< Ezekiel 27 >

1 Ọ̀rọ̀ Olúwa tún tọ̀ mí wá wí pé:
La parole de Yahweh me fut adressée en ces termes:
2 “Ọmọ ènìyàn, pohùnréré ẹkún fún Tire.
« Toi, fils de l’homme, prononce sur Tyr une lamentation,
3 Sọ fún Tire, tí a tẹ̀dó sí ẹnu-bodè Òkun, oníṣòwò àwọn orílẹ̀-èdè fún ọ̀pọ̀lọpọ̀ erékùṣù. ‘Èyí yìí ní Olúwa Olódùmarè wí: “‘Ìwọ Tire wí pé, “Ẹwà mi pé.”
et dis à Tyr: O toi qui es assise aux entrées de la mer, qui trafiquais avec les peuples, vers des îles nombreuses, ainsi parle le Seigneur Yahweh: O Tyr, tu as dit: « Je suis parfaite en beauté! »
4 Ààlà rẹ wà ní àárín Òkun; àwọn ọ̀mọ̀lé rẹ ti mú ẹwà rẹ pé.
ton domaine est au sein des mers; ceux qui t’ont bâtie ont rendu parfaite ta beauté.
5 Wọn ṣe gbogbo pákó rẹ ní igi junifa láti Seniri; wọ́n ti mú igi kedari láti Lebanoni wá láti fi ṣe òpó ọkọ̀ fún ọ.
Ils ont construit en cyprès de Sanir toutes tes planches; ils ont pris un cèdre du Liban, pour t’en faire un mât.
6 Nínú igi óákù ti Baṣani ní wọn ti fi gbẹ́ ìtukọ̀ ọ̀pá rẹ̀; ìjókòó rẹ ni wọn fi eyín erin ṣe pẹ̀lú igi bokisi láti erékùṣù Kittimu wá.
De chênes de Basant ils ont fait tes rames; ils ont fait tes bancs d’ivoire incrusté dans du buis provenant des îles de Kittim.
7 Ọ̀gbọ̀ dáradára aṣọ iṣẹ́ ọnà abẹ́rẹ́ láti Ejibiti wá ni èyí tí ìwọ ta láti fi ṣe àsíá ọkọ̀ rẹ; aṣọ aláró àti elése àlùkò láti erékùṣù ti Eliṣa ni èyí tí a fi bò ó.
Le fin lin d’Égypte, avec ses broderies, formait tes voiles, il te servait de pavillon; l’hyacinthe et l’écarlate des îles d’Elisa formaient tes tentures.
8 Àwọn ará ìlú Sidoni àti Arfadi ni àwọn atukọ̀ rẹ̀ àwọn ọlọ́gbọ́n ẹ̀rọ rẹ, ìwọ Tire, ni àwọn atukọ̀ rẹ.
Les habitants de Sidon et d’Arvad te servaient de rameurs; tes sages qui étaient chez toi, ô Tyr, étaient tes pilotes.
9 Àwọn àgbàgbà Gebali, àti àwọn ọlọ́gbọ́n ibẹ̀, wà nínú ọkọ̀ bí òṣìṣẹ́ atukọ̀ rẹ, gbogbo ọkọ̀ ojú Òkun àti àwọn atukọ̀ Òkun wá pẹ̀lú rẹ láti dòwò pọ̀ pẹ̀lú rẹ̀.
Les anciens de Giblium et ses sages étaient chez toi, réparant tes fissures. Tous les vaisseaux de la mer et leurs marins étaient chez toi, pour échanger tes marchandises.
10 “‘Àwọn ènìyàn Persia, Ludi àti Puti wà nínú jagunjagun rẹ àwọn ẹgbẹ́ ọmọ-ogun rẹ. Wọ́n gbé asà àti àṣíborí wọn ró sára ògiri rẹ, wọn fi ẹwà rẹ hàn.
Perses, Lydiens et Lybiens étaient dans ton armée, c’étaient tes hommes de guerre; ils suspendaient chez toi le casque et le bouclier, et te donnaient de la splendeur.
11 Àwọn ènìyàn Arfadi àti Heleki wà lórí odi rẹ yíká; àti àwọn akọni Gamadi, wà nínú ilé ìṣọ́ rẹ. Wọ́n fi àwọn asà wọn kọ ara odi rẹ; wọn ti mú ẹwà rẹ pé.
Les fils d’Arvad et ton armée étaient sur tes murailles tout autour, et des hommes vaillants étaient sur tes forteresses; ils suspendaient leurs boucliers à tes murs tout autour; ils te rendaient parfaite en beauté.
12 “‘Tarṣiṣi ṣòwò pẹ̀lú rẹ torí ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọrọ̀ tí ó ní; wọn ṣe ìpààrọ̀ fàdákà, irin idẹ àti òjé fún ọjà títà rẹ̀.
Tharsis trafiquait avec toi pour ses richesses de toutes sortes, argent, fer, étain et plomb, dont elle payait tes marchandises.
13 “‘Àwọn ará Giriki, Tubali, Jafani àti Meṣeki, ṣòwò pẹ̀lú rẹ, wọ́n fi ẹrù àti ohun èlò idẹ ṣe pàṣípàrọ̀ fún ọrọ̀ rẹ.
Javan, Tubal et Mosoch faisaient commerce avec toi; avec des âmes d’hommes et des vases de cuivre, ils soldaient tes créances.
14 “‘Àwọn ti ilé Beti-Togarma ṣe ìpààrọ̀ ẹṣin-ìṣiṣẹ́, ẹṣin ogun àti ìbáaka ṣòwò ní ọjà rẹ.
Ceux de la maison de Thogorma, avec des chevaux de trait, des chevaux de course et des mulets, payaient tes marchandises.
15 “‘Àwọn ènìyàn Dedani ni àwọn oníṣòwò rẹ, àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ erékùṣù ni wọ́n jẹ́ oníbàárà rẹ̀; wọ́n mú eyín erin àti igi eboni san owó rẹ.
Les fils de Dédan faisaient commerce avec toi; le trafic d’îles nombreuses était dans ta main; elles te donnaient en paiement des cornes d’ivoires et de l’ébène.
16 “‘Aramu ṣòwò pẹ̀lú nítorí ọ̀pọ̀lọpọ̀ iṣẹ́ òwò rẹ̀; wọn ṣe ìpààrọ̀ òkúta iyebíye, òwú elése àlùkò, aṣọ iṣẹ́ ọnà abẹ́rẹ́, aṣọ ọ̀gbọ̀ dáradára, ìlẹ̀kẹ̀ iyùn pupa fún ọjà títà rẹ.
Aram trafiquait avec toi, pour la multitude de tes produits; avec des escarboucles, de la pourpre, des broderies, du fin lin, du corail et des rubis, il soldait tes créances.
17 “‘Juda àti Israẹli, àwọn ni oníṣòwò rẹ; wọn ṣe ìpààrọ̀ ọkà, Minniti, àkàrà àdídùn; oyin, epo àti ìkunra olóòórùn dídùn ni wọ́n fi ná ọjà rẹ.
Juda et le pays d’Israël faisaient commerce avec toi, pour le froment de Minnith, les parfums, le miel, l’huile et le baume.
18 “‘Damasku ni oníṣòwò rẹ, nítorí ọ̀pọ̀lọpọ̀ ohun ọjà tí ó ṣe àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọrọ̀; ní ti ọtí wáìnì tí Helboni, àti irun àgùntàn funfun láti Sahari,
Damas trafiquait avec toi, pour la multitude de tes produits, pour la multitude de tes biens, qu’elle échangeait avec du vin de Helbon et de la laine de Tsachar.
19 àti ìdẹ̀ ọtí wáìnì láti Isali, ohun wíwọ̀: irin dídán, kasia àti kálàmù ni àwọn ohun pàṣípàrọ̀ fún ọjà rẹ.
Védan et Javan de Ouzzal, avec du fer fabriqué, payaient tes marchandises; la casse et le roseau odorant soldaient ta créance.
20 “‘Dedani ni oníṣòwò rẹ ní aṣọ ìjókòó-lẹ́sin fún ẹṣin-gígùn.
Dédan faisait commerce avec toi, pour des housses servant à monter à cheval.
21 “‘Àwọn ará Arabia àti gbogbo àwọn ọmọ-aládé ìlú Kedari àwọn ni àwọn oníbàárà rẹ; ní ti ọ̀dọ́-àgùntàn, àgbò àti ewúrẹ́, nínú ìwọ̀nyí ni wọ́n ti jẹ́ oníbàárà rẹ.
L’Arabie et tous les princes de Cédar trafiquaient avec toi; pour des moutons, des béliers et des boucs, ils trafiquaient avec toi.
22 “‘Àwọn oníṣòwò ti Ṣeba àti Raama, àwọn ni oníṣòwò rẹ; wọ́n ta onírúurú tùràrí olóòórùn dídùn dáradára ní ọjà rẹ, àti àwọn òkúta iyebíye àti wúrà.
Les commerçants de Saba et de Rééma faisaient commerce avec toi; avec tous les meilleurs aromates, avec toute espèce de pierres précieuses et avec de l’or ils payaient tes marchandises.
23 “‘Harani àti Kanneh àti Edeni, àwọn oníṣòwò Ṣeba, Asiria àti Kilmadi, ni àwọn oníṣòwò rẹ.
Haran, Chéné et Eden, les commerçants de Saba, Assur et Chelmad faisaient commerce avec toi;
24 Wọ̀nyí ní oníbàárà rẹ ní onírúurú nǹkan: aṣọ aláró, àti oníṣẹ́-ọnà àti àpótí aṣọ olówó iyebíye, tí a fi okùn dì, tí a sì fi igi kedari ṣe, nínú àwọn ilé-ìtajà rẹ.
ils faisaient avec toi commerce d’objets de luxe; manteaux de pourpre violette et de brocart, coffres à vêtements, cordes tressées et fortes, planches de cèdre pour tes expéditions.
25 “‘Àwọn ọkọ̀ Tarṣiṣi ní èrò ní ọjà rẹ a ti mú ọ gbilẹ̀ a sì ti ṣe ọ́ lógo ní àárín gbùngbùn Òkun.
Les vaisseaux de Tharsis étaient tes caravanes, pour transporter tes marchandises. Tu es devenue tout à fait opulente et glorieuse, au sein des mers.
26 Àwọn atukọ̀ rẹ ti mú ọ wá sínú omi ńlá. Ṣùgbọ́n afẹ́fẹ́ ìlà-oòrùn yóò fọ́ ọ sí wẹ́wẹ́ ní àárín gbùngbùn Òkun.
Mais sur les grandes eaux où te conduisaient ceux qui maniaient tes rames, le vent d’Orient t’a brisée, au sein des mers.
27 Ọrọ̀ rẹ, ọjà rẹ àti àwọn ohun títà rẹ, àwọn ìṣúra rẹ, òṣìṣẹ́ ìtukọ̀ rẹ. Àwọn oníbàárà rẹ àti gbogbo àwọn jagunjagun rẹ, tí ó wà nínú rẹ, àti nínú gbogbo ẹgbẹ́ rẹ tí ó wà ní àárín rẹ yóò rì sínú àárín gbùngbùn Òkun ní ọjọ́ ìparun rẹ.
Tes richesses, ton trafic, tes marchandises, tes marins et tes pilotes, tes radoubeurs, les courtiers de ton commerce, tous tes hommes de guerre, qui sont chez toi, avec toute la multitude qui est au milieu de toi, tomberont au sein des mers, au jour de ta chute.
28 Ilẹ̀ etí Òkun yóò mì nítorí ìró igbe àwọn atukọ̀ rẹ.
Au bruit des cris de tes pilotes, les plages trembleront;
29 Gbogbo àwọn alájẹ̀, àwọn atukọ̀ Òkun àti àwọn atọ́kọ̀ ojú Òkun; yóò sọ̀ kálẹ̀ kúrò nínú ọkọ̀ wọn, wọn yóò dúró lórí ilẹ̀.
Et ils descendront de leurs navires, tous ceux qui manient une rame, les marins, tous les pilotes de la mer, et ils se tiendront sur terre.
30 Wọn yóò jẹ́ kí a gbọ́ ohùn wọn lòdì sí ọ wọn yóò sì sọkún kíkorò lé ọ lórí wọn yóò ku eruku lé orí ara wọn wọn yóò sì yí ara wọn nínú eérú.
Ils élèveront la voix sur toi, et pousseront des cris amers; ils jetteront de la poussière sur leurs têtes, et se rouleront dans la cendre.
31 Wọn yóò fá irun orí wọn nítorí rẹ wọn yóò wọ aṣọ yíya wọn yóò pohùnréré ẹkún pẹ̀lú ìkorò ọkàn nítorí rẹ pẹ̀lú ohùn réré ẹkún kíkorò.
Pour toi ils se raseront la tête, ils se revêtiront de sacs, et, dans l’amertume de leur âme, ils verseront sur toi des larmes, des pleurs amers.
32 Àti nínú arò wọn ni wọn yóò sì pohùnréré ẹkún fún ọ wọn yóò sì pohùnréré ẹkún sórí rẹ, wí pé: “Ta ni ó dàbí Tire èyí tí ó parun ní àárín Òkun?”
Dans leur douleur, ils prononceront sur toi une lamentation, ils se lamenteront sur toi, en disant: Qui est comme Tyr, comme celle qui est devenue muette, au milieu de la mer?
33 Nígbà tí ọjà títà rẹ ti Òkun jáde wá ìwọ tẹ́ ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀-èdè lọ́rùn ìwọ fi ọrọ̀ tí ó pọ̀ àti àwọn ọjà títà rẹ sọ àwọn ọba ayé di ọlọ́rọ̀.
Quand tes marchandises sortaient des mers, tu rassasiais des peuples nombreux; par l’abondance de tes richesses et de ton trafic, tu enrichissais les rois de la terre.
34 Ní ìsinsin yìí tí Òkun fọ ọ túútúú nínú ibú omi; nítorí náà òwò rẹ àti gbogbo ẹgbẹ́ rẹ ní àárín rẹ, ni yóò ṣubú.
Maintenant que tu as été brisée par les mers, et jetée au fond des eaux, tes marchandises et toute ta multitude ont sombré avec toi.
35 Ẹnu yóò ya gbogbo àwọn ti ń gbé ní erékùṣù náà sí ọ jìnnìjìnnì yóò bo àwọn ọba wọn, ìyọnu yóò sì han ní ojú wọn.
Tous les habitants des îles sont dans la stupeur à cause de toi; leurs rois sont saisis d’épouvante, leurs visages sont bouleversés.
36 Àwọn oníṣòwò láàrín àwọn orílẹ̀-èdè dún bí ejò sí ọ ìwọ yóò sì jẹ́ ẹ̀rù ìwọ kì yóò sì ṣí mọ́ láéláé.’”
Les commerçants des peuples sifflent sur toi; tu es devenue un sujet d’effroi; et pour jamais tu n’es plus! »

< Ezekiel 27 >