< Ezekiel 27 >

1 Ọ̀rọ̀ Olúwa tún tọ̀ mí wá wí pé:
Et la parole du Seigneur me vint, disant:
2 “Ọmọ ènìyàn, pohùnréré ẹkún fún Tire.
Et toi, fils de l'homme, chante sur Tyr une lamentation.
3 Sọ fún Tire, tí a tẹ̀dó sí ẹnu-bodè Òkun, oníṣòwò àwọn orílẹ̀-èdè fún ọ̀pọ̀lọpọ̀ erékùṣù. ‘Èyí yìí ní Olúwa Olódùmarè wí: “‘Ìwọ Tire wí pé, “Ẹwà mi pé.”
Et dis à cette Tyr, qui réside à l'entrée de la mer, dis à ce marché des peuples venant d'une multitude d'îles: Ainsi parle le Seigneur à Tyr: Tu as dit: C'est de moi-même que je tiens ma beauté.
4 Ààlà rẹ wà ní àárín Òkun; àwọn ọ̀mọ̀lé rẹ ti mú ẹwà rẹ pé.
Au cœur de la mer, tes fils t'ont revêtue de beauté pour te consacrer à Baal.
5 Wọn ṣe gbogbo pákó rẹ ní igi junifa láti Seniri; wọ́n ti mú igi kedari láti Lebanoni wá láti fi ṣe òpó ọkọ̀ fún ọ.
Le cèdre de Sénir a servi à construire tes vaisseaux; tes planches ont été prises en des poutres de cyprès du Liban, et pour faire tes mâts on a employé des sapins.
6 Nínú igi óákù ti Baṣani ní wọn ti fi gbẹ́ ìtukọ̀ ọ̀pá rẹ̀; ìjókòó rẹ ni wọn fi eyín erin ṣe pẹ̀lú igi bokisi láti erékùṣù Kittimu wá.
On a fait tes rames de bois de Basan; on a fait en ivoire tes choses saintes, et tes chambres ombragées d'arbres en bois des Iles de Cétim.
7 Ọ̀gbọ̀ dáradára aṣọ iṣẹ́ ọnà abẹ́rẹ́ láti Ejibiti wá ni èyí tí ìwọ ta láti fi ṣe àsíá ọkọ̀ rẹ; aṣọ aláró àti elése àlùkò láti erékùṣù ti Eliṣa ni èyí tí a fi bò ó.
Le fin lin d'Égypte avec des broderies a formé ta couche; il en a été l'ornement; tu as été vêtue d'hyacinthe et de la pourpre des îles d'Élisa; c'était là ton manteau.
8 Àwọn ará ìlú Sidoni àti Arfadi ni àwọn atukọ̀ rẹ̀ àwọn ọlọ́gbọ́n ẹ̀rọ rẹ, ìwọ Tire, ni àwọn atukọ̀ rẹ.
Et tes princes, ceux qui habitent Sidon, et ceux d'Arad, te servaient de rameurs; et tes sages, ô Tyr, ceux qui résidaient en toi, étaient là tes pilotes.
9 Àwọn àgbàgbà Gebali, àti àwọn ọlọ́gbọ́n ibẹ̀, wà nínú ọkọ̀ bí òṣìṣẹ́ atukọ̀ rẹ, gbogbo ọkọ̀ ojú Òkun àti àwọn atukọ̀ Òkun wá pẹ̀lú rẹ láti dòwò pọ̀ pẹ̀lú rẹ̀.
Les anciens de Biblos et leurs sages, ceux qui étaient en toi, ceux-là fortifiaient ton conseil. Et tous les navires de la mer, et tous leurs rameurs trafiquaient pour toi, jusqu'aux confins de l'Occident.
10 “‘Àwọn ènìyàn Persia, Ludi àti Puti wà nínú jagunjagun rẹ àwọn ẹgbẹ́ ọmọ-ogun rẹ. Wọ́n gbé asà àti àṣíborí wọn ró sára ògiri rẹ, wọn fi ẹwà rẹ hàn.
Les Perses, les Lydiens, les Libyens étaient dans ton armée; tes hommes de guerre avaient suspendu chez toi leurs boucliers et leurs casques, pour servir à ta gloire.
11 Àwọn ènìyàn Arfadi àti Heleki wà lórí odi rẹ yíká; àti àwọn akọni Gamadi, wà nínú ilé ìṣọ́ rẹ. Wọ́n fi àwọn asà wọn kọ ara odi rẹ; wọn ti mú ẹwà rẹ pé.
Les fils d'Arad et ton armée étaient sur tes remparts; ils faisaient bonne garde sur tes tours; ils avaient suspendu leurs carquois autour de tes édifices; c'était l'achèvement de ta beauté.
12 “‘Tarṣiṣi ṣòwò pẹ̀lú rẹ torí ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọrọ̀ tí ó ní; wọn ṣe ìpààrọ̀ fàdákà, irin idẹ àti òjé fún ọjà títà rẹ̀.
Les Carthaginois, par leur trafic, t'apportaient une grande part de tes richesses; ils remplissaient ton marché d'argent, d'or, de fer, d'étain et de plomb.
13 “‘Àwọn ará Giriki, Tubali, Jafani àti Meṣeki, ṣòwò pẹ̀lú rẹ, wọ́n fi ẹrù àti ohun èlò idẹ ṣe pàṣípàrọ̀ fún ọrọ̀ rẹ.
La Grèce tout entière et ses colons entraient chez toi avec des âmes d'hommes, et ils apportaient sur ton marché des vases d'airain.
14 “‘Àwọn ti ilé Beti-Togarma ṣe ìpààrọ̀ ẹṣin-ìṣiṣẹ́, ẹṣin ogun àti ìbáaka ṣòwò ní ọjà rẹ.
Ils t'amenaient des chevaux de Thogarma et des cavaliers.
15 “‘Àwọn ènìyàn Dedani ni àwọn oníṣòwò rẹ, àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ erékùṣù ni wọ́n jẹ́ oníbàárà rẹ̀; wọ́n mú eyín erin àti igi eboni san owó rẹ.
Les fils des Rhodiens trafiquaient avec toi; ils multipliaient sur ton marché ce qui provenait des îles; ils t'apportaient des dents d'éléphants; et à ceux qui entraient chez toi, tu donnais des marchandises en échange:
16 “‘Aramu ṣòwò pẹ̀lú nítorí ọ̀pọ̀lọpọ̀ iṣẹ́ òwò rẹ̀; wọn ṣe ìpààrọ̀ òkúta iyebíye, òwú elése àlùkò, aṣọ iṣẹ́ ọnà abẹ́rẹ́, aṣọ ọ̀gbọ̀ dáradára, ìlẹ̀kẹ̀ iyùn pupa fún ọjà títà rẹ.
Des esclaves pris dans la multitude de ceux que tu avais à vendre, de l'huile de myrrhe et des broderies de Tharsis; Rhamoth et Chorchor approvisionnaient aussi ton marché.
17 “‘Juda àti Israẹli, àwọn ni oníṣòwò rẹ; wọn ṣe ìpààrọ̀ ọkà, Minniti, àkàrà àdídùn; oyin, epo àti ìkunra olóòórùn dídùn ni wọ́n fi ná ọjà rẹ.
Juda et les fils d'Israël trafiquaient avec toi; ils te vendaient du blé, des parfums et de la cannelle; ils t'apportaient le meilleur miel, de l'huile et de la résine pour tes marchands.
18 “‘Damasku ni oníṣòwò rẹ, nítorí ọ̀pọ̀lọpọ̀ ohun ọjà tí ó ṣe àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọrọ̀; ní ti ọtí wáìnì tí Helboni, àti irun àgùntàn funfun láti Sahari,
Damas trafiquait avec toi; ils t'achetaient une part de la multitude de tes marchandises, du vin de Chelbon, des laines de Milet.
19 àti ìdẹ̀ ọtí wáìnì láti Isali, ohun wíwọ̀: irin dídán, kasia àti kálàmù ni àwọn ohun pàṣípàrọ̀ fún ọjà rẹ.
Et ils apportaient du vin sur ton marché. D'Asel venaient chez tes marchands du fer travaillé et des roues.
20 “‘Dedani ni oníṣòwò rẹ ní aṣọ ìjókòó-lẹ́sin fún ẹṣin-gígùn.
Dédan trafiquait avec toi; elle t'amenait des bêtes de somme, choisies pour les chars.
21 “‘Àwọn ará Arabia àti gbogbo àwọn ọmọ-aládé ìlú Kedari àwọn ni àwọn oníbàárà rẹ; ní ti ọ̀dọ́-àgùntàn, àgbò àti ewúrẹ́, nínú ìwọ̀nyí ni wọ́n ti jẹ́ oníbàárà rẹ.
L'Arabie et tous les princes de Cédar trafiquaient avec toi; ils venaient chez toi avec des chameaux, des agneaux et des béliers.
22 “‘Àwọn oníṣòwò ti Ṣeba àti Raama, àwọn ni oníṣòwò rẹ; wọ́n ta onírúurú tùràrí olóòórùn dídùn dáradára ní ọjà rẹ, àti àwọn òkúta iyebíye àti wúrà.
Les marchands de Saba et de Rhamma trafiquaient avec toi; ils apportaient à ton marché les épices les plus recherchées, des pierres précieuses et de l'or.
23 “‘Harani àti Kanneh àti Edeni, àwọn oníṣòwò Ṣeba, Asiria àti Kilmadi, ni àwọn oníṣòwò rẹ.
Charrha et Chanaa trafiquaient avec toi; Assur et Charman trafiquaient avec toi.
24 Wọ̀nyí ní oníbàárà rẹ ní onírúurú nǹkan: aṣọ aláró, àti oníṣẹ́-ọnà àti àpótí aṣọ olówó iyebíye, tí a fi okùn dì, tí a sì fi igi kedari ṣe, nínú àwọn ilé-ìtajà rẹ.
Ils t'apportaient de l'hyacinthe et des ballots de marchandises précieuses, attachés avec des cordes, et des bois de cyprès
25 “‘Àwọn ọkọ̀ Tarṣiṣi ní èrò ní ọjà rẹ a ti mú ọ gbilẹ̀ a sì ti ṣe ọ́ lógo ní àárín gbùngbùn Òkun.
Pour en faire des navires. Ceux qui trafiquaient avec toi se mêlaient à la multitude de tes marchands, et tu étais remplie et pesamment chargée au cœur de la mer.
26 Àwọn atukọ̀ rẹ ti mú ọ wá sínú omi ńlá. Ṣùgbọ́n afẹ́fẹ́ ìlà-oòrùn yóò fọ́ ọ sí wẹ́wẹ́ ní àárín gbùngbùn Òkun.
Tes rameurs t'ont conduite dans les grandes eaux; et le souffle du midi t'a brisée au cœur de la mer.
27 Ọrọ̀ rẹ, ọjà rẹ àti àwọn ohun títà rẹ, àwọn ìṣúra rẹ, òṣìṣẹ́ ìtukọ̀ rẹ. Àwọn oníbàárà rẹ àti gbogbo àwọn jagunjagun rẹ, tí ó wà nínú rẹ, àti nínú gbogbo ẹgbẹ́ rẹ tí ó wà ní àárín rẹ yóò rì sínú àárín gbùngbùn Òkun ní ọjọ́ ìparun rẹ.
Tes richesses, tes trésors, ceux de tes marchands; tes rameurs, tes pilotes, tes conseillers; ces hommes qui trafiquent avec toi, ces guerriers qui sont chez toi, toute la multitude rassemblée en toi, tomberont au cœur de la mer le jour de ta ruine.
28 Ilẹ̀ etí Òkun yóò mì nítorí ìró igbe àwọn atukọ̀ rẹ.
Au cri de ta voix, tes pilotes seront frappés d'épouvante.
29 Gbogbo àwọn alájẹ̀, àwọn atukọ̀ Òkun àti àwọn atọ́kọ̀ ojú Òkun; yóò sọ̀ kálẹ̀ kúrò nínú ọkọ̀ wọn, wọn yóò dúró lórí ilẹ̀.
Tous tes rameurs, tous tes matelots descendront des navires; tous les pilotes de la mer resteront sur le rivage.
30 Wọn yóò jẹ́ kí a gbọ́ ohùn wọn lòdì sí ọ wọn yóò sì sọkún kíkorò lé ọ lórí wọn yóò ku eruku lé orí ara wọn wọn yóò sì yí ara wọn nínú eérú.
Et ils te plaindront à haute voix, et ils crieront amèrement, et ils mettront de la poussière sur leurs têtes, et ils se couvriront de cendre.
31 Wọn yóò fá irun orí wọn nítorí rẹ wọn yóò wọ aṣọ yíya wọn yóò pohùnréré ẹkún pẹ̀lú ìkorò ọkàn nítorí rẹ pẹ̀lú ohùn réré ẹkún kíkorò.
Et leurs fils feront sur toi une lamentation, une complainte sur Tyr, disant:
32 Àti nínú arò wọn ni wọn yóò sì pohùnréré ẹkún fún ọ wọn yóò sì pohùnréré ẹkún sórí rẹ, wí pé: “Ta ni ó dàbí Tire èyí tí ó parun ní àárín Òkun?”
Et leurs fils feront sur toi une lamentation, une complainte sur Tyr, disant:
33 Nígbà tí ọjà títà rẹ ti Òkun jáde wá ìwọ tẹ́ ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀-èdè lọ́rùn ìwọ fi ọrọ̀ tí ó pọ̀ àti àwọn ọjà títà rẹ sọ àwọn ọba ayé di ọlọ́rọ̀.
Quel profit as-tu retiré de la mer? Tu avais rempli de ton abondance toutes les nations; tu avais enrichi par ton trafic tous les rois de la terre.
34 Ní ìsinsin yìí tí Òkun fọ ọ túútúú nínú ibú omi; nítorí náà òwò rẹ àti gbogbo ẹgbẹ́ rẹ ní àárín rẹ, ni yóò ṣubú.
Maintenant tu es brisée dans la mer; tes trafiquants sont au fond de l'abîme, avec toute la multitude assemblée en toi.
35 Ẹnu yóò ya gbogbo àwọn ti ń gbé ní erékùṣù náà sí ọ jìnnìjìnnì yóò bo àwọn ọba wọn, ìyọnu yóò sì han ní ojú wọn.
Tous tes rameurs sont tombés; tous les habitants des îles se sont affligés sur toi; leurs rois ont été saisis de stupeur, et leur visage s'est couvert de larme.
36 Àwọn oníṣòwò láàrín àwọn orílẹ̀-èdè dún bí ejò sí ọ ìwọ yóò sì jẹ́ ẹ̀rù ìwọ kì yóò sì ṣí mọ́ láéláé.’”
Les marchands des nations t'ont sifflée; tu es perdue, et tu ne seras plus dans les siècles.

< Ezekiel 27 >