< Ezekiel 26 >

1 Ní ọjọ́ kìn-ín-ní, oṣù kọ́kànlá, ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé:
On birinchi yili, ayning birinchi künide shundaq boldiki, Perwerdigarning sözi manga kélip mundaq déyildi: —
2 “Ọmọ ènìyàn, nítorí pé Tire sọ nípa Jerusalẹmu pé, ‘Háà! A fọ́ èyí tí í ṣe bodè àwọn orílẹ̀-èdè, a yí i padà sí mi, èmi yóò di kíkún, òun yóò sì di ahoro,’
I insan oghli, Turning Yérusalém toghruluq: «Wah! Yaxshi boldi! Ellerning derwazisi bolghuchi weyran boldi! U manga qarap qayrilip échildi; uning weyran qilinishi bilen özümni toyghuzimen!» dégini tüpeylidin,
3 nítorí náà, báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí, kíyèsi i, èmí dojúkọ ọ́ ìwọ tire, Èmi yóò sì jẹ́ kí Orílẹ̀-èdè púpọ̀ dìde sí ọ, gẹ́gẹ́ bí Òkun tí ru sókè.
— Shunga Reb Perwerdigar mundaq deydu: — Mana, i Tur, Men sanga qarshimen, déngiz dolqunlarni qozghighandek, köp ellerni sen bilen qarshilishqa qozghaymen;
4 Wọn yóò wó odi tire lulẹ̀, wọn yóò sì wo ilé ìṣọ́ rẹ̀ lulẹ̀, Èmi yóò sì ha erùpẹ̀ rẹ̀ kúrò, Èmi yóò sì sọ ọ́ di orí àpáta.
ular Turning sépillirini berbat qilip, uning munarlirini chéqip yoqitidu. Uning üstidiki topilirini qirip tashlap, uni taqir tash qilip qoyimen.
5 Yóò sì jẹ́ ibi nína àwọ̀n tí wọn fi ń pẹja sí láàrín Òkun, ní Olúwa Olódùmarè wí. Yóò di ìkógun fún àwọn orílẹ̀-èdè.
U peqet déngiz otturisidiki torlar yéyilidighan jay bolidu; chünki Men shundaq söz qildim, deydu Reb Perwerdigar; u eller üchün olja bolup qalidu.
6 Ìlú tí ó tẹ̀dó sí, ní àárín gbùngbùn ilẹ̀ rẹ̀ ni a ó fi idà sọ ọ́ di ahoro. Nígbà náà ní wọn yóò mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.
Uning quruqluqta qalghan qizliri qilich bilen qirilidu; shuning bilen ular Méning Perwerdigar ikenlikimni tonup yétidu.
7 “Nítorí báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí: Kíyèsi i, láti ìhà àríwá ni èmi yóò ti mú Nebukadnessari ọba Babeli, ọba àwọn ọba, dìde sí Tire pẹ̀lú ẹṣin àti kẹ̀kẹ́ ogun pẹ̀lú àwọn ẹlẹ́ṣin àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn ológun.
— Chünki Reb Perwerdigar mundaq deydu: — Mana, Men Tur bilen qarshilishishqa Babil padishahi Néboqadnesar, yeni «padishahlarning padishahi»ni, atlar, jeng harwiliri bilen, atliq chewendazlar, qoshun we zor bir top ademler bilen shimal teripidin chiqirip épkélimen.
8 Yóò sì fi idà sá àwọn ọmọbìnrin rẹ ní oko, yóò sì kọ́ odi tì ọ́, yóò sì mọ òkìtì tì ọ́, yóò sì gbé àpáta sókè sí ọ.
U quruqluqta qalghan qizlirini qilich bilen soyidu, sanga muhasire poteylirini quridu, sépilgha chiqidighan dönglükni yasaydu, sanga qarap qalqanlirini kötüridu.
9 Yóò sì gbé ẹ̀rọ ogun tí odi rẹ, yóò sì fi ohun èlò ogun wó ilé ìṣọ́ rẹ palẹ̀.
U sépilliringgha bösküchi bazghanlarni qaritip tikleydu, qoral-paltiliri bilen munarliringni chéqip ghulitidu.
10 Àwọn ẹṣin rẹ̀ yóò pọ̀ dé bí pé wọn yóò fi eruku bò ọ́ mọ́lẹ̀. Àwọn ògiri rẹ yóò mì tìtì fún igbe àwọn ẹṣin ogun kẹ̀kẹ́ ẹrù àti kẹ̀kẹ́ ogun nígbà tí ó bá wọ ẹnu-ọ̀nà odi gẹ́gẹ́ bí ènìyàn tí ń wọ ìlú láti inú àwọn ògiri rẹ̀ ti ó di fífọ́ pátápátá.
Uning atlirining köplükidin ularning kötürgen chang-topisi séni qaplaydu; sépilliri bösülgen bir sheherge bösüp kirgendek u séning qowuqliringdin kirgende, sépilliring atliq eskerlerning, chaqlarning hem jeng harwilirining sadasi bilen tewrinip kétidu.
11 Pátákò ẹsẹ̀ ẹṣin rẹ̀ ni yóò fi tẹ gbogbo òpópónà rẹ mọ́lẹ̀; yóò fi idà pa àwọn ènìyàn rẹ, àwọn ọ̀wọ́n rẹ ti o lágbára yóò wó palẹ̀.
Atlirining tuyaqliri bilen u barliq reste-kochiliringni cheyleydu; u puqraliringni qilich bilen qiridu, küchlük tüwrükliring yerge yiqilidu.
12 Wọn yóò kó ọrọ̀ rẹ, wọn yóò sì fi òwò rẹ ṣe ìjẹ ogun; wọn yóò sì wó odi rẹ lulẹ̀, wọn yóò sì ba àwọn ilé rẹ dídára jẹ́, wọn yóò sì kó àwọn òkúta rẹ̀, àti igi ìtì ìkọ́lé rẹ̀, àti erùpẹ̀ rẹ̀, dà sí inú Òkun.
Ular bayliqliringni olja, mal-tawarliringni ghenimet qilidu; ular sépilliringni buzup ghulitip, heshemetlik öyliringni xarabe qilidu; ular séning tashliring, yaghach-limliring we topa-changliringni déngiz suliri ichige tashlaydu.
13 Èmi yóò sì mú ariwo orin rẹ̀ dákẹ́ àti ìró dùùrù orin rẹ̀ ni a kì yóò gbọ́ mọ́.
Men naxshliringning sadasini tügitimen; chiltarliringning awazi qaytidin anglanmaydu.
14 Èmi yóò sọ ọ di àpáta lásán, ìwọ yóò sì di ibi tí a ń sá àwọ̀n ẹja sí. A kì yóò sì tún ọ mọ nítorí Èmi Olúwa ti sọ ọ̀rọ̀ ní Olúwa Olódùmarè wí.
Men séni taqir tash qilimen; sen torlar yéyilidighan bir jay bolisen, xalas; sen qaytidin qurulmaysen; chünki Menki Perwerdigar shundaq dégenmen, deydu Reb Perwerdigar.
15 “Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí sí Tire: Ǹjẹ́ àwọn erékùṣù kì yóò ha wárìrì nípa ìṣubú rẹ, nígbà tí ìkórìíra ìpalára àti rírẹ́ni lọ́run bá ń ṣẹlẹ̀ ní inú rẹ?
Reb Perwerdigar Turgha mundaq deydu: — Sen ghulap ketkiningde, yarilan’ghanlar ah-zarlighinida, otturungda qirghin-chapqun qilin’ghanda, déngizning chet yaqiliri tewrinip ketmemdu?
16 Nígbà náà ni gbogbo àwọn ọmọ-aládé etí Òkun yóò sọ̀kalẹ̀ láti orí ìtẹ́ wọn, wọn yóò sì pa àwọn aṣọ ìgúnwà wọn da, tì wọn yóò sì bọ́ àwọn aṣọ iṣẹ́ ọnà abẹ́rẹ́ kúrò. Ẹ̀rù yóò bò wọ́n, wọn yóò sì jókòó lórí ilẹ̀ pẹ̀pẹ̀, wọn yóò sì máa wárìrì ní gbogbo ìgbà, ẹnu yóò sì yà wọ́n sí ọ́.
Déngizdiki shahzadiler textliridin chüshüp, tonlirini biryaqqa tashlap, keshtilik kiyim-kécheklirini séliwétidu; ular özlirini qorqunch-titrek bilen pürkeydu; ular yerge olturup, héch toxtawsiz titrep, sanga qarap sarasimige chüshidu.
17 Nígbà náà wọn yóò gbóhùn ẹkún sókè nítorí rẹ, wọn yóò sì wí fún ọ pé: “‘Báwo ni a ṣe pa ọ́ run, ìwọ ìlú olókìkí ìwọ tí àwọn èrò okun ti gbé inú rẹ̀! Ìwọ jẹ alágbára lórí okun gbogbo òun àti àwọn olùgbé inú rẹ̀; ìwọ gbé ẹ̀rù rẹ lórí gbogbo olùgbé ibẹ̀.
Ular sen üchün bir mersiyeni oqup sanga mundaq deydu: — «I ahaleng déngizdikilerdin bolghan, dangqi chiqqan, Déngiz üstidin küchlük höküm sürgen, Öz wehshetliringni barliq déngizda turuwatqanlargha salghan sheher! Sen we senda turuwatqanlar neqeder halak bolghan!
18 Nísinsin yìí erékùṣù wárìrì ní ọjọ́ ìṣubú rẹ; erékùṣù tí ó wà nínú Òkun ni ẹ̀rù bà torí ìṣubú rẹ.’
Hazir séning ghulap ketken kününgde, Déngiz boyidikiler titrep kétidu; Déngizdiki arallar we qirghaqtikiler séning yoq bolup ketkiningdin dekke-dükkige chüshüp qaldi».
19 “Èyí yìí ní Olúwa Olódùmarè wí: Nígbà tí mo bá sọ ọ́ di ìlú ahoro, gẹ́gẹ́ bi àwọn ìlú tí a kò gbé inú wọn mọ́, àti nígbà tí èmi yóò mú ibú agbami Òkun wá sí orí rẹ, omi ńlá yóò sì bò ọ́,
— Chünki Reb Perwerdigar mundaq deydu: — «Men séni ademzatsiz sheherlerdek, xarabe sheher qilghinimda, Men üstüngge déngiz chongqurluqlirini chiqirip séni chökürginimde, Ulugh sular séni bésip yapqanda,
20 nígbà tí èmi yóò mú ọ wálẹ̀ pẹ̀lú àwọn tí ó sọ̀kalẹ̀ lọ sínú ihò, pẹ̀lú àwọn ènìyàn àtijọ́. Èmi yóò sì gbé ọ lọ si bi ìsàlẹ̀, ní ibi ahoro àtijọ́, pẹ̀lú àwọn tí ó sọ̀kalẹ̀ lọ sínú ihò, ìwọ kì yóò sì padà gbé inú rẹ̀ mọ́, èmi yóò sì gbé ògo kalẹ̀ ní ilẹ̀ àwọn alààyè.
Shu tapta Men séni hanggha chüshkenler bilen bille chüshürimen, Qedimki zamandikilerning qatarigha chüshürimen; Séni yerning tégiliride turghuzimen; Séningde qaytidin ademzat bolmasliqi üchün, Séni qedimki xarabiler arisigha, Hanggha chüshkenler bilen bille bolushqa chüshürimen; Biraq tiriklerning zéminida bolsa güzellik tiklep qoyimen;
21 Èmi yóò ṣe ọ ní ẹ̀rù, ìwọ kì yóò sì ṣí mọ́. Bí a tilẹ̀ wá ọ, síbẹ̀ a kì yóò tún rí ọ mọ́, ní Olúwa Olódùmarè wí.”
Men séni bashqilargha bir agahi-wehshet qilimen; Sen qaytidin héch bolmaysen; Ular séni izdeydu, biraq sen menggüge tépilmaysen» — deydu Reb Perwerdigar.

< Ezekiel 26 >