< Ezekiel 26 >
1 Ní ọjọ́ kìn-ín-ní, oṣù kọ́kànlá, ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé:
Et il arriva à la onzième année, au premier jour du mois, que la parole du Seigneur me fut adressée, disant:
2 “Ọmọ ènìyàn, nítorí pé Tire sọ nípa Jerusalẹmu pé, ‘Háà! A fọ́ èyí tí í ṣe bodè àwọn orílẹ̀-èdè, a yí i padà sí mi, èmi yóò di kíkún, òun yóò sì di ahoro,’
Fils d’un homme, à cause que Tyr a dit de Jérusalem: Très bien: les portes des peuples ont été brisées, elle s’est tournée vers moi; je serai remplie, elle est déserte;
3 nítorí náà, báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí, kíyèsi i, èmí dojúkọ ọ́ ìwọ tire, Èmi yóò sì jẹ́ kí Orílẹ̀-èdè púpọ̀ dìde sí ọ, gẹ́gẹ́ bí Òkun tí ru sókè.
À cause de cela, voici ce que dit le Seigneur Dieu: Voilà que moi je suis contre toi, ô Tyr, et je ferai monter vers toi des nations nombreuses, comme la mer fait monter ses flots.
4 Wọn yóò wó odi tire lulẹ̀, wọn yóò sì wo ilé ìṣọ́ rẹ̀ lulẹ̀, Èmi yóò sì ha erùpẹ̀ rẹ̀ kúrò, Èmi yóò sì sọ ọ́ di orí àpáta.
Et ils renverseront les murs de Tyr, et ils détruiront ses tours; j’en raclerai la poussière, et je la rendrai comme une pierre très lisse.
5 Yóò sì jẹ́ ibi nína àwọ̀n tí wọn fi ń pẹja sí láàrín Òkun, ní Olúwa Olódùmarè wí. Yóò di ìkógun fún àwọn orílẹ̀-èdè.
Elle servira à sécher les filets au milieu de la mer; parce que moi j’ai parlé, dit le Seigneur Dieu; et Tyr sera en proie aux nations.
6 Ìlú tí ó tẹ̀dó sí, ní àárín gbùngbùn ilẹ̀ rẹ̀ ni a ó fi idà sọ ọ́ di ahoro. Nígbà náà ní wọn yóò mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.
Ses filles aussi qui sont dans la campagne seront tuées par le glaive; et ils sauront que je suis le Seigneur.
7 “Nítorí báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí: Kíyèsi i, láti ìhà àríwá ni èmi yóò ti mú Nebukadnessari ọba Babeli, ọba àwọn ọba, dìde sí Tire pẹ̀lú ẹṣin àti kẹ̀kẹ́ ogun pẹ̀lú àwọn ẹlẹ́ṣin àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn ológun.
Parce que voici ce que dit le Seigneur Dieu: Voilà que moi j’amènerai à Tyr, de la terre de l’aquilon, Nabuchodonosor, roi de Babylone, roi des rois, avec des chevaux et des chars, et des cavaliers, et une multitude, et un nombreux peuple.
8 Yóò sì fi idà sá àwọn ọmọbìnrin rẹ ní oko, yóò sì kọ́ odi tì ọ́, yóò sì mọ òkìtì tì ọ́, yóò sì gbé àpáta sókè sí ọ.
Tes filles qui sont dans la campagne, il les tuera par le glaive; et il t’environnera de fortifications, et il formera un rempart autour, et il élèvera contre toi un bouclier.
9 Yóò sì gbé ẹ̀rọ ogun tí odi rẹ, yóò sì fi ohun èlò ogun wó ilé ìṣọ́ rẹ palẹ̀.
Et il organisera des mantelets et des béliers contre tes murs, et il détruira tes tours avec ses armes.
10 Àwọn ẹṣin rẹ̀ yóò pọ̀ dé bí pé wọn yóò fi eruku bò ọ́ mọ́lẹ̀. Àwọn ògiri rẹ yóò mì tìtì fún igbe àwọn ẹṣin ogun kẹ̀kẹ́ ẹrù àti kẹ̀kẹ́ ogun nígbà tí ó bá wọ ẹnu-ọ̀nà odi gẹ́gẹ́ bí ènìyàn tí ń wọ ìlú láti inú àwọn ògiri rẹ̀ ti ó di fífọ́ pátápátá.
À cause de l’inondation de ses chevaux tu seras couverte de poussière; au bruit des cavaliers, et des roues, et des chars, tes murailles s’ébranleront, lorsqu’il entrera dans tes portes comme par la brèche d’une ville prise d’assaut.
11 Pátákò ẹsẹ̀ ẹṣin rẹ̀ ni yóò fi tẹ gbogbo òpópónà rẹ mọ́lẹ̀; yóò fi idà pa àwọn ènìyàn rẹ, àwọn ọ̀wọ́n rẹ ti o lágbára yóò wó palẹ̀.
Sous les sabots de ses chevaux il foulera toutes tes places: il frappera ton peuple du glaive, et tes fameuses statues tomberont à terre.
12 Wọn yóò kó ọrọ̀ rẹ, wọn yóò sì fi òwò rẹ ṣe ìjẹ ogun; wọn yóò sì wó odi rẹ lulẹ̀, wọn yóò sì ba àwọn ilé rẹ dídára jẹ́, wọn yóò sì kó àwọn òkúta rẹ̀, àti igi ìtì ìkọ́lé rẹ̀, àti erùpẹ̀ rẹ̀, dà sí inú Òkun.
Ils raviront tes richesses, pilleront tes marchandises, et détruiront tes murs; ils renverseront tes maisons magnifiques, et tes pierres, et tes bois, et ta poussière, ils les jetteront au milieu des eaux.
13 Èmi yóò sì mú ariwo orin rẹ̀ dákẹ́ àti ìró dùùrù orin rẹ̀ ni a kì yóò gbọ́ mọ́.
Et je ferai cesser la multitude de tes cantiques, et le son de tes harpes ne sera plus entendu.
14 Èmi yóò sọ ọ di àpáta lásán, ìwọ yóò sì di ibi tí a ń sá àwọ̀n ẹja sí. A kì yóò sì tún ọ mọ nítorí Èmi Olúwa ti sọ ọ̀rọ̀ ní Olúwa Olódùmarè wí.
Et je te rendrai comme une pierre très lisse, et tu serviras à sécher les filets, et tu ne seras plus rebâtie; parce que moi j’ai parlé, dit le Seigneur Dieu.
15 “Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí sí Tire: Ǹjẹ́ àwọn erékùṣù kì yóò ha wárìrì nípa ìṣubú rẹ, nígbà tí ìkórìíra ìpalára àti rírẹ́ni lọ́run bá ń ṣẹlẹ̀ ní inú rẹ?
Voici ce que dit le Seigneur Dieu à Tyr: Est-ce qu’au bruit de ta ruine, et au gémissement de tes tués, lorsqu’ils auront été mis à mort au milieu de toi, les îles ne seront pas émues?
16 Nígbà náà ni gbogbo àwọn ọmọ-aládé etí Òkun yóò sọ̀kalẹ̀ láti orí ìtẹ́ wọn, wọn yóò sì pa àwọn aṣọ ìgúnwà wọn da, tì wọn yóò sì bọ́ àwọn aṣọ iṣẹ́ ọnà abẹ́rẹ́ kúrò. Ẹ̀rù yóò bò wọ́n, wọn yóò sì jókòó lórí ilẹ̀ pẹ̀pẹ̀, wọn yóò sì máa wárìrì ní gbogbo ìgbà, ẹnu yóò sì yà wọ́n sí ọ́.
Et tous les princes de la mer descendront de leurs trônes, et ils quitteront les marques de leur grandeur, et ils jetteront leurs habits de diverses couleurs, et ils seront vêtus de stupeur; ils s’assiéront sur la terre, et épouvantés de ta chute soudaine, ils seront dans l’étonnement.
17 Nígbà náà wọn yóò gbóhùn ẹkún sókè nítorí rẹ, wọn yóò sì wí fún ọ pé: “‘Báwo ni a ṣe pa ọ́ run, ìwọ ìlú olókìkí ìwọ tí àwọn èrò okun ti gbé inú rẹ̀! Ìwọ jẹ alágbára lórí okun gbogbo òun àti àwọn olùgbé inú rẹ̀; ìwọ gbé ẹ̀rù rẹ lórí gbogbo olùgbé ibẹ̀.
Et faisant entendre sur toi des lamentations, ils te diront: Comment as-tu péri, toi qui habites sur la mer, ville illustre, qui as été puissante sur la mer, avec tes habitants que tous redoutaient?
18 Nísinsin yìí erékùṣù wárìrì ní ọjọ́ ìṣubú rẹ; erékùṣù tí ó wà nínú Òkun ni ẹ̀rù bà torí ìṣubú rẹ.’
Désormais les vaisseaux seront frappés de stupeur au jour de ton effroi, et les îles seront troublées dans la mer, parce que personne ne sort de toi.
19 “Èyí yìí ní Olúwa Olódùmarè wí: Nígbà tí mo bá sọ ọ́ di ìlú ahoro, gẹ́gẹ́ bi àwọn ìlú tí a kò gbé inú wọn mọ́, àti nígbà tí èmi yóò mú ibú agbami Òkun wá sí orí rẹ, omi ńlá yóò sì bò ọ́,
Parce que voici ce que dit le Seigneur Dieu: Lorsque j’aurai fait de toi une ville désolée comme les cités qui ne sont pas habitées, et que j’aurai amené sur toi l’abîme, et que les grandes eaux t’auront couverte;
20 nígbà tí èmi yóò mú ọ wálẹ̀ pẹ̀lú àwọn tí ó sọ̀kalẹ̀ lọ sínú ihò, pẹ̀lú àwọn ènìyàn àtijọ́. Èmi yóò sì gbé ọ lọ si bi ìsàlẹ̀, ní ibi ahoro àtijọ́, pẹ̀lú àwọn tí ó sọ̀kalẹ̀ lọ sínú ihò, ìwọ kì yóò sì padà gbé inú rẹ̀ mọ́, èmi yóò sì gbé ògo kalẹ̀ ní ilẹ̀ àwọn alààyè.
Et que je t’aurai précipitée avec ceux qui descendent dans la fosse vers le peuple éternel, et que je t’aurai placée dans une terre très profonde, comme les solitudes anciennes, avec ceux qui sont conduits dans la fosse, afin que tu ne sois pas habitée; mais lorsque j’aurai établi ma gloire dans la terre des vivants,
21 Èmi yóò ṣe ọ ní ẹ̀rù, ìwọ kì yóò sì ṣí mọ́. Bí a tilẹ̀ wá ọ, síbẹ̀ a kì yóò tún rí ọ mọ́, ní Olúwa Olódùmarè wí.”
Je te réduirai à rien, et tu ne seras plus; et on te cherchera, et on ne te trouvera plus jamais, dit le Seigneur Dieu.