< Ezekiel 28 >

1 Ọ̀rọ̀ Olúwa tún tọ̀ mí wá wí pé:
Et la parole du Seigneur me vint, disant:
2 “Ọmọ ènìyàn, sọ fún ọmọ-aládé Tire pé, ‘Báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí: “‘Nítorí tí ọkàn rẹ gbé sókè sí mi, ìwọ wí pé, “Èmi ni Ọlọ́run; Èmi jókòó sí orí ìtẹ́ òrìṣà, ní àárín gbùngbùn Òkun.” Ṣùgbọ́n ènìyàn ni ọ́, kì i ṣe òrìṣà, bí ó tilẹ̀ jẹ́ wí pé ìwọ rò pé ìwọ gbọ́n bí Ọlọ́run.
Et toi, fils de l'homme, dis au roi de Tyr: Voici ce que dit le Seigneur: En punition de ce que ton cœur s'est enorgueilli, et de ce que tu as dit: Je suis Dieu, j'habite au cœur de la mer une demeure de Dieu; tu verras que tu es un homme et non un Dieu; et tu as élevé ton cœur, comme s'il eût été le cœur de Dieu.
3 Ìwọ gbọ́n ju Daniẹli lọ bí? Ṣé kò sí àṣírí kan tí ó pamọ́ fún ọ?
Es-tu plus sage que Daniel? Les sages ne t'ont-ils pas instruit de leur science?
4 Pẹ̀lú ọgbọ́n àti ìmọ̀ rẹ, ìwọ tí jèrè ọrọ̀ fún ara rẹ, àti àkójọpọ̀ wúrà àti fàdákà, nínú àwọn ilé ìṣúra rẹ.
Est-ce par ton propre savoir et ton intelligence que tu t'es rendu puissant, et que tu as entassé l'or et l'argent dans tes trésors?
5 Nípa ọgbọ́n rẹ ńlá àti nípa òwò rẹ, ìwọ ti sọ ọrọ̀ rẹ di púpọ̀, àti nítorí ọrọ̀ rẹ di púpọ̀, ọkàn rẹ gbé sókè, nítorí ọrọ̀ rẹ.
Tu as accru ta puissance par ta science et par ton commerce, et ton cœur s'est enorgueilli de ta puissance.
6 “‘Nítorí náà èyí yìí ní Olúwa Olódùmarè wí: “‘Nítorí pé ìwọ rò pé o gbọ́n, pé ìwọ gbọ́n bí Ọlọ́run.
C'est pourquoi ainsi parle le Seigneur: Puisque tu as élevé ton cœur comme s'il eût été le cœur de Dieu;
7 Èmi yóò mú kí àwọn àjèjì dìde sí ọ, ẹlẹ́rù nínú àwọn orílẹ̀-èdè; wọn yóò yọ idà wọn sí ọ, ẹwà rẹ àti ọgbọ́n rẹ, wọn yóò sì ba dídán rẹ̀ jẹ́.
À cause de cela, voilà que j'amène contre toi des fléaux étrangers, venus des nations; et elles arriveront l'épée nue pour frapper toi, ta beauté, ta science, et elles jetteront à terre ta beauté, qu'elles détruiront.
8 Wọn yóò mú ọ sọ̀kalẹ̀ wá sínú ihò, ìwọ yóò sì kú ikú gbígbóná, àwọn tí a pa ní àárín Òkun.
Et elles te renverseront, et tu mourras de mort avec ceux qui périront au cœur de la mer.
9 Ṣé ìwọ yóò wá wí pé, “Èmi ni Ọlọ́run,” ní ojú àwọn tí ó pa ọ́? Ìwọ yóò jẹ́ ènìyàn, kì í ṣe Ọlọ́run, ní ọwọ́ àwọn ti yóò pa ọ́.
Diras-tu: Je suis Dieu, devant ceux qui te tueront? Tu es un homme, et non un Dieu.
10 Ìwọ yóò kú ikú aláìkọlà, ní ọwọ́ àwọn àjèjì. Èmi ni ó ti sọ ọ́, ní Olúwa Olódùmarè wí.’”
Tu périras par les mains des étrangers, au milieu de la multitude des incirconcis; car moi j'ai parlé, dit le Seigneur.
11 Ọ̀rọ̀ Olúwa tún tọ̀ mí wá wí pé:
Et la parole du Seigneur me vint, disant:
12 “Ọmọ ènìyàn, pohùnréré ẹkún sórí ọba Tire kí ó sì sọ fún un pé: ‘Èyí yìí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: “‘Ìwọ jẹ́ àpẹẹrẹ ìjẹ́pípé náà, o kún fún ọgbọ́n, o sì pé ní ẹwà.
Fils de l'homme, fais une lamentation sur le roi de Tyr, et dis-lui: Ainsi parle le Seigneur Maître: Toi, le sceau de la ressemblance de Dieu; toi, couronné de beauté,
13 Ìwọ ti wà ní Edeni, ọgbà Ọlọ́run; onírúurú òkúta oníyebíye ni ìbora rẹ; sardiu, topasi àti diamọndi, berili, óníkìsì, àti jasperi, safire, emeradi, turikuose, àti karbunkili, àti wúrà, ìpilẹ̀ṣẹ̀ rẹ àti àwọn òkè rẹ ní a dà, láti ara wúrà, ní ọjọ́ tí á dá ọ ní a pèsè wọn.
Tu as été dans les délices du paradis de Dieu; tu t'es paré de toute pierre précieuse, de la sardoine, de la topaze, de l'émeraude, de l'escarboucle, du saphir, du jaspe, de l'argent, de l'or, de l'ambre, de l'agate, de l'améthyste, de la chrysolithe, du béryl, de l'onyx; tu as rempli d'or tes trésors et tes celliers.
14 A fi àmì òróró yàn ọ́ gẹ́gẹ́ bí olùtọ́jú kérúbù, torí èyí ni mo fi yàn ọ́. Ìwọ wà lórí òkè mímọ́ Ọlọ́run; ìwọ rìn ni àárín òkúta a mú bí iná.
Le jour où tu as été créé, tu as été avec le chérubin; je t'ai mis en la montagne sainte de Dieu, au milieu de pierres de feu lançant des flammes.
15 Ìwọ pé ní ọ̀nà rẹ, láti ọjọ́ tí a ti dá ọ, títí a fi rí àìṣedéédéé ní inú rẹ.
Tu as été irréprochable en ta vie, du jour où tu as été créé jusqu'au jour où des iniquités ont été trouvées en toi.
16 Nípa ìtànkálẹ̀ òwò rẹ, ìwọ kún fún ìwà ipá; ìwọ sì dẹ́ṣẹ̀. Nítorí náà ni mo ṣe sọ ọ nù, bí ohun àìlọ́wọ̀ kúrò lórí òkè Ọlọ́run. Èmi sì pa ọ run, ìwọ kérúbù, tí ó bọ́ kúrò ní àárín òkúta a mú bí iná.
En multipliant ton commerce, tu as rempli d'iniquités tes trésors, et tu as péché, et tu as été blessé et exclu de la montagne de Dieu; et le chérubin t'a banni du milieu des pierres de feu lançant des flammes.
17 Ọkàn rẹ gbéraga, nítorí ẹwà rẹ. Ìwọ sì ba ọgbọ́n rẹ jẹ́, nítorí dídára rẹ. Nítorí náà mo le ọ sórí ayé; mo sọ ọ di awòojú níwájú àwọn ọba.
Ton cœur s'est enorgueilli de ta beauté; ta science a péri avec ta beauté. À cause de la multitude de tes péchés, je t'ai jeté à terre, je t'ai rendu infâme en présence de tous les rois.
18 Nípa ẹ̀ṣẹ̀ púpọ̀ rẹ àti òwò àìṣòótọ́ rẹ, ìwọ ti ba àwọn ibi mímọ́ rẹ jẹ́. Nítorí náà mo mú kí iná jáde wá, láti inú rẹ, yóò sì jó ọ run, èmi yóò sì sọ ọ́ di eérú lórí ilẹ̀, lójú gbogbo àwọn tí ó ń wò ọ́.
À cause de la multitude de tes péchés et de l'iniquité de tes trafics, j'ai souillé tes choses saintes; et je ferai sortir du milieu de toi un feu qui te dévorera; et je te réduirai en cendres sur la terre aux yeux de tous ceux qui te verront.
19 Gbogbo orílẹ̀-èdè tí ó mọ̀ ọ́n, ní ẹnu ń yà sí ọ; ìwọ yóò sì jẹ́ ẹ̀rù, ìwọ kì yóò sì ṣí mọ́ láéláé.’”
Et tous ceux qui te connaissent parmi les nations gémiront sur toi. Tu es anéanti, et tu ne seras plus dans les siècles.
20 Ọ̀rọ̀ Olúwa tún tọ̀ mí wá wí pé:
Et la parole du Seigneur me vint, disant:
21 “Ọmọ ènìyàn, kọ ojú sí Sidoni; kí o sì sọtẹ́lẹ̀ sí i,
Fils de l'homme, tourne ton visage contre Sidon, et prophétise contre elle.
22 kí ó sì wí pé, ‘Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí: “‘Èmi lòdì sí ọ, ìwọ Sidoni, a ó sì ṣe mí lógo láàrín rẹ. Wọn yóò mọ̀ pé èmi ní Olúwa, nígbà tí mo bá mú ìdájọ́ mi ṣẹ nínú rẹ, tí a sì yá mí sí mímọ́ nínú rẹ.
Et je dis: Ainsi parle le Seigneur: Voilà que je sois contre toi, Sidon, et je serai glorifié en toi, et tu connaîtras que je suis le Seigneur, lorsque j'aurai exercé mes jugements sur toi, et que je serai sanctifié en toi.
23 Èmi yóò sì rán àjàkálẹ̀-ààrùn sínú rẹ, èmi yóò sì mú kí ẹ̀jẹ̀ sàn ní ìgboro rẹ, ẹni ti á pa yóò ṣubú ní àárín rẹ, pẹ̀lú idà lára rẹ ní gbogbo ẹ̀gbẹ́, nígbà náà wọn yóò mọ̀ wí pé èmi ni Olúwa.
Le sang et la mort seront sur tes places, et autour de toi tomberont ceux que chez toi le glaive aura blessés; et ils sauront que je suis le Seigneur.
24 “‘Kì yóò sì ṣí ẹ̀gún tí ń gun ni ní ilẹ̀ Israẹli mọ́, tàbí ẹ̀gún bíbani nínú jẹ́ ti gbogbo àwọn tí wọn wà ní àyíká wọn, tí wọ́n sì ń fi ojú yẹpẹrẹ wò wọ́n, nígbà náà ni wọn yóò mọ́ wí pé èmi ni Olúwa Olódùmarè.
Et il n'y aura plus dans la maison d'Israël d'aiguillon d'amertume ni d'épine de douleur venant de ceux qui l'entourent; et ils sauront que je suis le Seigneur.
25 “‘Èyí yìí ní Olúwa Olódùmarè wí: Nígbà tí èmi yóò bá sa àwọn ènìyàn Israẹli jọ kúrò ní gbogbo orílẹ̀-èdè tí wọ́n ti fọ́nká sí, tí a ó sì yà mí sí mímọ́ láàrín wọn lójú àwọn aláìkọlà. Nígbà náà ni wọn yóò gbé ní ilẹ̀ àwọn tìkálára wọn, èyí tí mo fún ìránṣẹ́ mi Jakọbu.
Voici ce que dit le Seigneur Maître: Alors je rassemblerai Israël d'entre les nations où il a été dispersé; et je serai sanctifié en lui, devant les peuples et les nations; et ils demeureront en leur terre, que j'ai donnée à mon serviteur Jacob.
26 Wọn yóò sì máa gbé ní inú rẹ̀ ní àìléwu, wọn yóò sì kọ́lé, wọn yóò sì gbin ọgbà àjàrà; nítòótọ́ wọn yóò wà ní ìbàlẹ̀ àyà, nígbà tí èmi bá ti mú ìdájọ́ mi ṣẹ̀ sí ara àwọn tí ń ṣátá wọn ní gbogbo àyíká wọn. Nígbà náà ni wọn yóò mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa Ọlọ́run wọn.’”
Et ils l'habiteront pleins d'espérance; et ils bâtirent des maisons, et ils planteront des vignes, et ils habiteront leur terre, pleins d'espérance, lorsque j'aurai exercé mes jugements sur tous ceux qui les entourent et qui les ont méprisés; et ils sauront que je suis le Seigneur leur Dieu, et le Dieu de leurs pères.

< Ezekiel 28 >