< Ezekiel 26 >

1 Ní ọjọ́ kìn-ín-ní, oṣù kọ́kànlá, ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé:
I stało się roku jedenastego, pierwszego dnia miesiąca, stało się słowo Pańskie do mnie, mówiąc:
2 “Ọmọ ènìyàn, nítorí pé Tire sọ nípa Jerusalẹmu pé, ‘Háà! A fọ́ èyí tí í ṣe bodè àwọn orílẹ̀-èdè, a yí i padà sí mi, èmi yóò di kíkún, òun yóò sì di ahoro,’
Synu człowieczy! przeto, iż Tyr mówił o Jeruzalemie wykrzykając: Hej, hej! zniszczone jest miasto bram bardzo ludnych, obraca się do mnie, teraz napełniony będę, gdyż to jest spustoszone;
3 nítorí náà, báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí, kíyèsi i, èmí dojúkọ ọ́ ìwọ tire, Èmi yóò sì jẹ́ kí Orílẹ̀-èdè púpọ̀ dìde sí ọ, gẹ́gẹ́ bí Òkun tí ru sókè.
Dlatego tak mówi panujący Pan: Otom Ja powstał przeciwko tobie, o Tyrze! a przywiodę na cię wiele narodów, jakobym przywiódł morze z nawałnościami jego;
4 Wọn yóò wó odi tire lulẹ̀, wọn yóò sì wo ilé ìṣọ́ rẹ̀ lulẹ̀, Èmi yóò sì ha erùpẹ̀ rẹ̀ kúrò, Èmi yóò sì sọ ọ́ di orí àpáta.
I zburzą mury Tyrskie, i rozwalą wieże jego; i wymiotę z niego proch jego, i uczynię go wierzchołkiem skały gładkiej,
5 Yóò sì jẹ́ ibi nína àwọ̀n tí wọn fi ń pẹja sí láàrín Òkun, ní Olúwa Olódùmarè wí. Yóò di ìkógun fún àwọn orílẹ̀-èdè.
Tak, że będą wysuszać sieci w pośród morza; bom Ja rzekł, mówi panujący Pan, przeto będzie na rozchwycenie narodom.
6 Ìlú tí ó tẹ̀dó sí, ní àárín gbùngbùn ilẹ̀ rẹ̀ ni a ó fi idà sọ ọ́ di ahoro. Nígbà náà ní wọn yóò mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.
A córki jego, które będą na polu, mieczem pobite będą, a dowiedzą się, żem Ja Pan.
7 “Nítorí báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí: Kíyèsi i, láti ìhà àríwá ni èmi yóò ti mú Nebukadnessari ọba Babeli, ọba àwọn ọba, dìde sí Tire pẹ̀lú ẹṣin àti kẹ̀kẹ́ ogun pẹ̀lú àwọn ẹlẹ́ṣin àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn ológun.
Bo tak mówi panujący Pan: Oto Ja przywiodę przeciwko Tyrowi Nabuchodonozora, króla Babilońskiego, od północy, króla nad królmi, z końmi i z wozami, i z jezdnymi i z zgrają, i z ludem wielkim.
8 Yóò sì fi idà sá àwọn ọmọbìnrin rẹ ní oko, yóò sì kọ́ odi tì ọ́, yóò sì mọ òkìtì tì ọ́, yóò sì gbé àpáta sókè sí ọ.
Córki twoje na polu mieczem pomorduje, i przeciwko tobie porobi baszty, i usypie wał przeciwko tobie, i postawi przeciwko tobie tarcz;
9 Yóò sì gbé ẹ̀rọ ogun tí odi rẹ, yóò sì fi ohun èlò ogun wó ilé ìṣọ́ rẹ palẹ̀.
I tarany zasadzi przeciwko murom twoim, a wieże twoje potłucze młotami swemi.
10 Àwọn ẹṣin rẹ̀ yóò pọ̀ dé bí pé wọn yóò fi eruku bò ọ́ mọ́lẹ̀. Àwọn ògiri rẹ yóò mì tìtì fún igbe àwọn ẹṣin ogun kẹ̀kẹ́ ẹrù àti kẹ̀kẹ́ ogun nígbà tí ó bá wọ ẹnu-ọ̀nà odi gẹ́gẹ́ bí ènìyàn tí ń wọ ìlú láti inú àwọn ògiri rẹ̀ ti ó di fífọ́ pátápátá.
Od mnóstwa koni jego okryje cię proch ich; od grzmotu jezdnych i kar i wozów poruszą się mury twoje, gdy wchodzić będzie w bramy twoje, jako wchodzą do miasta zburzonego.
11 Pátákò ẹsẹ̀ ẹṣin rẹ̀ ni yóò fi tẹ gbogbo òpópónà rẹ mọ́lẹ̀; yóò fi idà pa àwọn ènìyàn rẹ, àwọn ọ̀wọ́n rẹ ti o lágbára yóò wó palẹ̀.
Kopytami koni swoich zdepcze wszystkie ulice twoje, lud twój mieczem pobije, a mocne słupy twoje upadną na ziemię;
12 Wọn yóò kó ọrọ̀ rẹ, wọn yóò sì fi òwò rẹ ṣe ìjẹ ogun; wọn yóò sì wó odi rẹ lulẹ̀, wọn yóò sì ba àwọn ilé rẹ dídára jẹ́, wọn yóò sì kó àwọn òkúta rẹ̀, àti igi ìtì ìkọ́lé rẹ̀, àti erùpẹ̀ rẹ̀, dà sí inú Òkun.
I robiorą majętność twoję, a rozchwycą towary twoje, i rozwalą mury twoje, i domy twoje rozkoszne poburzą, a kamienie twoje, i drzewo twoje, i proch twój do wody wrzucą.
13 Èmi yóò sì mú ariwo orin rẹ̀ dákẹ́ àti ìró dùùrù orin rẹ̀ ni a kì yóò gbọ́ mọ́.
I uczynię. że ustanie głos pieśni twoich, a dźwięk harf twoich nie będzie więcej słyszany.
14 Èmi yóò sọ ọ di àpáta lásán, ìwọ yóò sì di ibi tí a ń sá àwọ̀n ẹja sí. A kì yóò sì tún ọ mọ nítorí Èmi Olúwa ti sọ ọ̀rọ̀ ní Olúwa Olódùmarè wí.
I uczynię cię wierzchołkiem gładkiej skały; staniesz się miejscem ku wysuszaniu sieci, nie będziesz więcj zbudowany; bom Ja Pan powiedział, mówi panujący Pan.
15 “Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí sí Tire: Ǹjẹ́ àwọn erékùṣù kì yóò ha wárìrì nípa ìṣubú rẹ, nígbà tí ìkórìíra ìpalára àti rírẹ́ni lọ́run bá ń ṣẹlẹ̀ ní inú rẹ?
Tak mówi panujący Pan do Tyru: Izali się od trzasku upadku twego, gdy ranni wołać będą, gdy okrutne morderstwo będzie w pośrodku ciebie, wyspy się nie poruszą?
16 Nígbà náà ni gbogbo àwọn ọmọ-aládé etí Òkun yóò sọ̀kalẹ̀ láti orí ìtẹ́ wọn, wọn yóò sì pa àwọn aṣọ ìgúnwà wọn da, tì wọn yóò sì bọ́ àwọn aṣọ iṣẹ́ ọnà abẹ́rẹ́ kúrò. Ẹ̀rù yóò bò wọ́n, wọn yóò sì jókòó lórí ilẹ̀ pẹ̀pẹ̀, wọn yóò sì máa wárìrì ní gbogbo ìgbà, ẹnu yóò sì yà wọ́n sí ọ́.
I powstaną z stolic swoich wszyscy książęta pomorscy, i złożą z siebie płaszcze swoje, a szaty swe haftowane zewleką, strachem będą przyodziani, na ziemi usiądą, a wzdrygając się co chwila zdumiewać się będą nad tobą,
17 Nígbà náà wọn yóò gbóhùn ẹkún sókè nítorí rẹ, wọn yóò sì wí fún ọ pé: “‘Báwo ni a ṣe pa ọ́ run, ìwọ ìlú olókìkí ìwọ tí àwọn èrò okun ti gbé inú rẹ̀! Ìwọ jẹ alágbára lórí okun gbogbo òun àti àwọn olùgbé inú rẹ̀; ìwọ gbé ẹ̀rù rẹ lórí gbogbo olùgbé ibẹ̀.
I podniosą nad tobą lament i rzekną do ciebie: Jakoś zginęło, o miasto! w którem mieszkano dla przyległości morza, miasto sławne, które było mocne na morzu, ono i z obywatelami swymi, którzy byli straszni wszystkim obywatelom jego.
18 Nísinsin yìí erékùṣù wárìrì ní ọjọ́ ìṣubú rẹ; erékùṣù tí ó wà nínú Òkun ni ẹ̀rù bà torí ìṣubú rẹ.’
Tedy się zatrwożą wyspy w dzień upadku twego; zatrwożą się mówię wyspy morskie nad zginieniem twojem.
19 “Èyí yìí ní Olúwa Olódùmarè wí: Nígbà tí mo bá sọ ọ́ di ìlú ahoro, gẹ́gẹ́ bi àwọn ìlú tí a kò gbé inú wọn mọ́, àti nígbà tí èmi yóò mú ibú agbami Òkun wá sí orí rẹ, omi ńlá yóò sì bò ọ́,
Bo tak mówi panujący Pan: Gdy cię uczynię miastem spustoszonem, jako miasta, w których nie mieszkają, gdy na cię przepaść przywiodę, tak, że cię wody wielkie przykryją;
20 nígbà tí èmi yóò mú ọ wálẹ̀ pẹ̀lú àwọn tí ó sọ̀kalẹ̀ lọ sínú ihò, pẹ̀lú àwọn ènìyàn àtijọ́. Èmi yóò sì gbé ọ lọ si bi ìsàlẹ̀, ní ibi ahoro àtijọ́, pẹ̀lú àwọn tí ó sọ̀kalẹ̀ lọ sínú ihò, ìwọ kì yóò sì padà gbé inú rẹ̀ mọ́, èmi yóò sì gbé ògo kalẹ̀ ní ilẹ̀ àwọn alààyè.
Gdy uczynię, że zstąpisz z tymi, którzy zstępują do dołu, do ludu dawnego, a położę cię w najniższych stronach ziemi, na pustyniach dawnych, z tymi, co zstępują do dołu, aby nie mieszkano w tobie, tedy dokażę sławy w ziemi żyjących.
21 Èmi yóò ṣe ọ ní ẹ̀rù, ìwọ kì yóò sì ṣí mọ́. Bí a tilẹ̀ wá ọ, síbẹ̀ a kì yóò tún rí ọ mọ́, ní Olúwa Olódùmarè wí.”
Bo uczynię to, że będziesz na wielki postrach, gdy cię nie stanie; a choćby cię szukano, nie znajdą cię na wieki, mówi panujący Pan.

< Ezekiel 26 >