 Nípa ọgbọ́n rẹ ńlá àti nípa òwò rẹ, ìwọ ti sọ ọrọ̀ rẹ di púpọ̀, àti nítorí ọrọ̀ rẹ di púpọ̀, ọkàn rẹ gbé sókè, nítorí ọrọ̀ rẹ.
Prin înțelepciunea ta cea mare [și] prin comerțul tău ți-ai înmulțit bogățiile și inima ta s-a înălțat datorită bogățiilor tale.
6 “‘Nítorí náà èyí yìí ní Olúwa Olódùmarè wí: “‘Nítorí pé ìwọ rò pé o gbọ́n, pé ìwọ gbọ́n bí Ọlọ́run.
De aceea astfel spune Domnul DUMNEZEU: Pentru că ți-ai pus inima ca inima lui Dumnezeu;
7 Èmi yóò mú kí àwọn àjèjì dìde sí ọ, ẹlẹ́rù nínú àwọn orílẹ̀-èdè; wọn yóò yọ idà wọn sí ọ, ẹwà rẹ àti ọgbọ́n rẹ, wọn yóò sì ba dídán rẹ̀ jẹ́.
Iată, de aceea eu voi aduce străini asupra ta, pe cei [mai] tirani dintre națiuni; și ei își vor scoate săbiile împotriva frumuseții înțelepciunii tale și îți vor întina strălucirea.
8 Wọn yóò mú ọ sọ̀kalẹ̀ wá sínú ihò, ìwọ yóò sì kú ikú gbígbóná, àwọn tí a pa ní àárín Òkun.
Ei te vor coborî în groapă și vei muri de moartea [celor care sunt] uciși în mijlocul mărilor.
9 Ṣé ìwọ yóò wá wí pé, “Èmi ni Ọlọ́run,” ní ojú àwọn tí ó pa ọ́? Ìwọ yóò jẹ́ ènìyàn, kì í ṣe Ọlọ́run, ní ọwọ́ àwọn ti yóò pa ọ́.
Vei mai spune tu înaintea celui care te ucide: Eu [sunt] Dumnezeu? Dar tu [vei fi] om și nu Dumnezeu, în mâna celui care te ucide.
10 Ìwọ yóò kú ikú aláìkọlà, ní ọwọ́ àwọn àjèjì. Èmi ni ó ti sọ ọ́, ní Olúwa Olódùmarè wí.’”
Vei muri de moartea celor necircumciși, prin mâna străinilor, pentru că eu am vorbit [aceasta], spune Domnul DUMNEZEU.
11 Ọ̀rọ̀ Olúwa tún tọ̀ mí wá wí pé:
Mai mult, cuvântul DOMNULUI a venit la mine, spunând:
12 “Ọmọ ènìyàn, pohùnréré ẹkún sórí ọba Tire kí ó sì sọ fún un pé: ‘Èyí yìí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: “‘Ìwọ jẹ́ àpẹẹrẹ ìjẹ́pípé náà, o kún fún ọgbọ́n, o sì pé ní ẹwà.
Fiu al omului, înalță o plângere asupra împăratului Tirului și spune-i: Astfel spune Domnul DUMNEZEU: Tu sigilezi măsura [desăvârșirii], plin de înțelepciune și desăvârșit în frumusețe.
13 Ìwọ ti wà ní Edeni, ọgbà Ọlọ́run; onírúurú òkúta oníyebíye ni ìbora rẹ; sardiu, topasi àti diamọndi, berili, óníkìsì, àti jasperi, safire, emeradi, turikuose, àti karbunkili, àti wúrà, ìpilẹ̀ṣẹ̀ rẹ àti àwọn òkè rẹ ní a dà, láti ara wúrà, ní ọjọ́ tí á dá ọ ní a pèsè wọn.
Tu erai în Eden grădina lui Dumnezeu; fiecare piatră prețioasă [era] acoperitoarea ta: sardonixul, topazul și diamantul, berilul, onixul și iaspisul, safirul, smaraldul și rubinul și aurul; măiestria tamburinelor tale și a fluierelor tale era pregătită în tine în ziua când ai fost creat.
14 A fi àmì òróró yàn ọ́ gẹ́gẹ́ bí olùtọ́jú kérúbù, torí èyí ni mo fi yàn ọ́. Ìwọ wà lórí òkè mímọ́ Ọlọ́run; ìwọ rìn ni àárín òkúta a mú bí iná.
Tu [ești] heruvimul uns care acoperă; și eu te-am pus [astfel]; erai pe muntele cel sfânt al lui Dumnezeu; ai umblat în sus și în jos prin mijlocul pietrelor de foc.
15 Ìwọ pé ní ọ̀nà rẹ, láti ọjọ́ tí a ti dá ọ, títí a fi rí àìṣedéédéé ní inú rẹ.
Tu [erai] desăvârșit în căile tale din ziua când ai fost creat, până când nelegiuire a fost găsită în tine.
16 Nípa ìtànkálẹ̀ òwò rẹ, ìwọ kún fún ìwà ipá; ìwọ sì dẹ́ṣẹ̀. Nítorí náà ni mo ṣe sọ ọ nù, bí ohun àìlọ́wọ̀ kúrò lórí òkè Ọlọ́run. Èmi sì pa ọ run, ìwọ kérúbù, tí ó bọ́ kúrò ní àárín òkúta a mú bí iná.
Prin mulțimea mărfurilor tale, ei ți-au umplut mijlocul cu violență și tu ai păcătuit; de aceea ca pângărit te voi arunca de pe muntele lui Dumnezeu; și te voi nimici, pe tine heruvim care acoperă, din mijlocul pietrelor de foc.
17 Ọkàn rẹ gbéraga, nítorí ẹwà rẹ. Ìwọ sì ba ọgbọ́n rẹ jẹ́, nítorí dídára rẹ. Nítorí náà mo le ọ sórí ayé; mo sọ ọ di awòojú níwájú àwọn ọba.
Inima ta a fost înălțată din cauza frumuseții tale; tu ți-ai corupt înțelepciunea datorită strălucirii tale; te voi arunca la pământ, te voi întinde înaintea împăraților ca ei să te privească.
18 Nípa ẹ̀ṣẹ̀ púpọ̀ rẹ àti òwò àìṣòótọ́ rẹ, ìwọ ti ba àwọn ibi mímọ́ rẹ jẹ́. Nítorí náà mo mú kí iná jáde wá, láti inú rẹ, yóò sì jó ọ run, èmi yóò sì sọ ọ́ di eérú lórí ilẹ̀, lójú gbogbo àwọn tí ó ń wò ọ́.
Tu ai spurcat sanctuarele tale prin mulțimea nelegiuirilor tale, prin nelegiuirea comerțului tău; de aceea voi scoate un foc din mijlocul tău, acesta te va mistui și te voi preface în cenușă pe pământ înaintea ochilor tuturor celor care te privesc.
19 Gbogbo orílẹ̀-èdè tí ó mọ̀ ọ́n, ní ẹnu ń yà sí ọ; ìwọ yóò sì jẹ́ ẹ̀rù, ìwọ kì yóò sì ṣí mọ́ láéláé.’”
Toți cei care te cunosc între popoare vor fi înmărmuriți din [cauza] ta; vei fi o teroare și niciodată nu [vei] mai [fi].
20 Ọ̀rọ̀ Olúwa tún tọ̀ mí wá wí pé:
Din nou, cuvântul DOMNULUI a venit la mine, spunând:
21 “Ọmọ ènìyàn, kọ ojú sí Sidoni; kí o sì sọtẹ́lẹ̀ sí i,
Fiu al omului, îndreaptă-ți fața împotriva Sidonului și profețește împotriva lui,
22 kí ó sì wí pé, ‘Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí: “‘Èmi lòdì sí ọ, ìwọ Sidoni, a ó sì ṣe mí lógo láàrín rẹ. Wọn yóò mọ̀ pé èmi ní Olúwa, nígbà tí mo bá mú ìdájọ́ mi ṣẹ nínú rẹ, tí a sì yá mí sí mímọ́ nínú rẹ.
Și spune: Astfel spune Domnul DUMNEZEU: Iată, eu [sunt] împotriva ta, Sidonule; și voi fi glorificat în mijlocul tău; și ei vor cunoaște că eu [sunt] DOMNUL, când voi fi făcut judecăți în el și voi fi sfințit în el.
23 Èmi yóò sì rán àjàkálẹ̀-ààrùn sínú rẹ, èmi yóò sì mú kí ẹ̀jẹ̀ sàn ní ìgboro rẹ, ẹni ti á pa yóò ṣubú ní àárín rẹ, pẹ̀lú idà lára rẹ ní gbogbo ẹ̀gbẹ́, nígbà náà wọn yóò mọ̀ wí pé èmi ni Olúwa.
Fiindcă voi trimite ciumă în el și sânge pe străzile lui; și răniții vor cădea în mijlocul lui prin sabia [care va fi] asupra lui de fiecare parte; și ei vor cunoaște că eu [sunt] DOMNUL.
24 “‘Kì yóò sì ṣí ẹ̀gún tí ń gun ni ní ilẹ̀ Israẹli mọ́, tàbí ẹ̀gún bíbani nínú jẹ́ ti gbogbo àwọn tí wọn wà ní àyíká wọn, tí wọ́n sì ń fi ojú yẹpẹrẹ wò wọ́n, nígbà náà ni wọn yóò mọ́ wí pé èmi ni Olúwa Olódùmarè.
Și nu va mai fi niciun spin înțepător pentru casa lui Israel, nici [vreun] mărăcine apăsător dintre toți cei [care sunt] în jurul lor, care îi disprețuiau; și ei vor cunoaște că eu [sunt] Domnul DUMNEZEU.
25 “‘Èyí yìí ní Olúwa Olódùmarè wí: Nígbà tí èmi yóò bá sa àwọn ènìyàn Israẹli jọ kúrò ní gbogbo orílẹ̀-èdè tí wọ́n ti fọ́nká sí, tí a ó sì yà mí sí mímọ́ láàrín wọn lójú àwọn aláìkọlà. Nígbà náà ni wọn yóò gbé ní ilẹ̀ àwọn tìkálára wọn, èyí tí mo fún ìránṣẹ́ mi Jakọbu.
Astfel spune Domnul DUMNEZEU: După ce voi fi adunat casa lui Israel dintre popoarele între care sunt împrăștiați și voi fi sfințit în ei înaintea ochilor păgânilor, atunci vor locui în țara lor pe care am dat-o servitorului meu Iacob.
26 Wọn yóò sì máa gbé ní inú rẹ̀ ní àìléwu, wọn yóò sì kọ́lé, wọn yóò sì gbin ọgbà àjàrà; nítòótọ́ wọn yóò wà ní ìbàlẹ̀ àyà, nígbà tí èmi bá ti mú ìdájọ́ mi ṣẹ̀ sí ara àwọn tí ń ṣátá wọn ní gbogbo àyíká wọn. Nígbà náà ni wọn yóò mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa Ọlọ́run wọn.’”
Și vor locui în ea, în siguranță, și vor construi case și vor sădi vii; da, vor locui cu încredere, după ce îmi voi fi împlinit judecățile asupra tuturor celor care îi disprețuiesc de jur împrejurul lor; și vor cunoaște că eu [sunt] DOMNUL Dumnezeul lor.