< Ezekiel 27 >

1 Ọ̀rọ̀ Olúwa tún tọ̀ mí wá wí pé:
Cuvântul DOMNULUI a venit din nou la mine, spunând:
2 “Ọmọ ènìyàn, pohùnréré ẹkún fún Tire.
Și tu, fiu al omului, înalță o plângere pentru Tir;
3 Sọ fún Tire, tí a tẹ̀dó sí ẹnu-bodè Òkun, oníṣòwò àwọn orílẹ̀-èdè fún ọ̀pọ̀lọpọ̀ erékùṣù. ‘Èyí yìí ní Olúwa Olódùmarè wí: “‘Ìwọ Tire wí pé, “Ẹwà mi pé.”
Și spune Tirului: Tu, cel care ești situat la intrarea mării, [care ești] un comerciant pentru popoarele din multe insule: Astfel spune Domnul DUMNEZEU: Tirule, tu ai spus: Eu [sunt] de o frumusețe desăvârșită.
4 Ààlà rẹ wà ní àárín Òkun; àwọn ọ̀mọ̀lé rẹ ti mú ẹwà rẹ pé.
Granițele tale [sunt] în mijlocul mărilor, constructorii tăi ți-au desăvârșit frumusețea.
5 Wọn ṣe gbogbo pákó rẹ ní igi junifa láti Seniri; wọ́n ti mú igi kedari láti Lebanoni wá láti fi ṣe òpó ọkọ̀ fún ọ.
Ei ți-au făcut toate scândurile [pentru corăbii] din brazi de Senir; au luat cedri din Liban pentru a face catarge pentru tine.
6 Nínú igi óákù ti Baṣani ní wọn ti fi gbẹ́ ìtukọ̀ ọ̀pá rẹ̀; ìjókòó rẹ ni wọn fi eyín erin ṣe pẹ̀lú igi bokisi láti erékùṣù Kittimu wá.
[Din] stejarii Basanului ți-au făcut vâslele; ceata de așuriți ți-au făcut băncile [din] fildeș, [adus] din insulele Chitimului.
7 Ọ̀gbọ̀ dáradára aṣọ iṣẹ́ ọnà abẹ́rẹ́ láti Ejibiti wá ni èyí tí ìwọ ta láti fi ṣe àsíá ọkọ̀ rẹ; aṣọ aláró àti elése àlùkò láti erékùṣù ti Eliṣa ni èyí tí a fi bò ó.
In subțire, cu lucrare brodată din Egipt, era ceea ce tu întindeai pentru a fi pânza ta; albastru și purpură din insulele Elișei era ceea ce te acoperea.
8 Àwọn ará ìlú Sidoni àti Arfadi ni àwọn atukọ̀ rẹ̀ àwọn ọlọ́gbọ́n ẹ̀rọ rẹ, ìwọ Tire, ni àwọn atukọ̀ rẹ.
Locuitorii Sidonului și ai Arvadului erau marinarii tăi; înțelepții tăi Tirule, [care] erau în tine, erau cârmacii tăi.
9 Àwọn àgbàgbà Gebali, àti àwọn ọlọ́gbọ́n ibẹ̀, wà nínú ọkọ̀ bí òṣìṣẹ́ atukọ̀ rẹ, gbogbo ọkọ̀ ojú Òkun àti àwọn atukọ̀ Òkun wá pẹ̀lú rẹ láti dòwò pọ̀ pẹ̀lú rẹ̀.
Bătrânii Ghebalului și [bărbații] lui înțelepți erau în tine reparându-ți [spărturile] tale; toate corăbiile mării cu marinarii lor erau în tine pentru a face schimb cu marfa ta.
10 “‘Àwọn ènìyàn Persia, Ludi àti Puti wà nínú jagunjagun rẹ àwọn ẹgbẹ́ ọmọ-ogun rẹ. Wọ́n gbé asà àti àṣíborí wọn ró sára ògiri rẹ, wọn fi ẹwà rẹ hàn.
Cei din Persia și din Lud și din Put erau în armata ta, bărbații tăi de război; ei își atârnau scutul și coiful în tine; ei îți dădeau frumusețea.
11 Àwọn ènìyàn Arfadi àti Heleki wà lórí odi rẹ yíká; àti àwọn akọni Gamadi, wà nínú ilé ìṣọ́ rẹ. Wọ́n fi àwọn asà wọn kọ ara odi rẹ; wọn ti mú ẹwà rẹ pé.
Bărbații Arvadului cu armata ta [erau] pe zidurile tale de jur împrejur și gamadimii erau în turnurile tale; ei își atârnau scuturile pe zidurile tale de jur împrejur; ei îți desăvârșeau frumusețea.
12 “‘Tarṣiṣi ṣòwò pẹ̀lú rẹ torí ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọrọ̀ tí ó ní; wọn ṣe ìpààrọ̀ fàdákà, irin idẹ àti òjé fún ọjà títà rẹ̀.
Tarsisul [era] comerciantul tău din cauza mulțimii tuturor [felurilor de] bogății; ei au făcut comerț în târgurile tale cu argint, fier, cositor și plumb.
13 “‘Àwọn ará Giriki, Tubali, Jafani àti Meṣeki, ṣòwò pẹ̀lú rẹ, wọ́n fi ẹrù àti ohun èlò idẹ ṣe pàṣípàrọ̀ fún ọrọ̀ rẹ.
Iavanul, Tubalul și Meșecul, ei [erau] comercianții tăi: ei făceau comerț cu sufletele oamenilor și vase de aramă în piața ta.
14 “‘Àwọn ti ilé Beti-Togarma ṣe ìpààrọ̀ ẹṣin-ìṣiṣẹ́, ẹṣin ogun àti ìbáaka ṣòwò ní ọjà rẹ.
Cei din casa Togarmei făceau comerț în târgurile tale cu cai și călăreți și catâri.
15 “‘Àwọn ènìyàn Dedani ni àwọn oníṣòwò rẹ, àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ erékùṣù ni wọ́n jẹ́ oníbàárà rẹ̀; wọ́n mú eyín erin àti igi eboni san owó rẹ.
Bărbații Dedanului [erau] comercianții tăi; multe insule [erau] marfa mâinii tale; ei îți aduceau colți de fildeș și abanos [ca] dar.
16 “‘Aramu ṣòwò pẹ̀lú nítorí ọ̀pọ̀lọpọ̀ iṣẹ́ òwò rẹ̀; wọn ṣe ìpààrọ̀ òkúta iyebíye, òwú elése àlùkò, aṣọ iṣẹ́ ọnà abẹ́rẹ́, aṣọ ọ̀gbọ̀ dáradára, ìlẹ̀kẹ̀ iyùn pupa fún ọjà títà rẹ.
Siria [era] comerciantul tău datorită mulțimii mărfurilor tale; ei făceau schimb în târgurile tale cu smaralde, purpură și lucrare brodată și in subțire și corali și agate.
17 “‘Juda àti Israẹli, àwọn ni oníṣòwò rẹ; wọn ṣe ìpààrọ̀ ọkà, Minniti, àkàrà àdídùn; oyin, epo àti ìkunra olóòórùn dídùn ni wọ́n fi ná ọjà rẹ.
Iuda și țara lui Israel [erau] comercianții tăi; ei făceau comerț în piața ta [cu] grâu de Minit și Panag și miere și untdelemn și balsam.
18 “‘Damasku ni oníṣòwò rẹ, nítorí ọ̀pọ̀lọpọ̀ ohun ọjà tí ó ṣe àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọrọ̀; ní ti ọtí wáìnì tí Helboni, àti irun àgùntàn funfun láti Sahari,
Damascul [era] comerciantul tău datorită mulțimii mărfurilor tale, datorită mulțimii tuturor bogățiilor; în vin din Helbon și lână albă.
19 àti ìdẹ̀ ọtí wáìnì láti Isali, ohun wíwọ̀: irin dídán, kasia àti kálàmù ni àwọn ohun pàṣípàrọ̀ fún ọjà rẹ.
Dan de asemenea și Iavanul mergând încoace și încolo făceau schimb în târgurile tale; fier strălucitor, casie și trestie [mirositoare] erau în piața ta.
20 “‘Dedani ni oníṣòwò rẹ ní aṣọ ìjókòó-lẹ́sin fún ẹṣin-gígùn.
Dedanul [era] comerciantul tău în învelitori prețioase pentru care.
21 “‘Àwọn ará Arabia àti gbogbo àwọn ọmọ-aládé ìlú Kedari àwọn ni àwọn oníbàárà rẹ; ní ti ọ̀dọ́-àgùntàn, àgbò àti ewúrẹ́, nínú ìwọ̀nyí ni wọ́n ti jẹ́ oníbàárà rẹ.
Arabia și toți prinții Chedarului făceau schimb cu tine cu miei și berbeci și capre; cu acestea [erau] comercianții tăi.
22 “‘Àwọn oníṣòwò ti Ṣeba àti Raama, àwọn ni oníṣòwò rẹ; wọ́n ta onírúurú tùràrí olóòórùn dídùn dáradára ní ọjà rẹ, àti àwọn òkúta iyebíye àti wúrà.
Comercianții din Seba și din Raama [erau] comercianții tăi; ei făceau schimb în târgurile tale cu cele mai alese dintre toate mirodeniile și cu toate pietrele prețioase și aur.
23 “‘Harani àti Kanneh àti Edeni, àwọn oníṣòwò Ṣeba, Asiria àti Kilmadi, ni àwọn oníṣòwò rẹ.
Haranul și Canehul și Edenul, comercianții Sebei, ai Așurului [și] ai Chilmadului [erau] comercianții tăi.
24 Wọ̀nyí ní oníbàárà rẹ ní onírúurú nǹkan: aṣọ aláró, àti oníṣẹ́-ọnà àti àpótí aṣọ olówó iyebíye, tí a fi okùn dì, tí a sì fi igi kedari ṣe, nínú àwọn ilé-ìtajà rẹ.
Aceștia [erau] comercianți cu toate felurile [de lucruri], cu veșminte albastre și lucrare brodată și cu lăzi cu haine bogate, legate cu funii și făcute din cedru, printre mărfurile tale.
25 “‘Àwọn ọkọ̀ Tarṣiṣi ní èrò ní ọjà rẹ a ti mú ọ gbilẹ̀ a sì ti ṣe ọ́ lógo ní àárín gbùngbùn Òkun.
Corăbiile Tarsisului cântau despre tine în piața ta; și erai umplut și ai ajuns foarte glorios în mijlocul mărilor.
26 Àwọn atukọ̀ rẹ ti mú ọ wá sínú omi ńlá. Ṣùgbọ́n afẹ́fẹ́ ìlà-oòrùn yóò fọ́ ọ sí wẹ́wẹ́ ní àárín gbùngbùn Òkun.
Vâslașii tăi te-au adus în ape mari; vântul de est te-a frânt în mijlocul mărilor.
27 Ọrọ̀ rẹ, ọjà rẹ àti àwọn ohun títà rẹ, àwọn ìṣúra rẹ, òṣìṣẹ́ ìtukọ̀ rẹ. Àwọn oníbàárà rẹ àti gbogbo àwọn jagunjagun rẹ, tí ó wà nínú rẹ, àti nínú gbogbo ẹgbẹ́ rẹ tí ó wà ní àárín rẹ yóò rì sínú àárín gbùngbùn Òkun ní ọjọ́ ìparun rẹ.
Bogățiile tale și târgurile tale, mărfurile tale, marinarii tăi și cârmacii tăi, reparatorii [spărturilor] tale și cei care făceau schimb cu mărfurile tale și toți bărbații tăi de război, care [sunt] în tine și în toată ceata ta, din mijlocul tău, vor cădea în mijlocul mărilor în ziua ruinării tale.
28 Ilẹ̀ etí Òkun yóò mì nítorí ìró igbe àwọn atukọ̀ rẹ.
Împrejurimile se vor zgudui la sunetul strigătului cârmacilor tăi.
29 Gbogbo àwọn alájẹ̀, àwọn atukọ̀ Òkun àti àwọn atọ́kọ̀ ojú Òkun; yóò sọ̀ kálẹ̀ kúrò nínú ọkọ̀ wọn, wọn yóò dúró lórí ilẹ̀.
Și toți cei ce mânuiesc vâsla, marinarii [și] toți cârmacii mării vor coborî din corăbiile lor [și] vor sta în picioare pe uscat;
30 Wọn yóò jẹ́ kí a gbọ́ ohùn wọn lòdì sí ọ wọn yóò sì sọkún kíkorò lé ọ lórí wọn yóò ku eruku lé orí ara wọn wọn yóò sì yí ara wọn nínú eérú.
Și vor face ca vocea lor să fie auzită împotriva ta și vor striga cu amărăciune și își vor arunca țărână pe capete, se vor tăvăli în cenușă;
31 Wọn yóò fá irun orí wọn nítorí rẹ wọn yóò wọ aṣọ yíya wọn yóò pohùnréré ẹkún pẹ̀lú ìkorò ọkàn nítorí rẹ pẹ̀lú ohùn réré ẹkún kíkorò.
Și se vor cheli în întregime pentru tine și se vor încinge cu pânză de sac și vor plânge pentru tine cu amărăciune a inimii [și] bocet amar.
32 Àti nínú arò wọn ni wọn yóò sì pohùnréré ẹkún fún ọ wọn yóò sì pohùnréré ẹkún sórí rẹ, wí pé: “Ta ni ó dàbí Tire èyí tí ó parun ní àárín Òkun?”
Și în bocetul lor vor înălța o plângere pentru tine și te vor plânge, [spunând]: Care [cetate este] ca Tirul, ca acea distrusă în mijlocul mării?
33 Nígbà tí ọjà títà rẹ ti Òkun jáde wá ìwọ tẹ́ ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀-èdè lọ́rùn ìwọ fi ọrọ̀ tí ó pọ̀ àti àwọn ọjà títà rẹ sọ àwọn ọba ayé di ọlọ́rọ̀.
Când mărfurile tale treceau mările, tu săturai multe popoare; tu ai îmbogățit pe împărații pământului cu abundența bogățiilor tale și a mărfurilor tale.
34 Ní ìsinsin yìí tí Òkun fọ ọ túútúú nínú ibú omi; nítorí náà òwò rẹ àti gbogbo ẹgbẹ́ rẹ ní àárín rẹ, ni yóò ṣubú.
În timpul [când] vei fi frânt de mări în adâncurile apelor, mărfurile tale și toată ceata ta din mijlocul tău, vor cădea.
35 Ẹnu yóò ya gbogbo àwọn ti ń gbé ní erékùṣù náà sí ọ jìnnìjìnnì yóò bo àwọn ọba wọn, ìyọnu yóò sì han ní ojú wọn.
Toți locuitorii insulelor vor fi înmărmuriți din [cauza] ta și împărații lor vor fi foarte înspăimântați, vor fi tulburați în înfățișarea [lor].
36 Àwọn oníṣòwò láàrín àwọn orílẹ̀-èdè dún bí ejò sí ọ ìwọ yóò sì jẹ́ ẹ̀rù ìwọ kì yóò sì ṣí mọ́ láéláé.’”
Comercianții dintre popoare te vor șuiera; vei fi o teroare și nu [vei] mai [fi].

< Ezekiel 27 >