< Ezekiel 28 >

1 Ọ̀rọ̀ Olúwa tún tọ̀ mí wá wí pé:
The word of the Lord came againe vnto me, saying,
2 “Ọmọ ènìyàn, sọ fún ọmọ-aládé Tire pé, ‘Báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí: “‘Nítorí tí ọkàn rẹ gbé sókè sí mi, ìwọ wí pé, “Èmi ni Ọlọ́run; Èmi jókòó sí orí ìtẹ́ òrìṣà, ní àárín gbùngbùn Òkun.” Ṣùgbọ́n ènìyàn ni ọ́, kì i ṣe òrìṣà, bí ó tilẹ̀ jẹ́ wí pé ìwọ rò pé ìwọ gbọ́n bí Ọlọ́run.
Sonne of man, say vnto the prince of Tyrus, Thus saieth the Lord God, Because thine heart is exalted, and thou hast said, I am a God, I sit in the seat of God in ye mids of the sea, yet thou art but a man and not God, and though thou didest thinke in thine heart, that thou wast equall with God,
3 Ìwọ gbọ́n ju Daniẹli lọ bí? Ṣé kò sí àṣírí kan tí ó pamọ́ fún ọ?
Behold, thou art wiser then Daniel: there is no secrete, that they can hide from thee.
4 Pẹ̀lú ọgbọ́n àti ìmọ̀ rẹ, ìwọ tí jèrè ọrọ̀ fún ara rẹ, àti àkójọpọ̀ wúrà àti fàdákà, nínú àwọn ilé ìṣúra rẹ.
With thy wisedome and thine vnderstanding thou hast gotten thee riches, and hast gotten golde and siluer into thy treasures.
5 Nípa ọgbọ́n rẹ ńlá àti nípa òwò rẹ, ìwọ ti sọ ọrọ̀ rẹ di púpọ̀, àti nítorí ọrọ̀ rẹ di púpọ̀, ọkàn rẹ gbé sókè, nítorí ọrọ̀ rẹ.
By thy great wisedome and by thine occupying hast thou increased thy riches, and thine heart is lifted vp because of thy riches.
6 “‘Nítorí náà èyí yìí ní Olúwa Olódùmarè wí: “‘Nítorí pé ìwọ rò pé o gbọ́n, pé ìwọ gbọ́n bí Ọlọ́run.
Therefore thus sayeth the Lord God, Because thou didest thinke in thine heart, that thou wast equall with God,
7 Èmi yóò mú kí àwọn àjèjì dìde sí ọ, ẹlẹ́rù nínú àwọn orílẹ̀-èdè; wọn yóò yọ idà wọn sí ọ, ẹwà rẹ àti ọgbọ́n rẹ, wọn yóò sì ba dídán rẹ̀ jẹ́.
Behold, therefore I wil bring strangers vpon thee, euen the terrible nations: and they shall drawe their swordes against the beautie of thy wisedome, and they shall defile thy brightnes.
8 Wọn yóò mú ọ sọ̀kalẹ̀ wá sínú ihò, ìwọ yóò sì kú ikú gbígbóná, àwọn tí a pa ní àárín Òkun.
They shall cast thee downe to the pit, and thou shalt die the death of them, that are slaine in the middes of the sea.
9 Ṣé ìwọ yóò wá wí pé, “Èmi ni Ọlọ́run,” ní ojú àwọn tí ó pa ọ́? Ìwọ yóò jẹ́ ènìyàn, kì í ṣe Ọlọ́run, ní ọwọ́ àwọn ti yóò pa ọ́.
Wilt thou say then before him, that slayeth thee, I am a god? but thou shalt be a man, and no God, in the hands of him that slayeth thee.
10 Ìwọ yóò kú ikú aláìkọlà, ní ọwọ́ àwọn àjèjì. Èmi ni ó ti sọ ọ́, ní Olúwa Olódùmarè wí.’”
Thou shalt die the death of the vncircumcised by the hands of stragers: for I haue spoken it, sayth the Lord God.
11 Ọ̀rọ̀ Olúwa tún tọ̀ mí wá wí pé:
Moreouer the word of the Lord came vnto me, saying,
12 “Ọmọ ènìyàn, pohùnréré ẹkún sórí ọba Tire kí ó sì sọ fún un pé: ‘Èyí yìí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: “‘Ìwọ jẹ́ àpẹẹrẹ ìjẹ́pípé náà, o kún fún ọgbọ́n, o sì pé ní ẹwà.
Sonne of man, take vp a lamentation vpon the King of Tyrus, and say vnto him, Thus sayeth the Lord God, Thou sealest vp the summe, and art full of wisedome and perfite in beautie.
13 Ìwọ ti wà ní Edeni, ọgbà Ọlọ́run; onírúurú òkúta oníyebíye ni ìbora rẹ; sardiu, topasi àti diamọndi, berili, óníkìsì, àti jasperi, safire, emeradi, turikuose, àti karbunkili, àti wúrà, ìpilẹ̀ṣẹ̀ rẹ àti àwọn òkè rẹ ní a dà, láti ara wúrà, ní ọjọ́ tí á dá ọ ní a pèsè wọn.
Thou hast ben in Eden the garden of God: euery precious stone was in thy garment, the rubie, the topaze and the diamonde, the chrysolite, the onix, and the iasper, the saphir, emeraude, and the carbuncle and golde: the woorkemanship of thy timbrels, and of thy pipes was prepared in thee in the day that thou wast created.
14 A fi àmì òróró yàn ọ́ gẹ́gẹ́ bí olùtọ́jú kérúbù, torí èyí ni mo fi yàn ọ́. Ìwọ wà lórí òkè mímọ́ Ọlọ́run; ìwọ rìn ni àárín òkúta a mú bí iná.
Thou art the anointed Cherub, that couereth, and I haue set thee in honour: thou wast vpon the holy mountaine of God: thou hast walked in the middes of the stones of fire.
15 Ìwọ pé ní ọ̀nà rẹ, láti ọjọ́ tí a ti dá ọ, títí a fi rí àìṣedéédéé ní inú rẹ.
Thou wast perfite in thy wayes from the day that thou wast created, till iniquitie was found in thee.
16 Nípa ìtànkálẹ̀ òwò rẹ, ìwọ kún fún ìwà ipá; ìwọ sì dẹ́ṣẹ̀. Nítorí náà ni mo ṣe sọ ọ nù, bí ohun àìlọ́wọ̀ kúrò lórí òkè Ọlọ́run. Èmi sì pa ọ run, ìwọ kérúbù, tí ó bọ́ kúrò ní àárín òkúta a mú bí iná.
By the multitude of thy marchandise, they haue filled the middes of thee with crueltie, and thou hast sinned: therefore I will cast thee as prophane out of the mountaine of God: and I will destroy thee, O couering Cherub from the mids of the stones of fire.
17 Ọkàn rẹ gbéraga, nítorí ẹwà rẹ. Ìwọ sì ba ọgbọ́n rẹ jẹ́, nítorí dídára rẹ. Nítorí náà mo le ọ sórí ayé; mo sọ ọ di awòojú níwájú àwọn ọba.
Thine heart was lifted vp because of thy beautie, and thou hast corrupted thy wisedome by reason of thy brightnes: I wil cast thee to ye grounde: I will lay thee before Kinges that they may beholde thee.
18 Nípa ẹ̀ṣẹ̀ púpọ̀ rẹ àti òwò àìṣòótọ́ rẹ, ìwọ ti ba àwọn ibi mímọ́ rẹ jẹ́. Nítorí náà mo mú kí iná jáde wá, láti inú rẹ, yóò sì jó ọ run, èmi yóò sì sọ ọ́ di eérú lórí ilẹ̀, lójú gbogbo àwọn tí ó ń wò ọ́.
Thou hast defiled thy sanctification by the multitude of thine iniquities, and by the iniquitie of thy marchandise: therefore wil I bring forth a fire from the mids of thee, which shall deuoure thee: and I wil bring thee to ashes vpon the earth, in the sight of all them that beholde thee.
19 Gbogbo orílẹ̀-èdè tí ó mọ̀ ọ́n, ní ẹnu ń yà sí ọ; ìwọ yóò sì jẹ́ ẹ̀rù, ìwọ kì yóò sì ṣí mọ́ láéláé.’”
All they that knowe thee among the people, shalbe astonished at thee: thou shalt be a terrour, and neuer shalt thou be any more.
20 Ọ̀rọ̀ Olúwa tún tọ̀ mí wá wí pé:
Againe, the worde of the Lord came vnto me, saying,
21 “Ọmọ ènìyàn, kọ ojú sí Sidoni; kí o sì sọtẹ́lẹ̀ sí i,
Sonne of man, set thy face against Zidon, and prophesie against it,
22 kí ó sì wí pé, ‘Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí: “‘Èmi lòdì sí ọ, ìwọ Sidoni, a ó sì ṣe mí lógo láàrín rẹ. Wọn yóò mọ̀ pé èmi ní Olúwa, nígbà tí mo bá mú ìdájọ́ mi ṣẹ nínú rẹ, tí a sì yá mí sí mímọ́ nínú rẹ.
And say, Thus saith the Lord God, Behold, I come against thee, O Zidon, and I will be glorified in the mids of thee: and they shall know that I am the Lord, when I shall haue executed iudgements in her, and shalbe sanctified in her.
23 Èmi yóò sì rán àjàkálẹ̀-ààrùn sínú rẹ, èmi yóò sì mú kí ẹ̀jẹ̀ sàn ní ìgboro rẹ, ẹni ti á pa yóò ṣubú ní àárín rẹ, pẹ̀lú idà lára rẹ ní gbogbo ẹ̀gbẹ́, nígbà náà wọn yóò mọ̀ wí pé èmi ni Olúwa.
For I wil send into her pestilence, and blood into her streetes, and the slaine shall fall in the middes of her: the enemie shall come against her with the sword on euery side, and they shall know that I am the Lord.
24 “‘Kì yóò sì ṣí ẹ̀gún tí ń gun ni ní ilẹ̀ Israẹli mọ́, tàbí ẹ̀gún bíbani nínú jẹ́ ti gbogbo àwọn tí wọn wà ní àyíká wọn, tí wọ́n sì ń fi ojú yẹpẹrẹ wò wọ́n, nígbà náà ni wọn yóò mọ́ wí pé èmi ni Olúwa Olódùmarè.
And they shalbe no more a pricking thorne vnto the house of Israel, nor any grieuous thorne of all that are round about them, and despised them, and they shall knowe that I am the Lord God.
25 “‘Èyí yìí ní Olúwa Olódùmarè wí: Nígbà tí èmi yóò bá sa àwọn ènìyàn Israẹli jọ kúrò ní gbogbo orílẹ̀-èdè tí wọ́n ti fọ́nká sí, tí a ó sì yà mí sí mímọ́ láàrín wọn lójú àwọn aláìkọlà. Nígbà náà ni wọn yóò gbé ní ilẹ̀ àwọn tìkálára wọn, èyí tí mo fún ìránṣẹ́ mi Jakọbu.
Thus saith the Lord God, When I shall haue gathered the house of Israel from the people where they are scattered, and shalbe sanctified in them in the sight of the heathen, then shall they dwel in the land, that I haue giuen to my seruant Iaakob.
26 Wọn yóò sì máa gbé ní inú rẹ̀ ní àìléwu, wọn yóò sì kọ́lé, wọn yóò sì gbin ọgbà àjàrà; nítòótọ́ wọn yóò wà ní ìbàlẹ̀ àyà, nígbà tí èmi bá ti mú ìdájọ́ mi ṣẹ̀ sí ara àwọn tí ń ṣátá wọn ní gbogbo àyíká wọn. Nígbà náà ni wọn yóò mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa Ọlọ́run wọn.’”
And they shall dwell safely therein, and shall builde houses, and plant vineyards: yea, they shall dwell safely, when I haue executed iudgements vpon al round about them that despise them, and they shall knowe that I am the Lord their God.

< Ezekiel 28 >