< Ezekiel 26 >
1 Ní ọjọ́ kìn-ín-ní, oṣù kọ́kànlá, ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé:
Bylo pak jedenáctého léta, prvního dne měsíce, že se stalo slovo Hospodinovo ke mně, řkoucí:
2 “Ọmọ ènìyàn, nítorí pé Tire sọ nípa Jerusalẹmu pé, ‘Háà! A fọ́ èyí tí í ṣe bodè àwọn orílẹ̀-èdè, a yí i padà sí mi, èmi yóò di kíkún, òun yóò sì di ahoro,’
Synu člověčí, proto že Týrus o Jeruzalému říká: Dobře se stalo, že jest potříno město bran velmi lidných, obrací se ke mně, naplněn budu, kdyžtě zpuštěno,
3 nítorí náà, báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí, kíyèsi i, èmí dojúkọ ọ́ ìwọ tire, Èmi yóò sì jẹ́ kí Orílẹ̀-èdè púpọ̀ dìde sí ọ, gẹ́gẹ́ bí Òkun tí ru sókè.
Protož takto praví Panovník Hospodin: Aj, já proti tobě, ó Týre, a přivedu na tě národy mnohé, tak jako bych přivedl moře s vlnami jeho.
4 Wọn yóò wó odi tire lulẹ̀, wọn yóò sì wo ilé ìṣọ́ rẹ̀ lulẹ̀, Èmi yóò sì ha erùpẹ̀ rẹ̀ kúrò, Èmi yóò sì sọ ọ́ di orí àpáta.
I zkazí zdi Týru, a zboří věže jeho; vymetu také z něho prach jeho, a obrátím jej v skálu vysedlou,
5 Yóò sì jẹ́ ibi nína àwọ̀n tí wọn fi ń pẹja sí láàrín Òkun, ní Olúwa Olódùmarè wí. Yóò di ìkógun fún àwọn orílẹ̀-èdè.
Tak že budou vysušovati síti u prostřed moře. Nebo jsem já mluvil, praví Panovník Hospodin, protož bude v loupež národům.
6 Ìlú tí ó tẹ̀dó sí, ní àárín gbùngbùn ilẹ̀ rẹ̀ ni a ó fi idà sọ ọ́ di ahoro. Nígbà náà ní wọn yóò mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.
Dcery pak jeho, kteréž na poli budou, mečem zmordovány budou, i zvědí, že já jsem Hospodin.
7 “Nítorí báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí: Kíyèsi i, láti ìhà àríwá ni èmi yóò ti mú Nebukadnessari ọba Babeli, ọba àwọn ọba, dìde sí Tire pẹ̀lú ẹṣin àti kẹ̀kẹ́ ogun pẹ̀lú àwọn ẹlẹ́ṣin àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn ológun.
Nebo takto praví Panovník Hospodin: Aj, já přivedu na Týr Nabuchodonozora krále Babylonského od půlnoci, krále nad králi, s koňmi a s vozy, i s jezdci i s vojskem a s lidem mnohým.
8 Yóò sì fi idà sá àwọn ọmọbìnrin rẹ ní oko, yóò sì kọ́ odi tì ọ́, yóò sì mọ òkìtì tì ọ́, yóò sì gbé àpáta sókè sí ọ.
Dcery tvé na poli mečem zmorduje, a vzdělá proti tobě šance, a vysype proti tobě násyp, a postaví proti tobě pavézníky.
9 Yóò sì gbé ẹ̀rọ ogun tí odi rẹ, yóò sì fi ohun èlò ogun wó ilé ìṣọ́ rẹ palẹ̀.
I střelbu zasadí proti zdem tvým, a věže tvé poboří nosatci svými.
10 Àwọn ẹṣin rẹ̀ yóò pọ̀ dé bí pé wọn yóò fi eruku bò ọ́ mọ́lẹ̀. Àwọn ògiri rẹ yóò mì tìtì fún igbe àwọn ẹṣin ogun kẹ̀kẹ́ ẹrù àti kẹ̀kẹ́ ogun nígbà tí ó bá wọ ẹnu-ọ̀nà odi gẹ́gẹ́ bí ènìyàn tí ń wọ ìlú láti inú àwọn ògiri rẹ̀ ti ó di fífọ́ pátápátá.
Od množství koní jeho přikryje tě prach jejich; od hřmotu jezdců a kár i vozů zatřesou se zdi tvé, když on vcházeti bude do bran tvých, jako do průchodů města probořeného.
11 Pátákò ẹsẹ̀ ẹṣin rẹ̀ ni yóò fi tẹ gbogbo òpópónà rẹ mọ́lẹ̀; yóò fi idà pa àwọn ènìyàn rẹ, àwọn ọ̀wọ́n rẹ ti o lágbára yóò wó palẹ̀.
Kopyty koní svých pošlapá všecky ulice tvé, lid tvůj mečem pomorduje, a sloupové pamětní síly tvé na zem padnou.
12 Wọn yóò kó ọrọ̀ rẹ, wọn yóò sì fi òwò rẹ ṣe ìjẹ ogun; wọn yóò sì wó odi rẹ lulẹ̀, wọn yóò sì ba àwọn ilé rẹ dídára jẹ́, wọn yóò sì kó àwọn òkúta rẹ̀, àti igi ìtì ìkọ́lé rẹ̀, àti erùpẹ̀ rẹ̀, dà sí inú Òkun.
I rozberou zboží tvá, a rozchvátají kupectví tvá, a rozválejí zdi tvé, i domy tvé rozkošné poboří, a kamení tvé i dříví tvé, i prach tvůj do vody vmecí.
13 Èmi yóò sì mú ariwo orin rẹ̀ dákẹ́ àti ìró dùùrù orin rẹ̀ ni a kì yóò gbọ́ mọ́.
A tak přítrž učiním hluku zpěvů tvých, a zvuku citar tvých aby nebylo slýcháno více.
14 Èmi yóò sọ ọ di àpáta lásán, ìwọ yóò sì di ibi tí a ń sá àwọ̀n ẹja sí. A kì yóò sì tún ọ mọ nítorí Èmi Olúwa ti sọ ọ̀rọ̀ ní Olúwa Olódùmarè wí.
A obrátím tě v skálu vysedlou, budeš k vysušování sítí, nebudeš vystaven více; nebo já Hospodin mluvil jsem, praví Panovník Hospodin.
15 “Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí sí Tire: Ǹjẹ́ àwọn erékùṣù kì yóò ha wárìrì nípa ìṣubú rẹ, nígbà tí ìkórìíra ìpalára àti rírẹ́ni lọ́run bá ń ṣẹlẹ̀ ní inú rẹ?
Takto praví Panovník Hospodin Týru: Zdaliž od hřmotu padání tvého, když stonati budou zranění, když ukrutný mord bude u prostřed tebe, nepohnou se ostrovové?
16 Nígbà náà ni gbogbo àwọn ọmọ-aládé etí Òkun yóò sọ̀kalẹ̀ láti orí ìtẹ́ wọn, wọn yóò sì pa àwọn aṣọ ìgúnwà wọn da, tì wọn yóò sì bọ́ àwọn aṣọ iṣẹ́ ọnà abẹ́rẹ́ kúrò. Ẹ̀rù yóò bò wọ́n, wọn yóò sì jókòó lórí ilẹ̀ pẹ̀pẹ̀, wọn yóò sì máa wárìrì ní gbogbo ìgbà, ẹnu yóò sì yà wọ́n sí ọ́.
A vyvstanou z stolic svých všecka knížata pomořská, a složí z sebe pláště své, i roucha svá krumpovaná svlekou; v hrůzu se oblekou, na zemi seděti budou, a třesouce se každé chvíle, trnouti budou nad tebou.
17 Nígbà náà wọn yóò gbóhùn ẹkún sókè nítorí rẹ, wọn yóò sì wí fún ọ pé: “‘Báwo ni a ṣe pa ọ́ run, ìwọ ìlú olókìkí ìwọ tí àwọn èrò okun ti gbé inú rẹ̀! Ìwọ jẹ alágbára lórí okun gbogbo òun àti àwọn olùgbé inú rẹ̀; ìwọ gbé ẹ̀rù rẹ lórí gbogbo olùgbé ibẹ̀.
I vydadí se nad tebou v naříkání, a řeknou tobě: Jak jsi zahynulo, ó město, v němž bydleno bylo pro moře, město slovoutné, ješto bylo pevné na moři, ono i s obyvateli svými, kteříž pouštěli strach svůj na všecky obyvatele jeho!
18 Nísinsin yìí erékùṣù wárìrì ní ọjọ́ ìṣubú rẹ; erékùṣù tí ó wà nínú Òkun ni ẹ̀rù bà torí ìṣubú rẹ.’
Tehdáž třásti se budou ostrovové v den pádu tvého; předěšeni, pravím, budou ostrovové, kteříž jsou na moři, nad zahynutím tvým.
19 “Èyí yìí ní Olúwa Olódùmarè wí: Nígbà tí mo bá sọ ọ́ di ìlú ahoro, gẹ́gẹ́ bi àwọn ìlú tí a kò gbé inú wọn mọ́, àti nígbà tí èmi yóò mú ibú agbami Òkun wá sí orí rẹ, omi ńlá yóò sì bò ọ́,
Nebo tak praví Panovník Hospodin: Když tě učiním městem zpuštěným jako města, v nichž se nebydlí, když uvedu na tě hlubinu, tak že tě přikryjí vody mnohé,
20 nígbà tí èmi yóò mú ọ wálẹ̀ pẹ̀lú àwọn tí ó sọ̀kalẹ̀ lọ sínú ihò, pẹ̀lú àwọn ènìyàn àtijọ́. Èmi yóò sì gbé ọ lọ si bi ìsàlẹ̀, ní ibi ahoro àtijọ́, pẹ̀lú àwọn tí ó sọ̀kalẹ̀ lọ sínú ihò, ìwọ kì yóò sì padà gbé inú rẹ̀ mọ́, èmi yóò sì gbé ògo kalẹ̀ ní ilẹ̀ àwọn alààyè.
Když učiním, že sstoupíš s sstupujícími do jámy k lidu dávnímu, a posadím tě v nejnižších stranách země, na pustinách starodávních s těmi, jenž sstupují do jámy, aby nebylo bydleno v tobě: prokáži slávu v zemi živých.
21 Èmi yóò ṣe ọ ní ẹ̀rù, ìwọ kì yóò sì ṣí mọ́. Bí a tilẹ̀ wá ọ, síbẹ̀ a kì yóò tún rí ọ mọ́, ní Olúwa Olódùmarè wí.”
Nebo učiním to, že budeš k náramné hrůze, když tě nestane, a bys pak bylo hledáno, abys nebylo na věky nalezeno, praví Panovník Hospodin.