< Ezekiel 26 >

1 Ní ọjọ́ kìn-ín-ní, oṣù kọ́kànlá, ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé:
Og det skete i det ellevte Aar, paa den første Dag i Maaneden, at Herrens Ord kom til mig saaledes:
2 “Ọmọ ènìyàn, nítorí pé Tire sọ nípa Jerusalẹmu pé, ‘Háà! A fọ́ èyí tí í ṣe bodè àwọn orílẹ̀-èdè, a yí i padà sí mi, èmi yóò di kíkún, òun yóò sì di ahoro,’
Du Menneskesøn! fordi Tyrus siger over Jerusalem: Ha ha! sønderbrudt er Folkenes Port; det har vendt sig til mig; jeg vil blive fyldt, den er ødelagt;
3 nítorí náà, báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí, kíyèsi i, èmí dojúkọ ọ́ ìwọ tire, Èmi yóò sì jẹ́ kí Orílẹ̀-èdè púpọ̀ dìde sí ọ, gẹ́gẹ́ bí Òkun tí ru sókè.
derfor, saa siger den Herre, Herre: Se, jeg kommer over dig, Tyrus! og jeg vil føre mange Folkefærd op imod dig, ligesom Havet rejser sine Bølger.
4 Wọn yóò wó odi tire lulẹ̀, wọn yóò sì wo ilé ìṣọ́ rẹ̀ lulẹ̀, Èmi yóò sì ha erùpẹ̀ rẹ̀ kúrò, Èmi yóò sì sọ ọ́ di orí àpáta.
Og de skulle ødelægge Murene om Tyrus og nedbryde dens Taarne, og jeg vil bortfeje dens Støv af den og gøre den til en solbrændt Klippe.
5 Yóò sì jẹ́ ibi nína àwọ̀n tí wọn fi ń pẹja sí láàrín Òkun, ní Olúwa Olódùmarè wí. Yóò di ìkógun fún àwọn orílẹ̀-èdè.
Den skal blive til at udbrede Fiskegarn paa midt i Havet; thi jeg har talt det, siger den Herre, Herre; og den skal vorde til Bytte for Folkene.
6 Ìlú tí ó tẹ̀dó sí, ní àárín gbùngbùn ilẹ̀ rẹ̀ ni a ó fi idà sọ ọ́ di ahoro. Nígbà náà ní wọn yóò mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.
Og dens Døtre, som ere paa Landet, skulle ihjelslaaes med Sværdet; og de skulle fornemme, at jeg er Herren.
7 “Nítorí báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí: Kíyèsi i, láti ìhà àríwá ni èmi yóò ti mú Nebukadnessari ọba Babeli, ọba àwọn ọba, dìde sí Tire pẹ̀lú ẹṣin àti kẹ̀kẹ́ ogun pẹ̀lú àwọn ẹlẹ́ṣin àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn ológun.
Thi saa siger den Herre, Herre: Se, jeg vil lade Nebukadnezar, Kongen af Babel, komme imod Tyrus fra Norden, ham, som er Kongers Konge, med Heste og med Vogne og med Ryttere og med en Skare og meget Folk.
8 Yóò sì fi idà sá àwọn ọmọbìnrin rẹ ní oko, yóò sì kọ́ odi tì ọ́, yóò sì mọ òkìtì tì ọ́, yóò sì gbé àpáta sókè sí ọ.
Dine Døtre paa Landet skal han ihjelslaa med Sværdet; og han skal sætte Vagttaarne op imod dig og opkaste en Vold imod dig og oprejse et Skjoldtag imod dig.
9 Yóò sì gbé ẹ̀rọ ogun tí odi rẹ, yóò sì fi ohun èlò ogun wó ilé ìṣọ́ rẹ palẹ̀.
Og han skal sætte Murbrækker imod dine Mure og nedbryde dine Taarne ved sine Sværd.
10 Àwọn ẹṣin rẹ̀ yóò pọ̀ dé bí pé wọn yóò fi eruku bò ọ́ mọ́lẹ̀. Àwọn ògiri rẹ yóò mì tìtì fún igbe àwọn ẹṣin ogun kẹ̀kẹ́ ẹrù àti kẹ̀kẹ́ ogun nígbà tí ó bá wọ ẹnu-ọ̀nà odi gẹ́gẹ́ bí ènìyàn tí ń wọ ìlú láti inú àwọn ògiri rẹ̀ ti ó di fífọ́ pátápátá.
Formedelst Mangfoldigheden af hans Heste skal deres Støv bedække dig; dine Mure skulle ryste af Rytteres og Hjuls og Vognes Lyd, naar han drager ind ad dine Porte, ligesom man drager ind i en stormet Stad.
11 Pátákò ẹsẹ̀ ẹṣin rẹ̀ ni yóò fi tẹ gbogbo òpópónà rẹ mọ́lẹ̀; yóò fi idà pa àwọn ènìyàn rẹ, àwọn ọ̀wọ́n rẹ ti o lágbára yóò wó palẹ̀.
Han skal nedtrampe alle dine Gader med sine Hestes Hove; han skal ihjelslaa dit Folk med Sværdet, og dine stærke Støtter skulle falde til Jorden.
12 Wọn yóò kó ọrọ̀ rẹ, wọn yóò sì fi òwò rẹ ṣe ìjẹ ogun; wọn yóò sì wó odi rẹ lulẹ̀, wọn yóò sì ba àwọn ilé rẹ dídára jẹ́, wọn yóò sì kó àwọn òkúta rẹ̀, àti igi ìtì ìkọ́lé rẹ̀, àti erùpẹ̀ rẹ̀, dà sí inú Òkun.
Og de skulle røve dit Gods og gøre dine Varer til Bytte og nedbryde dine Mure og nedrive dine lystelige Huse, og de skulle kaste dine Stene og dit Tømmer og dit Støv midt ud i Vandet.
13 Èmi yóò sì mú ariwo orin rẹ̀ dákẹ́ àti ìró dùùrù orin rẹ̀ ni a kì yóò gbọ́ mọ́.
Og jeg vil bringe dine Sanges Bulder til at tie, og dine Harpers Klang skal ikke høres ydermere.
14 Èmi yóò sọ ọ di àpáta lásán, ìwọ yóò sì di ibi tí a ń sá àwọ̀n ẹja sí. A kì yóò sì tún ọ mọ nítorí Èmi Olúwa ti sọ ọ̀rọ̀ ní Olúwa Olódùmarè wí.
Jeg vil gøre dig til en solbrændt Klippe, du skal blive til at udbrede Fiskegarn paa, du skal ikke ydermere bygges; thi jeg Herren, jeg har talt det, siger den Herre, Herre.
15 “Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí sí Tire: Ǹjẹ́ àwọn erékùṣù kì yóò ha wárìrì nípa ìṣubú rẹ, nígbà tí ìkórìíra ìpalára àti rírẹ́ni lọ́run bá ń ṣẹlẹ̀ ní inú rẹ?
Saa siger den Herre, Herre til Tyrus: Mon Øerne ikke skulle bæve ved Lyden af dit Fald, naar de saarede jamre sig, naar Mord rase i din Midte?
16 Nígbà náà ni gbogbo àwọn ọmọ-aládé etí Òkun yóò sọ̀kalẹ̀ láti orí ìtẹ́ wọn, wọn yóò sì pa àwọn aṣọ ìgúnwà wọn da, tì wọn yóò sì bọ́ àwọn aṣọ iṣẹ́ ọnà abẹ́rẹ́ kúrò. Ẹ̀rù yóò bò wọ́n, wọn yóò sì jókòó lórí ilẹ̀ pẹ̀pẹ̀, wọn yóò sì máa wárìrì ní gbogbo ìgbà, ẹnu yóò sì yà wọ́n sí ọ́.
Og alle Fyrster ved Havet skulle nedstige af deres Troner og aflægge deres Kapper og afføre sig deres stukne Klæder; de skulle iføre sig Forfærdelse, sidde paa Jorden og forfærdes hvert Øjeblik og forskrækkes over dig.
17 Nígbà náà wọn yóò gbóhùn ẹkún sókè nítorí rẹ, wọn yóò sì wí fún ọ pé: “‘Báwo ni a ṣe pa ọ́ run, ìwọ ìlú olókìkí ìwọ tí àwọn èrò okun ti gbé inú rẹ̀! Ìwọ jẹ alágbára lórí okun gbogbo òun àti àwọn olùgbé inú rẹ̀; ìwọ gbé ẹ̀rù rẹ lórí gbogbo olùgbé ibẹ̀.
Og de skulle opløfte et Klagemaal over dig og sige til dig: Hvorledes er du gaaet til Grunde, du Havets Beboerinde? den lovpriste Stad, som var fast i Havet, den og dens Indbyggere, som udbredte Skræk for sig over alle dem, som boede der!
18 Nísinsin yìí erékùṣù wárìrì ní ọjọ́ ìṣubú rẹ; erékùṣù tí ó wà nínú Òkun ni ẹ̀rù bà torí ìṣubú rẹ.’
Nu skulle Øerne forfærdes paa dit Falds Dag, og Øerne, som ere i Havet, skulle forskrækkes over den Udgang, det tog med dig.
19 “Èyí yìí ní Olúwa Olódùmarè wí: Nígbà tí mo bá sọ ọ́ di ìlú ahoro, gẹ́gẹ́ bi àwọn ìlú tí a kò gbé inú wọn mọ́, àti nígbà tí èmi yóò mú ibú agbami Òkun wá sí orí rẹ, omi ńlá yóò sì bò ọ́,
Thi saa siger den Herre, Herre: Naar jeg gør dig til en ødelagt Stad som Stæderne, i hvilke man ikke mere bor; naar jeg lader Dybet stige op over dig, og de mange Vande bedække dig:
20 nígbà tí èmi yóò mú ọ wálẹ̀ pẹ̀lú àwọn tí ó sọ̀kalẹ̀ lọ sínú ihò, pẹ̀lú àwọn ènìyàn àtijọ́. Èmi yóò sì gbé ọ lọ si bi ìsàlẹ̀, ní ibi ahoro àtijọ́, pẹ̀lú àwọn tí ó sọ̀kalẹ̀ lọ sínú ihò, ìwọ kì yóò sì padà gbé inú rẹ̀ mọ́, èmi yóò sì gbé ògo kalẹ̀ ní ilẹ̀ àwọn alààyè.
Da vil jeg kaste dig ned til dem, som fare ned i Hulen, til Oldtidens Folk, og lade dig bo i Underverdenens Land, i Ørkenerne fra Oldtiden hos dem, som fore ned i Hulen, paa det du ikke mere skal bebos; men jeg vil give Herlighed i de levendes Land.
21 Èmi yóò ṣe ọ ní ẹ̀rù, ìwọ kì yóò sì ṣí mọ́. Bí a tilẹ̀ wá ọ, síbẹ̀ a kì yóò tún rí ọ mọ́, ní Olúwa Olódùmarè wí.”
Jeg vil gøre dig til Gru, og du skal ikke være mere; naar der spørges om dig, da skal du ikke findes ydermere evindelig, siger den Herre, Herre.

< Ezekiel 26 >